< Batur Hakimlar 19 >

1 Israilda téxi padishah tiklenmigen shu künlerde, Efraim taghliq rayonining chet teripide olturushluq bir Lawiy kishi bar idi; u Yehuda yurtidiki Beyt-Lehemlik bir qizni kénizeklikke aldi.
Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì Israẹli kò ní ọba. Ọ̀kan nínú àwọn ọmọ Lefi tí ń gbé ibi tí ó sá pamọ́ nínú àwọn agbègbè òkè Efraimu, mú àlè kan láti Bẹtilẹhẹmu ní Juda.
2 Lékin u kénizek érige wapasizliq qilip, uning yénidin chiqip, Yehuda yurtidiki Beyt-Lehemge atisining öyige bérip, töt ayche turdi.
Ṣùgbọ́n àlè rẹ̀ náà sì ṣe panṣágà sí i, òun fi sílẹ̀, ó sì padà lọ sí ilé baba rẹ̀ ní Bẹtilẹhẹmu ti Juda, ó sì wà ní ibẹ̀ ní ìwọ̀n oṣù mẹ́rin,
3 U waqitta uning éri qopup kénizikige yaxshi geplerni qilip, könglini élip yandurup kélishke kénizikining yénigha keldi. U bir xizmetkarini we ikki éshekni élip bardi. Kénizek érini atisining öyige élip kirdi; atisi uni körüp xush bolup qarshi aldi.
ọkọ rẹ̀ lọ sí ibẹ̀ láti rọ̀ ọ́ pé kí ó padà sí ọ̀dọ̀ òun. Nígbà tí ó ń lọ ó mú ìránṣẹ́ àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ méjì lọ́wọ́, obìnrin náà mú un wọ inú ilé baba rẹ̀ lọ, nígbà tí baba obìnrin náà rí i ó fi tayọ̀tayọ̀ gbà á.
4 Uning qéynatisi, yeni qizning atisi uni tutup qaldi, u u yerde üch kün’giche yep-ichip, uning bilen yétip qopti.
Àna rẹ̀, baba ọmọbìnrin náà rọ̀ ọ́, ó sì borí rẹ̀ láti dá a dúró fún ìgbà díẹ̀, òun sì dúró fún ọjọ́ mẹ́ta, ó ń jẹ, ó ń mu, ó sì ń sùn níbẹ̀.
5 Tötinchi küni Lawiy kishi seher qopup mangghili teyyarliniwidi, kénizikining atisi küy’oghligha: — Bir toghram nan yep yürikingni quwwetlendürüp andin mangghin, — dédi.
Ní ọjọ́ kẹrin, wọ́n dìde ní òwúrọ̀ kùtùkùtù òun sì múra láti padà lọ, ṣùgbọ́n baba ọmọbìnrin náà wí fún àna rẹ̀ pé, “Fi ohun jíjẹ díẹ̀ gbé inú ró nígbà náà kí ìwọ máa lọ.”
6 Shuning bilen ular ikkisi olturup bille yep-ichip tamaqlandi. Qizning atisi u kishige: — Sendin ötüney, bu kéchimu qon’ghin, könglüng échilsun, dédi.
Àwọn méjèèjì sì jùmọ̀ jókòó láti jọ jẹun àti láti jọ mu. Lẹ́yìn èyí ni baba ọmọbìnrin wí pé, “Jọ̀wọ́ dúró ní alẹ́ yìí kí o sì gbádùn ara rẹ.”
7 Bu kishi mangghili qopuwidi, lékin qéynatisi uni zorlap, yene élip qaldi, u yene bir kün qondi.
Nígbà tí ọkùnrin náà dìde láti máa lọ, baba ìyàwó rẹ̀ rọ̀ ọ́, torí náà ó sùn níbẹ̀ ní alẹ́ ọjọ́ náà.
8 Beshinchi küni u seher qopup mangghili teyyarlandi, lékin qizning atisi uninggha: — [Awwal] yürikingni quwwetlendürgin, dédi. Shuning bilen ular ikkisi kün égilgüche olturup, bille tamaqlandi.
Ní òwúrọ̀ ọjọ́ karùn-ún nígbà tí ó dìde láti lọ, baba ọmọbìnrin wí pé, “Fi oúnjẹ gbé ara ró. Dúró de ọ̀sán!” Àwọn méjèèjì sì jùmọ̀ jọ jẹun.
9 Andin bu kishi kéniziki we xizmetkarini élip mangghili teyyarliniwidi, qéynatisi, yeni qizning dadasi uninggha: — Mana, kech kirey dewatidu, sendin ötüney, bu yerde yene bir kéchini ötküzünglar; mana, kün meghriqqe égiliptu, bu yerde qon’ghin, könglüng échilsun; andin ete seherde yolgha chiqip, öyünglerge kétinglar, — dédi.
Nígbà tí ọkùnrin náà, pẹ̀lú àlè àti ìránṣẹ́ rẹ̀, dìde láti máa lọ, àna rẹ̀, baba ọmọbìnrin náà ní, “Wò ó ilẹ̀ ti ń ṣú lọ, dúró níbí, ọjọ́ ti lọ. Dúró kí o sì gbádùn ara rẹ. Ìwọ lè jí ní àárọ̀ kùtùkùtù ọ̀la kí ìwọ sì máa lọ ilé.”
10 Lékin u kishi emdi yene bir kéche qonushqa unimay, qopup yolgha chiqip Yebusning, yeni Yérusalémning uduligha keldi. Uning bilen bille ikki toquqluq éshek we kéniziki bar idi.
Ṣùgbọ́n nítorí pé òun kò fẹ́ dúró mọ́ níbẹ̀ ní òru náà ọkùnrin náà kúrò ó sì gba ọ̀nà Jebusi: ọ̀nà Jerusalẹmu pẹ̀lú àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀ méjèèjì tí ó fi dì í ní gàárì àti àlè rẹ̀.
11 Ular Yebusqa yéqin kelgende kün olturay dep qalghachqa, xizmetkari ghojisigha: — Yebusiylarning bu shehirige kirip, shu yerde qonayli, dédi.
Nígbà tí wọ́n súnmọ́ Jebusi tí ilẹ̀ ti fẹ́ ṣú tan, ìránṣẹ́ náà sọ fún ọ̀gá rẹ̀ pé, “Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a dúró ní ìlú yìí tí í ṣe ti àwọn ará Jebusi kí a sì sùn níbẹ̀.”
12 Lékin ghojisi uninggha jawab bérip: — Biz Israillar turmaydighan, yat eller turidighan sheherge kirmeyli, belki Gibéahqa ötüp kéteyli, dédi.
Ọ̀gá rẹ̀ dá a lóhùn pé, “Rárá o, àwa kì yóò wọ ìlú àwọn àjèjì, àwọn tí olùgbé ibẹ̀ kì í ṣe ọmọ Israẹli, a yóò dé Gibeah.”
13 Andin u yene xizmetkarigha: — Kelgin, biz yéqindiki jaylardin birige barayli, Gibéahda yaki Ramahda qonayli, dédi.
Ó fi kún un pé, ẹ wá ẹ jẹ́ kí a gbìyànjú kí a dé Gibeah tàbí Rama kí a sùn ní ọ̀kan nínú wọn.
14 Shuning bilen ular méngip, Binyamin yurtidiki Gibéahning yénigha yétip barghanda kün olturghanidi.
Wọ́n sì tẹ̀síwájú nínú ìrìnàjò wọn, oòrùn wọ̀ bí wọ́n ti súnmọ́ Gibeah tí ṣe ti àwọn Benjamini.
15 Ular Gibéahqa kirip, u yerde qonmaqchi boldi; sheherning chong meydanigha kirip olturushti; lékin héchkim ularni qondurushqa öyige teklip qilmidi.
Wọ́n yípadà wọ́n lọ sí inú ìlú Gibeah láti wọ̀ síbẹ̀ ní òru náà, wọ́n lọ wọ́n sì jókòó níbi gbọ̀ngàn ìlú náà, ṣùgbọ́n kò sí ẹni tí ó gbà wọ́n sínú ilé rẹ̀ láti wọ̀ sí.
16 Halbuki, u kéchisi qéri bir adem ishini tügitip, étizliqtin yénip kéliwatqanidi. U eslide Efraim taghliq rayoniliq adem idi, u Gibéahda musapir bolup, olturaqliship qalghanidi; lékin u yerdiki xelqler Binyaminlardin idi.
Ní alẹ́ ọjọ́ náà ọkùnrin arúgbó kan láti àwọn òkè Efraimu, ṣùgbọ́n tí ń gbé ní Gibeah (ibẹ̀ ni àwọn ẹ̀yà Benjamini ń gbé) ń ti ibi iṣẹ́ rẹ̀ bọ̀ láti inú oko.
17 U béshini kötürüp qarap, bu yoluchining sheherning meydanida olturghinini körüp uningdin: — Qeyerdin kelding? Qeyerge barisen? — dep soridi.
Nígbà tí ó wòkè ó rí arìnrìn-àjò náà ní gbọ̀ngàn ìlú náà, ọkùnrin arúgbó yìí bi í léèrè pé, “Níbo ni ò ń lọ? Níbo ni o ti ń bọ̀?”
18 U jawab bérip: — Biz Yehuda yurtidiki Beyt-Lehemdin Efraim taghliqining chet yaqilirigha kétip barimiz; men esli shu jaydin bolup, Yehuda yurtidiki Beyt-Lehemge barghanidim; ishlirim Perwerdigarning öyige munasiwetlik idi; lékin bu yerde héch kim méni öyige teklip qilmidi.
Ọmọ Lefi náà dá a lóhùn pé, “Bẹtilẹhẹmu ti Juda ni àwa ti ń bọ̀, àwa sì ń lọ sí agbègbè tí ó sá pamọ́ ní àwọn òkè Efraimu níbi ti mo ń gbé. Mo ti lọ sí Bẹtilẹhẹmu ti Juda, èmi sì ń lọ sí ilé Olúwa nísinsin yìí. Kò sí ẹni tí ó gbà mí sí ilé rẹ̀.
19 Bizning ésheklirimizge béridighan saman we boghuzimiz bar, özüm, dédekliri, shundaqla keminiliring bilen bolghan yigitkimu nan we sharablar bar, bizge héch néme kem emes, — dédi.
Àwa ní koríko àti oúnjẹ tó tó fún àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wa àti oúnjẹ àti wáìnì fún àwa ìránṣẹ́ rẹ—èmi, ìránṣẹ́bìnrin rẹ àti ọ̀dọ́mọkùnrin tí ó wà pẹ̀lú wa. A ò ṣe aláìní ohun kankan.”
20 Buni anglap qéri kishi: — Tinch-aman bolghaysen; silering mohtajliringlarning hemmisi méning üstümge bolsun, emma kochida yatmanglar! — dep,
Ọkùnrin arúgbó náà sì wí pé. “Àlàáfíà fún ọ, bí ó ti wù kí ó rí, èmi yóò pèsè gbogbo ohun tí o nílò, kìkì pé kí ìwọ má ṣe sun ní ìgboro.”
21 uni öz öyige élip bérip, ésheklirige yem berdi. Méhmanlar putlirini yuyup, yep-ichip ghizalandi.
Òun sì mú wa sí ilé rẹ̀, ó ń bọ́ àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀. Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n ti wẹ ẹsẹ̀ wọn, àwọn àlejò náà jẹ, wọ́n mu.
22 Ular könglide xush bolup turghinida, mana, sheherning ademliridin birnechcheylen, yeni birqanche lükchek kélip öyni qorshiwélip, ishikni urup-qéqip, öyning igisi bolghan qéri kishige: — Séning öyüngge kelgen shu kishini bizge chiqirip bergin, uning bilen yéqinchiliq qilimiz, — dédi.
Ǹjẹ́ bí wọ́n ti ń ṣe àríyá, kíyèsi i, àwọn ọkùnrin ìlú náà, àwọn ọmọ Beliali kan, yí ilé náà ká, wọ́n sì ń lu ìlẹ̀kùn; wọ́n sì sọ fún baálé ilé náà ọkùnrin arúgbó náà pé, “Mú ọkùnrin tí ó wọ̀ sínú ilé rẹ wá, kí àwa lè mọ̀ ọ́n.”
23 Buni anglap öy igisi ularning qéshigha chiqip ulargha: — Bolmaydu, ey buraderlirim, silerdin ötünüp qalay, mundaq rezillikni qilmanglar; bu kishi méning öyümge méhman bolup kelgeniken, siler bundaq iplasliq qilmanglar.
Ọkùnrin, baálé ilé náà sì jáde tọ̀ wọ́n lọ, ó sì wí fún un pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́ ẹ̀yin arákùnrin mi, èmi bẹ̀ yín, ẹ má ṣe hùwà búburú; nítorí tí ọkùnrin yìí ti wọ ilé mi, ẹ má ṣe hùwà òmùgọ̀ yìí.
24 Mana, méning pak bir qizim bar, yene u kishining kéniziki bar. Men ularni qéshinglargha chiqirip bérey, siler ularni ayagh asti qilsanglar meyli, neziringlargha néme xush yaqsa ularni shundaq qilinglar, lékin bu kishige mushundaq iplasliq ishni qilmanglar, — dédi.
Kíyèsi i, ọmọbìnrin mi ni èyí, wúńdíá, àti àlè rẹ̀; àwọn ni èmi ó mú jáde wá nísinsin yìí, kí ẹ̀yin tẹ̀ wọ́n lógo, kí ẹ̀yin ṣe sí wọn bí ó ti tọ́ lójú yín: ṣùgbọ́n ọkùnrin yìí ni kí ẹ̀yin má ṣe hùwà òmùgọ̀ yìí sí.”
25 Lékin u ademler uninggha qulaq salmidi; yoluchi kénizikini ularning aldigha sörep chiqirip berdi. Ular uning bilen bille bolup kechtin etigen’giche ayagh asti qildi; ular tang yorughanda andin uni qoyup berdi.
Ṣùgbọ́n àwọn ọkùnrin náà kò fetí sí tirẹ̀. Nítorí náà ọkùnrin náà mú àlè rẹ̀ ó sì tari rẹ̀ jáde sí wọn, wọ́n sì bá a fi ipá lòpọ̀, wọ́n sì fi gbogbo òru náà bá a lòpọ̀, nígbà tí ó di àfẹ̀mọ́júmọ́ wọ́n jọ̀wọ́ rẹ̀ lọ́.
26 Chokan tang seherde qaytip kélip, uning ghojisi qon’ghan öyning derwazisining bosughisigha kelgende yiqilip qélip, tang atquche shu yerde yétip qaldi.
Nígbà tí ojúmọ́ bẹ̀rẹ̀ sí là obìnrin náà padà lọ sí ilé tí ọ̀gá rẹ̀ wà, ó ṣubú lulẹ̀ lọ́nà, ó sì wà níbẹ̀ títí ó fi di òwúrọ̀.
27 Etigende uning ghojisi qopup öyning ishikini échip, yolgha chiqmaqchi bolup téshigha chiqiwidi, mana, uning kéniziki bolghan chokan öyning derwazisi aldida qolliri bosughining üstige qoyuqluq halda yatatti.
Nígbà tí ọ̀gá rẹ̀ jí tí ó sì dìde ní òwúrọ̀ tí ó sì ṣí ìlẹ̀kùn ilé náà, tí ó sì bọ́ sí òde láti tẹ̀síwájú nínú ìrìnàjò rẹ̀, kíyèsi i àlè rẹ̀ wà ní ṣíṣubú ní iwájú ilé, tí ọwọ́ rẹ̀ sì di òpó ẹnu-ọ̀nà ibẹ̀ mú,
28 U uninggha: — Qopqin, biz mangayli, dédi. Lékin chokan héchbir jawab bermidi. Shuning bilen u chokanni éshekke artip, qozghilip öz öyige yürüp ketti.
òun sì wí fún obìnrin náà pé, “Dìde jẹ́ kí a máa bá ọ̀nà wa lọ.” Ṣùgbọ́n òun kò dá a lóhùn. Nígbà náà ni ọkùnrin náà gbé e lé orí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀, ó sì kọjá lọ sí ilé e rẹ̀.
29 Öz öyige kelgende, pichaqni élip kénizikining jesitini söngekliri boyiche on ikki parche qilip, pütkül Israil yurtining chet-yaqilirighiche ewetti.
Nígbà tí ó dé ilé, ó mú ọ̀bẹ ó sì gé àlè rẹ̀ ní oríkeríke sí ọ̀nà méjìlá, ó sì fi wọ́n ránṣẹ́ sí gbogbo agbègbè Israẹli.
30 Shundaq boldiki, buni körgenlerning hemmisi: «Israil Misirdin chiqqan kündin tartip bügün’giche bundaq ish bolup baqmighanidi yaki körülüp baqmighanidi. Emdi bu ishni obdan oyliship, qandaq qilish kéreklikini meslihetlisheyli» — déyishti.
Gbogbo ẹni tí ó rí i sì wí pé, “A kò ti rí i, bẹ́ẹ̀ a kò tí ì ṣe irú nǹkan yìí rí, kì í ṣe láti ọjọ́ tí Israẹli ti jáde tí Ejibiti wá títí di òní olónìí. Ẹ rò ó wò, ẹ gbìmọ̀ràn, kí ẹ sọ fún wa ohun tí a yóò ṣe!”

< Batur Hakimlar 19 >