< Yaritilix 33 >
1 Yaⱪup bexini kɵtürüp ⱪariwidi, mana Əsaw tɵt yüz kixi bilǝn keliwatatti. Xuning bilǝn u balilirini ayrip, Leyaⱨ, Raⱨilǝ wǝ ikki dedǝkkǝ tapxurdi;
Jakọbu sì gbójú sókè, ó sì rí Esau àti irinwó ọkùnrin tí wọ́n ń bọ̀, ó sì pín àwọn ọmọ fún Lea, Rakeli àti àwọn ìránṣẹ́bìnrin méjèèjì.
2 u ikki dedǝk wǝ ularning balilirini ⱨǝmmining aldida mangdurdi, andin Leyaⱨ bilǝn uning balilirini, ǝng ahirida Raⱨilǝ bilǝn Yüsüpni mangdurdi.
Ó sì ti àwọn ìránṣẹ́bìnrin àti àwọn ọmọ wọn síwájú, Lea àti àwọn ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọ̀wọ́ kejì tí ó tẹ̀lé wọn, Rakeli àti Josẹfu sì wà lẹ́yìn pátápátá.
3 Ɵzi bolsa ularning aldiƣa ɵtüp mangdi, u akisining aldiƣa yetip barƣuqǝ yǝttǝ ⱪetim yǝrgǝ bax urup tǝzim ⱪildi.
Jakọbu fúnra rẹ̀ wa lọ síwájú pátápátá, ó sì tẹríba ní ìgbà méje bí ó ti ń súnmọ́ Esau, arákùnrin rẹ̀.
4 Əsaw uning aldiƣa yügürüp kelip, uni ⱪuqaⱪlap, boyniƣa girǝ selip, uni sɵydi; ⱨǝr ikkisi yiƣlixip kǝtti.
Ṣùgbọ́n Esau sáré pàdé Jakọbu, ó sì dì mọ́ ọn, ó rọ̀ mọ́ ọn lọ́rùn, ó sì fẹnukò ó lẹ́nu. Àwọn méjèèjì sì sọkún.
5 Andin Əsaw bexini kɵtürüp ⱪarap, ayallar wǝ balilarni kɵrüp: — Bu sǝn bilǝn billǝ kǝlgǝnlǝr kimlǝr? — dǝp soridi. Yaⱪup: — Bular Huda xapaǝt ⱪilip kǝminilirigǝ bǝrgǝn balilardur, — dedi.
Nígbà tí Esau sì ṣe àkíyèsí àwọn ìyàwó àti ọmọ Jakọbu, ó béèrè lọ́wọ́ Jakọbu pé, “Ti ta ni àwọn wọ̀nyí?” Jakọbu sì fèsì wí pé, “Èyí ni àwọn ọmọ tí Ọlọ́run nínú àánú rẹ̀ ti fi fún ìránṣẹ́ rẹ.”
6 Andin ikki dedǝk wǝ ularning baliliri aldiƣa berip, uningƣa tǝzim ⱪildi;
Nígbà náà ni àwọn ìránṣẹ́bìnrin àti àwọn ọmọ wọn súnmọ́ tòsí, wọ́n sì tẹríba.
7 Andin Leyaⱨmu uning baliliri bilǝn aldiƣa berip, tǝzim ⱪildi, ahirida Yüsüp bilǝn Raⱨilǝ aldiƣa berip, tǝzim ⱪildi.
Lẹ́yìn náà ni Lea àti àwọn ọmọ rẹ̀ pẹ̀lú dé, wọ́n sì tún tẹríba. Ní ìkẹyìn ni Josẹfu àti Rakeli dé, wọ́n sì tún tẹríba pẹ̀lú.
8 Əsaw: — Manga yolda uqriƣan axu topliringda nemǝ mǝⱪsiting bar? — dewidi, Yaⱪup jawab berip: — Bu hojamning aldida iltipat tepixim üqündur, dedi.
Esau sì béèrè pé, “Kí ni èrò rẹ tí o fi to àwọn ọ̀wọ̀ọ̀wọ́ tí mo pàdé wọ̀nyí?” Jakọbu dáhùn pé, “Kí n ba le rí ojúrere rẹ ni olúwa mi.”
9 Lekin Əsaw: — Əy ⱪerindixim, mǝndǝ yetip axⱪudǝk bar. Sening ɵz nǝrsiliring ɵzünggǝ ⱪalsun, dedi.
Ṣùgbọ́n Esau wí pé, “Tèmi ti tó mi, pa èyí tí o ní mọ́ fún ara rẹ.”
10 Əmma Yaⱪup: — Undaⱪ ⱪilmiƣin; ǝgǝr mǝn nǝzǝrliridǝ iltipat tapⱪan bolsam, sowƣitimni ⱪolumdin ⱪobul ⱪilƣayla; qünki silining meni huxalliⱪ bilǝn ⱪobul ⱪilƣanlirini kɵrüp, didarlirini kɵrginimdǝ Hudaning didarini kɵrgǝndǝk boldum!
Jakọbu bẹ̀ ẹ́ wí pé, “Rárá bẹ́ẹ̀ kọ́, bí ó bá ṣe pé, mo rí ojúrere rẹ, jọ̀wọ́ gba ọrẹ lọ́wọ́ mi. Bí mo ṣe rí ojú rẹ̀ yìí, ó dàbí wí pé mo rí ojú Ọlọ́run ni báyìí, tí inú rẹ̀ ti dùn sí mi.
11 Əmdi sanga kǝltürülgǝn, [Hudadin kɵrgǝn] bu bǝrikǝtlirimni ⱪobul ⱪilƣayla; qünki Huda manga xapaǝt kɵrsǝtti, ⱨǝmmǝ nǝrsilirim bar boldi, — dǝp uningdin ⱪayta-ⱪayta ɵtünüwidi, u ⱪobul ⱪildi.
Jọ̀wọ́ gba àwọn ohun tí mo mú wá wọ̀nyí lọ́wọ́ mi. Nítorí Ọlọ́run ti fi oore-ọ̀fẹ́ rẹ̀ hàn sí mi, gbogbo ohun tí mo fẹ́ sì ni mo ní.” Nígbà tí Jakọbu sì rọ̀ ọ́ pé Esau gbọdọ̀ gbà wọ́n, Esau sì gbà á.
12 Andin Əsaw: — Əmdi biz ⱪozƣilip sǝpirimizni dawamlaxturayli, mǝn sening aldingda mangay, dedi.
Nígbà náà ni Esau wí pé, “Jẹ́ kí a máa lọ, n ó sìn ọ.”
13 U uningƣa jawabǝn: — Hojam kɵrdilǝ, balilar kiqik, ⱪeximda emidiƣan ⱪoza wǝ mozaylar bar; ǝgǝr mǝn bularni bir künla aldirtip ⱪoƣlap mangdursam, pütkül pada ɵlüp ketidu.
Ṣùgbọ́n Jakọbu wí fún un pé, “Ṣe ìwọ náà ṣe àkíyèsí pé ọ̀pọ̀ nínú àwọn ọmọ wọ̀nyí kéré, àwọn màlúù àti àgùntàn pẹ̀lú sì ní àwọn ọmọ kéékèèké. Bí a bá dà wọ́n rìn jìnnà ju bí agbára wọn ṣe mọ lọ, wọ́n lè kú.
14 Xunga ɵtünimǝnki, hojam kǝminiliridin aldida mangƣaq tursun; mǝn aldimdiki mal-qarwilarning mengixiƣa, xundaⱪla balilarning mengixiƣa ⱪarap asta mengip, hojamning ⱪexiƣa Seirƣa udul baray, dedi.
Èmi bẹ̀ ọ́, máa lọ síwájú ìránṣẹ́ rẹ, àwọn ó sì máa rọra bọ̀, títí èmi àti àwọn ọmọ yóò fi dé ọ̀dọ̀ olúwa mi ní Seiri.”
15 U waⱪitta Əsaw: — Undaⱪ bolsa, mǝn ɵzüm bilǝn kǝlgǝn kixilǝrdin birnǝqqini ⱪexingda ⱪoyup ketǝy, dedi. Lekin u jawab berip: — Buning nemǝ ⱨajiti? Pǝⱪǝt hojamning nǝziridǝ iltipat tapsamla xu kupayǝ, dedi.
Esau wí pé, “Jẹ́ kí n fi díẹ̀ sílẹ̀ fún ọ nínú àwọn ọkùnrin mi nígbà náà.” Jakọbu wí pé, “Èéṣe, àní kí n sá à rí ojúrere olúwa mi?”
16 Əsaw u küni yolƣa qiⱪip Seirƣa yenip kǝtti.
Ní ọjọ́ náà gan an ni Esau padà lọ sí Seiri.
17 Yaⱪup sǝpǝr ⱪilip, Sukkot degǝn jayƣa kǝlgǝndǝ, u yǝrgǝ bir ɵy selip, malliriƣa lapaslarni yasidi. Xunga bu yǝr «Sukkot» dǝp ataldi.
Jakọbu sì lọ sí Sukkoti, ó sì kọ́ ilé fún ara rẹ̀, ó sì ṣe ọgbà fún àwọn ẹran. Ìdí èyí ní a fi ń pe ibẹ̀ ní Sukkoti.
18 Xu tǝriⱪidǝ Yaⱪup Padan-Aramdin ⱪaytip, Ⱪanaan zeminidiki Xǝkǝm xǝⱨirigǝ aman-esǝn kǝldi. U xǝⱨǝrning aldida qedir tikti.
Lẹ́yìn ìgbà tí Jakọbu tí Padani-Aramu dé, àlàáfíà ni Jakọbu dé ìlú Ṣekemu ní ilẹ̀ Kenaani, ó sì pàgọ́ sí itòsí ìlú náà.
19 Andin u qedir tikkǝn yǝrning bir ⱪisimini Xǝkǝmning atisi bolƣan Ⱨamorning oƣulliridin bir yüz ⱪǝsitigǝ setiwelip,
Ó sì ra ilẹ̀ kan tí ó pàgọ́ sí ni ọgọ́rùn-ún owó fàdákà lọ́wọ́ àwọn ọmọ Hamori tí í ṣe baba Ṣekemu.
20 Xu yǝrdǝ bir ⱪurbangaⱨ selip, namini «Əl-Əloⱨǝ-Israil» dǝp atidi.
Níbẹ̀ ni ó gbé tẹ́ pẹpẹ kan tí ó pè ní El Elohe Israẹli.