< Batur Ⱨakimlar 8 >
1 (Keyin, Əfraimlar uningƣa: — Sǝn nemixⱪa bizgǝ xundaⱪ muamilǝ ⱪilisǝn, Midiyaniylar bilǝn soⱪuxⱪa qiⱪⱪanda, bizni qaⱪirmidingƣu, dǝp uning bilǝn ⱪattiⱪ deyixip kǝtti.
Àwọn àgbàgbà ẹ̀yà Efraimu sì bínú gidigidi sí Gideoni wọ́n bi í léèrè pé, kí ló dé tí o fi ṣe irú èyí sí wa? Èéṣe tí ìwọ kò fi pè wá nígbà tí ìwọ kọ́kọ́ jáde lọ láti bá àwọn ará Midiani jagun? Ohùn ìbínú ni wọ́n fi bá a sọ̀rọ̀.
2 U ularƣa jawabǝn: — Mening ⱪilƣanlirimni ⱪandaⱪmu silǝrning ⱪilƣininglarƣa tǝnglǝxtürgili bolsun? Əfraimning üzümlǝrni pasangdiƣini, Abieǝzǝrlǝrning üzüm üzginidin artuⱪ ǝmǝsmu?
Ṣùgbọ́n Gideoni dá wọn lóhùn pé, “Àṣeyọrí wo ni mo ti ṣe tí ó tó fiwé tiyín? Àṣàkù àjàrà Efraimu kò ha dára ju gbogbo ìkórè àjàrà Abieseri lọ bí?
3 Huda Midiyanning ǝmirliri Orǝb bilǝn Zǝǝbni ⱪolunglarƣa tapxurƣan yǝrdǝ, mening ⱪolumdin kǝlginini ⱪandaⱪmu silǝrning ⱪilƣininglarƣa tǝnglǝxtürgili bolsun? — dedi. Xundaⱪ dewidi, ularning uningƣa bolƣan aqqiⱪi yandi).
Ọlọ́run ti fi Orebu àti Seebu àwọn olórí àwọn ará Midiani lé yín lọ́wọ́. Kí ni ohun tí Mose ṣe tí ó tó fiwé e yín tàbí tí ó tó àṣeyọrí i yín?” Nígbà tí ó wí èyí ríru ìbínú wọn rọlẹ̀.
4 Əmdi Gideon Iordan dǝryasining boyiƣa yetip kǝldi. U wǝ ɵzigǝ ⱨǝmraⱨ bolƣan üq yüz adǝm ⱨerip kǝtkǝn bolsimu, ular yǝnila Midiyaniylarni ⱪoƣlap dǝryadin ɵtti.
Gideoni àti àwọn ọ̀ọ́dúnrún ọkùnrin tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ tẹ̀síwájú láti lépa àwọn ọ̀tá bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ó ti rẹ̀ wọ́n, wọ́n dé Jordani wọ́n sì kọjá sí òdìkejì.
5 Gideon Sukkot xǝⱨiridikilǝrgǝ: — Manga ⱨǝmraⱨ bolup kǝlgǝn kixilǝrgǝ nan bǝrsǝnglar, qünki ular ⱨerip-qarqap kǝtti. Biz Midiyanning ikki padixaⱨi Zǝbaⱨ wǝ Zalmunnani ⱪoƣlap ketip barimiz, — dedi.
Ó wí fún àwọn ọkùnrin Sukkoti pé, “Ẹ fún àwọn ọmọ-ogun mi ní oúnjẹ díẹ̀, nítorí ó ti rẹ̀ wọ́n, èmi sì ń lépa Seba àti Salmunna àwọn ọba Midiani.”
6 Lekin Sukkotning qongliri jawab berip: — Zǝbaⱨ wǝ Zalmunna ⱨazir sening ⱪolungƣa qüxtimu?! Biz sening muxu lǝxkǝrliringgǝ nan berǝmduⱪ?! — dedi.
Ṣùgbọ́n àwọn ìjòyè Sukkoti fèsì pé ṣé ọwọ́ rẹ ti tẹ Seba àti Salmunna náà ni? Èéṣe tí àwa yóò ṣe fún àwọn ológun rẹ ní oúnjẹ?
7 Gideon: — Hǝp! Xundaⱪ bolƣini üqün Pǝrwǝrdigar Zǝbaⱨ wǝ Zalmunnani mening ⱪolumƣa tapxurƣanda, ǝtliringlarni qɵldiki yantaⱪ wǝ xoha bilǝn hamanda tepimǝn, — dedi.
Gideoni dá wọn lóhùn pé, “Ó dára, nígbà tí Olúwa bá fi Seba àti Salmunna lé mi lọ́wọ́ tán èmi yóò fi ẹ̀gún ijù àti ẹ̀gún òṣùṣú ya ẹran-ara yín.”
8 Gideon u yǝrdin Pǝnuǝlgǝ berip, u yǝrdiki adǝmlǝrgimu xundaⱪ dewidi, Pǝnuǝldiki kixilǝrmu uningƣa Sukkottikilǝrdǝk jawab bǝrdi.
Láti ibẹ̀, ó lọ sí Penieli ó sì bẹ̀ wọ́n bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́, ṣùgbọ́n àwọn náà dá a lóhùn bí àwọn ará Sukkoti ti dá a lóhùn.
9 U Pǝnuǝldikilǝrgǝ: — Mǝn ƣǝlibǝ bilǝn yenip kǝlginimdǝ, bu munaringlarni ɵrüwetimǝn, — dedi.
Nígbà náà ni ó sọ fún àwọn ọkùnrin Penieli pé, “Nígbà tí mo bá ṣẹ́gun tí mo sì padà dé ní àlàáfíà, èmi yóò wó ilé ìṣọ́ yìí.”
10 U qaƣda Zǝbaⱨ wǝ Zalmunna Karkor degǝn jayda idi; ular bilǝn mangƣan ⱪoxunda on bǝx mingqǝ lǝxkǝr bar idi. Bular bolsa mǝxriⱪliⱪlǝrning pütkül ⱪoxunidin ⱪelip ⱪalƣanliri idi, qünki ulardin ⱪiliq tutⱪanliridin bir yüz yigirmǝ mingi ɵltürülgǝnidi.
Ní àsìkò náà Seba àti Salmunna wà ní Karkori pẹ̀lú ọmọ-ogun wọn tí ó tó ẹgbẹ̀rún mẹ́ẹ̀ẹ́dógún ọkùnrin, àwọn wọ̀nyí ni ó ṣẹ́kù nínú gbogbo ogun àwọn ènìyàn apá ìlà-oòrùn, nítorí ọ̀kẹ́ mẹ́fà ọkùnrin tí ó fi idà jà ti kú ní ojú ogun.
11 Gideon bolsa Nobaⱨ wǝ Yogbihaⱨning xǝrⱪidiki kɵqmǝnlǝr yoli bilǝn qiⱪip Midiyanning lǝxkǝrgaⱨiƣa ⱨujum ⱪilip, ularni tarmar ⱪildi; qünki lǝxkǝrgaⱨtikilǝr tolimu ǝndixsiz turƣanidi.
Gideoni gba ọ̀nà tí àwọn darandaran máa ń rìn ní apá ìhà ìlà-oòrùn Noba àti Jogbeha ó sì kọjú ogun sí àwọn ọmọ-ogun náà nítorí wọ́n ti túra sílẹ̀.
12 Zǝbaⱨ wǝ Zalmunna ⱪeqip kǝtti; Gideon kǝynidin ⱪoƣlap berip, Midiyanning bu ikki padixaⱨi Zǝbaⱨ wǝ Zalmunnani tutuwaldi; u pütkül lǝxkǝrgaⱨtikilǝrni alaⱪzadǝ ⱪilip tiripirǝn ⱪiliwǝtti.
Seba àti Salmunna, àwọn ọba Midiani méjèèjì sá, ṣùgbọ́n Gideoni lépa wọn ó sì mú wọn, ó run gbogbo ogun wọn.
13 Andin Yoaxning oƣli Gideon Ⱨǝrǝs dawinidin ɵtüp, jǝngdin ⱪaytip kǝldi.
Gideoni ọmọ Joaṣi gba ọ̀nà ìgòkè Heresi padà sẹ́yìn láti ojú ogun.
14 U Sukkotluⱪ bir yax yigitni tutuwelip, uningdin sürüxtǝ ⱪiliwidi, yigit uningƣa Sukkotning qongliri wǝ aⱪsaⱪallirining isimlirini yezip bǝrdi. Ular jǝmiy bolup yǝtmix yǝttǝ adǝm idi.
Ó mú ọ̀dọ́mọkùnrin kan ará Sukkoti, ó sì béèrè àwọn ìbéèrè ní ọwọ́ rẹ̀, ọ̀dọ́mọkùnrin náà sì kọ orúkọ àwọn ìjòyè Sukkoti mẹ́tàdínlọ́gọ́rin fún un tí wọ́n jẹ́ àgbàgbà ìlú náà.
15 Andin Gideon Sukkotning adǝmlirining ⱪexiƣa yetip barƣanda: — Silǝr meni zangliⱪ ⱪilip: «Zǝbaⱨ wǝ Zalmunna ⱨazir sening ⱪolungƣa qüxtimu? Biz sening bilǝn billǝ mangƣan muxu ⱨarƣin adǝmliringgǝ nan berǝmduⱪ?» degǝnidinglar! Mana, u Zǝbaⱨ wǝ Zalmunna degǝnlǝr! — dedi.
Nígbà náà ni Gideoni wá ó sọ fún àwọn ọkùnrin Sukkoti pé, “Seba àti Salmunna nìwọ̀nyí nípa àwọn tí ẹ̀yin fi mí ṣẹ̀fẹ̀ nígbà tí ẹ wí pé, ‘Ṣé ó ti ṣẹ́gun Seba àti Salmunna? Èéṣe tí àwa ó fi fún àwọn ọmọ-ogun rẹ tí ó ti rẹ̀ ní oúnjẹ?’”
16 Xuni dǝp u xǝⱨǝrning aⱪsaⱪallirini tutup kelip, qɵldiki yantaⱪ bilǝn xohilarni elip kelip, ular bilǝn Sukkotning adǝmlirini urup ǝdipini bǝrdi.
Ó mú àwọn àgbàgbà ìlú náà, ó sì fi kọ́ àwọn Sukkoti lọ́gbọ́n nípa jíjẹ wọ́n ní yà pẹ̀lú àwọn ẹ̀gún ijù àti ẹ̀gún ọ̀gàn.
17 Andin u Pǝnuǝlning munarini ɵrüp, xǝⱨǝrdiki adǝmlǝrni ɵltürdi.
Ó wó ilé ìṣọ́ Penieli, ó sì pa àwọn ọkùnrin ìlú náà.
18 Gideon Zǝbaⱨ wǝ Zalmunnani soraⱪ ⱪilip: — Silǝr ikkinglar Taborda ɵltürgǝn adǝmlǝr ⱪandaⱪ adǝmlǝr idi? — dǝp soriwidi, ular jawab berip: — Ular sanga intayin ohxaytti; ularning ⱨǝrbiri xaⱨzadidǝk idi, — dedi.
Gideoni bi Seba àti Salmunna pé, “Irú ọkùnrin tí ẹ pa ní Tabori, báwo ni wọ́n ṣe rí?” “Àwọn ọkùnrin náà dàbí rẹ ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn dàbí ọmọ ọba,” ní ìdáhùn wọn.
19 U buni anglap: — Ular mening bir tuƣⱪanlirimdur, biz bir anining oƣullirimiz. Pǝrwǝrdigarning ⱨayati bilǝn ⱪǝsǝm ⱪilimǝnki, silǝr ǝyni waⱪitta ularni tirik ⱪoyƣan bolsanglar, mǝn silǝrni ⱨǝrgiz ɵltürmǝyttim, — dedi;
Gideoni dáhùn pé, “Arákùnrin mi ni wọ́n, àwọn ọmọ ìyá mi. Mo fi Olúwa búra, bí ó bá ṣe pé ẹ dá ẹ̀mí wọn sí, èmi náà ò nípa yín.”
20 xuning bilǝn u qong oƣli Yǝtǝrgǝ: — Sǝn ⱪopup bularni ɵltürgin, — dedi. Lekin oƣul kiqik bolƣaqⱪa ⱪorⱪup, ⱪiliqini suƣurmidi.
Ó yí padà sí Jeteri, ọmọ rẹ̀ tí ó dàgbà jùlọ, ó wí fún un pé, “Pa wọ́n!” Ṣùgbọ́n Jeteri kò fa idà rẹ̀ yọ láti pa wọ́n nítorí ó jẹ́ ọ̀dọ́mọdé ẹ̀rù sì bà á láti pa wọ́n.
21 Xuning bilǝn Zǝbaⱨ wǝ Zalmunna: — Sǝn ɵzüng ⱪopup bizni ɵltürgin; qünki adǝm ⱪandaⱪ bolsa küqimu xundaⱪ bolidu, — dedi. Xundaⱪ dewidi, Gideon ⱪopup Zǝbaⱨ wǝ Zalmunnani ɵltürdi. U tɵgilirining boynidiki ⱨilal ay xǝkillik bezǝklǝrni eliwaldi.
Seba àti Salmunna dá Gideoni lóhùn pé, “Wá pa wá fún raàrẹ, ‘Nítorí bí ènìyàn bá ti rí bẹ́ẹ̀ ni agbára rẹ̀ yóò rí.’” Gideoni bọ́ síwájú ó sì pa wọ́n, ó sì mú ohun ọ̀ṣọ́ tí ó wà ní ọrùn àwọn ìbákasẹ wọn.
22 Andin Israillar Gideonƣa: — Sǝn bizni Midiyanning ⱪolidin ⱪutⱪuzƣanikǝnsǝn, ɵzüng bizgǝ padixaⱨ bolƣin; oƣlung wǝ oƣlungning oƣlimu bizning üstimizgǝ ⱨɵküm sürsun, — dedi.
Àwọn ará Israẹli wí fún Gideoni pé, “Jọba lórí wa—ìwọ, àwọn ọmọ rẹ àti àwọn ọmọ ọmọ rẹ pẹ̀lú, nítorí tí ìwọ ti gbà wá lọ́wọ́ àwọn ará Midiani.”
23 Əmma Gideon ularƣa jawab berip: — Mǝn üstünglǝrgǝ sǝltǝnǝt ⱪilmaymǝn, oƣlummu üstünglǝrgǝ sǝltǝnǝt ⱪilmaydu; bǝlki Pǝrwǝrdigar Ɵzi üstünglǝrgǝ sǝltǝnǝt ⱪilidu, dedi.
Ṣùgbọ́n Gideoni dá wọn lóhùn pé, “Èmi kì yóò jẹ ọba lórí yín, bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọ mi kì yóò jẹ ọba lórí yín. Olúwa ni yóò jẹ ọba lórí yín.”
24 Andin Gideon ularƣa yǝnǝ: — Silǝrgǝ pǝⱪǝt birla iltimasim bar: — Ⱨǝr biringlar ɵz oljanglardin ⱨalⱪa-zerilǝrni manga beringlar, dedi (Midiyanlar Ismaillardin bolƣaqⱪa, ⱨǝrbiri altun zirǝ-ⱨalⱪilarni taⱪaytti).
Gideoni sì wí pé, “Mo ní ẹ̀bẹ̀ kan tí mo fẹ́ bẹ̀ yín kí ẹnìkọ̀ọ̀kan yín fún mi ní yẹtí kọ̀ọ̀kan láti inú ohun ti ó kàn yín láti inú ìkógun.” (Àṣà àwọn ará Iṣmaeli ni láti máa fi yẹtí wúrà sétí.)
25 Ular jawabǝn: — Berixkǝ razimiz, dǝp yǝrgǝ bir yepinqini selip, ⱨǝrbiri uning üstigǝ oljisidin zirǝ-ⱨalⱪilarni elip taxlidi.
Wọ́n dáhùn pé, “Tayọ̀tayọ̀ ni àwa yóò fi wọ́n sílẹ̀.” Wọ́n tẹ́ aṣọ kan sílẹ̀ ọkùnrin kọ̀ọ̀kan sì ń sọ yẹtí kọ̀ọ̀kan tí ó kàn wọ́n láti ibi ìkógun síbẹ̀.
26 U sorap yiƣⱪan altun zirilǝrning eƣirliⱪi bir ming yǝttǝ yüz xǝkǝl altun idi, buningdin baxⱪa Midiyan padixaⱨliri ɵzigǝ asⱪan ⱨilal ay xǝkillik buyumlar, zunnar, uqisiƣa kiygǝn sɵsün eginlǝr wǝ tɵgilǝrning boyniƣa asⱪan altun zǝnjirlǝrmu bar idi.
Ìwọ̀n òrùka wúrà tí ó béèrè fún tó ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀sán ìwọ̀n ṣékélì, láìka àwọn ohun ọ̀ṣọ́ àti ohun sísorọ̀ tí ó wà lára ìlẹ̀kẹ̀ ọrùn àti aṣọ elése àlùkò tí àwọn ọba Midiani ń wọ̀ tàbí àwọn ẹ̀wọ̀n tí ó wà ní ọrùn àwọn ìbákasẹ wọn.
27 Gideon bu nǝrsilǝrdin bir ǝfod yasitip, ɵz xǝⱨiri Ofraⱨta ⱪoyup ⱪoydi. Nǝtijidǝ, pütkül Israil uni izdǝp buzuⱪqiliⱪ ⱪildi. Buning bilǝn bu nǝrsǝ Gideon wǝ uning pütün ailisigǝ bir tor-tuzaⱪ boldi.
Gideoni fi àwọn wúrà náà ṣe efodu èyí tí ó gbé kalẹ̀ ní Ofira ìlú rẹ̀. Àwọn ọmọ Israẹli sì sọ ara wọn di àgbèrè nípa sínsin-ín ní ibẹ̀. Ó sì di ìdẹ̀kùn fún Gideoni àti ìdílé rẹ̀.
28 Midiyaniylar xu tǝriⱪidǝ Israillarning aldida boysundurulup, ikkinqi bax kɵtürǝlmidi; zemin Gideonning künliridǝ ⱪiriⱪ yilƣiqǝ tinq-aramliⱪ tapti.
Báyìí ni a ṣe tẹrí àwọn ará Midiani ba níwájú àwọn ọmọ Israẹli bẹ́ẹ̀ ni wọn kò tún gbé orí mọ́. Ní ọjọ́ Gideoni, Israẹli wà ní àlàáfíà fún ogójì ọdún.
29 Yoaxning oƣli Yǝrubbaal ⱪaytip berip, ɵz ɵyidǝ olturdi.
Jerubbaali ọmọ Joaṣi padà lọ láti máa gbé ní ìlú rẹ̀.
30 Gideonning ayalliri kɵp bolƣaqⱪa, uning puxtidin yǝtmix oƣul tɵrǝldi.
Àádọ́rin ọmọ ni Gideoni bí, nítorí ó ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ìyàwó.
31 Xǝkǝmdǝ uning bir kenizikimu bar idi; u uningƣa bir oƣul tuƣup bǝrdi, Gideon uning ismini «Abimǝlǝk» dǝp ⱪoydi.
Àlè rẹ̀, tó ń gbé ní Ṣekemu, pàápàá bí ọmọkùnrin kan fún un tí ó pe orúkọ rẹ̀ ní Abimeleki.
32 Yoaxning oƣli Gideon uzun ɵmür kɵrüp, ⱪerip alǝmdin ɵtti. U Abiezǝrlǝrgǝ tǝwǝ bolƣan Ofraⱨda, ɵz atisi Yoaxning ⱪǝbrisigǝ dǝpnǝ ⱪilindi.
Gideoni ọmọ Joaṣi kú ní ògbólógbòó ọjọ́ rẹ̀, ó sì pọ̀ ní ọjọ́ orí, wọ́n sì sin ín sí ibojì baba rẹ̀ ní Ofira ti àwọn ará Abieseri.
33 Gideon ɵlgǝndin keyin Israillar kǝynigǝ yenip, Baal butliriƣa ǝgixip buzuⱪqiliⱪ ⱪildi wǝ «Baal-Berit»ni ɵzlirining ilaⱨi ⱪilip bekitti.
Láìpẹ́ jọjọ lẹ́yìn ikú Gideoni ni àwọn ará Israẹli ṣe àgbèrè tọ Baali lẹ́yìn, wọ́n fi Baali-Beriti ṣe òrìṣà wọn.
34 Xundaⱪ ⱪilip Israillar ɵzlirini ǝtrapidiki barliⱪ düxmǝnlirining ⱪolidin ⱪutⱪuzƣan ɵz Hudasi Pǝrwǝrdigarni untudi
Wọn kò sì rántí Olúwa Ọlọ́run wọn, ẹni tí ó gbà wọ́n kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wọn gbogbo tí ó wà ní gbogbo àyíká wọn.
35 wǝ xuningdǝk Gideonning Israilƣa ⱪilƣan ⱨǝmmǝ yahxiliⱪlirini ⱨeq ǝslimǝy, Yǝrubbaal (yǝni Gideon)ning jǝmǝtigǝ ⱨeqbir meⱨribanliⱪ kɵrsǝtmidi.
Wọ́n kùnà láti fi inú rere hàn sí ìdílé Jerubbaali (èyí ni Gideoni) fún gbogbo oore tí ó ṣe fún wọn.