< Ⱨoxiya 1 >
1 Pǝrwǝrdigarning kalami — Uzziya, Yotam, Aⱨaz wǝ Ⱨǝzǝkiyalar Yǝⱨudaƣa, Yoaxning oƣli Yǝroboam Israilƣa padixaⱨ bolƣan waⱪitlarda, kalam Bǝǝrining oƣli Ⱨoxiyaƣa kǝldi;
Ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó tọ Hosea ọmọ Beeri wá ní àkókò ìjọba Ussiah, Jotamu, Ahasi àti Hesekiah; àwọn ọba Juda àti ní àkókò ọba Jeroboamu ọmọ Jehoaṣi ní Israẹli.
2 Pǝrwǝrdigarning Ⱨoxiya arⱪiliⱪ kǝlgǝn sɵzining baxlinixi — Pǝrwǝrdigar Ⱨoxiyaƣa: «Barƣin, paⱨixilikkǝ berilgǝn bir ayalni ǝmringgǝ alƣin, paⱨixiliktin bolƣan balilarni ɵz ⱪolungƣa alƣin; qünki zemin Pǝrwǝrdigardin waz keqip paⱨixilikkǝ pütünlǝy berildi» dedi.
Nígbà tí Olúwa bẹ̀rẹ̀ sí ní sọ̀rọ̀ láti ẹnu Hosea, Olúwa wí fún un pé, “Lọ, fẹ́ àgbèrè obìnrin kan fún ara rẹ, kí ó sì bí ọmọ àgbèrè fún ọ nípasẹ̀ àwọn ọkùnrin mìíràn, nítorí ilẹ̀ ti ṣẹ ẹ̀ṣẹ̀ àgbèrè púpọ̀ nípa yíyapa kúrò lọ́dọ̀ Olúwa.”
3 Xuning bilǝn u berip Diblaimning ⱪizi Gomǝrni ǝmrigǝ aldi; ayal uningdin ⱨamilidar bolup bir oƣul tuƣdi.
Nígbà náà ni ó sì lọ, ó sì fẹ́ Gomeri ọmọbìnrin Diblaimu, ọmọbìnrin náà sì lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan fún un.
4 Pǝrwǝrdigar uningƣa: «Uning ismini «Yizrǝǝl» dǝp ⱪoyƣin; qünki yǝnǝ azƣina waⱪit ɵtkǝndǝ, Mǝn «Yizrǝǝl»ning ⱪenining intiⱪamini Yǝⱨuning jǝmǝti üstigǝ ⱪoyimǝn wǝ Israil jǝmǝtining padixaⱨliⱪiƣa hatimǝ berimǝn.
Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Hosea pé, “Pe orúkọ ọmọ náà ní Jesreeli, nítorí pé láìpẹ́ ni èmi yóò jẹ ìdílé Jehu ní ìyà fún ẹ̀jẹ̀ àwọn ènìyàn tó pa ní ìpakúpa ní Jesreeli, Èmi yóò sì mú ìjọba Israẹli wá sí òpin.
5 Wǝ xu künidǝ ǝmǝlgǝ axuruliduki, Mǝn Israilning oⱪyasini Yizrǝǝl jilƣisida sundiriwetimǝn».
Ní ọjọ́ náà ni Èmi yóò ṣẹ́ ọrun Israẹli ní àfonífojì Jesreeli.”
6 [Gomǝr] yǝnǝ ⱨamilidar bolup, ⱪiz tuƣdi. Pǝrwǝrdigar Ⱨoxiyaƣa: «Uning ismini «Lo-ruⱨamaⱨ» dǝp ⱪoyƣin; qünki Mǝn Israil jǝmǝtigǝ ikkinqi rǝⱨim ⱪilmaymǝn, ularni ⱪǝt’iy kǝqürüm ⱪilmaymǝn;
Gomeri sì tún lóyún, ó sì bí ọmọbìnrin kan. Olúwa sọ fún un pé, “Pe orúkọ rẹ̀ ní Lo-ruhama, nítorí pé, Èmi kò ní ṣàánú fún ilé Israẹli mọ́, Èmi kò sì ní dáríjì wọ́n.
7 Biraⱪ Yǝⱨuda jǝmǝtigǝ rǝⱨim ⱪilimǝn wǝ ularning Hudasi bolƣan Pǝrwǝrdigar arⱪiliⱪ ularni ⱪutⱪuzimǝn; ularni oⱪyasiz, ⱪiliqsiz, jǝngsiz, atlarsiz wǝ atliⱪ ǝskǝrsiz ⱪutⱪuzimǝn» — dedi.
Síbẹ̀, èmi yóò ṣàánú fún ilé Juda, èmi ó gbà wọ́n—kì í ṣe nípa ọfà, idà tàbí ogun, ẹṣin tàbí kẹ̀kẹ́ ẹlẹ́ṣin bí kò ṣe nípa Olúwa Ọlọ́run wọn.”
8 Gomǝr Lo-ruⱨamaⱨni ǝmqǝktin ayriƣandin keyin yǝnǝ ⱨamilidar bolup oƣul tuƣdi;
Lẹ́yìn ìgbà tí ó gba ọmú lẹ́nu Lo-ruhama, ó sì lóyún ó sì bí ọmọkùnrin mìíràn. Nígbà náà ni
9 [Rǝb]: «Uning ismini: «Lo-ammi» dǝp ⱪoyƣin; qünki silǝr Mening hǝlⱪim ǝmǝs wǝ Mǝn silǝrgǝ [Pǝrwǝrdigar] bolmaymǝn» dedi.
Olúwa sì sọ fún un pé, “Pe orúkọ rẹ̀ ní Lo-Ammi, nítorí pé ẹ kì í ṣe ènìyàn mi, èmi náà kì í sì í ṣe Ọlọ́run yín.
10 — Biraⱪ Israilning balilirining sani dengizdiki ⱪumdǝk bolup, uni ɵlqigili yaki saniƣili bolmaydu; «Silǝr mening hǝlⱪim ǝmǝssilǝr» deyilgǝn jayda xu ǝmǝlgǝ axuruliduki, ularƣa: «[Silǝr] tirik Tǝngrining oƣulliri!» — deyilidu.
“Ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Israẹli yóò pọ̀ bí i iyanrìn etí Òkun tí a kò le wọ́n, tí a kò sì le è kà, yóò sì ṣe. Ní ibi tí wọ́n ti sọ fún wọn pé. ‘Ẹ̀yin kì í ṣe ènìyàn mi,’ níbẹ̀ ni a ó ti máa pè wọ́n ní ‘Ọmọ Ọlọ́run alààyè.’
11 Israil baliliri wǝ Yǝⱨuda baliliri birgǝ yiƣilidu, ɵzlirigǝ birla baxni tiklǝydu wǝ turƣan zemindin qiⱪidu; qünki «Yizrǝǝlning küni» uluƣdur! Aka-ukiliringlarƣa «Ammi! ([Mening hǝlⱪim]!)» wǝ singilliringlarƣa «Ruⱨamaⱨ! ([rǝⱨim ⱪilinƣan]!)» — dǝnglar!
Àwọn ènìyàn Juda àti àwọn ènìyàn Israẹli yóò parapọ̀, wọn yóò sì yan olórí kan tí yóò jáde láti ilẹ̀ náà, nítorí pé ọjọ́ ńlá ni ọjọ́ Jesreeli yóò jẹ́.