< Padixaⱨlar 1 12 >
1 Rǝⱨoboam Xǝⱪǝmgǝ bardi; qünki pütkül Israil uni padixaⱨ tikligili Xǝⱪǝmgǝ kǝlgǝnidi.
Rehoboamu sì lọ sí Ṣekemu, nítorí gbogbo Israẹli ti lọ síbẹ̀ láti fi í jẹ ọba.
2 Nibatning oƣli Yǝroboam xu ixni angliƣanda, xundaⱪ boldiki, u tehi Misirda idi (qünki Yǝroboam Sulayman padixaⱨtin ⱪeqip Misirda turuwatatti).
Nígbà tí Jeroboamu ọmọ Nebati, tí ó wà ní Ejibiti síbẹ̀ gbọ́, nítorí tí ó ti sá kúrò níwájú Solomoni ọba, ó sì wà ní Ejibiti.
3 Əmdi ular adǝm ǝwǝtip uni qaⱪirtip kǝldi. Xuning bilǝn Yǝroboam wǝ pütkül Israil jamaiti kelip Rǝⱨoboamƣa sɵz ⱪilip:
Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ránṣẹ́ sí Jeroboamu, òun àti gbogbo ìjọ Israẹli sì lọ sọ́dọ̀ Rehoboamu, wọ́n sì wí fún un pé,
4 — Silining atiliri boynimizƣa salƣan boyunturuⱪini eƣir ⱪildi. Sili ǝmdi atilirining bizgǝ ⱪoyƣan ⱪattiⱪ tǝlǝpliri bilǝn eƣir boyunturuⱪini yeniklitip bǝrsilǝ, silining hizmǝtliridǝ bolimiz, deyixti.
“Baba rẹ sọ àjàgà wa di wúwo, ṣùgbọ́n nísinsin yìí, mú kí ìsìn baba rẹ̀ tí ó le, àti àjàgà rẹ̀ tí ó wúwo, tí ó fi sí wa ní ọrùn kí ó fẹ́rẹ̀ díẹ̀, àwa yóò sì sìn ọ́.”
5 U ularƣa: — Ⱨazirqǝ ⱪaytip üq kündin keyin andin ⱪeximƣa yǝnǝ kelinglar, dedi. Xuning bilǝn hǝlⱪ tarilip kǝtti.
Rehoboamu sì wí fún wọn pé, “Ẹ lọ ná títí di ọjọ́ mẹ́ta, nígbà náà ni kí ẹ padà tọ̀ mí wá.” Àwọn ènìyàn náà sì lọ.
6 Rǝⱨoboam padixaⱨ ɵz atisi Sulayman ⱨayat waⱪtida uning hizmitidǝ turƣan moysipitlardin mǝsliⱨǝt sorap: — Bu hǝlⱪⱪǝ beridiƣan jawabim toƣrisida nemǝ mǝsliⱨǝt kɵrsitisilǝr? — dedi.
Nígbà náà ni Rehoboamu ọba fi ọ̀rọ̀ lọ àwọn àgbàgbà tí ń dúró níwájú Solomoni baba rẹ̀ nígbà tí ó wà láààyè. Ó sì béèrè pé, “Ìmọ̀ràn wo ni ẹ̀yin yóò gbà mí láti dá àwọn ènìyàn wọ̀nyí lóhùn?”
7 Ular uningƣa: — Əgǝr sili raziliⱪ bilǝn bügün bu hǝlⱪning hizmitidǝ bolimǝn desilǝ, (wǝ dǝrwǝⱪǝ ularning hizmitidǝ bolsila) ularƣa yahxi sɵzlǝr bilǝn jawab ⱪilsila, ular silining barliⱪ künliridǝ hizmǝtliridǝ bolidu, dedi.
Wọ́n sì dá a lóhùn pé, “Bí ìwọ yóò bá jẹ́ ìránṣẹ́ fún àwọn ènìyàn wọ̀nyí lónìí, kí o sì sìn wọ́n, àti kí o sì sọ ọ̀rọ̀ rere sí wọn nígbà tí ìwọ bá ń dá wọn lóhùn, wọn yóò máa ṣe ìránṣẹ́ rẹ títí láé.”
8 Lekin u moysipitlarning kɵrsǝtkǝn mǝsliⱨǝtini ⱪayrip ⱪoyup, ɵzi bilǝn qong bolƣan, aldida hizmitidǝ boluwatⱪan yaxlardin mǝsliⱨǝt sorap
Ṣùgbọ́n Rehoboamu kọ ìmọ̀ràn tí àwọn àgbàgbà fún un, ó sì fi ọ̀rọ̀ náà lọ àwọn ọmọdé tí wọ́n dàgbà pẹ̀lú rẹ̀, tí wọ́n sì ń sìn ín.
9 ularƣa: — Manga «Silining atiliri bizgǝ salƣan boyunturuⱪni yeniklǝtkǝyla» dǝp tiligǝn bu hǝlⱪⱪǝ jawab beriximiz toƣruluⱪ ⱪandaⱪ mǝsliⱨǝt berisilǝr? — dedi.
Ó sì bi wọ́n pé, “Kí ni ìmọ̀ràn yín? Báwo ni a ó ṣe dá àwọn ènìyàn yí lóhùn, tí wọ́n wí fún mi pé, ‘Ṣé kí àjàgà tí baba rẹ fi sí wa lọ́rùn kí ó fúyẹ́ díẹ̀’?”
10 Uning bilǝn qong bolƣan bu yaxlar uningƣa: — «Silining atiliri boyunturuⱪimizni eƣir ⱪildi, ǝmdi sili uni bizgǝ yenik ⱪilƣayla» dǝp eytⱪan bu hǝlⱪⱪǝ sɵz ⱪilip: — «Mening qimqilaⱪ barmiⱪim atamning belidin tomraⱪtur.
Àwọn ọmọdé tí ó dàgbà pẹ̀lú rẹ̀ dá a lóhùn pé, “Sọ fún àwọn ènìyàn tí wọ́n wí fún ọ pé, ‘Baba rẹ̀ mú kí àjàgà wa wúwo ṣùgbọ́n ìwọ mú kí ó fúyẹ́ díẹ̀ fún wa’; sọ fún wọn pé, ìka ọwọ́ mi kékeré nípọn ju ẹ̀gbẹ́ baba mi lọ.
11 Atam silǝrgǝ eƣir boyunturuⱪni salƣan, lekin mǝn boyunturuⱪunglarni tehimu eƣir ⱪilimǝn. Atam silǝrgǝ ⱪamqilar bilǝn tǝnbiⱨ-tǝrbiyǝ bǝrgǝn bolsa, mǝn silǝrgǝ «qayanliⱪ ⱪamqilar» bilǝn tǝnbiⱨ berimǝn», degǝyla, — dedi.
Baba mi ti gbé àjàgà wúwo lé e yín; Èmi yóò sì fi kún àjàgà yín. Baba mi ti fi pàṣán nà yín, Èmi yóò fi àkéekèe nà yín.”
12 Rǝⱨoboam padixaⱨ ularƣa: «Üq kündin keyin andin ⱪeximƣa yǝnǝ kelinglar» deginidǝk, Yǝroboam wǝ barliⱪ hǝlⱪ üqinqi küni uning ⱪexiƣa kǝldi.
Jeroboamu àti gbogbo àwọn ènìyàn náà wá sọ́dọ̀ Rehoboamu ní ọjọ́ kẹta, gẹ́gẹ́ bí ọba ti wí pé, “Ẹ padà tọ̀ mí wá ní ọjọ́ kẹta.”
13 Padixaⱨ moysipitlarning uningƣa bǝrgǝn mǝsliⱨǝtini taxlap, hǝlⱪⱪǝ ⱪattiⱪliⱪ bilǝn jawab bǝrdi.
Ọba sì fi ohùn líle dá àwọn ènìyàn lóhùn, ó sì kọ ìmọ̀ràn tí àwọn àgbàgbà fún un,
14 U yaxlarning mǝsliⱨǝti boyiqǝ ularƣa: — Atam silǝrgǝ eƣir boyunturuⱪni salƣan, lekin mǝn boyunturuⱪunglarni tehimu eƣir ⱪilimǝn. Atam silǝrgǝ ⱪamqilar bilǝn tǝnbiⱨ-tǝrbiyǝ bǝrgǝn bolsa mǝn silǝrgǝ «qayanliⱪ ⱪamqilar» bilǝn tǝnbiⱨ-tǝrbiyǝ berimǝn, dedi.
Ó sì tẹ̀lé ìmọ̀ràn àwọn ọmọdé, ó sì wí pé, “Baba mí sọ àjàgà yín di wúwo, èmi yóò sì jẹ́ kí ó wúwo sí i, baba mi fi pàṣán nà yín èmi yóò fi àkéekèe nà yín.”
15 Xuning bilǝn padixaⱨ hǝlⱪning sɵzini anglimidi. Bu ix Pǝrwǝrdigar tǝripidin bolƣan; qünki buning bilǝn Pǝrwǝrdigarning Xiloⱨluⱪ Ahiyaⱨning wasitisidǝ Nibatning oƣli Yǝroboamƣa eytⱪan sɵzi ǝmǝlgǝ axurulidiƣan boldi.
Bẹ́ẹ̀ ni ọba kò sì fi etí sí ti àwọn ènìyàn, nítorí tí ọ̀ràn náà ti ọwọ́ Olúwa wá láti mú ọ̀rọ̀ tí ó sọ fún Jeroboamu ọmọ Nebati láti ẹnu Ahijah ará Ṣilo ṣẹ.
16 Pütkül Israil padixaⱨning ularning sɵzigǝ ⱪulaⱪ salmiƣinini kɵrgǝndǝ hǝlⱪ padixaⱨⱪa jawab berip: — Dawuttin bizgǝ nemǝ nesiwǝ bar? Yǝssǝning oƣlida bizning ⱨeq mirasimiz yoⱪtur! Ɵz ɵy-qedirliringlarƣa ⱪaytinglar, i Israil! I Dawut, sǝn ɵz jǝmǝtinggila igǝ bol, — dedi. Xuning bilǝn Israillar ɵz ɵy-qedirliriƣa ⱪaytip ketixti.
Nígbà tí gbogbo Israẹli rí i pé ọba kọ̀ láti gbọ́ ti àwọn, wọ́n sì dá ọba lóhùn pé, “Ìpín wo ni àwa ní nínú Dafidi, ìní wo ni àwa ní nínú ọmọ Jese? Padà sí àgọ́ rẹ, ìwọ Israẹli! Bojútó ilé ara rẹ, ìwọ Dafidi!” Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ará Israẹli padà sí ilé wọn.
17 Əmma Yǝⱨuda xǝⱨǝrliridǝ olturƣan Israillarƣa bolsa, Yǝroboam ularning üstigǝ ⱨɵküm sürdi.
Ṣùgbọ́n fún ti àwọn ọmọ Israẹli tí ń gbé nínú ìlú Juda, Rehoboamu jẹ ọba lórí wọn síbẹ̀.
18 Rǝⱨoboam padixaⱨ baj-alwan begi Adoramni Israillarƣa ǝwǝtti, lekin pütkül Israil uni qalma-kesǝk ⱪilip ɵltürdi. U qaƣda Rǝⱨoboam padixaⱨ aldirap, ɵzining jǝng ⱨarwisiƣa qiⱪip, Yerusalemƣa tikiwǝtti.
Ọba Rehoboamu rán Adoniramu jáde, ẹni tí ó wà ní ìkáwọ́ iṣẹ́ onírúurú, ṣùgbọ́n gbogbo Israẹli sọ ọ́ ní òkúta pa. Ọba Rehoboamu, gbìyànjú láti dé inú kẹ̀kẹ́ rẹ̀ ó sì sálọ sí Jerusalẹmu.
19 Xu tǝriⱪidǝ Israil Dawutning jǝmǝtidin yüz ɵrüp, bügüngǝ ⱪǝdǝr uningƣa ⱪarxi qiⱪip kǝldi.
Bẹ́ẹ̀ ni Israẹli ṣọ̀tẹ̀ sí ilé Dafidi títí di òní yìí.
20 Israilning ⱨǝmmisi Yǝroboamning yenip kǝlgǝnlikini angliƣanda, adǝm ǝwǝtip uni hǝlⱪning jamaitigǝ qaⱪirdi. Ular uni pütkül Israilning üstigǝ rǝsmiy padixaⱨ ⱪildi. Yǝⱨuda ⱪǝbilisidin baxⱪa ⱨeqkim Dawutning jǝmǝtigǝ ǝgǝxmidi.
Nígbà tí gbogbo Israẹli sì gbọ́ pé Jeroboamu ti padà dé, wọ́n ránṣẹ́, wọ́n sì pè é wá sí àjọ, wọ́n sì fi jẹ ọba lórí gbogbo Israẹli. Kò sí ẹnìkan tí ó tọ ilé Dafidi lẹ́yìn bí kò ṣe kìkì ẹ̀yà Juda nìkan.
21 Rǝⱨoboam Yerusalemƣa ⱪaytip kelip, Israilning jǝmǝti bilǝn jǝng ⱪilip, padixaⱨliⱪni Sulaymanning oƣli bolƣan ɵzigǝ ⱪayturup ǝkilix üqün Yǝⱨudaning pütkül jǝmǝtidin wǝ Binyamin ⱪǝbilisidin bir yüz sǝksǝn ming hillanƣan jǝnggiwar ǝskǝrni toplidi.
Nígbà tí Rehoboamu sì dé sí Jerusalẹmu, ó kó gbogbo ilé Juda jọ, àti ẹ̀yà Benjamini; ọ̀kẹ́ mẹ́sàn-án ènìyàn tí a yàn, tí wọ́n ń ṣe ológun, láti bá ilé Israẹli jà àti láti mú ìjọba náà padà bọ̀ sọ́dọ̀ Rehoboamu, ọmọ Solomoni.
22 Lekin Hudaning sɵzi Hudaning adimi Xemayaƣa kelip: —
Ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ Ọlọ́run tọ Ṣemaiah ènìyàn Ọlọ́run wá wí pé,
23 «Yǝⱨudaning padixaⱨi, Sulaymanning oƣli Rǝⱨoboamƣa, pütün Yǝⱨuda bilǝn Binyaminning jǝmǝtigǝ wǝ hǝlⱪning ⱪalƣanliriƣa sɵz ⱪilip: —
“Sọ fún Rehoboamu, ọmọ Solomoni, ọba Juda àti fún gbogbo ilé Juda àti ti Benjamini, àti fún àwọn ènìyàn tókù wí pé,
24 «Pǝrwǝrdigar mundaⱪ dǝydu: — Ⱨujumƣa qiⱪmanglar, ⱪerindaxliringlar Israillar bilǝn jǝng ⱪilmanglar; ⱨǝrbiringlar ɵz ɵyünglarƣa ⱪaytip ketinglar; qünki bu ix Mǝndindur», degin» — deyildi. Ular Pǝrwǝrdigarning sɵzigǝ ⱪulaⱪ saldi. Pǝrwǝrdigarning sɵzi boyiqǝ ular ɵylirigǝ ⱪaytip kǝtti.
‘Báyìí ni Olúwa wí, “Ẹ má ṣe gòkè lọ láti bá àwọn arákùnrin yín jà, àwọn ènìyàn Israẹli. Kì olúkúlùkù yín padà sí ilé rẹ̀, nítorí nǹkan yìí láti ọ̀dọ̀ mi wá ni.”’” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa, wọ́n sì tún padà sí ilé wọn, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa.
25 Yǝroboam bolsa Əfraim taƣliⱪidiki Xǝⱪǝm xǝⱨirini yasap xu yǝrdǝ turdi; keyin u yǝrdin qiⱪip Pǝnuǝlni yasidi.
Nígbà náà ni Jeroboamu kọ́ Ṣekemu ní òkè Efraimu, ó sì ń gbé inú rẹ̀. Láti ibẹ̀ ó sì jáde lọ, ó sì kọ́ Penieli.
26 Rǝⱨoboam kɵnglidǝ ɵz-ɵzigǝ: — Əmdi padixaⱨliⱪ Dawutning jǝmǝtigǝ yenixi mumkin.
Jeroboamu rò nínú ara rẹ̀ pé, “Ìjọba náà yóò padà nísinsin yìí sí ilé Dafidi.
27 Əgǝr bu hǝlⱪ Pǝrwǝrdigarning ɵyidǝ ⱪurbanliⱪ ⱪilixⱪa Yerusalemƣa qiⱪsa, bu hǝlⱪning ⱪǝlbi ɵz ƣojisi, yǝni Yǝⱨuda padixaⱨi Rǝⱨoboamƣa yǝnǝ mayil bolidu, andin ular meni ɵltürüp yǝnǝ Yǝⱨuda padixaⱨi Rǝⱨoboamning tǝripigǝ yanarmikin, dedi.
Bí àwọn ènìyàn wọ̀nyí bá gòkè lọ láti ṣe ìrúbọ ní ilé Olúwa ní Jerusalẹmu, wọn yóò tún fi ọkàn wọn fún Olúwa wọn, Rehoboamu ọba Juda. Wọn yóò sì pa mí, wọn yóò sì tún padà tọ Rehoboamu ọba Juda lọ.”
28 Padixaⱨ mǝsliⱨǝt sorap, altundin ikki mozay ⱨǝykilini yasitip hǝlⱪⱪǝ: — Yerusalemƣa qiⱪix silǝrgǝ eƣir kelidu. I Israil, mana silǝrni Misir zeminidin qiⱪarƣan ilaⱨlar! — dedi.
Lẹ́yìn tí ó ti gba ìmọ̀ràn, ọba sì yá ẹgbọrọ màlúù wúrà méjì. Ó sì wí fún àwọn ènìyàn pé, “Ó ti pọ̀jù fún yín láti máa gòkè lọ sí Jerusalẹmu. Àwọn Ọlọ́run yín nìyìí, Israẹli, tí ó mú yín láti ilẹ̀ Ejibiti wá.”
29 Birini u Bǝyt-Əldǝ, yǝnǝ birini Danda turƣuzup ⱪoydi.
Ó sì gbé ọ̀kan kalẹ̀ ní Beteli, àti èkejì ní Dani.
30 Bu ix gunaⱨⱪa sǝwǝb boldi, qünki hǝlⱪ mozaylirining birining aldida bax urƣili ⱨǝtta Danƣiqǝ baratti.
Nǹkan yìí sì di ẹ̀ṣẹ̀; àwọn ènìyàn sì lọ títí dé Dani láti sin èyí tí ó wà níbẹ̀.
31 U ⱨǝm «egiz jaylar»da [ibadǝt] ɵylirini yasidi wǝ ⱨǝm Lawiydin bolmiƣan adǝmlǝrni kaⱨin ⱪilip tǝyinlǝp ⱪoydi.
Jeroboamu sì kọ́ ojúbọ sórí ibi gíga, ó sì yan àwọn àlùfáà láti inú àwọn ènìyàn bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé wọn kì í ṣe inú àwọn ọmọ Lefi.
32 Yǝroboam yǝnǝ sǝkkizinqi ayning on bǝxinqi künini huddi Yǝⱨudaning zeminidiki ⱨeytkǝ ohxax bir ⱨeyt ⱪilip bekitti. U ɵzi ⱪurbangaⱨ üstigǝ ⱪurbanliⱪ ⱪilƣili qiⱪti. Xundaⱪ ⱪilip u Bǝyt-Əldǝ ɵzi ǝtküzgǝn mozay mǝbudlirigǝ ⱪurbanliⱪ ɵtküzdi. U yǝnǝ Bǝyt-Əldǝ saldurƣan xu «egiz jaylar» üqün kaⱨinlarni tǝyinlidi.
Jeroboamu sì dá àsè sílẹ̀ ní ọjọ́ kẹ́ẹ̀dógún oṣù kẹjọ gẹ́gẹ́ bí àsè tí ó wà ní Juda, ó sì rú ẹbọ lórí pẹpẹ. Ó ṣe èyí ní Beteli, ó rú ẹbọ sí àwọn ọmọ màlúù tí ó ṣe. Ó sì fi àwọn àlùfáà sí ibi gíga tí ó ti ṣe sí Beteli.
33 U Bǝyt-Əldǝ yasiƣan ⱪurbangaⱨ üstigǝ sǝkkizinqi ayning on bǝxinqi küni (bu ay-künni u ɵz mǝyliqǝ talliƣanidi) ⱪurbanliⱪlarni sunuxⱪa qiⱪti; xu tǝriⱪidǝ u Israillarƣa bir ⱨeyt yaratti; u ɵzi ⱪurbangaⱨ üstigǝ ⱪurbanliⱪlarni sundi wǝ huxbuy yaⱪti.
Ní ọjọ́ kẹ́ẹ̀dógún oṣù kẹjọ, oṣù tí ó rò ní ọkàn ara rẹ̀, ó sì rú ẹbọ lórí pẹpẹ tí ó kọ́ ní Beteli. Bẹ́ẹ̀ ni ó sì dá àsè sílẹ̀ fún àwọn ọmọ Israẹli, ó sì gun orí pẹpẹ náà lọ láti rú ẹbọ.