< Padixaⱨlar 1 17 >
1 Əmdi Gileadta turuwatⱪanlardin bolƣan Tixbiliⱪ Iliyas Aⱨabⱪa: — Mǝn hizmitidǝ turuwatⱪan Israilning Hudasi Pǝrwǝrdigarning ⱨayati bilǝn ⱪǝsǝm ⱪilimǝnki, mening sɵzümsiz bu yillarda nǝ xǝbnǝm nǝ yamƣur qüxmǝydu, dedi.
Elijah ará Tiṣibi láti Tiṣbi ní Gileadi wí fún Ahabu pé, “Bí Olúwa Ọlọ́run Israẹli ti wà, ẹni tí èmi ń sìn, kì yóò sí ìrì tàbí òjò ní ọdún díẹ̀ tí ń bọ̀ bí kò ṣe nípa ọ̀rọ̀ mi.”
2 Andin Pǝrwǝrdigarning sɵzi uningƣa kelip: —
Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Elijah wá pé,
3 Bu yǝrdin ketip, mǝxriⱪ tǝrǝpkǝ berip, Iordan dǝryasining u tǝripidiki ⱪerit eⱪinining boyida ɵzüngni yoxurƣin;
“Kúrò níhìn-ín, kọjú sí ìhà ìlà-oòrùn, kí o sì fi ara rẹ pamọ́ níbi odò Keriti, tí ń bẹ níwájú Jordani.
4 wǝ xundaⱪ boliduki, sǝn eⱪinning süyidin iqisǝn; mana, sanga u yǝrdǝ ozuⱪ yǝtküzüp berixkǝ ⱪaƣa-ⱪuzƣunlarni buyrudum, deyildi.
Ìwọ yóò mu nínú odò náà, mo sì ti pàṣẹ fún àwọn ẹyẹ ìwò láti máa bọ́ ọ níbẹ̀.”
5 Xuning bilǝn u Pǝrwǝrdigar buyruƣandǝk ⱪilip, Iordan dǝryasining u tǝripidiki ⱪerit eⱪiniƣa berip, u yǝrdǝ turdi.
Bẹ́ẹ̀ ni ó sì ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ fún un. Ó sì lọ sí ẹ̀bá odò Keriti, tí ń bẹ níwájú Jordani, ó sì dúró síbẹ̀.
6 Ⱪaƣa-ⱪuzƣunlar ǝtigǝndǝ nan bilǝn gɵx, ⱨǝr kǝqtǝ yǝnǝ nan bilǝn gɵx yǝtküzüp berǝtti. U ɵzi eⱪinning süyidin iqǝtti.
Àwọn ẹyẹ ìwò sì mú àkàrà àti ẹran wá fún un ní òwúrọ̀, àti àkàrà àti ẹran ní alẹ́, ó sì ń mu nínú odò náà.
7 Lekin zeminda yamƣur yaƣmiƣini üqün birmǝzgildin keyin eⱪin su ⱪurup kǝtti.
Ó sì ṣe lẹ́yìn ọjọ́ díẹ̀, odò náà sì gbẹ nítorí kò sí òjò ní ilẹ̀ náà.
8 U waⱪitta Pǝrwǝrdigarning sɵzi uningƣa kelip: —
Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ ọ́ wá wí pé,
9 Ornungdin turup Zidondiki Zarǝfatⱪa berip, u yǝrdǝ turƣin; mana, Mǝn u yǝrdiki bir tul hotunni seni beⱪixⱪa buyrudum, deyildi.
“Lọ nísinsin yìí sí Sarefati ti Sidoni, kí o sì dúró síbẹ̀. Èmi ti pàṣẹ fún obìnrin opó kan níbẹ̀ láti máa bọ́ ọ.”
10 U ornidin turup Zarǝfatⱪa berip, xǝⱨǝrning dǝrwazisiƣa kǝlgǝndǝ, mana u yǝrdǝ bir tul hotun otun terip turatti. U tul hotunni qaⱪirip: — Ɵtünimǝn, ⱪaqida manga iqkili azraⱪ su elip kǝlgǝysǝn, dedi.
Bẹ́ẹ̀ ni ó sì lọ sí Sarefati. Nígbà tí ó sì dé ibodè ìlú náà, obìnrin opó kan ń ṣa igi jọ níbẹ̀. Ó sì ké sí i, ó sì béèrè pé, “Ǹjẹ́ o lè bu omi díẹ̀ fún mi wá nínú ohun èlò kí èmi kí ó lè mu?”
11 U su alƣili mangƣanda, u yǝnǝ: — Ɵtünimǝn, manga ⱪolungda bir qixlǝm nanmu alƣaq kǝlgǝysǝn, dedi.
Bí ó sì ti ń lọ bù ú wá, ó ké sí i pé, “Jọ̀ ọ́, mú òkèlè oúnjẹ díẹ̀ fún mi wá lọ́wọ́ rẹ.”
12 Əmma u: — Pǝrwǝrdigar Hudayingning ⱨayati bilǝn, sanga ⱪǝsǝm ⱪilimǝnki, mǝndǝ ⱨeq nan yoⱪ, pǝⱪǝt idixta bir qanggal un, kozida azƣinǝ may bar, mana ikki tal otun teriwatimǝn; andin berip ɵzüm bilǝn oƣlumƣa nan etip, uni yǝp ɵlimiz, dedi.
Obìnrin opó náà sì dá a lóhùn wí pé, “Bí Olúwa Ọlọ́run rẹ ti wà, èmi kò ní àkàrà, bí kò ṣe ìkúnwọ́ ìyẹ̀fun nínú ìkòkò àti òróró díẹ̀ nínú kólòbó. Èmi ń ṣa igi díẹ̀ jọ láti kó lọ ilé, kí èmi kí ó sì pèsè rẹ̀ fún mi àti fún ọmọ mi, kí àwa lè jẹ ẹ́: kí a sì kú.”
13 Iliyas uningƣa: — Ⱪorⱪmiƣin; berip eytⱪiningdǝk ⱪilƣin; lekin awwal bir kiqik toⱪaq etip, manga elip kǝlgin; andin ɵzüng bilǝn oƣlungƣa nan ǝtkin.
Elijah sì wí fún un pé, “Má ṣe bẹ̀rù. Lọ, kí o sì ṣe gẹ́gẹ́ bí o ti wí. Ṣùgbọ́n kọ́kọ́ ṣe àkàrà kékeré kan fún mi nínú rẹ̀ ná, kí o sì mú fún mi wá, lẹ́yìn náà, kí o ṣe tìrẹ àti ti ọmọ rẹ.
14 Qünki Israilning Hudasi Pǝrwǝrdigar mundaⱪ dǝydu: — «Pǝrwǝrdigar yǝr yüzigǝ yamƣur yaƣduridiƣan küngiqilik idixtiki un tügimǝydu wǝ kozidiki may kemǝymǝydu», dedi.
Nítorí báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí: ‘Ìkòkò ìyẹ̀fun náà kì yóò ṣófo, bẹ́ẹ̀ ni kólòbó òróró náà kì yóò gbẹ, títí di ọjọ́ tí Olúwa yóò rọ òjò sí orí ilẹ̀.’”
15 Xuning bilǝn u berip, Iliyasning eytⱪinidǝk ⱪildi wǝ u, Iliyas wǝ ayalning ɵyidikilǝr heli künlǝrgiqǝ yedi.
Ó sì lọ, ó sì ṣe gẹ́gẹ́ bí Elijah ti sọ fún un. Oúnjẹ sì wà fún Elijah àti obìnrin náà àti ilé rẹ̀ ní ojoojúmọ́.
16 Pǝrwǝrdigarning Iliyas arⱪiliⱪ eytⱪan sɵzi boyiqǝ, idixtiki un tügimidi wǝ kozidiki maymu kemǝymidi.
Nítorí ìkòkò ìyẹ̀fun náà kò ṣófo, kólòbó òróró náà kò gbẹ, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó ti ipa Elijah sọ.
17 Xu ixlardin keyin xundaⱪ boldiki, ɵyning igisi bolƣan bu ayalning oƣli kesǝl boldi. Uning kesili xundaⱪ eƣirlixip kǝttiki, uningda nǝpǝs ⱪalmidi.
Ó sì ṣe lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí, ọmọ obìnrin tí ó ni ilé náà ṣe àìsàn, àìsàn náà sì le tó bẹ́ẹ̀, tí ó fi kú.
18 Ayal Iliyasⱪa: — I Hudaning adimi, mening sǝn bilǝn nemǝ alaⱪǝm bar idi? Sǝn gunaⱨimni yadⱪa kǝltürüp, oƣlumning jeniƣa zamin boluxⱪa kǝldingmu? — dedi.
Obìnrin náà sì wí fún Elijah pé, “Kí lo ní sí mi, ènìyàn Ọlọ́run? Ìwọ ha tọ̀ mí wá láti mú ẹ̀ṣẹ̀ mi wá sí ìrántí, àti láti pa mí ní ọmọ?”
19 U uningƣa: — Oƣlungni ⱪolumƣa bǝrgin, dǝp uni uning ⱪuqiⱪidin elip ɵzi olturƣan balihaniƣa elip qiⱪip ɵz orniƣa ⱪoyup,
Elijah sì wí fún un pé, “Gbé ọmọ rẹ fún mi.” Ó sì yọ ọ́ jáde ní àyà rẹ̀, ó sì gbé e lọ sí iyàrá òkè ilé níbi tí òun ń gbé, ó sì tẹ́ ẹ sí orí ibùsùn tirẹ̀.
20 Pǝrwǝrdigarƣa pǝryad ⱪilip: — I Hudayim Pǝrwǝrdigar, mǝn meⱨman bolƣan bu tul hotunning oƣlini ɵltürüx bilǝn uning bexiƣimu bala qüxürdungmu? — dǝp nida ⱪildi.
Nígbà náà ni ó sì ké pe Olúwa wí pé, “Olúwa Ọlọ́run mi, ìwọ ha mú ibi wá bá opó náà pẹ̀lú lọ́dọ̀ ẹni tí èmi ń ṣe àtìpó, nípa pípa ọmọ rẹ̀?”
21 U balining üstigǝ üq ⱪetim ɵzini qaplap, Pǝrwǝrdigarƣa pǝryad ⱪilip: — I Pǝrwǝrdigar Hudayim, bu balining jeni ɵzigǝ yǝnǝ yenip kirsun! — dǝp nida ⱪildi.
Nígbà náà ni ó sì na ara rẹ̀ lórí ọmọdé náà ní ẹ̀ẹ̀mẹta, ó sì ké pe Olúwa pé, “Olúwa Ọlọ́run mi, jẹ́ kí ẹ̀mí ọmọdé yìí kí ó tún padà tọ̀ ọ́ wá!”
22 Pǝrwǝrdigar Iliyasning pǝryadini anglidi; balining jeni uningƣa yenip kirixi bilǝn u tirildi.
Olúwa sì gbọ́ igbe Elijah, ẹ̀mí ọmọdé náà sì tún padà tọ̀ ọ́ wá, ó sì sọjí.
23 Iliyas balini balihanidin elip qüxüp, ɵygǝ kirip, anisiƣa tapxurup bǝrdi. Iliyas: — Mana oƣlung tiriktur, dedi.
Elijah sì mú ọmọdé náà, ó sì gbé e sọ̀kalẹ̀ láti inú yàrá òkè náà wá sínú ilé. Ó sì fi lé ìyá rẹ̀ lọ́wọ́; Elijah sì wí pé, “Wò ó, ọmọ rẹ yè!”
24 Ayal Iliyasⱪa: — Mǝn xu ix arⱪiliⱪ ǝmdi sening Hudaning adimi ikǝnlikingni, aƣzingdin qiⱪⱪan Pǝrwǝrdigarning sɵzi ⱨǝⱪiⱪǝt ikǝnlikini bildim, dedi.
Obìnrin náà sì wí fún Elijah pé, “Nísinsin yìí mo mọ̀ pé ènìyàn Ọlọ́run ni ìwọ ń ṣe, àti pé òtítọ́ ni ọ̀rọ̀ Olúwa ní ẹnu rẹ.”