< Ayup 7 >

1 Insan’gha zéminda jewre-japa chékidighan turmush békitilgen emesmu? Uning künliri bir medikarningkige oxshash emesmu?
“Ṣé ìjà kò ha si fún ènìyàn lórí ilẹ̀? Ọjọ́ rẹ̀ pẹ̀lú kò ha dàbí ọjọ́ alágbàṣe?
2 Qul kechqurunning sayisige teshna bolghandek, Medikar öz emgikining heqqini kütkendek,
Bí ọmọ ọ̀dọ̀ tí máa ń kánjú bojú wo òjìji, àti bí alágbàṣe ti í kánjú wo ọ̀nà owó iṣẹ́ rẹ̀.
3 Mana bihude aylar manga békitilgen, Gheshlikke tolghan kéchiler manga nésip qilin’ghan.
Bẹ́ẹ̀ ni a mú mi ní ìbànújẹ́ ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ oṣù, òru ìdáni-lágara ni a sì là sílẹ̀ fún mi.
4 Men yatqinimda: «Qachan qoparmen?» dep oylaymen, Biraq kech uzundin uzun bolidu, Tang atquche pütün bir kéche men tolghinip yatimen.
Nígbà ti mo dùbúlẹ̀, èmi wí pé, ‘Nígbà wo ni èmi ó dìde?’ Tí òru yóò sì kọjá, ó sì tó fún mi láti yí síyìn-ín yí sọ́hùn-ún, títí yóò fi di àfẹ̀mọ́júmọ́.
5 Etlirim qurtlar hem topa-changlar bilen qaplandi, Térilirim yérilip, yiringlap ketti.
Kòkòrò àti ògúlùtu erùpẹ̀ ni á fi wọ̀ mi ni aṣọ, awọ ara mi bù, o sì di bíbàjẹ́.
6 Künlirim bapkarning mokisidinmu ittik ötidu, Ular ümidsizlik bilen ayaghlishay dep qaldi.
“Ọjọ́ mi yára jù ọkọ̀ ìhunṣọ lọ, o sì di lílò ní àìní ìrètí.
7 [Ah Xuda], méning jénim bir nepesla xalas. Közüm yaxshiliqni qaytidin körmeydighanliqi ésingde bolsun;
Háà! Rántí pé afẹ́fẹ́ ni ẹ̀mí mi; ojú mi kì yóò padà rí rere mọ́.
8 Méni Körgüchining közi ikkinchi qétim manga qarimaydu, Sen neziringni üstümge chüshürginingde, men yoqalghan bolimen.
Ojú ẹni tí ó rí mi, kì yóò rí mi mọ́; ojú rẹ̀ tẹ̀ mọ́ra mi, èmi kò sí mọ́.
9 Bulut ghayib bolup, qayta körünmigendek, Oxshashla tehtisaragha chüshken adem qaytidin chiqmaydu. (Sheol h7585)
Bí ìkùùkuu tí i túká, tí í sì fò lọ, bẹ́ẹ̀ ni ẹni tí ń lọ sí ipò òkú tí kì yóò padà wa mọ́. (Sheol h7585)
10 U yene öz öyige qaytmaydu, Öz yurti uni qayta tonumaydu.
Kì yóò padà sínú ilé rẹ̀ mọ́, bẹ́ẹ̀ ní ipò rẹ̀ kì yóò mọ̀ ọn mọ́.
11 Shunga men aghzimni yummay, Rohimning derd-elimi bilen söz qilay, Jénimning azabidin zarlaymen.
“Nítorí náà èmi kì yóò pa ẹnu mi mọ́, èmi yóò máa sọ nínú ìrora ọkàn mi, èmi yóò máa ṣe ìráhùn nínú kíkorò ọkàn mi.
12 Némishqa Sen üstümdin közet qilisen? Men [xeterlik] bir déngizmu-ya? Yaki déngizdiki bir ejdihamumen?
Èmi a máa ṣe Òkun tàbí ẹ̀mí búburú, tí ìwọ fi ń yan olùṣọ́ tì mi?
13 Men: «Ah, yatqan ornum manga rahet béridu, Körpem nale-peryadimgha derman bolidu» — désem,
Nígbà tí mo wí pé, ibùsùn mi yóò tù mí lára, ìtẹ́ mi yóò mú ara mi fúyẹ́ pẹ̀lú.
14 Emdi Sen chüshler bilen méni qorqutiwatisen, Ghayibane alametler bilen manga wehime salisen.
Nígbà náà ni ìwọ fi àlá da yọ mi lénu bò mi, ìwọ sì fi ìran òru dẹ́rùbà mí.
15 Shuning üchün boghulushumni, ölümni, Bu söngeklirimge qarap olturushtin artuq bilimen.
Bẹ́ẹ̀ ni ọkàn mí yàn láti fún pa àti ikú ju kí ń wà láààyè ní ipò tí ara mí wà yìí lọ.
16 Men öz jénimdin toydum; Méning menggüge yashighum yoq, Méni meylimge qoyiwetkin, Méning künlirim bihudidur.
O sú mi, èmi kò le wà títí: jọ̀wọ́ mi jẹ́, nítorí pé asán ni ọjọ́ mi.
17 Insan balisi némidi? Sen némishqa uni chong bilisen, Néme dep uninggha köngül bérisen?
“Kí ni ènìyàn tí ìwọ o máa kókìkí rẹ̀? Àti tí ìwọ ìbá fi gbé ọkàn rẹ lé e?
18 Her etigende uni sürüshtürüp kélisen, Her nepes uni sinaysen!
Àti ti ìwọ ó fi máa wá í bẹ̀ ẹ́ wò ni òròòwúrọ̀, ti ìwọ o sì máa dán an wò nígbàkígbà!
19 Qachan’ghiche méningdin neziringni almaysen, Manga qachan’ghiche aghzimdiki sériq suni yutuwalghudek aram bermeysen?
Yóò ti pẹ́ tó kí ìwọ kí ó tó fi mí sílẹ̀ lọ, tí ìwọ o fi mí sílẹ̀ jẹ́ẹ́ títí èmi yóò fi lè dá itọ́ mi mì.
20 Men gunah qilghan bolsammu, i insaniyetni Közetküchi, Sanga néme qiliptimen?! Men Sanga yük bolup qaldimmu? Buning bilen méni Özüngge zerbe nishani qilghansenmu?
Èmi ti ṣẹ̀, ki ní èmi ó ṣe sí ọ. Ìwọ Olùsójú ènìyàn? Èéṣe tí ìwọ fi fi mí ṣe àmì itasi níwájú rẹ, bẹ́ẹ̀ ni èmi sì di ẹrẹ̀ wíwo fún ọ?
21 Sen némishqa méning itaetsizlikimni kechürüm qilip, Gunahimni saqit qilmaysen? Chünki men pat arida topining ichide uxlaymen; Sen méni izdep kélisen, lékin men mewjut bolmaymen».
Èéṣe tí ìwọ kò sì dárí ìrékọjá mi jìn, kí ìwọ kí ó sì mú àìṣedéédéé mi kúrò? Ǹjẹ́ nísinsin yìí ni èmi ìbá sùn nínú erùpẹ̀, ìwọ ìbá sì wá mi kiri ní òwúrọ̀, èmi kì bá tí sí.”

< Ayup 7 >