< Lawiylar 20 >

1 Pǝrwǝrdigar Musaƣa sɵz ⱪilip mundaⱪ dedi: —
Olúwa sọ fún Mose pé,
2 Sǝn Israillarƣa sɵz ⱪilip mundaⱪ degin: — Əgǝr Israillarning biri wǝ yaki Israil zeminida turuwatⱪan musapirlarning biri Molǝk butiƣa nǝslining birini beƣixlisa, uningƣa ɵlüm jazasi berilixi kerǝk; zemindikilǝr uni qalma-kesǝk ⱪilsun.
“Sọ fún àwọn ará Israẹli pé, ‘Ẹnikẹ́ni nínú àwọn ará Israẹli tàbí àwọn àlejò tí ń gbé láàrín Israẹli, tí ó bá fi èyíkéyìí nínú àwọn ọmọ rẹ̀ fún Moleki, kí wọ́n pa á, kí àwọn olùgbé ilẹ̀ náà sọ ọ́ ní òkúta pa.
3 Wǝ Mǝn Ɵz yüzümni bu kixigǝ ⱪarxi ⱪilimǝn, qünki ɵzi ɵz ǝwladlirining birini Molǝk butiƣa beƣixlap muⱪǝddǝs jayimni paskina ⱪilip, Mening namimni bulƣiƣini üqün uni ɵz hǝlⱪidin üzüp taxlaymǝn.
Èmi tìkára mi yóò bínú sí irú ẹni bẹ́ẹ̀, ń ó sì gé e kúrò láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀ fún òrìṣà Moleki ó ti ba ibi mímọ́ mi jẹ́ pẹ̀lú.
4 Əgǝr zeminda turuwatⱪanlar ɵz nǝslidin birini Molǝkkǝ beƣixliƣanda xu kixigǝ kɵzlirini yumup, uning bilǝn kari bolmisa, xundaⱪla uni ɵltürmisǝ,
Bí àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà bá mójú kúrò lára irú ẹni bẹ́ẹ̀ tí ó fi ọ̀kan nínú àwọn ọmọ rẹ̀ fún òrìṣà Moleki tí wọn kò sì pa irú ẹni bẹ́ẹ̀.
5 Mǝn Ɵzüm yüzümni u kixi bilǝn uning ailisigǝ ⱪarxi ⱪilimǝn, uni wǝ uningƣa ǝgixip buzuⱪqiliⱪ ⱪilƣuqilar, yǝni Molǝkning kǝynidin yürüp buzuⱪqiliⱪ ⱪilƣuqilarning ⱨǝmmisini ɵz hǝlⱪidin üzüp taxlaymǝn.
Èmi yóò bínú sí irú ẹni bẹ́ẹ̀ àti gbogbo ìdílé rẹ̀, èmi yóò sì ké wọn kúrò láàrín àwọn ènìyàn wọn, òun àti gbogbo àwọn tí ó jọ ṣe àgbèrè tọ òrìṣà Moleki lẹ́yìn.
6 Jinkǝxlǝr bilǝn seⱨirgǝrlǝrgǝ tayinip, ularning kǝynigǝ kirip buzuⱪqiliⱪ ⱪilip yürgüqilǝr bolsa, Mǝn yüzümni xu kixilǝrgǝ ⱪarxi ⱪilip, uni ɵz hǝlⱪidin üzüp taxlaymǝn.
“‘Bí ẹnikẹ́ni bá tọ àwọn abókùúsọ̀rọ̀ àti àwọn ẹlẹ́mìí òkùnkùn lọ, tí ó sì ṣe àgbèrè tọ̀ wọ́n lẹ́yìn, Èmi yóò bínú sí irú ẹni bẹ́ẹ̀, Èmi yóò sì gé e kúrò láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀.
7 Xunga ɵzünglarni pak ⱪilip muⱪǝddǝs bolunglar, qünki Mǝn Hudayinglar Pǝrwǝrdigardurmǝn.
“‘Torí náà ẹ ya ara yín sí mímọ́ kí ẹ sì jẹ́ mímọ́, torí pé, Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.
8 Ⱪanun-bǝlgilimilirimni tutup, ularƣa ǝmǝl ⱪilinglar; Mǝn bolsam silǝrni muⱪǝddǝs ⱪilƣuqi Pǝrwǝrdigardurmǝn.
Ẹ máa kíyèsi àṣẹ mi, kí ẹ sì máa pa wọ́n mọ́. Èmi ni Olúwa tí ó sọ yín di mímọ́.
9 Əgǝr birkim ɵz atisi yaki anisini ⱪarƣisa, ularƣa ɵlüm jazasi berilmisǝ bolmaydu; qünki u ɵz ata-anisini ⱪarƣiƣini üqün ɵz ⱪeni ɵz bexiƣa qüxkǝn bolidu.
“‘Ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣépè lé baba tàbí ìyá rẹ̀ ni kí ẹ pa, ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ wà lórí ara rẹ̀ torí pé ó ti ṣépè lé baba àti ìyá rẹ̀.
10 Əgǝr birkim baxⱪisining ayali bilǝn zina ⱪilsa, yǝni ɵz ⱪoxnisining ayali bilǝn zina ⱪilsa, zina ⱪilƣan ǝr bilǝn ayal ikkisi ɵlüm jazasini tartmisa bolmaydu.
“‘Bí ẹnikẹ́ni bá bá aya aládùúgbò rẹ̀ lòpọ̀: ọkùnrin àti obìnrin náà ni kí ẹ sọ ní òkúta pa.
11 Əgǝr birsi atisining ayali bilǝn yatsa, ɵz atisining ǝwritigǝ tǝgkǝn bolidu; ular ikkisi ɵlüm jazasini tartmisa bolmaydu; ularning ⱪeni ɵz bexiƣa qüxkǝn bolidu.
“‘Ẹnikẹ́ni tí ó bá bá aya baba rẹ̀ lòpọ̀ ti tàbùkù baba rẹ̀. Àwọn méjèèjì ni kí ẹ pa. Ẹ̀jẹ̀ wọn yóò wà lórí wọn.
12 Birsi ɵz kelini bilǝn yatsa, ikkisi nijisliⱪ ⱪilƣini üqün ɵlüm jazasini tartmisa bolmaydu; ularning ⱪeni ɵz bexiƣa qüxkǝn bolidu.
“‘Bí ọkùnrin kan bá bá arábìnrin ìyàwó rẹ̀ lòpọ̀, àwọn méjèèjì ni kí ẹ pa, wọ́n ti ṣe ohun tí ó lòdì, ẹ̀jẹ̀ wọn yóò wà lórí wọn.
13 Birsi ayal kixi bilǝn yatⱪandǝk ǝr kixi bilǝn yatsa ikkisi yirginqlik ix ⱪilƣan bolidu; ularƣa ɵlüm jazasi berilmisǝ bolmaydu. Ɵz ⱪeni ɵz bexiƣa qüxkǝn bolidu.
“‘Bí ọkùnrin kan bá bá ọkùnrin mìíràn lòpọ̀ bí wọ́n ti í bá obìnrin lòpọ̀: àwọn méjèèjì ti ṣe ohun ìríra, pípa ni kí ẹ pa wọ́n, ẹ̀jẹ̀ wọn yóò wà lórí wọn.
14 Əgǝr birsi ⱪizi bilǝn anisini ⱪoxup hotunluⱪⱪa alsa pǝsǝndilik ⱪilƣan bolidu. Ər bilǝn ikki ayal otta kɵydürülsun. Xuning bilǝn aranglarda ⱨeq pǝsǝndilik ix bolmaydu.
“‘Bí ọkùnrin kan bá fẹ́ tìyátọmọ papọ̀, ìwà búburú ni èyí: iná ni kí ẹ fi sun wọ́n, òun àti àwọn méjèèjì, kí ìwà búburú má ba à gbilẹ̀ láàrín yín.
15 Birsi bir ⱨaywan bilǝn munasiwǝt ɵtküzsǝ, u ɵlüm jazasini tartsun, ⱨaywannimu ɵlturünglar.
“‘Bí ọkùnrin kan bá bá ẹranko lòpọ̀, ẹ gbọdọ̀ pa ọkùnrin náà àti ẹranko náà.
16 Əgǝr ayal kixi bir ⱨaywanning ⱪexiƣa berip munasiwǝt ⱪildursa, ayal bilǝn ⱨaywanning ikkisini ɵltürünglar; ɵz ⱪeni ɵz bexiƣa qüxkǝn bolidu.
“‘Bí obìnrin kan bá súnmọ́ ẹranko tí ó sì bá a lòpọ̀ obìnrin náà àti ẹranko náà ni kí ẹ pa, ẹ̀jẹ̀ wọn yóò sì wà lórí ara wọn.
17 Birsi aqa-singlisini, yǝni atisidin yaki anisidin bolƣan ⱪizni elip, ǝwritigǝ tǝgsǝ wǝ bu ⱪizmu uning ǝwritigǝ tǝgsǝ uyatliⱪ ix bolidu; xuning üqün ǝr-ayal ikkisi ɵz hǝlⱪining kɵz aldidin üzüp taxlansun; u ɵz aqa yaki singlisining ǝwritigǝ tǝgkǝqkǝ, ɵz ⱪǝbiⱨliki ɵz bexiƣa qüxkǝn bolidu.
“‘Bí ọkùnrin kan bá fẹ́ arábìnrin rẹ̀ yálà ọmọbìnrin baba rẹ̀ tàbí ọmọbìnrin ìyá rẹ̀ tí ó sì bá a lòpọ̀, ohun ìtìjú ni èyí, ẹ ó gé wọn kúrò lójú àwọn ènìyàn wọn, ó ti tàbùkù arábìnrin rẹ̀. Ẹ̀bi rẹ̀ yóò wá sórí rẹ̀.
18 Birsi adǝt kɵrgǝn aƣriⱪ waⱪtida bir ayal bilǝn birgǝ yetip, uning ǝwritigǝ tǝgsǝ, undaⱪta u uning ⱪan mǝnbǝsigǝ tǝgkǝn, ayalmu ⱪan mǝnbǝsini eqip bǝrgǝn bolup, ikkisi ɵz hǝlⱪidin üzüp taxlinidu.
“‘Bí ọkùnrin kan bá súnmọ́ obìnrin, ní àkókò nǹkan oṣù rẹ̀ tí ó sì bá a lòpọ̀. Ó ti tú orísun ẹ̀jẹ̀ rẹ̀. Òun náà sì gbà á láààyè. Àwọn méjèèjì ni a ó gé kúrò láàrín àwọn ènìyàn wọn.
19 Sǝn ɵz anangning aqa-singlisi wǝ atangning aqa-singlisining ǝwritigǝ tǝgmǝ; qünki kimki xundaⱪ ⱪilsa yeⱪin tuƣⱪinining ǝwritigǝ tǝgkǝn bolidu; ular ikkilisining ɵz ⱪǝbiⱨliki ɵz bexiƣa qüxkǝn bolidu.
“‘Má ṣe bá arábìnrin baba tàbí ti ìyá rẹ lòpọ̀, nítorí o ti tú ìhòhò ìbátan rẹ, ẹ̀yin méjèèjì ni yóò ru ẹ̀bi yín.
20 Birsi taƣisining ayali bilǝn yatsa taƣisining ǝwritigǝ tǝgkǝn bolidu; ikkilisi ɵz gunaⱨini ɵz bexiƣa alidu; ular pǝrzǝntsiz ɵlidu.
“‘Bí ọkùnrin kan bá bá aya arákùnrin baba rẹ̀ lòpọ̀ ó ti tàbùkù arákùnrin baba rẹ̀. A ó jẹ wọ́n ní ìyà; wọn yóò sì kú láìlọ́mọ.
21 Birsi aka-inisining ayalini alsa paskina bir ix bolidu. U ɵz birtuƣⱪan aka-inisining ǝwritigǝ tǝgkǝn bolidu; ular ikkilisi pǝrzǝntsiz ⱪalidu.
“‘Bí ọkùnrin kan bá gba aya arákùnrin rẹ̀, ohun àìmọ́ ni èyí, ó ti tàbùkù arákùnrin rẹ̀, wọn ó wà láìlọ́mọ.
22 Silǝr Mening barliⱪ ⱪanun bǝlgilimilirim bilǝn barliⱪ ⱨɵkümlirimni tutup, buningƣa muwapiⱪ ǝmǝl ⱪilinglar; bolmisa, Mǝn silǝrni elip berip turƣuzidiƣan zemin silǝrni ⱪusup qiⱪiriwetidu.
“‘Kí ẹ pa gbogbo àṣẹ àti òfin mi mọ́, kí ẹ sì máa ṣe wọ́n. Kí ilẹ̀ náà tí èmi ó fi fún yín láti máa gbé má ba à pọ̀ yín jáde.
23 Silǝr Mǝn aldinglardin ⱨǝydiwetidiƣan ǝllǝrning rǝsim-ⱪaidiliri boyiqǝ mangsanglar bolmaydu; qünki ular bu yirginqlik ixlarning ⱨǝmmisini ⱪilip kǝldi, wǝ xuning üqün ular Manga yirginqlik boldi.
Ẹ má ṣe tẹ̀lé àṣà àwọn orílẹ̀-èdè tí mo lé jáde níwájú yín torí pé gbogbo nǹkan wọ̀nyí ni wọ́n ń ṣe, tí mo kórìíra wọn.
24 Xuning üqün Mǝn silǝrgǝ: «Silǝr ularning zeminini miras ⱪilip alisilǝr; Mǝn xu süt bilǝn ⱨǝsǝl aⱪidiƣan zeminni silǝrgǝ berimǝn», dǝp eytⱪanidim; silǝrni baxⱪa hǝlⱪlǝrdin ayrim ⱪilƣan Hudayinglar Pǝrwǝrdigardurmǝn.
Ṣùgbọ́n mo ti sọ fún yín pé, “Ẹ̀yin ni yóò jogún ilẹ̀ wọn, Èmi yóò sì fi fún yín láti jogún ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin.” Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín tí ó ti yà yín sọ́tọ̀ kúrò láàrín àwọn ènìyàn yòókù.
25 Xunga silǝr pak wǝ napak qarpaylarni pǝrⱪ etip, pak wǝ napak uqar-ⱪanatlarni tonup, Mǝn silǝr üqün ayrip, napak ⱪilip bekitip bǝrgǝn janiwarlarning iqidin ⱨǝrⱪandiⱪi, qarpay yaki uqar-ⱪanat bolsun yaki yǝrdǝ ɵmiligüqi janiwar bolsun, ularning ⱨeqbiri bilǝn ɵzünglarni napak ⱪilmanglar.
“‘Ẹ gbọdọ̀ pààlà sáàrín ẹran tí ó mọ́ àti àwọn tí kò mọ́. Láàrín ẹyẹ tí ó mọ́ àti àwọn tí kò mọ́. Ẹ má ṣe sọ ara yín di àìmọ́ nípasẹ̀ àwọn ẹranko tàbí ẹyẹ tàbí ohunkóhun tí ń rìn lórí ilẹ̀: èyí tí mo yà sọ́tọ̀ fún yín gẹ́gẹ́ bí ohun àìmọ́.
26 Silǝr Manga has pak-muⱪǝddǝs boluxunglar kerǝk; qünki Mǝn Pǝrwǝrdigar pak-muⱪǝddǝsturmǝn, silǝrni Manga has bolsun dǝp barliⱪ ǝllǝrdin ayrim ⱪilƣanmǝn.
Ẹ gbọdọ̀ jẹ́ mímọ́ fún mi torí pé, Èmi Olúwa fẹ́ mímọ́. Mó sì ti yà yín kúrò nínú àwọn orílẹ̀-èdè yòókù kí ẹ le jẹ́ tèmi.
27 Jinkǝx yaki seⱨirgǝr bolƣan ⱨǝrⱪandaⱪ ǝr yaki hotun kixigǝ ɵlüm jazasi berilmisǝ bolmaydu; hǝlⱪ ularni qalma-kesǝk ⱪilsun; ularning ⱪeni ɵz bexiƣa qüxkǝn bolidu.
“‘Ọkùnrin tàbí obìnrin tí ó jẹ́ abókùúsọ̀rọ̀ tàbí oṣó láàrín yín ni kí ẹ pa. Ẹ sọ wọ́n ní òkúta, ẹ̀jẹ̀ wọn yóò wà lórí wọn.’”

< Lawiylar 20 >