< Yǝrǝmiya 9 >

1 Aⱨ, mening bexim suning bexi, Kɵzüm yaxning buliⱪi bolsiidi! Undaⱪta hǝlⱪimning ⱪizi arisidiki ɵltürülgǝnlǝr üqün keqǝ-kündüz yiƣlayttim!
Háà! Orí ìbá jẹ́ orísun omi kí ojú mi sì jẹ́ orísun omijé! Èmi yóò sì sọkún tọ̀sán tòru nítorí ìparun àwọn ènìyàn mi.
2 Aⱨ, mǝn üqün qɵl-bayawanda yoluqilar qüxkidǝk bir turalƣu bolsiidi! Undaⱪta hǝlⱪimni taxlap, ulardin ayrilƣan bolattim! Qünki ularning ⱨǝmmisi zinahorlar, Munapiⱪlarning bir jamaitidur!»
Háà, èmi ìbá ní ni aginjù ilé àgbàwọ̀ fún àwọn arìnrìn-àjò, kí n ba à lè fi àwọn ènìyàn mi sílẹ̀ kí n sì lọ kúrò lọ́dọ̀ wọn: nítorí gbogbo wọn jẹ́ panṣágà àjọ aláìṣòótọ́ ènìyàn.
3 — Ular oⱪyaqi lǝxkǝrlǝr oⱪyayini egildürgǝndǝk tilini yalƣanqiliⱪⱪa egildürüxkǝ tǝyyarliƣan; ular zeminda üstünlük ⱪazanƣan, biraⱪ bu sǝmimiylik bilǝn bolƣan ǝmǝs; ular rǝzillik üstigǝ rǝzillik ⱪilƣan, Meni ⱨeq tonup bilmigǝn» — dǝydu Pǝrwǝrdigar.
Wọ́n ti pèsè ahọ́n wọn sílẹ̀ bí ọfà láti fi pa irọ́; kì í ṣe nípa òtítọ́ ni wọ́n fi borí ní ilẹ̀ náà. Wọ́n ń lọ láti inú ẹ̀ṣẹ̀ kan sí òmíràn; wọn kò sì náání mi, ní Olúwa wí.
4 — Ⱨǝrbiringlar ɵz yeⱪininglardin ⱨezi bolunglar, ⱪerindaxliringlarƣa ⱨeq tayanmanglar; qünki ⱨǝrbir ⱪerindax pǝⱪǝtla aldiƣuqi, halas, ⱨǝrbir yeⱪinliring bolsa tɵⱨmǝthorluⱪta yürmǝktǝ.
“Ṣọ́ra fún àwọn ọ̀rẹ́ rẹ; má ṣe gbẹ́kẹ̀lé àwọn arákùnrin rẹ. Nítorí pé oníkálùkù arákùnrin jẹ́ atannijẹ, oníkálùkù ọ̀rẹ́ sì jẹ́ abanijẹ́.
5 Ular ⱨǝrbiri ɵz yeⱪinliriƣa aldamqiliⱪ ⱪilmaⱪta, ⱨeqkim ⱨǝⱪiⱪǝtni sɵzlimǝydu; ular ɵz tilini yalƣan sɵzlǝxkǝ ɵgitidu, ular ⱪǝbiⱨliktǝ ɵzlirini upritidu.
Ọ̀rẹ́ ń dalẹ̀ ọ̀rẹ́. Kò sì ṣí ẹni tó sọ òtítọ́, wọ́n ti kọ́ ahọ́n wọn láti máa purọ́. Wọ́n sọ ara wọn di onírẹ̀wẹ̀sì pẹ̀lú ẹ̀ṣẹ̀
6 Ular jǝbir-zulum üstigǝ jǝbir-zulum ⱪilmaⱪta, aldamqiliⱪtin yǝnǝ bir aldamqiliⱪⱪa ɵtmǝktǝ; ular Meni tonuxni rǝt ⱪilidu, — dǝydu Pǝrwǝrdigar.
Ó ń gbé ní àárín ẹ̀tàn; wọ́n kọ̀ láti mọ̀ mí nínú ẹ̀tàn wọn,” ni Olúwa wí.
7 Xunga samawi ⱪoxunlarning Sǝrdari bolƣan Pǝrwǝrdigar mundaⱪ dǝydu: — Mana, Mǝn ularni eritip tawlap sinaymǝn; hǝlⱪimning ⱪizining rǝzillikigǝ Manga baxⱪa yol ⱪalmidimu?
Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Àwọn ọmọ-ogun wí: “Wò ó, èmi dán wọn wo; nítorí pé kí ni èmi tún le è ṣe? Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ènìyàn mi?
8 Ularning tili ǝjǝl oⱪidur; u aldamqiliⱪni sɵzlǝydu; ⱨǝrbir eƣiz sɵzidǝ yeⱪini bilǝn tinq-amanliⱪni sɵzlǝydu, lekin kɵnglidǝ ⱪiltaⱪ tǝyyarlaydu.
Ahọ́n wọn dàbí ọfà olóró; ó ń sọ ẹ̀tàn. Oníkálùkù sì ń fi ẹnu rẹ̀ sọ̀rọ̀ àlàáfíà sí aládùúgbò rẹ̀, ní inú ọkàn rẹ̀, ó dẹ tàkúté sílẹ̀.
9 Bu ixlar tüpǝylidin ularni jazalimay ⱪoyamdim? — dǝydu Pǝrwǝrdigar, — Mening jenim muxundaⱪ bir ǝldin ⱪisas almay ⱪoyamdu?
Èmi kì yóò ha fi ìyà jẹ wọ́n nítorí èyí?” ni Olúwa wí. “Èmi kì yóò ha gbẹ̀san ara mi lórí irú orílẹ̀-èdè yìí bí?”
10 «Taƣlardiki yaylaⱪlar üqün yiƣa wǝ nalǝ-pǝryad kɵtürimǝn, Daladiki otlaⱪlar üqün mǝrsiyǝ oⱪuymǝn; Qünki ular kɵyüp kǝttiki, ⱨeqkim u yǝrdin ɵtmǝydu; Kalilarning ⱨɵrkirǝxliri anglanmaydu; Ⱨǝm asmandiki uqar-ⱪanatlar ⱨǝm ⱨaywanatlarmu ⱪeqip, Xu yǝrdin kǝtti!».
Èmi yóò sì sọkún, pohùnréré ẹkún fún àwọn òkè àti ẹkún ìrora lórí pápá oko aginjù wọ̀n-ọn-nì. Nítorí wọ́n di ahoro, wọn kò sì kọjá ní ibẹ̀. A kò sì gbọ́ igbe ẹran ọ̀sìn. Àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run sì ti sálọ, bẹ́ẹ̀ náà ni àwọn ẹranko sì ti lọ.
11 — Mǝn Yerusalemni harablaxⱪan top-top dɵwǝ, qilbɵrilǝrning bir turalƣusi ⱪilimǝn; Yǝⱨuda xǝⱨǝrlirini adǝm turmaydiƣan dǝrijidǝ wayranǝ ⱪilimǝn.
“Èmi yóò sì sọ Jerusalẹmu di òkìtì àlàpà àti ihò àwọn ìkookò. Èmi ó sì sọ ìlú Juda di ahoro tí ẹnikẹ́ni kò sì ní le è gbé.”
12 — Kim bu ixlarni qüxinixkǝ danixmǝn bolidu? Kim Pǝrwǝrdigarning aƣzidin sɵz elip bularni qüxǝndürǝlǝydu? Nemixⱪa zemin wǝyranǝ, ⱨeqkim ɵtmigüdǝk, kɵyüp qɵl-bayawandǝk bolup kǝtti?
Ta ni ẹni náà tí ó ní ọgbọ́n láti mòye nǹkan wọ̀nyí? Ta ni Olúwa ti sọ èyí fún, tí ó sì lè ṣàlàyé rẹ̀? Èéṣe tí ilẹ̀ náà fi ṣègbé bí aginjù, tí ẹnìkankan kò sì le là á kọjá?
13 Pǝrwǝrdigar dǝydu, — Qünki ular Mǝn ular aldiƣa ⱪoyƣan Tǝwrat-ⱪanunni taxliwǝtkǝn, Mening awazimƣa ⱪulaⱪ salmiƣan wǝ uningda mangmiƣan,
Olúwa sì wí pé, nítorí pé wọ́n ti kọ òfin mi sílẹ̀, èyí tí mo gbé kalẹ̀ níwájú wọn, wọn ṣe àìgbọ́ràn sí wọn, wọn kò sì rìn nínú òfin mi.
14 Bǝlki ɵz ⱪǝlbidiki jaⱨilliⱪⱪa ǝgǝxkǝn, ata-bowiliri ularƣa ɵgǝtkǝndǝk Baallarning kǝynigǝ ǝgixip kǝtkǝn,
Dípò èyí, wọ́n ti tẹ̀lé agídí ọkàn wọn, wọ́n ti tẹ̀lé Baali gẹ́gẹ́ bí àwọn baba wọn ṣe kọ́ wọn.
15 Xunga samawi ⱪoxunlarning Sǝrdari bolƣan Pǝrwǝrdigar, Israilning Hudasi mundaⱪ dǝydu: — Mana, Mǝn bu hǝlⱪⱪǝ kǝkrini yegüzimǝn, ularƣa ɵt süyini iqküzimǝn,
Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli wí, “Wò ó, Èmi yóò mú kí àwọn ènìyàn wọ̀nyí jẹ oúnjẹ kíkorò àti láti mu omi májèlé.
16 ularni ular yaki ata-bowiliri ilgiri ⱨeq tonumaydiƣan ǝllǝr arisiƣa tarⱪitimǝn; Mǝn ularni yoⱪatⱪuqǝ ularning kǝynidin ⱪoƣlaxⱪa ⱪiliqni ǝwǝtimǝn.
Èmi yóò sì tú wọn ká láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, nínú èyí tí àwọn tàbí àwọn baba wọn kò mọ̀. Èmi yóò sì lépa wọn pẹ̀lú idà títí èmi yóò fi pa wọ́n run.”
17 Samawi ⱪoxunlarning Sǝrdari bolƣan Pǝrwǝrdigar mundaⱪ dǝydu: — Kɵngül ⱪoyunglar, matǝmqi ayallarni kelixkǝ qaⱪiringlar, yiƣlaxⱪa ǝng usta bolƣan ⱪiz-ayallarni qaⱪirip kelixkǝ adǝm ǝwǝtinglar!
Èyí sì ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun wí: “Sá à wò ó nísinsin yìí! Ké sí obìnrin ti ń ṣọ̀fọ̀ nì kí ó wá; sì ránṣẹ́ pe àwọn tí ó mòye nínú wọn.
18 — Bǝrⱨǝⱪ, ular tez kǝlsun, biz üqün zor yiƣa kɵtürsunki, bizning kɵzlirimizdinmu yaxlar taramlap tɵkülsun, qanaⱪlirimizdinmu yax tamqiliri aⱪsun —
Jẹ́ kí wọn wá kíákíá, kí wọn wá pohùnréré ẹkún lé wa lórí títí ojú wa yóò fi sàn fún omijé tí omi yóò sì máa sàn àwọn ìpéǹpéjú wa.
19 qünki Ziondin yiƣa awazi anglinip: — «Biz ⱪanqilik bulang-talang ⱪilinduⱪ! Ⱪanqilik xǝrmǝndǝ bolduⱪ! Ular turalƣulirimizni ɵrüwǝtti, biz zeminimizni taxliduⱪ!» — deyilidu.
A gbọ́ igbe ìpohùnréré ẹkún ní Sioni: ‘Àwa ti ṣègbé tó! A gbọdọ̀ fi ilẹ̀ wa sílẹ̀, nítorí pé àwọn ilé wa ti parun.’”
20 Pǝrwǝrdigarning sɵzini anglanglar, i ayallar, Uning aƣzidiki sɵzgǝ ⱪulaⱪ selinglar; Ⱪizinglarƣa yiƣlaxni ɵgitinglar, Ⱨǝrbiringlar yeⱪininglarƣa mǝrsiyǝ oⱪutunglar;
Nísinsin yìí, ẹ̀yin obìnrin ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa; ṣí etí yín sí ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ. Kọ́ àwọn ọmọbìnrin yín ní ìpohùnréré ẹkún, kí ẹ sì kọ́ ara yín ní arò.
21 Qünki ɵlüm bolsa derizilirimizdin yamixip kirgǝn, Orda-istiⱨkamlirimizƣimu kirgǝn; U balilarni koqilardin, Yigitlǝrni rǝstǝ-mǝydanlardin yulup taxliƣan.
Ikú ti gba ojú fèrèsé wa wọlé ó sì ti wọ odi alágbára wa ó ti ké àwọn ọmọ kúrò ní àdúgbò àti àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin kúrò ní gbọ̀ngàn ìta gbangba.
22 [Yeⱪinliringlarƣa] uⱪturup: «Pǝrwǝrdigar mundaⱪ dǝydu: — Bǝrⱨǝⱪ, jǝsǝtlǝr dalada tezǝktǝk yiⱪilidu; Ular ormiqining orƣiⱪining astiƣa yiⱪilƣan, Lekin ⱨeqkim yiƣmaydiƣan baxaⱪtǝk yǝrgǝ qeqilidu!» — dǝnglar!
Sọ pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “‘Òkú àwọn ènìyàn yóò ṣubú bí ààtàn ní oko gbangba àti bí ìbùkúnwọ́ lẹ́yìn olùkórè láìsí ẹnìkankan láti kó wọn jọ.’”
23 Pǝrwǝrdigar mundaⱪ dǝydu: — Dana kixi danaliⱪi bilǝn, küqlük kixi küqlükliki bilǝn, bay bayliⱪliri bilǝn pǝhirlinip mahtanmisun;
Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Má ṣe jẹ́ kí ọlọ́gbọ́n yangàn nítorí agbára ọgbọ́n rẹ̀, tàbí alágbára nítorí agbára rẹ̀, tàbí ọlọ́rọ̀ nítorí ọrọ̀ rẹ̀.
24 pǝhirlinip mahtiƣuqi bolsa xuningdin, yǝni Meni, yǝr yüzidǝ meⱨir-muⱨǝbbǝt, adalǝt wǝ ⱨǝⱪⱪaniyliⱪni yürgüzgüqi Mǝn Pǝrwǝrdigarni tonup yǝtkǝnlikidin pǝhirlinip mahtansun; qünki Mening hursǝnlikim dǝl muxu ixlardindur, — dǝydu Pǝrwǝrdigar.
Ẹ jẹ́ kí ẹni tí ń ṣògo nípa èyí nì wí pé: òun ní òye, òun sì mọ̀ mí wí pé, Èmi ni Olúwa tí ń ṣe òtítọ́, ìdájọ́ àti òdodo ní ayé, nínú èyí ni mo ní inú dídùn sí,” Olúwa wí.
25 Mana, xundaⱪ künlǝr keliduki, — dǝydu Pǝrwǝrdigar, — Mǝn hǝtnǝ ⱪilmiƣanlarni hǝtnǝ ⱪilinƣanlar bilǝn billǝ jazalaymǝn;
“Ọjọ́ ń bọ̀,” ni Olúwa wí, “tí Èmi yóò fi ìyà jẹ gbogbo àwọn tí a kọ ilà fún nínú ara nìkan.
26 yǝni Misir, Yǝⱨuda, Edom, Ammoniylar wǝ Moabiylar, jümlidin qɵl-bayawanda turuwatⱪan, qekǝ qaqlirini qüxürüwǝtkǝn ǝllǝrni jazalaymǝn; qünki bu ǝllǝrning ⱨǝmmisi hǝtnisizdur; Israilning barliⱪ jǝmǝtimu kɵnglidǝ hǝtnisizdur.
Ejibiti, Juda, Edomu, Ammoni, Moabu àti gbogbo àwọn tí ń gbé ní ọ̀nà jíjìn réré ní aginjù. Nítorí pé gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè wọ̀nyí jẹ́ aláìkọlà gbogbo àwọn ará ilé Israẹli sì jẹ́ aláìkọlà ọkàn.”

< Yǝrǝmiya 9 >