< Tarih-tǝzkirǝ 2 20 >

1 Keyinki waⱪitlarda xundaⱪ boldiki, Moabiylar, Ammoniylar wǝ Maoniylardin bǝziliri birlixip kelip Yǝⱨoxafatⱪa ⱨujum ⱪilixⱪa qiⱪti.
Lẹ́yìn èyí, àwọn ọmọ Moabu àti àwọn ọmọ Ammoni àti díẹ̀ nínú àwọn ọmọ Mehuni wá láti gbé ogun ti Jehoṣafati.
2 [Qaparmǝnlǝr] kelip Yǝⱨoxafatⱪa: — [Ɵlük] dengizning u ⱪetidin, yǝni Edomdin siligǝ ⱨujum ⱪilƣili zor bir ⱪoxun qiⱪip kǝldi; mana, ular Ⱨazazon-Tamarda, dedi (Ⱨazazon-Tamar yǝnǝ «Ən-Gǝdi» dǝpmu atilidu).
Àwọn díẹ̀ nínú àwọn ọkùnrin wá láti sọ fún Jehoṣafati, “Àwọn ọ̀pọ̀ ọ̀wọ́ ogun ń bọ̀ wá bá ọ láti apá kejì Òkun láti Siria. Ó ti wà ní Hasason Tamari náà” (èyí tí í ṣe En-Gedi).
3 Buni angliƣan Yǝⱨoxafat ⱪorⱪup, Pǝrwǝrdigarni izdǝxkǝ niyǝt baƣlap, pütün Yǝⱨuda tǝwǝsidǝ «roza tutuximiz kerǝk» dǝp jakarlidi.
Nípa ìró ìdágìrì, Jehoṣafati pinnu láti wádìí lọ́wọ́ Olúwa, ó sì kéde àwẹ̀ kíákíá fún gbogbo Juda.
4 Yǝⱨudalar ǝmdi Pǝrwǝrdigardin yardǝm tiligili yiƣildi; hǝlⱪ Yǝⱨudaning ⱨǝrⱪaysi xǝⱨǝrliridin qiⱪip Pǝrwǝrdigardin yardǝm tilǝxkǝ kelixti.
Àwọn ènìyàn Juda sì kó ara wọn jọ pọ̀ láti wá ìrànlọ́wọ́ láti ọ̀dọ̀ Olúwa; pẹ̀lúpẹ̀lú, wọ́n wá láti gbogbo ìlú ní Juda láti wá a.
5 Yǝⱨoxafat Yǝⱨuda wǝ Yerusalemdiki jamaǝt arisiƣa qiⱪip, Pǝrwǝrdigar ɵyining yengi ⱨoylisining aldida ɵrǝ turup
Nígbà náà Jehoṣafati dìde dúró níwájú àpéjọ Juda àti Jerusalẹmu ní ilé Olúwa níwájú àgbàlá tuntun.
6 mundaⱪ dua ⱪilip: — «I Pǝrwǝrdigar, ata-bowilirimizning Hudasi, Sǝn ǝrxtǝ turƣuqi Huda, barliⱪ ǝl-mǝmlikǝtlǝrning üstidin ⱨɵküm sürgüqi ǝmǝsmiding? Sening ⱪolung küq-ⱪudrǝtkǝ tolƣandur, ⱨeqkim Seni tosalmaydu.
O sì wí pé, “Olúwa, Ọlọ́run àwọn baba wa, ìwọ kì ha ṣe Ọlọ́run tí ń bẹ ní ọ̀run? Ìwọ ń ṣe alákòóso lórí gbogbo ìjọba àwọn orílẹ̀-èdè. Agbára àti ipá ń bẹ ní ọwọ́ rẹ, kò sì sí ẹnìkan tí ó lè kò ọ́ lójú.
7 I Hudayimiz, Sǝn bu zemindiki aⱨalini Ɵz hǝlⱪing Israillar aldidin ⱪoƣlap, uni Ɵz dostung Ibraⱨimning nǝsligǝ mǝnggülük miras ⱪilip bǝrgǝn ǝmǝsmiding?
Ìwọ ha kọ́ Ọlọ́run wa, tí o ti lé àwọn olùgbé ilẹ̀ yìí jáde níwájú àwọn ènìyàn Israẹli, tí o sì fi fún irú-ọmọ Abrahamu ọ̀rẹ́ rẹ láéláé?
8 Ular xu yǝrdǝ turdi ⱨǝm xu yǝrdǝ Sening namingƣa atap bir muⱪǝddǝshana selip:
Wọ́n ti ń gbé nínú rẹ̀ wọ́n sì ti kọ́ sínú rẹ ibi mímọ́ fún orúkọ rẹ wí pé,
9 «Mubada beximizƣa birǝr balayi’apǝt kǝlsǝ, mǝyli u ⱪiliq, jaza, waba, aqarqiliⱪ bolsun, ⱪiyinqiliⱪta ⱪalƣan waⱪtimizda, muxu ɵy, yǝni Sening aldingda turup, Sanga murajiǝt ⱪilsaⱪ (qünki Sening naming muxu ɵydidur), Sǝn anglaysǝn wǝ ⱪutⱪuzisǝn» degǝnidi.
‘Tí ibi bá wá sí orí wa, bóyá idà ìjìyà tàbí àjàkálẹ̀-ààrùn àwọn yóò dúró níwájú rẹ níwájú ilé yìí tí ń jẹ́ orúkọ rẹ, àwa yóò sì sọkún jáde, ìwọ yóò sì gbọ́ wa. Ìwọ yóò sì gbà wá là?’
10 Əmdi mana, bu yǝrgǝ Ammoniylar, Moabiylar wǝ Seir teƣidikilǝr besip keliwatidu! Ilgiri Israillar Misir zeminidin qiⱪⱪan qaƣda Sǝn Israillarning ularƣa tajawuz ⱪilixiƣa yol ⱪoymiƣaniding; u qaƣda Israillar ularni yoⱪatmay u yǝrdin aylinip ɵtkǝn.
“Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, àwọn ọkùnrin nìyí láti Ammoni, Moabu àti òkè Seiri, agbègbè ibi ti ìwọ kò ti gba àwọn ọmọ Israẹli láyè láti gbóguntì nígbà tí wọn wá láti Ejibiti, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n yípadà kúrò ní ọ̀dọ̀ wọn, wọn kò sì pa wọ́n run.
11 Əmdi ⱪara, ⱨazir ularning yahxiliⱪimizni ⱪandaⱪ yol bilǝn ⱪayturmaⱪqi boluwatⱪiniƣa! Ular bizni Sǝn bizgǝ miras ⱪilip bǝrgǝn bu zemindin ⱪoƣlap qiⱪarmaⱪqi boluwatidu.
Sì kíyèsi i, bí wọ́n ti san án padà fún wa; láti wá lé wa jáde kúrò nínú ìní rẹ, tí ìwọ ti fi fún wa láti ní.
12 I Hudayimiz, Sǝn ularning üstidin ⱨɵküm qiⱪarmamsǝn? Qünki bizning bizgǝ ⱨujum ⱪilixⱪa keliwatⱪan bu zor ⱪoxun bilǝn ⱪarxilaxⱪudǝk küqimiz yoⱪ; nemǝ ⱪiliximiznimu bilmǝy ⱪalduⱪ; lekin bizning kɵzimiz Sanga tikilip turmaⱪta» — dedi.
Ọlọ́run wa, ṣé ìwọ kò ní ṣe ìdájọ́ fún wọn? Nítorí àwa kò ní agbára láti dojúkọ àwọn ọ̀pọ̀ ogun ńlá yìí tí ń bọ̀ wá kó wa. Àwa kò mọ̀ ohun tó yẹ ká ṣe, ṣùgbọ́n ojú wa wà ní ọ̀dọ̀ rẹ.”
13 Bu qaƣda pütün Yǝⱨuda hǝlⱪi, ularning ⱪuqaⱪtiki baliliri, hotun bala-qaⱪilirining ⱨǝmmisi Pǝrwǝrdigarning aldida turatti.
Gbogbo àwọn ọkùnrin Juda, pẹ̀lú àwọn aya wọn àti ọmọ wọn àti àwọn kéékèèké, dúró níbẹ̀ níwájú Olúwa.
14 Wǝ xu pǝyttǝ Pǝrwǝrdigarning Roⱨi jamaǝtning otturisida turƣan Lawiylardin Asafning ǝwladi bolƣan Mattaniyaning qǝwrisi, Jǝiyǝlning ǝwrisi, Binayaning nǝwrisi, Zǝkǝriyaning oƣli Yaⱨaziyǝlgǝ qüxti;
Nígbà náà, ẹ̀mí Olúwa sì bà lé Jahasieli ọmọ Sekariah, ọmọ Benaiah, ọmọ Jeieli, ọmọ Mattaniah ọmọ Lefi àti ọmọ Asafu, gẹ́gẹ́ bí ó ṣe dìde dúró láàrín àpéjọ ènìyàn.
15 U: — I pütün Yǝⱨuda hǝlⱪi, silǝr Yerusalemda turuwatⱪanlar wǝ padixaⱨ Yǝⱨoxafat, ⱪulaⱪ selinglar! Pǝrwǝrdigar silǝrgǝ mundaⱪ dǝydu: — «Silǝr bu zor ⱪoxundin ⱪorⱪup kǝtmǝnglar wǝ alaⱪzadǝ bolup kǝtmǝnglar; qünki bu jǝng silǝrningki ǝmǝs, bǝlki Hudaning Ɵziningkidur.
Ó sì wí pé, “Ẹ tẹ́tí sílẹ̀, ọba Jehoṣafati àti gbogbo àwọn tí ń gbé ní Juda àti Jerusalẹmu! Èyí ní ohun tí Olúwa sọ wí pé kí a ṣe: ‘Ẹ má ṣe bẹ̀rù tàbí fòyà nítorí ọ̀pọ̀ ogun ńlá yìí. Nítorí ogun náà kì í ṣe tiyín, ṣùgbọ́n ti Ọlọ́run ni.
16 Ətǝ ularƣa ⱨujum ⱪilixⱪa qiⱪinglar; mana, ular Ziz dawanidin qiⱪip kelidu wǝ silǝr ularni Yǝruǝl qɵlining aldidiki jilƣa eƣizida uqritisilǝr.
Ní ọ̀la, ẹ sọ̀kalẹ̀ tọ̀ wọ́n lọ, wọn yóò gòkè pẹ̀lú, ẹ̀yin yóò sì rí wọn ní ìpẹ̀kun odò náà, níwájú aginjù Jerueli.
17 Silǝr bu dɵrǝm jǝngdǝ uruxuxunglarning ⱨajiti bolmaydu; pǝⱪǝt sǝpkǝ tizilip turunglar, silǝr bilǝn billǝ bolƣan Pǝrwǝrdigarning nijat-nusritini kɵrünglar! I Yǝⱨuda, i Yerusalemdikilǝr, ⱪorⱪmanglar, alaⱪzadimu bolup kǝtmǝnglar; ǝtǝ ularƣa ⱨujum ⱪilixⱪa qiⱪinglar, Pǝrwǝrdigar qoⱪum silǝr bilǝn billǝ bolidu!» — dedi.
Ẹ̀yin kò ní láti bá ogun yìí jà. ẹ dúró ní ààyè yín; ẹ dúró jẹ́ẹ́ kí ẹ sì rí ìgbàlà Olúwa tí yóò fi fún yín, ìwọ Juda àti Jerusalẹmu. Ẹ má ṣe bẹ̀rù; ẹ má sì ṣe fòyà. Ẹ jáde lọ láti lọ dojúkọ wọ́n ní ọ̀la, Olúwa yóò sì wà pẹ̀lú yín.’”
18 Bu gǝpni anglap Yǝⱨoxafat bexini yǝrgǝ tǝgküzüp tizlandi wǝ barliⱪ Yǝⱨuda hǝlⱪi ⱨǝm Yerusalemdikilǝr Pǝrwǝrdigar aldida düm yiⱪilip Pǝrwǝrdigarƣa sǝjdǝ ⱪildi.
Jehoṣafati tẹ orí rẹ̀ ba sílẹ̀ pẹ̀lú ojú rẹ̀, àti gbogbo àwọn ènìyàn Juda àti Jerusalẹmu wólẹ̀ níwájú láti sin Olúwa.
19 Koⱨat ǝwladi wǝ Koraⱨ ǝwladi iqidiki Lawiylardin bolƣanlar orunliridin turuxup intayin küqlük awaz bilǝn Israilning Hudasi Pǝrwǝrdigarni mǝdⱨiyilǝxti.
Nígbà náà díẹ̀ lára àwọn ọmọ Lefi àti àwọn ọmọ Kohati àti àwọn ọmọ Kora sì dìde dúró wọ́n sì sin Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, pẹ̀lú ohùn ariwo ńlá.
20 Pütün hǝlⱪ ǝtisi ⱪaⱪ sǝⱨǝrdǝ turup Tǝkoa qɵligǝ ⱪarap atlandi; ular atlinip ketiwatⱪanda, Yǝⱨoxafat ornidin turup ularƣa: — I Yǝⱨuda hǝlⱪi, i Yerusalemdikilǝr, gepimgǝ ⱪulaⱪ selinglar! Hudayinglar Pǝrwǝrdigarƣa tayininglar, qoⱪum mǝzmut turƣuzulisilǝr; Uning pǝyƣǝmbǝrlirigǝ ixininglar, yolunglar qoⱪum rawan bolidu! — dedi.
Ní òwúrọ̀ kùtùkùtù wọ́n jáde lọ sí aginjù Tekoa. Gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti ń jáde lọ, Jehoṣafati dìde dúró ó sì wí pé, “Ẹ gbọ́ mi, Juda àti ènìyàn Jerusalẹmu! Ẹ ní ìgbàgbọ́ nínú Olúwa Ọlọ́run yín ẹ̀yin yóò sì borí, ẹ ní ìgbàgbọ́ nínú àwọn wòlíì rẹ̀ ẹ̀yìn yóò sì ṣe rere.”
21 Andin u hǝlⱪ bilǝn obdan mǝsliⱨǝtlixip, Pǝrwǝrdigarning muⱪǝddǝs bǝⱨǝywǝtlikini mǝdⱨiyilǝp, Uningƣa atap ƣǝzǝl-küy eytidiƣanlarni: «Silǝr Pǝrwǝrdigarƣa rǝⱨmǝt-tǝxǝkkür eytinglar, qünki Uning ɵzgǝrmǝs muⱨǝbbiti mǝnggülüktur!» dǝp oⱪuxⱪa tǝyinlǝp, ⱪoxunning aldida mangdurdi.
Lẹ́yìn ìgbà tí ó bá àwọn ènìyàn náà gbèrò tán, Jehoṣafati yàn wọ́n láti kọrin sí Olúwa àti láti fi ìyìn fún ẹwà ìwà mímọ́ gẹ́gẹ́ bí ó tì ń jáde lọ sí iwájú ogun ńlá náà, wí pé, “Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, nítorí àánú rẹ̀ dúró títí láéláé.”
22 Ular tǝntǝnǝ ⱪilip ⱨǝmdusana oⱪuxi bilǝn, Pǝrwǝrdigar Yǝⱨuda hǝlⱪigǝ ⱨujum ⱪilixⱪa qiⱪⱪan Ammoniylar, Moabiylar wǝ Seir teƣidikilǝrgǝ pistirma ⱪoxunni ǝwǝtip, ularni tarmar ⱪildurdi.
Bí wọ́n ti bẹ̀rẹ̀ sí kọrin àti ìyìn, Olúwa rán ogun ẹ̀yìn sí àwọn ọkùnrin Ammoni àti Moabu àti òkè Seiri tí ó ń gbógun ti Juda, wọ́n sì kọlù wọ́n.
23 Xuning bilǝn Ammoniylar bilǝn Moabiylar Seir teƣidikilǝrgǝ ⱨujum ⱪilixⱪa ɵtti, ularni birini ⱪoymay ⱪiriwǝtti; ular Seir teƣidikilǝrni ⱪirip tügǝtkǝndin keyin yǝnǝ ɵzliri bir-birini ⱪirƣin ⱪilixⱪa qüxkǝnidi.
Àwọn ọkùnrin Ammoni àti Moabu dìde dúró sí àwọn ọkùnrin tí ń gbé òkè Seiri láti pa wọ́n run túútúú. Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n sì ti pa àwọn ọkùnrin láti òkè Seiri, wọ́n sì ran ra wọn lọ́wọ́ láti pa ara wọn run.
24 Yǝⱨudalar qɵldiki kɵzǝtgaⱨⱪa kelip xu zor ⱪoxun tǝrǝpkǝ ⱪarisa, mana ⱪeqip ⱪutulƣan birmu adǝm yoⱪ bolup, ⱨǝmmǝ yǝrni ɵlük ⱪaplap kǝtkǝnidi.
Nígbà tí àwọn ènìyàn Juda jáde sí ìhà ilé ìṣọ́ ní aginjù, wọn ń wo àwọn ọ̀pọ̀ ènìyàn, òkú nìkan ni wọ́n rí tí ó ṣubú sí ilẹ̀, kò sì sí ẹnìkan tí ó rí ààyè sá.
25 Yǝⱨoxafat ɵzining adǝmliri bilǝn düxmǝndin olja bulang-talang ⱪilixⱪa kǝlgǝndǝ, ular ɵlüklǝr bilǝn billǝ nurƣun mal-mülük wǝ kɵp ⱪimmǝtlik buyumlarni tapti. Ular salduruwalƣanlirining toliliⱪidin elip kitǝlmǝy ⱪaldi; olja xunqǝ kɵp bolƣaqⱪa, uni yiƣiwelixⱪa üq kün kǝtti.
Bẹ́ẹ̀ ni Jehoṣafati àti àwọn ènìyàn rẹ̀ lọ láti kó ìkógun wọn, wọ́n sì rí lára wọn ọ̀pọ̀ iyebíye ọrọ̀ púpọ̀, ó sì ju èyí tí wọ́n lè kó lọ. Ọ̀pọ̀ ìkógun sì wà níbẹ̀, èyí tí ó gbà wọ́n ní ọjọ́ mẹ́ta láti gbà pọ̀.
26 Ular tɵtinqi küni Bǝrakaⱨ jilƣisiƣa yiƣilip, Pǝrwǝrdigarƣa ⱨǝmdusana oⱪup mubarǝklidi; xunga u yǝr taki bügüngǝ ⱪǝdǝr «Bǝrakaⱨ jilƣisi» dǝp atilip kǝlmǝktǝ.
Ní ọjọ́ kẹrin, wọn kó ara jọ pọ̀ ní àfonífojì ìbùkún, níbi tí wọ́n ti ń fi ìbùkún fún Olúwa. Ìdí nìyí tí wọ́n fi ń pe ibẹ̀ ní àfonífojì ìbùkún títí di òní.
27 Andin barliⱪ Yǝⱨudadikilǝr wǝ Yerusalemdikilǝr Yǝⱨoxafatning baxlamqiliⱪida huxal-huram bolup Yerusalemƣa ⱪaytti; qünki Pǝrwǝrdigar ularni düxmǝnliri üstidin ƣalib ⱪilip huxalliⱪⱪa qɵmdürgǝnidi.
Nígbà náà wọ́n darí pẹ̀lú Jehoṣafati, gbogbo àwọn ènìyàn Juda àti Jerusalẹmu padà pẹ̀lú ayọ̀ sí Jerusalẹmu, nítorí Olúwa ti fún wọn ní ìdí láti yọ̀ lórí àwọn ọ̀tá wọn.
28 Ular Yerusalemƣa tǝmbur, qiltar wǝ kanaylar qelip kelip, Pǝrwǝrdigarning ɵyigǝ kirdi.
Wọ́n sì wọ Jerusalẹmu, wọ́n sì lọ sí ilé Olúwa pẹ̀lú ohun èlò orin olókùn àti dùùrù àti ìpè.
29 Barliⱪ ǝl-mǝmlikǝtlǝr Pǝrwǝrdigarning Israilning düxmǝnlirigǝ ⱪarxi qiⱪip jǝng ⱪilƣanliⱪini angliƣanda, Hudaning wǝⱨimisi ularning üstigǝ basti.
Ìbẹ̀rù Ọlọ́run wá si orí gbogbo ìjọba ilẹ̀ náà nígbà tí wọ́n gbọ́ bí Olúwa ti bá àwọn ọ̀tá Israẹli jà.
30 Xuning bilǝn Yǝⱨoxafatning padixaⱨliⱪi tinq-asayixliⱪta boldi; uning Hudasi uning tɵt ǝtrapini tinq ⱪilƣanidi.
Bẹ́ẹ̀ ni ìjọba Jehoṣafati sì wà ní àlàáfíà, nítorí Ọlọ́run rẹ̀ ti fún un ni ìsinmi ní gbogbo àyíká.
31 Xundaⱪ ⱪilip Yǝⱨoxafat Yǝⱨuda üstigǝ ⱨɵküm sürdi. U tǝhtkǝ qiⱪⱪan qaƣda ottuz bǝx yaxta idi; u Yerusalemda yigirmǝ bǝx yil sǝltǝnǝt ⱪildi. Uning anisining ismi Azubaⱨ bolup, u Xilⱨining ⱪizi idi.
Báyìí ni Jehoṣafati jẹ ọba lórí Juda. Ó sì jẹ́ ẹni ọdún márùndínlógójì. Nígbà tí ó di ọba Juda, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n. Orúkọ ìyá rẹ̀ sì ni Asuba ọmọbìnrin Silihi.
32 Yǝⱨoxafat ⱪaymay atisi Asaning yolida mengip, Pǝrwǝrdigarning nǝziridǝ durus bolƣanni ⱪildi.
Ó sì rin ọ̀nà baba rẹ̀ Asa kò sì yà kúrò nínú rẹ̀, ó sì ṣe èyí tí ó tọ́ ní ojú Olúwa.
33 Pǝⱪǝt «yuⱪiri jaylar»la yoⱪitilmiƣanidi; hǝlⱪ tehiqǝ kɵngüllirini ata-bowilirining Hudasiƣa mayil ⱪilmiƣanidi.
Ní ibi gíga, pẹ̀lúpẹ̀lú, kò mu wọn kúrò, gbogbo àwọn ènìyàn náà kò sì fi ọkàn wọn fún Ọlọ́run àwọn baba wọn.
34 Yǝⱨoxafatning ⱪalƣan ixliri bolsa, mana baxtin ahiriƣiqǝ «Yǝⱨuda wǝ Israil padixaⱨlirining tarihnamisi»ƣa kirgüzülgǝn «Ⱨananining oƣli Yǝⱨuning bayan sɵzliri»dǝ pütülgǝndur.
Ìyókù iṣẹ́ ìjọba Jehoṣafati, láti ìbẹ̀rẹ̀ títí dé òpin, ni a kọ sí inú ìwé ìtàn ti Jehu ọmọ Hanani, tí a kọ sí inú ìwé àwọn ọba Israẹli.
35 Bu ixlardin keyin Yǝⱨuda padixaⱨi Yǝⱨoxafat tola rǝzil ixlarni ⱪilƣan Israil padixaⱨi Aⱨaziya bilǝn ittipaⱪ tüzdi.
Nígbà tí ó yá, Jehoṣafati ọba Juda da ara rẹ̀ pọ̀ pẹ̀lú Ahasiah, ọba Israẹli, ẹni tí ó jẹ̀bi ìwà búburú.
36 Yǝⱨoxafat Tarxixⱪa baridiƣan kemilǝrni yasaxⱪa uning bilǝn xiriklǝxti; xu kemilǝrni ular Əzion-Gǝbǝrdǝ yasatti.
Ó sì gbà pẹ̀lú rẹ̀ láti kan ọkọ̀ láti lọ sí Tarṣiṣi, lẹ́yìn èyí wọ́n kan ọkọ̀ ní Esioni-Geberi.
37 U qaƣda Marǝxaⱨliⱪ Dodawaⱨuning oƣli Əliezǝr Yǝⱨoxafatni ǝyiblǝp uningƣa bexarǝt berip: — Aⱨaziya bilǝn ittipaⱪ tüzgining üqün Pǝrwǝrdigar sening yasiƣanliringni buzuwetidu» dedi. Dǝrwǝⱪǝ, keyinki waⱪitlarda u kemilǝr buzƣunqiliⱪⱪa uqrap Tarxixⱪa mangalmidi.
Elieseri ọmọ Dodafahu ti Meraṣa sọtẹ́lẹ̀ sí Jehoṣafati, wí pe, “Nítorí tí ìwọ ti da ara rẹ̀ pọ̀ mọ́ Ahasiah, Olúwa yóò pa ohun ti ìwọ ti ṣe run.” Àwọn ọkọ̀ náà sì fọ́, wọn kò sì le lọ sí ibi ìtajà.

< Tarih-tǝzkirǝ 2 20 >