< Tarih-tǝzkirǝ 1 23 >

1 Dawut ⱪerip künliri toxay dǝp ⱪalƣanda, oƣli Sulaymanni Israil üstigǝ padixaⱨ ⱪilip tiklidi.
Nígbà tí Dafidi sì dàgbà, tí ó sì di arúgbó, ó sì fi Solomoni ọmọ rẹ̀ jẹ ọba lórí Israẹli.
2 Dawut Israildiki ǝmǝldarlarni, kaⱨinlarni wǝ Lawiylarni yiƣdi.
Ó sì kó gbogbo àgbàgbà Israẹli jọ, àti gẹ́gẹ́ bí àwọn àlùfáà àti àwọn ará Lefi.
3 Lawiylardin ottuz yaxtin axⱪanlarning ⱨǝmmisi sanaⱪtin ɵtküzüldi; tizimlanƣini boyiqǝ, ulardin ǝrlǝr jǝmiy ottuz sǝkkiz ming kixi idi.
Àwọn ọmọ Lefi láti ọgbọ̀n ọdún tàbí jù bẹ́ẹ̀ lọ ni wọ́n kà àpapọ̀ iye àwọn ọkùnrin wọn sì jẹ́ ẹgbàá mọ́kàndínlógún.
4 Dawut: «Bularning iqidǝ yigirmǝ tɵt ming kixi Pǝrwǝrdigarning ɵyini baxⱪurux hizmitigǝ, altǝ ming kixi ǝmǝldar wǝ sotqiliⱪⱪa,
Dafidi sì wí pe, ní ti èyí, ẹgbàá méjìlá ni kí wọn jẹ́ alábojútó iṣẹ́ ilé fún Olúwa àti ẹgbẹ̀rún mẹ́fà ni kí ó ṣe olórí àti onídàájọ́.
5 tɵt ming kixi dǝrwaziwǝnlikkǝ wǝ yǝnǝ tɵt ming kixi mǝn yasiƣan sazlar bilǝn Pǝrwǝrdigarƣa ⱨǝmdusana oⱪux ixiƣa ⱪoyulsun» — dedi.
Ẹgbàajì ni kí ó jẹ́ olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà àti ẹgbàajì ni kí o sì jẹ́ ẹni ti yóò máa yin Olúwa pẹ̀lú ohun èlò orin, mo ti ṣe èyí fún ìdí pàtàkì yìí.
6 Dawut ularni Lawiyning oƣli Gǝrxon, Koⱨat wǝ Mǝrari jǝmǝtliri boyiqǝ guruppilarƣa bɵldi: —
Dafidi sì pín àwọn ọmọ Lefi sí ẹgbẹgbẹ́ láàrín àwọn ọmọ Lefi: Gerṣoni, Kohati àti Merari.
7 Gǝrxoniylardin Ladan bilǝn Ximǝy bar idi;
Àwọn tí ó jẹ́ ọmọ Gerṣoni: Laadani àti Ṣimei.
8 Ladanning oƣli: tunji oƣli Yǝⱨiyǝl, yǝnǝ Zitam bilǝn Yoeldin ibarǝt üq kixi idi;
Àwọn ọmọ Laadani Jehieli ẹni àkọ́kọ́, Setamu àti Joẹli, mẹ́ta ní gbogbo wọn.
9 Ximǝyning oƣlidin Xelomit, Ⱨaziyǝl wǝ Ⱨarandin ibarǝt üq kixi idi; yuⱪiriⱪilar Ladanning jǝmǝt baxliⱪliri idi.
Àwọn ọmọ Ṣimei: Ṣelomiti, Hasieli àti Harani mẹ́ta ní gbogbo wọn. Àwọn wọ̀nyí sì ni olórí àwọn ìdílé Laadani.
10 Ximǝyning oƣulliri Jaⱨat, Zina, Yǝux wǝ Beriyaⱨ, bu tɵtǝylǝnning ⱨǝmmisi Ximǝyning oƣli idi.
Àti ọmọ Ṣimei: Jahati, Sina, Jeuṣi àti Beriah. Àwọn wọ̀nyí ni ọmọ Ṣimei mẹ́rin ni gbogbo wọn.
11 Jaⱨat tunji oƣul, Ziza ikkinqi oƣul idi; Yǝux bilǝn Beriyaⱨning ǝwladliri kɵp bolmiƣaqⱪa, bir [jǝmǝt guruppisi] dǝp ⱨesablanƣan.
Jahati sì ni alákọ́kọ́ Sinah sì ni ẹlẹ́ẹ̀kejì, ṣùgbọ́n Jeuṣi àti Beriah kò ní àwọn ọmọ púpọ̀; bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì ka ara wọn sí ìdílé kan pẹ̀lú ìfilé lọ́wọ́ kan.
12 Koⱨatning oƣulliri Amram, Izⱨar, Ⱨebron wǝ Uzziyǝldin ibarǝt tɵt kixi idi.
Àwọn ọmọ Kohati: Amramu, Isari, Hebroni àti Usieli mẹ́rin ni gbogbo wọn.
13 Amramning oƣli Ⱨarun bilǝn Musa idi. Ⱨarun bilǝn uning ǝwladliri ǝng muⱪǝddǝs buyumlarni paklax, Pǝrwǝrdigarning aldida mǝnggügǝ [ⱪurbanliⱪlarni] sunux, uning hizmitini ⱪilix, mǝnggü uning namidin bǝht tilǝp dua berixkǝ ayrilƣanidi.
Àwọn ọmọ Amramu. Aaroni àti Mose. A sì ya Aaroni sọ́tọ̀ òun àti àwọn ọmọ rẹ̀ títí láéláé, láti kọjú sí ohun mímọ́ jùlọ, láti fi rú ẹbọ sísun níwájú Olúwa, láti máa ṣe òjíṣẹ́ níwájú rẹ̀ àti láti kéde ìbùkún ní orúkọ rẹ̀ títí láéláé.
14 Hudaning adimi Musaƣa kǝlsǝk, uning ǝwladliri Lawiy ⱪǝbilisidin dǝp ⱨesablinip pütülgǝn.
Àwọn ọmọ Mose ènìyàn Ọlọ́run ni wọ́n kà gẹ́gẹ́ bí apá kan ẹ̀yà Lefi.
15 Musaning oƣli Gǝrxom bilǝn Əliezǝr idi.
Àwọn ọmọ Mose: Gerṣomu àti Elieseri.
16 Gǝrxomning oƣulliridin Xǝbuyǝl qong oƣli idi.
Àwọn ọmọ Gerṣomu: Ṣubaeli sì ni alákọ́kọ́.
17 Əliezǝrning oƣli Rǝⱨabiya idi; Əliezǝrning baxⱪa oƣli bolmiƣan, lekin Rǝⱨabiyaning oƣulliri naⱨayiti kɵp idi.
Àwọn ọmọ Elieseri: Rehabiah sì ni ẹni àkọ́kọ́. Elieseri kò sì tún ní ọmọ mìíràn, ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Rehabiah wọ́n sì pọ̀ níye.
18 Izⱨarning tunji oƣli Xelomit idi.
Àwọn ọmọ Isari: Ṣelomiti sì ni ẹni àkọ́kọ́.
19 Ⱨebronning oƣulliri: tunji oƣli Yeriya, ikkinqi oƣli Amariya, üqinqi oƣli Yaⱨaziyǝl, tɵtinqi oƣli Jǝkamiyam idi.
Àwọn ọmọ Hebroni: Jeriah sì ni ẹni àkọ́kọ́, Amariah sì ni ẹni ẹ̀ẹ̀kejì, Jahasieli sì ni ẹ̀ẹ̀kẹ́ta àti Jekameamu ẹ̀ẹ̀kẹrin.
20 Uzziyǝlning oƣulliri: tunji oƣli Mikaⱨ, ikkinqi oƣli Yixiya idi.
Àwọn ọmọ Usieli: Mika ni àkọ́kọ́ àti Iṣiah ẹ̀ẹ̀kejì.
21 Mǝrarining oƣli Maⱨli bilǝn Muxi idi; Maⱨlining oƣli Əliazar bilǝn Kix idi.
Àwọn ọmọ Merari: Mahili àti Muṣi. Àwọn ọmọ Mahili: Eleasari àti Kiṣi.
22 Əliazar ɵlgǝndǝ oƣli yoⱪ, ⱪizlirila bar idi; ularning tuƣⱪanliri, yǝni Kixning oƣulliri u ⱪizlarni ǝmrigǝ aldi.
Eleasari sì kú pẹ̀lú àìní àwọn ọmọkùnrin: Ó ní ọmọbìnrin nìkan. Àwọn ọmọ ẹ̀gbọ́n, àwọn ọmọ Kiṣi, sì fẹ́ wọn.
23 Muxining Maⱨli, Edǝr wǝ Yǝrǝmot degǝn üqla oƣli bar idi.
Àwọn ọmọ Muṣi: Mahili, Ederi àti Jerimoti mẹ́ta ni gbogbo wọn.
24 Yuⱪiriⱪilarning ⱨǝmmisi Lawiyning ǝwladliri bolup, jǝmǝtliri boyiqǝ, yǝni jǝmǝt baxliri boyiqǝ yigirmǝ yaxtin axⱪan ǝrkǝklǝr royhǝtkǝ elinƣan; ular Pǝrwǝrdigarning ɵyidiki wǝzipilǝrni ɵtǝxkǝ ismiliri boyiqǝ tizimlanƣanidi.
Àwọn wọ̀nyí sì ni ọmọ Lefi bí ìdílé wọn. Olórí ìdílé gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti fi orúkọ sílẹ̀ lábẹ́ orúkọ wọn, ó sì kà wọn ní ẹyọ kọ̀ọ̀kan, wí pé, àwọn òṣìṣẹ́ tí ó jẹ́ ogún ọdún tàbí jù bẹ́ẹ̀ lọ tí ń ṣiṣẹ́ ìsìn nínú ilé Olúwa.
25 Qünki Dawut: «Israilning Hudasi Pǝrwǝrdigar Ɵz hǝlⱪigǝ aram berip, Ɵzi mǝnggü Yerusalemda makan ⱪilidu;
Nítorí pé Dafidi ti sọ pé, “Níwọ̀n ìgbà tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli, ti fi ìsinmi fún àwọn ènìyàn tí ó kù tí sì ń gbé Jerusalẹmu títí láéláé,
26 xuning bilǝn Lawiylarning muⱪǝddǝs qedirni wǝ uning iqidiki ⱨǝrⱪaysi ⱪaqa-ǝswablarni kɵtürüp yürüxning ⱨajiti yoⱪ» degǝnidi.
àwọn ọmọ Lefi kò sì tún ru àgọ́ tàbí ọ̀kankan lára àwọn ohun èlò tí wọ́n ń lò níbi ìsìn rẹ̀.”
27 Xunga Dawutning jan üzüx aldidiki wǝsiyiti boyiqǝ, Lawiylarning yigirmǝ yaxtin yuⱪirilirining ⱨǝmmisi sanaⱪtin ɵtküzülgǝnidi.
Gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ ìkẹyìn Dafidi sí, àwọn ọmọ Lefi, wọ́n sì kà wọ́n, bẹ̀rẹ̀ láti orí àwọn ọmọ ogún ọdún tàbí jù bẹ́ẹ̀ lọ.
28 Ularning wǝzipisi bolsa Ⱨarunning ǝwladlirining yenida turup, Pǝrwǝrdigarning ɵyining ixlirini ⱪilix idi; ular ⱨoyla-aramlarni baxⱪurux, barliⱪ muⱪǝddǝs buyumlarni pakiz tutux, ⱪisⱪisi, Pǝrwǝrdigarning ɵyining hizmǝt wǝzipilirini bejirixkǝ mǝs’ul idi;
Iṣẹ́ àwọn ọmọ Lefi ni láti ran àwọn ọmọ Aaroni lọ́wọ́ nínú iṣẹ́ wọn fún ti ilé Olúwa: láti wà lábẹ́ ìkáwọ́ agbára ìlú, àti ẹ̀gbẹ́ ilé, àti ìwẹ̀nùmọ́ ti gbogbo ohun ìyàsọ́tọ̀ àti ṣíṣe ohun tí í ṣe iṣẹ́ ìsìn nínú ilé Olúwa.
29 yǝnǝ «tizilƣan tǝⱪdim nan», ax ⱨǝdiyǝ unliri, petir ⱪoturmaqlar, ⱪazan nanliri wǝ mayliⱪ nanlarƣa, xundaⱪla ⱨǝrhil ɵlqǝx ǝswabliriƣa mǝs’ul idi;
Wọ́n sì wà ní ìkáwọ́ àkàrà tí wọ́n mú jáde láti orí tábìlì, àti ìyẹ̀fun fún ẹbọ, àti àkàrà aláìwú, àti fún púpọ̀ àti èyí tí a pòpọ̀, àti gbogbo onírúurú ìwọ̀n àti wíwọ̀n àti òsùwọ̀n.
30 ular yǝnǝ ⱨǝrküni ǝtigǝndǝ ɵrǝ turup Pǝrwǝrdigarƣa tǝxǝkkür eytip ⱨǝmdusana oⱪuytti, ⱨǝrküni kǝqlikimu xundaⱪ ⱪilatti.
Wọ́n sì gbọdọ̀ dúró ní gbogbo òwúrọ̀ láti dúpẹ́ àti láti yin Olúwa. Wọ́n sì gbọdọ̀ ṣe irú kan náà ní àṣálẹ́.
31 Yǝnǝ xabat küni, ⱨǝr yengi ayda, xuningdǝk bekitilgǝn ⱨeyt-bayramlarda sunulidiƣan barliⱪ kɵydürmǝ ⱪurbanliⱪlarƣa mǝs’ul idi. Ɵzlirigǝ ⱪaritilƣan bǝlgilimǝ boyiqǝ, ular daim Pǝrwǝrdigarning aldiƣa bekitiligǝn sani wǝ nɵwiti bilǝn hizmǝttǝ turatti.
Àti láti rú ẹbọ sísun fún Olúwa ní ọjọ́ ìsinmi àti ní àsìkò oṣù tuntun àti ní àjọ̀dún tí a yàn. Wọ́n gbọdọ̀ sìn níwájú Olúwa lójoojúmọ́ ní iye tó yẹ àti ní ọ̀nà tí a ti pàṣẹ fún wọn.
32 Ular jamaǝt qedirini ⱨǝm muⱪǝddǝs jayni baⱪatti, xundaⱪla ɵzlirining Pǝrwǝrdigarning ɵyidiki hizmǝttǝ boluwatⱪan ⱪerindaxliri, yǝni Ⱨarunning ǝwladliriƣa ⱪaraytti.
Bẹ́ẹ̀ ni nígbà náà, àwọn ọmọ Lefi gbé ìgbékalẹ̀ jáde fún ìpàdé àgọ́, fún Ibi Mímọ́ àti, lábẹ́ àwọn arákùnrin àwọn ọmọ Aaroni fún ìsìn ilé Olúwa.

< Tarih-tǝzkirǝ 1 23 >