< Yeremiya 26 >
1 Yehuda padishahi Yosiyaning oghli Yehoakim textke olturghan mezgilning béshida shu söz Perwerdigardin kélip mundaq déyildi: —
Ní ìbẹ̀rẹ̀ pẹ̀pẹ̀ ìjọba ọba Jehoiakimu ọmọ Josiah tí ń ṣe ọba Juda, ọ̀rọ̀ yìí wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa:
2 Perwerdigar mundaq deydu: — Sen Perwerdigarning öyining hoylisida turup ibadet qilish üchün Perwerdigarning öyige kirgen Yehudaning barliq sheherliridikilerge Men sanga buyrughan herbir sözlerni jakarlighin; eynen éytqin!
“Èyí ni ohun tí Olúwa wí, Dúró ní àgbàlá ilé Olúwa, kí o sì sọ fún gbogbo ènìyàn ilẹ̀ Juda tí ó ti wá láti wá jọ́sìn ní ilé Olúwa, sọ fún gbogbo ohun tí mo pàṣẹ fún ọ; má ṣaláìsọ gbogbo ọ̀rọ̀ náà.
3 Ular belkim anglap qoyar, herbiri öz rezil yolidin yanar; shundaq qilsa, Men qilmishlirining rezilliki tüpeylidin béshigha külpet chüshürmekchi bolghan niyitimdin yanimen.
Bóyá gbogbo wọn máa gbọ́ ọ̀rọ̀ náà tí ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn yóò kúrò nínú ìwà búburú wọn. Èmi ó yí ọkàn padà, n kò sì ní fi ibi tí mo ti rò sí wọn ṣe wọ́n.
4 Sen ulargha mundaq dégin: — «Perwerdigar mundaq deydu: — Manga qulaq salmay, Men silerning aldinglargha qoyghan Tewrat-qanunumda mangmisanglar,
Sọ fún wọn wí pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí: Tí ẹ kò bá fi etí sí ọ̀rọ̀ mi, tí ẹ kò sì gbọ́ òfin mi, ti mo gbé kalẹ̀ níwájú yín,
5 Men tang seherde ornumdin turup ewetken xizmetkarlirim bolghan peyghemberlerning sözlirini anglimisanglar (siler ulargha héch qulaq salmay kelgensiler!),
àti tí ẹ kò bá gbọ́ ọ̀rọ̀ àwọn ìránṣẹ́ mi, àwọn wòlíì tí mo rán sí i yín léraléra (ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò gbọ́),
6 undaqta, Men Shilohni qandaq qilghan bolsam, emdi bu öynimu shuninggha oxshash qilimen, bu sheherni yer yüzidiki barliq ellerge lenet sözi qilimen».
nígbà náà ni èmi yóò ṣe ilé yìí bí Ṣilo, èmi yóò sì ṣe ìlú yìí ní ìfibú sí gbogbo orílẹ̀-èdè ayé.’”
7 Shuning bilen kahinlar, peyghemberler we barliq xelq Yeremiyaning bu sözlirini Perwerdigarning öyide jakarlighanliqini anglidi.
Àwọn àlùfáà, àwọn wòlíì àti gbogbo ènìyàn ni ó gbọ́ ọ̀rọ̀ Jeremiah tí ó sọ ní ilé Olúwa.
8 Shundaq boldiki, Yeremiya barliq xelqqe Perwerdigar uninggha tapilighan bu sözlerning hemmisini éytip bergendin kéyin, kahinlar we peyghemberler we barliq xelq uni tutuwélip: «Sen choqum ölüshüng kérek!
Ṣùgbọ́n ní kété tí Jeremiah ti parí ọ̀rọ̀ rẹ̀ tí Olúwa pàṣẹ láti sọ; àwọn àlùfáà, àti gbogbo ènìyàn dìímú, wọ́n sì wí pé, “Kíkú ni ìwọ yóò kú!
9 Sen némishqa Perwerdigarning namida bésharet bérip: «Bu öy Shilohdek bolidu, bu sheher xarabe, ademzatsiz bolidu!» — déding?» — dédi. Shuning bilen Perwerdigarning öyidiki barliq xelq Yeremiyagha doq qilip uni oriwélishti.
Kí ló dé tí ìwọ ṣe sọ àsọtẹ́lẹ̀ ní orúkọ Olúwa pé, ilé yìí yóò dàbí Ṣilo, orílẹ̀-èdè yìí yóò sì di ahoro tí kì yóò ní olùgbé.” Gbogbo àwọn ènìyàn sì kójọpọ̀ pẹ̀lú Jeremiah nínú ilé Olúwa.
10 Yehuda emirliri bu ishlarni anglidi; ular padishahliq ordisidin chiqip Perwerdigarning öyige kirdi, Perwerdigarning öyidiki «Yéngi derwaza»da sotqa olturdi.
Nígbà tí àwọn aláṣẹ Juda gbọ́ nípa nǹkan wọ̀nyí, wọ́n lọ láti ààfin ọba sí ilé Olúwa, wọ́n sì mú ààyè wọn, wọ́n jókòó ní ẹnu-ọ̀nà tuntun ilé Olúwa.
11 Kahinlar we peyghemberler emirlerge we xelqqe sözlep: «Bu adem ölümge layiq, chünki siler öz qulaqliringlar bilen anglighandek u mushu sheherni eyiblep bésharet berdi» — dédi.
Àwọn àlùfáà àti àwọn wòlíì sọ fún àwọn aláṣẹ àti gbogbo ènìyàn pé, “Arákùnrin yìí gbọdọ̀ gba ìdájọ́ ikú nítorí pé ó sọ àsọtẹ́lẹ̀ lórí ìlú yìí: bí ẹ̀yin ti fi etí yín gbọ́!”
12 Andin Yeremiya barliq emirlerge we barliq xelqqe sözlep mundaq dédi: — «Perwerdigar méni bu öyni eyiblep, bu sheherni eyiblep, siler anglighan bu barliq sözler bilen bésharet bérishke ewetken.
Nígbà náà ni Jeremiah sọ fún gbogbo àwọn aláṣẹ àti gbogbo àwọn ènìyàn wí pé: “Olúwa rán mi láti sọ àsọtẹ́lẹ̀ ní ilé yìí àti ìlú yìí, gbogbo ohun tí ẹ ti gbọ́.
13 Hazir yolliringlarni we qilmishinglarni tüzitinglar, Perwerdigar Xudayinglarning awazini anglanglar! Shundaq bolghanda, Perwerdigar silerge jakarlighan külpettin yanidu.
Nísinsin yìí, tún ọ̀nà rẹ ṣe àti ìṣe rẹ, kí ẹ sì gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa Ọlọ́run yín. Olúwa yóò yí ọkàn rẹ̀ padà, kò sì ní mú ohun gbogbo tí ó ti sọ jáde ní búburú ṣẹ lórí yín.
14 Lékin men bolsam, mana, qolliringlardimen; manga közünglerge néme yaxshi we durus körülse shundaq qilinglar;
Bí ó bá ṣe tèmi ni, èmi wà ní ọwọ́ yín, ẹ ṣe ohun tí ẹ̀yin bá rò pé ó dára, tí ó sì tọ́ lójú yín fún mi.
15 peqet shuni bilip qoyunglarki, méni öltürüwetsengler gunahsiz qanning jazasini öz béshinglargha, bu sheherge we uningda turuwatqanlarning béshigha chüshürisiler; chünki déginim heq, Perwerdigar heqiqeten bu sözlerning hemmisini qulaqliringlargha déyishke méni ewetken».
Ẹ mọ̀ dájú pé tí ẹ bá pa mí, ẹ ó mú ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ wá sórí ara yín, sórí ìlú yìí àti àwọn olùgbé inú rẹ̀; nítorí pé nítòótọ́ ni Olúwa ti rán mi láti sọ ọ̀rọ̀ yìí fún un yín.”
16 Emirler we barliq xelq kahinlargha we peyghemberlerge: «Bu adem ölümge layiq emes; chünki u Perwerdigar Xudayimizning namida bizge sözlidi» — dédi.
Nígbà náà ni àwọn aláṣẹ àti gbogbo àwọn ènìyàn sọ fún àwọn àlùfáà àti àwọn wòlíì pé, “Ẹ má ṣe pa ọkùnrin yìí nítorí ó ti bá wa sọ̀rọ̀ ní orúkọ Olúwa àwọn ọmọ-ogun.”
17 Andin zémindiki bezi aqsaqallar ornidin turup xelq kéngishige mundaq dédi: —
Lára àwọn àgbàgbà ilẹ̀ náà sì sún síwájú, wọ́n sì sọ fún gbogbo àwọn ènìyàn náà wí pé,
18 «Moreshetlik Mikah Yehuda padishahi Hezekiyaning künliride barliq Yehuda xelqige bésharet bérip: — «Samawi qoshunlarning Serdari bolghan Perwerdigar mundaq deydu: — Zion téghi étizdek aghdurulidu, Yérusalém döng-töpiler bolup qalidu, «Öy jaylashqan tagh» bolsa, Ormanliqning otturisidiki yuqiri jaylarla bolidu, xalas» — dégenidi.
“Mika ti Moreṣeti sọ àsọtẹ́lẹ̀ ní ọjọ́ Hesekiah ọba Juda. Ó sọ fún gbogbo ènìyàn Juda pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “‘A ó sì fa Sioni tu bí oko Jerusalẹmu yóò di òkìtì àlàpà àti òkè ilẹ̀ yìí gẹ́gẹ́ bí ibi gíga igbó.’
19 Yehuda padishahi Hezekiya we barliq Yehuda xelqi Mikahni ölümge mehkum qilghanmu? Hezekiya Perwerdigardin qorqup, Perwerdigardin ötün’gen emesmu? We Perwerdigar ulargha qilmaqchi bolup jakarlighan külpettin yan’ghan emesmu? Biz [bu yoldin yanmisaq] öz jénimiz üstige zor bir külpetni chüshürgen bolmamdimiz?».
Ǹjẹ́ Hesekiah ọba Juda tàbí ẹnikẹ́ni ní Juda pa á bí? Ǹjẹ́ Hesekiah kò bẹ̀rù Olúwa tí ó sì wá ojúrere rẹ̀? Ǹjẹ́ Olúwa kò ha a sì yí ìpinnu rẹ̀ padà, tí kò sì mú ibi tí ó ti sọtẹ́lẹ̀ yẹ̀ kúrò lórí wọn? Ibi ni a fẹ́ mú wá sórí ara wa yìí.”
20 (Perwerdigarning namida Yeremiyaning barliq dégenliridek bu sheherni we bu zéminni eyiblep bésharet bergen, Kiriat-Yéarimliq Shemayaning oghli Uriya isimlik yene bir adem bar idi.
(Bákan náà Uriah ọmọ Ṣemaiah láti Kiriati-Jearimu jẹ́ ọkùnrin mìíràn tí ó sọ àsọtẹ́lẹ̀ kan náà ní orúkọ Olúwa. Ó sọ àsọtẹ́lẹ̀ kan náà sí ìlú náà àti ilẹ̀ yín bí Jeremiah ti ṣe.
21 Padishah Yehoakim we barliq palwanliri, barliq emirliri uning sözlirini anglighanda, padishah uni öltürüshke intilgen; lékin Uriya buni anglighanda qorqup, Misirgha qachti.
Nígbà tí ọba Jehoiakimu àti gbogbo àwọn aláṣẹ gbọ́ gbogbo ọ̀rọ̀ rẹ̀, ọba ń wá láti pa á: ṣùgbọ́n Uriah gbọ́ èyí, ẹ̀rù bà á, ó sì sálọ sí Ejibiti.
22 Lékin Yehoakim chaparmenlerni, yeni Akborning oghli Elnatan we bashqilarni Misirgha ewetken;
Ọba Jehoiakimu rán Elnatani ọmọ Akbori lọ sí Ejibiti pẹ̀lú àwọn ọkùnrin mìíràn.
23 ular Uriyani Misirdin élip chiqip padishah Yehoakimning aldigha aparghan; u uni qilichlap, jesitini puqralarning görlükige tashliwetken).
Wọ́n sì mú Uriah láti Ejibiti lọ sí ọ̀dọ̀ ọba Jehoiakimu; ẹni tí ó fi idà pa, ó sì sọ òkú rẹ̀ sí inú isà òkú àwọn ènìyàn lásán.)
24 — Halbuki, shu chaghda Shafanning oghli Ahikam ularning Yeremiyani ölümge mehkum qilip xelqning qoligha tapshurmasliqi üchün, uni qollidi.
Ahikamu ọmọ Ṣafani ń bẹ pẹ̀lú Jeremiah, wọn kò sì fi í lé àwọn ènìyàn lọ́wọ́ láti pa á.