< Yǝrǝmiya 19 >
1 Pǝrwǝrdigar mundaⱪ dǝydu: — Barƣin, sapalqidin bir sapal kozini alƣin; andin ǝlning aⱪsaⱪalliridin wǝ kaⱨinlarning aⱪsaⱪalliridin birnǝqqini apirip,
Èyí ní ohun tí Olúwa wí: “Lọ ra ìkòkò lọ́dọ̀ alámọ̀, mú dání lára àwọn àgbàgbà ọkùnrin àti wòlíì.
2 «Sapal parqiliri» dǝrwazisiƣa yeⱪin bolƣan «Ⱨinnomning oƣlining jilƣisi»ƣa berip xu yǝrdǝ Mǝn sanga eytidiƣan sɵzlǝrni jakarliƣin.
Kí o sì lọ sí àfonífojì ọmọ Beni-Hinnomu, níwájú ẹnu ibodè Harsiti, níbẹ̀ ni kí o sì kéde gbogbo ọ̀rọ̀ tí èmi yóò sọ fún ọ.
3 Mundaⱪ degin: — Pǝrwǝrdigarning sɵzini anglanglar, i Yǝⱨudaning padixaⱨliri wǝ Yerusalemdikilǝr! Samawi ⱪoxunlarning Sǝrdari bolƣan Pǝrwǝrdigar, Israilning Hudasi mundaⱪ dǝydu: — Mana, Mǝn muxu yǝrgǝ balayi’apǝtni qüxürimǝnki, kimki uni anglisila ⱪulaⱪliri zingildap ketidu.
Kí o sì wí pé, ‘Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa ẹ̀yin ọba àwọn Juda àti ẹ̀yin ará Jerusalẹmu. Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli sọ. Dẹtí sí mi! Èmi yóò mú ìparun wá síbí, etí gbogbo wọn tó bá gbọ́ ọ yóò hó yaya.
4 Qünki bu hǝlⱪ Mǝndin waz keqip, bu yǝrni Manga «yat» ⱪilƣan, uningda nǝ ɵzliri, nǝ ata-bowiliri, nǝ Yǝⱨuda padixaⱨliri ⱨeq tonumiƣan baxⱪa ilaⱨlarƣa huxbuy yaⱪⱪan; ular bu yǝrni gunaⱨsizlarning ⱪanliri bilǝn toldurƣan.
Nítorí wọ́n ti gbàgbé mi, wọ́n sì ti sọ ibí di ilé fún òrìṣà àjèjì; wọ́n ti sun ẹbọ nínú rẹ̀ fún òrìṣà tí àwọn baba wọn tàbí tí ọba Juda kò mọ̀ rí, wọ́n ti fi ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ kún ilẹ̀ yìí.
5 Ular Baalƣa ɵz balilirini kɵydürmǝ ⱪurbanliⱪlar süpitidǝ kɵydürüx üqün Baalning «yuⱪiri jaylar»ini ⱪurƣan; Mǝn bundaⱪ bir ixni ⱨeqⱪaqan buyrup baⱪmiƣan, ⱨeq eytmiƣan, u ⱨǝrgiz oyumƣa kirip baⱪmiƣan.
Wọ́n ti kọ́ ibi gíga fún Baali láti sun ọmọkùnrin wọn gẹ́gẹ́ bí ohun ẹbọ sísun sí Baali—èyí tí èmi kò pàṣẹ láti ṣe, tí èmi kò sì sọ, tàbí tí kò sì ru sókè láti inú ọkàn mi.
6 Xunga mana, xundaⱪ künlǝr keliduki, — dǝydu Pǝrwǝrdigar, — bu yǝr kǝlgüsidǝ «Tofǝt», yaki «Ⱨinnomning oƣlining jilƣisi» dǝp atalmaydu, bǝlki «Ⱪǝtl jilƣisi» dǝp atilidu.
Nítorí náà ṣọ́ra ọjọ́ ń bọ̀ ni Olúwa wí nígbà tí àwọn ènìyàn kì yóò pe ibí ní Tofeti mọ́ tàbí àfonífojì ọmọ Hinnomu, ṣùgbọ́n àfonífojì Ìpakúpa.
7 Mǝn bu yǝrdǝ Yǝⱨuda ⱨǝm Yerusalemning pilan-tǝdbirlirini ⱪuruⱪ ⱪiliwetimǝn; Mǝn ularni düxmǝnlirining ⱪiliqi bilǝn, yǝni janlirini izdigüqilǝrning ⱪolida yiⱪitimǝn; Mǝn jǝsǝtlirini asmandiki uqar-ⱪanatlarƣa wǝ yǝr-zemindiki ⱨaywanatlarƣa ozuⱪ boluxⱪa beriwetimǝn.
“‘Ní ibí yìí ni èmi yóò ti pa èrò Juda àti Jerusalẹmu run. Èmí yóò mú wọn ṣubú nípa idà níwájú àwọn ọ̀tá wọn, lọ́wọ́ àwọn tí ó ń wá ẹ̀mí wọn. Èmi yóò sì fi òkú wọn ṣe oúnjẹ fún àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run àti ẹranko ilẹ̀.
8 Mǝn bu xǝⱨǝrni dǝⱨxǝt basidiƣan ⱨǝm kixilǝr ux-ux ⱪilidiƣan obyekt ⱪilimǝn; uningdin ɵtüwatⱪanlarning ⱨǝmmisi uning barliⱪ yara-wabaliri tüpǝylidin dǝⱨxǝt besip üxⱪirtidu.
Èmi yóò sọ ìlú yìí di ahoro àti ohun ẹ̀gàn, gbogbo àwọn tí ń kọjá yóò bẹ̀rù wọn yóò sì máa fòyà nítorí gbogbo ọgbẹ́ rẹ̀.
9 Mǝn ularni düxmǝnlirining ⱨǝm janlirini izdigüqilǝrning ⱪattiⱪ ⱪistaydiƣan ⱪorxawining besimi astida oƣullirining gɵxini ⱨǝm ⱪizlirining gɵxini yǝydiƣan ⱪilimǝn, ularning ⱨǝrbiri ɵz yeⱪinining gɵxini yǝydu.
Èmi yóò mú kí wọ́n jẹ ẹran-ara ọmọ wọn ọkùnrin àti ẹran-ara ọmọ wọn obìnrin, ẹnìkínní yóò sì jẹ ẹran-ara ẹnìkejì, nígbà ìdótì àti ìhámọ́ láti ọwọ́ ọ̀tá wọn, àti àwọn tí ó ń wá ẹ̀mí wọn.’
10 Əmdi sǝn ɵzüng bilǝn billǝ aparƣan ⱨǝmraⱨliringning kɵz aldida ⱨeliⱪi kozini qeⱪiwǝtkin;
“Nígbà náà ni ìwọ yóò fọ́ ìkòkò náà ní ojú àwọn tí ó bá ọ lọ.
11 xundaⱪ ⱪilip ularƣa mundaⱪ degin: — Samawi ⱪoxunlarning Sǝrdari bolƣan Pǝrwǝrdigar mundaⱪ dǝydu: — Birsi sapalqining kozisini ⱪaytidin ⱨeq yasiyalmiƣudǝk dǝrijidǝ qeⱪiwǝtkinidǝk Mǝnmu bu hǝlⱪ wǝ bu xǝⱨǝrni xundaⱪ qeⱪiwetimǝn. Ular jǝsǝtlirini Tofǝttǝ kɵmidu, ⱨǝtta kɵmgüdǝk yǝr ⱪalmiƣuqǝ.
Kí o sì sọ fún wọn pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí. Èmi a fọ́ orílẹ̀-èdè yìí àti ìlú yìí gẹ́gẹ́ bí ìkòkò amọ̀ yìí ṣe fọ́ tí kò sì ní sí àtúnṣe. Wọn a sì sin àwọn òkú sí Tofeti títí tí kò fi ní sí ààyè mọ́.
12 Mǝn bu yǝrni wǝ buningda turuwatⱪanlarnimu muxundaⱪ ⱪilimǝn, — dǝydu Pǝrwǝrdigar, — bu xǝⱨǝrni Tofǝtkǝ ohxax ⱪilimǝn.
Èyí ni ohun tí èmi yóò ṣe sí ibí yìí àti àwọn tí ń gbé ní ibí yìí ni Olúwa wí. Èmi yóò mú ìlú yìí dàbí Tofeti.
13 Yerusalemdiki ɵylǝr wǝ Yǝⱨuda padixaⱨlirining ɵyliri, — yǝni ularning ɵgziliridǝ turup asmandiki barliⱪ yultuz-sǝyyarilǝrgǝ huxbuy yaⱪⱪan wǝ Mǝndin baxⱪa yat ilaⱨlarƣa «xarab ⱨǝdiyǝ»lǝrni tɵkkǝn barliⱪ ɵyliri huddi Tofǝt degǝn jaydǝk bulƣanƣan jaylar bolidu.
Àwọn ilé tí ó wà ní Jerusalẹmu àti ti ọba ìlú Juda ni a ó sọ di àìmọ́ bí Tofeti, gbogbo ilé tí wọ́n ti ń sun tùràrí ni orí òrùlé sí gbogbo ogun ọ̀run, tí a sì ń rú ẹbọ mímu sí ọlọ́run mìíràn.’”
14 Wǝ Yǝrǝmiya Pǝrwǝrdigar uni bexarǝt berixkǝ ǝwǝtkǝn Tofǝttin ⱪaytip kelip, Pǝrwǝrdigarning ɵyining ⱨoylisiƣa kirip turup barliⱪ hǝlⱪⱪǝ mundaⱪ dedi:
Jeremiah sì padà láti Tofeti níbi tí Olúwa rán an sí láti sọ àsọtẹ́lẹ̀ ó sì dúró ní gbangba tẹmpili Olúwa, ó sì sọ fún gbogbo ènìyàn pé,
15 — Samawi ⱪoxunlarning Sǝrdari bolƣan Pǝrwǝrdigar, Israilning Hudasi mundaⱪ dǝydu: — Mana, Mǝn bu xǝⱨǝr wǝ uning barliⱪ xǝⱨǝrlirigǝ ⱪarap eytⱪan balayi’apǝtning ⱨǝmmisini ularning bexiƣa qüxürimǝn; qünki ular boynini ⱪattiⱪ ⱪilip Mening sɵzlirimni ⱨeqⱪaqan anglimiƣan.
“Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli wí: ‘Tẹ́tí sílẹ̀! Èmi yóò mú ìdààmú tí mo ti sọ àsọtẹ́lẹ̀ rẹ̀ bá ìlú yìí àti ìgbèríko tí ó yí i ká, nítorí ọlọ́rùn líle ni wọ́n, wọn kò si ní fẹ́ fetí sí ọ̀rọ̀ mi.’”