< Yǝxaya 7 >

1 Yǝⱨuda padixaⱨi Aⱨaz (Uzziyaning nǝwrisi, Yotamning oƣli) tǝhtkǝ olturƣan künliridǝ, mundaⱪ ix boldi: — Suriyǝning padixaⱨi Rǝzin wǝ Israil padixaⱨi Rǝmaliyaning oƣli Pikaⱨ Yerusalemƣa ⱪarxi jǝng ⱪildi, lekin üstünlükkǝ erixǝlmidi.
Nígbà tí Ahasi ọmọ Jotamu ọmọ Ussiah jẹ́ ọba Juda, ọba Resini ti Aramu àti Peka ọmọ Remaliah ọba Israẹli gòkè wá láti bá Jerusalẹmu jà, ṣùgbọ́n wọn kò sì le è borí i rẹ̀.
2 Dawutning jǝmǝtigǝ: — «Suriyǝ Əfraim bilǝn ittipaⱪlixip birlǝxmǝ ⱪoxun ⱪurdi» — degǝn hǝwǝr kǝldi. Xuning bilǝn padixaⱨ jǝmǝtidikilǝrning kɵngli wǝ hǝlⱪining kɵngli ormanlar xamalda silkinip kǝtkǝndǝk silkinip kǝtti.
Báyìí, a sọ fún ilé Dafidi pé, “Aramu mà ti lẹ̀dí àpò pọ̀ mọ́ Efraimu”; fún ìdí èyí, ọkàn Ahasi àti àwọn ènìyàn rẹ̀ wárìrì gẹ́gẹ́ bí igi oko ṣe ń wárìrì níwájú afẹ́fẹ́.
3 Andin Pǝrwǝrdigar Yǝxayaƣa mundaⱪ dedi: — «Sǝn wǝ oƣlung Xear-Jaxub qiⱪip, kir yuƣuqilarning etizining boyidiki yolƣa, yuⱪiri kɵlqǝk norining bexiƣa berip, axu yǝrdǝ Aⱨaz bilǝn kɵrüxkin.
Lẹ́yìn èyí, Olúwa sọ fún Isaiah pé, “Jáde, ìwọ àti ọ̀dọ́mọkùnrin rẹ Ṣeari-Jaṣubu láti pàdé Ahasi ní ìpẹ̀kun ìṣàn omi ti adágún òkè, ní òpópó ọ̀nà tí ó lọ sí pápá Alágbàfọ̀.
4 Sǝn uningƣa: — «Sǝn eⱨtiyat bilǝn kɵnglüngni toⱪ tut! Bu ikki kɵymǝs otⱪaxning kɵtikidin, yǝni Rǝzin ⱨǝm Suriyǝning wǝ Rǝmaliyaning oƣlining dǝxti-ƣǝzǝpliridin ⱪorⱪma, yürǝkzadi bolup kǝtmǝ!
Sọ fún un, ‘Ṣọ́ra à rẹ, fi ọkàn balẹ̀, kí o má ṣe bẹ̀rù. Má ṣe ba ọkàn jẹ́ nítorí kùkùté igi ìdáná méjèèjì yìí, nítorí ìbínú gbígbóná Resini àti Aramu àti ti ọmọ Remaliah.
5 Qünki Suriyǝ, Əfraim wǝ Rǝmaliyaning oƣli seni ⱪǝstlǝp: —
Aramu, Efraimu àti Remaliah ti dìtẹ̀ ìparun rẹ, wọ́n wí pé,
6 «Biz Yǝⱨudaƣa besip kirip, parakǝndiqilik tuƣdurup, ɵzimiz üqün talan-taraj ⱪilip, uningƣa bir padixaⱨni, yǝni Tabǝǝlning oƣlini tiklǝyli!» degǝnidi.
“Jẹ́ kí a kọlu Juda; jẹ́ kí a fà á ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ, kí a sì pín in láàrín ara wa, kí a sì fi ọmọ Tabeli jẹ ọba lórí i rẹ̀.”
7 Xunga Rǝb Pǝrwǝrdigar mundaⱪ dǝydu: — «Bu sɵz aⱪmaydu, ⱨeq ǝmǝlgǝ axmaydu;
Síbẹ̀ èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: “‘Èyí kò ní wáyé èyí kò le ṣẹlẹ̀,
8 Qünki Suriyǝning bexi Dǝmǝxⱪ xǝⱨiri wǝ Dǝmǝxⱪ xǝⱨirining bexi Rǝzindur, halas; Wǝ atmix bǝx yil iqidǝ Əfraim xundaⱪ bitqit boliduki, ularni «bir hǝlⱪ» degili bolmaydu;
nítorí Damasku ni orí Aramu, orí Damasku sì ni Resini. Láàrín ọdún márùnlélọ́gọ́ta Efraimu yóò ti fọ́ tí kì yóò le jẹ́ ènìyàn mọ́.
9 Wǝ Əfraimning bexi Samariyǝ xǝⱨiridur, Samariyǝ xǝⱨirining bexi Rǝmaliyaning oƣlidur, halas; Silǝr bularƣa ixǝnmisǝnglar, mustǝⱨkǝmlǝnmǝysilǝr» — degin».
Orí Efraimu sì ni Samaria, orí Samaria sì ni ọmọ Remaliah. Bí ẹ̀yin kí yóò bá gbàgbọ́, lóòtítọ́, a kì yóò fi ìdí yín múlẹ̀.’”
10 Pǝrwǝrdigar yǝnǝ Aⱨazƣa sɵz ⱪilip: —
Bákan náà Olúwa tún bá Ahasi sọ̀rọ̀,
11 «Ɵzüng üqün bexarǝt sora; mǝyli yǝrning tegidǝ yaki pǝlǝkning ⱪǝridǝ bolsun sorawǝr» — dedi. (Sheol h7585)
“Béèrè fún àmì lọ́wọ́ Olúwa Ọlọ́run rẹ, bóyá ní ọ̀gbun tí ó jì jùlọ tàbí àwọn òkè tí ó ga jùlọ.” (Sheol h7585)
12 Biraⱪ Aⱨaz jawabǝn: «Mǝn ⱨǝm sorimaymǝn ⱨǝm Pǝrwǝrdigarni sinaⱪta ⱪoymaymǝn» — dedi.
Ṣùgbọ́n Ahasi sọ pé, “Èmi kì yóò béèrè; Èmi kò ní dán Olúwa wò.”
13 Andin [Yǝxaya]: — Əmdi i Dawut jǝmǝtidikilǝr, anglap ⱪoyunglar, adǝmlǝrning sǝwr-taⱪitini ⱪoymiƣininglarni az dǝp, silǝr Hudayimning sǝwr-taⱪitinimu ⱪoymiƣiliwatamsilǝr?
Lẹ́yìn náà Isaiah sọ pé, “Gbọ́ ní ìsinsin yìí, ìwọ ilé Dafidi, kò ha tọ́ láti tán ènìyàn ní sùúrù, ìwọ yóò ha tan Ọlọ́run ní sùúrù bí?
14 Xunga Rǝb Ɵzi silǝrgǝ bir bexarǝt beridu: — Mana, pak ⱪiz ⱨamilidar bolup bir oƣul tuƣidu; u uning ismini «Immanuel» dǝp ataydu.
Nítorí náà, Olúwa fúnra ara rẹ̀ ni yóò fún ọ ní àmì kan. Wúńdíá kan yóò lóyún, yóò sì bí ọmọkùnrin kan, yóò sì pe orúkọ rẹ̀ ní Emmanueli.
15 Yahxiliⱪni tallap, yamanliⱪni rǝt ⱪilixni bilgüqǝ u pixlaⱪ wǝ bal yǝydu.
Òun yóò jẹ wàrà àti oyin nígbà tí ó bá ní ìmọ̀ tó láti kọ ẹ̀bi àti láti yan rere.
16 Qünki bu yax bala yahxiliⱪni tallap, yamanliⱪni rǝt ⱪilixni bilgüqǝ, sǝn nǝprǝtlinidiƣan bu ikki padixaⱨning yǝr-zeminliri taxlinip ⱪalidu.
Ṣùgbọ́n kí ọ̀dọ́mọkùnrin náà tó mọ bí a ti ń kọ ẹ̀bi àti láti yan rere, ilẹ̀ àwọn ọba méjèèjì tí ń bà ọ́ lẹ́rù wọ̀nyí yóò ti di ahoro.
17 Qünki Pǝrwǝrdigar sening wǝ atangning jǝmǝtigǝ Əfraim Yǝⱨudadin ayrilƣan kündin buyan bolup baⱪmiƣan ⱪattiⱪ künlǝrni qüxüridu. U künlǝr bolsa Asuriyǝning padixaⱨidin ibarǝttur!
Olúwa yóò mú àsìkò mìíràn wá fún ọ àti àwọn ènìyàn rẹ àti lórí ilé baba rẹ irú èyí tí kò sí láti ìgbà tí Efraimu ti yà kúrò ní Juda, yóò sì mú ọba Asiria wá.”
18 Xu küni Pǝrwǝrdigar Misirning pinⱨan eriⱪliridiki paxilarni wǝ Asuriyǝdiki ⱨǝrilǝrni üxⱪirtip qaⱪiridu;
Ní ọjọ́ náà ni Olúwa yóò súfèé pe àwọn eṣinṣin láti àwọn odò tó jìnnà ní Ejibiti wá, àti fún àwọn oyin láti ilẹ̀ Asiria.
19 ularning ⱨǝmmisi kelip ⱨǝrbir hilwǝt jilƣilarƣa, taxlarning ⱨǝrbir araqliriƣa, ⱨǝmmǝ yantaⱪlarƣa wǝ ⱨǝmmǝ yaylaⱪlarƣa ƣuȥȥidǝ ⱪonuxidu.
Gbogbo wọn yóò sì wá dó sí gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ òkè àti pàlàpálá òkúta, lára koríko ẹ̀gún àti gbogbo ibi ihò omi.
20 Axu küni, Rǝb Əfrat dǝryasining nerisidin ijarigǝ alƣan bir ustira bilǝn, yǝni Asuriyǝ padixaⱨi bilǝn qaq qüxüridu; muxu ustira baxning qeqini, putning tüklirini wǝ saⱪalnimu qüxürüp ƣirdaydu;
Ní ọjọ́ náà, Olúwa yóò lo abẹ fífẹ́lẹ́ tí a yá láti ìkọjá odò Eufurate, ọba Asiria, láti fá irun orí àti ti àwọn ẹsẹ̀ ẹ yín, àti láti mú irùngbọ̀n yín kúrò pẹ̀lú.
21 xu künlǝrdǝ bir kixi yax bir siyir wǝ ikki ⱪoy baⱪidu,
Ní ọjọ́ náà, ọkùnrin kan yóò máa sin ọ̀dọ́ abo màlúù kan àti ewúrẹ́ méjì.
22 ularning xunqǝ kɵp süt bǝrginidin u seriⱪ may yǝydu; dǝrwǝⱪǝ, zeminda ⱪalƣanlarning ⱨǝmmisi seriⱪ may wǝ bal yǝydu.
Àti nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ wàrà tí wọn yóò máa fún un, yóò ní wàràǹkàṣì láti jẹ. Gbogbo àwọn tí ó bá kù ní ilẹ̀ náà yóò jẹ wàràǹkàṣì àti oyin.
23 Wǝ xundaⱪ boliduki, ⱨǝr teli bir kümüx tǝnggigǝ yaraydiƣan, ming teli bar üzümzarliⱪ bolƣan ⱨǝrbir jay jiƣanliⱪⱪa wǝ tikkǝnlikkǝ aylinip ketidu;
Ní ọjọ́ náà, ni gbogbo ibi tí àjàrà tí ó tó ẹgbẹ̀rún ṣékélì fàdákà, ẹ̀gún àti ẹ̀wọ̀n nìkan ni yóò wà níbẹ̀.
24 Axu yǝrgǝ adǝmlǝr pǝⱪǝt oⱪya kɵtürüp kelidu, qünki pütkül zemin jiƣanliⱪⱪa wǝ tikǝnlikkǝ aylinip ketidu.
Àwọn ènìyàn yóò máa lọ síbẹ̀ pẹ̀lú ọrun àti ọfà nítorí pé ẹ̀gún àti ẹ̀wọ̀n ni yóò bo gbogbo ilẹ̀ náà.
25 Ilgiri kǝtmǝn qepilƣan ⱨǝrbir taƣliⱪ jilƣilarƣa bolsa, — ular u yǝrlǝrgǝ jiƣanlardin wǝ tikǝnlǝrdin ⱪorⱪup barmaydu; Bu yǝrlǝr pǝⱪǝt kalilarni otlitidiƣan, Ⱪoylar dǝssǝp-qǝylǝydiƣan jaylar bolup ⱪalidu, halas.
Àti ní orí àwọn òkè kéékèèké tí a ti ń fi ọkọ́ ro nígbà kan rí, ẹ kò ní lọ síbẹ̀ mọ́ nítorí ìbẹ̀rù ẹ̀gún àti ẹ̀wọ̀n, wọn yóò di ibi tí a ń da màlúù lọ, àti ibi ìtẹ̀mọ́lẹ̀ fún àwọn àgùntàn kéékèèké.

< Yǝxaya 7 >