< Batur Hakimlar 6 >

1 Israillar Perwerdigarning neziride rezil bolghanni qildi; shuning bilen Perwerdigar ularni yette yilghiche Midiyaniylarning qoligha tapshurup berdi.
Àwọn ọmọ Israẹli sì túnṣe ohun tí ó burú ní ojú Olúwa, Ó sì fi wọ́n lé àwọn ará Midiani lọ́wọ́ fún ọdún méje.
2 U waqitta Midiyaniylar Israilning üstidin ghalib kélip, Israil Midiyaniylarning sewebidin özliri üchün taghlardin, öngkürlerdin we qoram tashlardin panah jaylarni yasidi.
Agbára àwọn ará Midiani sì pọ̀ púpọ̀ lórí àwọn Israẹli, wọ́n sì hùwà ipá sí wọn, nítorí ìdí èyí, àwọn Israẹli sálọ sí àwọn orí òkè, wọ́n sì kọ́ àgọ́ fún ara wọn nínú ihò àpáta, àti nínú ọ̀gbun àti ní ibi agbára nínú àpáta.
3 Her qétim Israillar uruq térighanda shundaq bolattiki, Midiyaniylar, Amalekiyler we meshriqtikiler kélip ulargha hujum qilatti.
Ní ìgbàkúgbà tí àwọn ọmọ Israẹli bá ti gbin ọ̀gbìn wọn, àwọn ará Midiani, àwọn ará Amaleki àti àwọn ará ìlà-oòrùn mìíràn yóò wá láti bá wọn jà.
4 Ulargha hujum qilishqa bargahlarni tikip, zémindiki hosulni weyran qilip, Gazaghiche Israilgha héchqandaq ashliq qaldurmay, ularning qoy, kala, ésheklirinimu élip kétetti.
Wọn yóò tẹ̀dó sí orí ilẹ̀ náà, wọn a sì bá irúgbìn wọ̀nyí jẹ́ títí dé Gasa, wọn kì í sì í fi ohun alààyè kankan sílẹ̀ fún àwọn ọmọ Israẹli, kì bá à ṣe àgùntàn, màlúù tàbí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́.
5 Chünki ular chéketkilerdek köp bolup, öz mal-charwiliri we chédirlirini élip kéletti; ularning ademliri we tögiliri san-sanaqsiz bolup, zéminni weyran qilish üchün tajawuz qilatti.
Wọn a máa wá pẹ̀lú ohun ọ̀sìn wọn àti àwọn àgọ́ wọn, wọn a sì dàbí eṣú nítorí i púpọ̀ wọn. Ènìyàn kò sì lè ka iye àwọn ènìyàn náà bẹ́ẹ̀ ni àwọn ìbákasẹ, wọ́n pọ̀ dé bi pé wọn kò ṣe é kà ní iye, wọn a bo ilẹ̀ náà wọn a sì jẹ ẹ́ run.
6 Shuning bilen Israil Midiyaniylarning aldida tolimu xar haletke chüshüp qaldi; andin Israillar Perwerdigargha nale-peryad kötürdi.
Àwọn ará Midiani sì pọ́n àwọn ọmọ Israẹli lójú, wọ́n sọ wọ́n di òtòṣì àti aláìní, fún ìdí èyí wọ́n ké pe Olúwa nínú àdúrà fún ìrànlọ́wọ́.
7 Midiyaniylarning destidin Israil Perwerdigargha peryad kötürginide shundaq boldiki,
Nígbà tí àwọn ọmọ Israẹli ké pe Olúwa nítorí àwọn ará Midiani.
8 Perwerdigar Israilgha bir peyghemberni ewetti. U kélip ulargha: — Israilning Xudasi Perwerdigar mundaq deydu: «Men silerni Misirdin chiqirip, «qulluq makani»din élip chiqqanidim;
Olúwa fi etí sí igbe wọn, ó sì rán wòlíì kan sí wọn, ẹni tí ó wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí: mo mú yín gòkè ti Ejibiti wá, láti oko ẹrú.
9 silerni misirliqlarning qolidin, shundaqla silerge barliq zulum qilghuchilarning qolidin qutquzup, ularni aldinglardin qoghliwétip, ularning zéminini silerge berdim
Mo gbà yín kúrò nínú agbára Ejibiti àti kúrò ní ọwọ́ gbogbo àwọn aninilára yín. Mo lé wọn kúrò ní iwájú yín, mo sì fi ilẹ̀ wọn fún yín.
10 we silerge: «Mana, Men Perwerdigar silerning Xudayinglardurmen; siler Amoriylarning zéminida turghininglar bilen ularning ilahliridin qorqmanglar» dégenidim. Lékin siler Méning awazimgha qulaq salmidinglar», — dédi.
Mo wí fún un yín pé, ‘Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín; ẹ má ṣe sin àwọn òrìṣà àwọn ará Amori, ní ilẹ̀ ẹni tí ẹ̀yin ń gbé.’ Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò gbọ́rọ̀ sí ohun tí mo sọ.”
11 Andin Perwerdigarning Perishtisi kélip Ofrah dégen jayda Abiézer jemetidiki Yoashqa tewe bolghan dub derixining tüwide olturdi. U waqitta [Yoashning] oghli Gidéon Midiyaniylarning [bulangchiliqidin] saqlinish üchün sharab kölchiki ichide bughday tépiwatatti.
Ní ọjọ́ kan angẹli Olúwa wá, ó sì jókòó ní abẹ́ igi óákù Ofira èyí ti ṣe ti Joaṣi ará Abieseri, níbi tí Gideoni ọmọ rẹ̀ ti ń lu ọkà jéró, níbi ìpọntí wáìnì láti fi pamọ́ kúrò níwájú àwọn ará Midiani.
12 Perwerdigarning Perishtisi uninggha körünüp: — Ey jasaretlik palwan, Perwerdigar sen bilen billidur! — dédi.
Nígbà tí angẹli Olúwa fi ara han Gideoni, ó wí fún un pé, “Olúwa wà pẹ̀lú rẹ, akọni ológun.”
13 Gidéon uninggha jawab bérip: — I xojam, eger Perwerdigar biz bilen bille bolghan bolsa, bu körgülükler némishqa üstimizge keldi? Ata-bowilirimiz bizge sözlep bergen uning barliq möjiziliri qéni? Bular toghrisida ata-bowilirimiz: «Mana, Perwerdigar bizni Misirdin chiqirip kelmigenmidi?» — dédi. Lékin bügünki künde Perwerdigar bizni tashlap, Midiyanning qoligha tapshurup berdi! — dédi.
Gideoni dáhùn pé, “Alàgbà, bí Olúwa bá wà pẹ̀lú wa, kí ló dé tí gbogbo ìwọ̀nyí fi ń ṣẹlẹ̀ sí wa? Níbi gbogbo àwọn iṣẹ́ ìyanu rẹ tí àwọn baba wa ròyìn rẹ̀ fún wa nígbà tí wọ́n wí pé, ‘Olúwa kò ha mú wa gòkè láti ilẹ̀ Ejibiti wá?’ Ṣùgbọ́n nísinsin yìí Olúwa ti kọ̀ wá sílẹ̀, ó sì ti fi wá lé àwọn ará Midiani lọ́wọ́.”
14 Perwerdigar uninggha qarap: — Sen mushu küchüngge tayinip, bérip Israilni Midiyanning qolidin qutquzghin! Mana, Men séni ewetken emesmu? — dédi.
Olúwa sì yípadà sí i, ó sì wí fún un pé, “Lọ nínú agbára tí o ní yìí, kí o sì gba àwọn ará Israẹli sílẹ̀ kúrò lọ́wọ́ àwọn ará Midiani. Èmi ni ó ń rán ọ lọ.”
15 Gidéon Uninggha: — I Reb, men Israilni qandaq qutquzalaymen? Méning ailem bolsa Manasseh qebilisi ichide eng namriti, özüm atamning jemetide eng kichikidurmen, — dédi.
Gideoni sì dáhùn pé, “Yéè olúwa mi, ọ̀nà wo ni èmi yóò fi gba Israẹli là? Ìdílé mi ni ó jẹ́ aláìlera jù ní Manase, àti pé èmi ni ó sì kéré jù ní ìdílé baba mi.”
16 Perwerdigar uninggha: — Men jezmen sen bilen bille bolimen; shunga sen Midiyanlarni bir ademni urghandek urup qirisen, — dédi.
Olúwa sì dáhùn pé, “Èmi yóò wà pẹ̀lú rẹ, ìwọ yóò sì pa gbogbo àwọn ará Midiani láì ku ẹnìkankan.”
17 Gidéon Uninggha iltija qilip: — Men neziringde iltipat tapqan bolsam, men bilen sözleshküchining heqiqeten Sen Özüng ikenlikige bir alamet körsetkeysen;
Gideoni sì dáhùn pé, nísinsin yìí tí mo bá bá ojúrere rẹ pàdé, fún mi ní àmì pé ìwọ ni ń bá mi sọ̀rọ̀.
18 ötünimen, men yénip kélip öz hediye-qurbanliqimni aldinggha qoyghuche bu yerdin ketmigeysen, — dédi. U jawab bérip: — Sen yénip kelgüche kütimen, dédi.
Jọ̀wọ́ má ṣe kúrò níbí títí èmi yóò fi mú ọrẹ wá fún ọ kí n sì gbé e sí iwájú rẹ. Olúwa sì wí pé, “Èmi yóò dúró títí ìwọ yóò fi dé.”
19 Gidéon bérip [öyge] kirip bir oghlaqni teyyarlap, bir efah ésil undin pétir nan pishurup, göshni séwetke sélip, shorpisini korigha usup bularni uning qéshigha élip kélip, uninggha sundi (U téxiche dub derixining tüwide olturatti).
Gideoni sì yára wọ ilé lọ, ó sì pa ọ̀dọ́ ewúrẹ́ kan, wọ́n sì sè é, ó sì mú ìyẹ̀fun efa kan, ó fi ṣe àkàrà aláìwú. Ó gbé ẹran náà sínú agbọ̀n, ṣùgbọ́n ó fi ọbẹ̀ rẹ̀ sínú ìkòkò, ó gbé wọn jáde tọ angẹli náà wá bí ọrẹ lábẹ́ igi óákù.
20 Andin Xudaning Perishtisi uninggha: — Bu gösh bilen pétir nanlarni élip bérip, mushu yerdiki [qoram] tashning üstige qoyup, shorpini tökkin, — déwidi, u shundaq qildi.
Angẹli Ọlọ́run náà sì wí fún un pé, “Gbé ẹran náà àti àkàrà àìwú náà, sí orí àpáta yìí, kí o sì da omi ọbẹ̀ rẹ̀ sí orí rẹ̀.” Gideoni sì ṣe bẹ́ẹ̀.
21 Perwerdigarning Perishtisi qolidiki hasini uzitip uchini gösh bilen pétir nanlargha tekküziwidi, [qoram] tashtin ot chiqip, gösh bilen pétir nanlarni yep ketti. Shu haman Perwerdigarning Perishtisimu uning közidin ghayib boldi.
Angẹli Olúwa sì fi orí ọ̀pá tí ó wà ní ọwọ́ rẹ̀ kan ẹran àti àkàrà àìwú náà. Iná sì jáde láti inú àpáta, ó sì jó ẹran àti àkàrà náà, kò sì rí angẹli náà mọ́.
22 Shuning bilen Gidéon uning Perwerdigarning Perishtisi ikenlikini bilip: — Apla, i Reb Perwerdigar! Chataq boldi, chünki men Perwerdigarning Perishtisi bilen yüzmuyüz körüshüp qaldim...! — dédi.
Nígbà tí Gideoni sì ti mọ̀ dájúdájú pé angẹli Olúwa ni, ó ké wí pé, “Háà! Olúwa Olódùmarè! Mo ti rí angẹli Olúwa ní ojúkorojú!”
23 Lékin Perwerdigar uninggha: — Xatirjem bolghin! Qorqmighin, ölmeysen, — dédi.
Ṣùgbọ́n Olúwa wí fún un pé, “Àlàáfíà! Má ṣe bẹ̀rù, ìwọ kì yóò kùú.”
24 Shuning bilen Gidéon Perwerdigargha atap u yerde bir qurban’gah yasap, uning ismini «Yahweh-shalom» dep atidi. Bu qurban’gah ta bügün’giche Abiézer jemetining Ofrah dégen jayida bar.
Báyìí ni Gideoni mọ pẹpẹ kan fún Olúwa níbẹ̀, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní “Àlàáfíà ni Olúwa.” Ó sì wà ní Ofira ti Abieseri títí di òní.
25 U kéchisi Perwerdigar uninggha: — Sen atangning [chong] buqisi we yette yashliq ikkinchi buqisini élip atanggha tewe bolghan Baal qurban’gahini örüp, uning yénidiki Asherah butini késiwetkin.
Ní òru ọjọ́ náà Olúwa wí fún un pé, mú akọ màlúù baba rẹ, àní akọ màlúù kejì ọlọ́dún méje. Wó pẹpẹ Baali baba rẹ lulẹ̀, kí o sì bẹ́ igi ère òrìṣà Aṣerah tí ó wà ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀ lulẹ̀.
26 Andin mushu qorghanning üstige Perwerdigar Xudayinggha atalghan, belgilen’gen resim boyiche bir qurban’gah yasap, ikkinchi bir buqini élip, özüng késiwetken Asherahning parchilirini otun qilip qalap, uni köydürme qurbanliq qilghin, — dédi.
Lẹ́yìn èyí kí o wá mọ pẹpẹ èyí tí ó yẹ fún Olúwa Ọlọ́run rẹ lórí òkè yìí. Kí o sì mú akọ màlúù kejì, kí o sì mú igi ère òrìṣà Aṣerah tí ìwọ bẹ́ lulẹ̀ rú ẹbọ sísun sí Olúwa.
27 Shuning bilen Gidéon öz xizmetchiliridin on ademni élip bérip, Perwerdigarning özige éytqinidek qildi; lékin u atisining öyidikilerdin we sheher ademliridin qorqqini üchün, u bu ishni kündüzi qilmay, kéchisi qildi.
Gideoni mú mẹ́wàá nínú àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, ó sì ṣe bí Olúwa ti pàṣẹ fún un ṣùgbọ́n, nítorí ó bẹ̀rù àwọn ará ilé baba rẹ̀ àti àwọn ènìyàn ìlú náà kò ṣe é ní ọ̀sán, òru ni ó ṣe.
28 Etisi seherde sheher xelqi qopup qarisa, mana, Baal qurban’gahi örüwétilgen, uning yénidiki Asherah buti késiwétilgenidi we yéngi yasalghan qurban’gahning üstide ikkinchi buqa qurbanliq qilin’ghanidi.
Nígbà tí ilẹ̀ ọjọ́ kejì mọ́, tí àwọn ènìyàn ìlú náà jí, wọ́n rí i pé àti fọ́ pẹpẹ Baali àti pé a ti bẹ́ igi ère òrìṣà Aṣerah tí ó wà ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀, a sì ti fi akọ màlúù kejì rú ẹbọ lórí pẹpẹ tí a ṣẹ̀ṣẹ̀ mọ.
29 Buni körüp ular bir-birige: — Bu ishni kim qilghandu? — déyishti. Ular sürüshtüriwidi, buni Yoashning oghli Gidéonning qilghanliqi melum boldi.
Àwọn ènìyàn ìlú náà bi ara wọn wí pé, “Ta ni ó ṣe èyí?” Lẹ́yìn tí wọn fi ara balẹ̀ ṣe ìwádìí, wọ́n gbọ́ wí pé, “Gideoni ọmọ Joaṣi ni ó ṣe é.”
30 Shuning üchün sheherning ademliri Yoashqa: — Oghlungni chiqirip bergin! U Baal qurban’gahini örüp, uning yénidiki Asherahni késiwetkini üchün öltürülsun! — dédi.
Àwọn ọkùnrin ìlú náà sì wí fún Joaṣi wí pé, “Mú ọmọ rẹ jáde wá. Ó ní láti kú nítorí pé ó ti wó pẹpẹ Baali lulẹ̀ ó sì ti ké ère òrìṣà Aṣerah tí ó wà ní ẹ̀bá rẹ̀ lulẹ̀.”
31 Biraq Yoash özige qarshilishishqa turghan köpchilikke jawab bérip: — Siler Baal üchün dewalashmaqchimusiler? Siler uni qutquzmaqchimu? Kimki uning toghrisida dewalashsa etige qalmay ölümge mehkum qilinsun! Eger Baal derweqe bir xuda bolsa, undaqta uning qurban’gahini birsi örüwetkini üchün, u shu adem bilen özi dewalashsun! — dédi.
Ṣùgbọ́n Joaṣi bi àwọn èrò tí wọ́n fi ìbínú dúró tì í wí pé, “Ẹ̀yin yóò ha gbìjà Baali bí? Ẹ̀yin yóò ha gbà á sílẹ̀ bí? Ẹnikẹ́ni tí ó bá gbìjà rẹ̀ kíkú ni olúwa rẹ̀ yóò kú ní òwúrọ̀. Bí Baali bá ṣe Ọlọ́run nítòótọ́ yóò jà fún ara rẹ̀ bí ẹnikẹ́ni bá wó pẹpẹ rẹ̀ lulẹ̀.”
32 Bu sewebtin [atisi] Gidéonni «Yerubbaal» dep atidi, chünki [atisi]: «U Baalning qurban’gahini örüwetkini üchün, Baal özi uning bilen dewalashsun!» dégenidi.
Fún ìdí èyí ní ọjọ́ náà wọ́n pe Gideoni ní “Jerubbaali” wí pé, “Jẹ́ kí Baali bá a jà,” nítorí pé ó ti wó pẹpẹ Baali.
33 Emma Midiyan, Amalekler we meshriqtikilerning hemmisi yighilip, [Iordan] deryasidin ötüp Yizreel jilghisida chédirlirini tikishti.
Láìpẹ́ jọjọ, àwọn ogun àwọn Midiani, ti àwọn Amaleki àti ti àwọn ènìyàn ìhà ìlà-oòrùn yòókù kó ara wọn jọ pọ̀ ní ìṣọ̀kan, wọ́n sì kọjá Jordani wọ́n sì tẹ̀dó sí àfonífojì Jesreeli.
34 U waqitta Perwerdigarning Rohi Gidéonning üstige chüshti; u kanay chéliwidi, Abiézer jemetidikiler yighilip uning keynidin egiship mangdi.
Ẹ̀mí Olúwa sì bà lé Gideoni, ó sì fun fèrè ìpè, láti pe àwọn ará Abieseri láti tẹ̀lé òun.
35 Andin u elchilerni Manassehning zéminigha bérip, u yerni aylinip kélishke ewetiwidi, Manassehler yighilip uninggha egiship keldi. U Ashirlargha, Zebulunlargha we Naftalilargha elchi ewetiwidi, ularmu uning aldigha chiqishti.
Ó rán àwọn oníṣẹ́ la ilẹ̀ Manase já pé kí wọ́n dira ogun, àti sí Aṣeri, Sebuluni àti Naftali gbogbo pẹ̀lú sì lọ láti pàdé wọn.
36 Gidéon Xudagha: — Eger Sen heqiqeten éytqiningdek méning qolum bilen Israilni qutquzidighan bolsang,
Gideoni wí fún Ọlọ́run pé, “Bí ìwọ yóò bá gba Israẹli là nípasẹ̀ mi bí ìwọ ti ṣe ìlérí—
37 Undaqta mana, men xaman’gha bir parche qoy térisi qoyup qoyimen; eger peqet térining üstigila shebnem chüshüp, chörisidiki yerlerning hemmisi quruq tursa, men Özüng éytqiningdek méning qolum arqiliq Israilni qutquzmaqchi bolghiningni bilimen, — dédi.
kíyèsi, èmi yóò fi awọ irun àgùntàn lé ilẹ̀ ìpakà ní alẹ́ òní. Bí ìrì bá sẹ̀ sí orí awọ yìí nìkan tí gbogbo ilẹ̀ yòókù sì gbẹ, nígbà náà ni èmi yóò mọ̀ lóòótọ́ pé ìwọ yóò gba Israẹli là nípasẹ̀ mi bí ìwọ ti sọ.”
38 Ish derweqe shundaq boldi. Etisi seherde Gidéon qopup, yungni siqiwidi, liq bir piyale shebnem süyi chiqti.
Èyí ni ó sì ṣẹlẹ̀. Nígbà tí Gideoni jí ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ó sì fún irun àgùntàn náà, ọpọ́n omi kan sì kún.
39 Andin Gidéon Xudagha yene: Ghezipingni manga qozghimighaysen, men peqet mushu bir qétimla deymen! Sendin ötüney, men peqet yene bu qétim bu tére bilen sinap baqay; iltija qilimenki, emdi bu qétim peqet tére quruq bolup, chörisidiki yerning hemmisige shebnem chüshkey, — dédi.
Gideoni sì tún wí fún Ọlọ́run pé, “Jọ̀wọ́ má ṣe bínú sí mi, ṣùgbọ́n jẹ́ kí n tún wá ìdánilójú kan sí i, èmi bẹ̀ ọ́ jẹ́ kí n fi awọ irun yìí ṣe ìdánwò kan sí i. Ní àsìkò yìí, jẹ́ kí awọ irun yìí gbẹ kí gbogbo ilẹ̀ sì tutù pẹ̀lú ìrì.”
40 Bu kéchisimu Xuda shundaq qildi; derweqe peqet térila quruq bolup, chörisidiki yerning hemmisige shebnem chüshkenidi.
Ní òru náà Ọlọ́run ṣe bẹ́ẹ̀, awọ irun àgùntàn nìkan ni ó gbẹ; gbogbo ilẹ̀ yòókù sì tutù nítorí ìrì.

< Batur Hakimlar 6 >