< Yeshaya 37 >
1 Shundaq boldiki, Hezekiya buni anglighanda, kiyim-kécheklirini yirtip, özini böz bilen qaplap Perwerdigarning öyige kirdi.
Nígbà tí ọba Hesekiah gbọ́ èyí, ó fa aṣọ rẹ̀ ya, ó sì fi aṣọ ọ̀fọ̀ bo ara rẹ̀, ó sì wọ inú tẹmpili Olúwa lọ.
2 U Hilqiyaning oghli, ordini bashquridighan Éliakim, orda diwanbégi Shebna we kahinlarning aqsaqallirini böz yépinchaqlighan péti Amozning oghli Yeshaya peyghemberge ewetti.
Òun sì rán Eliakimu alákòóso ààfin, Ṣebna akọ̀wé, àti aṣíwájú àwọn àlùfáà, gbogbo wọn nínú aṣọ ọ̀fọ̀ lọ sí ọ̀dọ̀ wòlíì Isaiah ọmọ Amosi.
3 Ular uninggha: — «Hezekiya mundaq deydu: — «Balilar tughulay dep qalghanda anining tughqudek hali qalmighandek, mushu kün külpet chüshidighan, reswa we mazaq qilinidighan bir kündur.
Wọ́n sọ fún un pé, “Báyìí ni Hesekiah wí, ọjọ́ òní jẹ́ ọjọ́ ìbànújẹ́, ìbáwí àti ẹ̀gàn gẹ́gẹ́ bí ìgbà ìbí àwọn ọmọdé tí kò sì ṣí agbára láti bí wọn.
4 Öz xojisi bolghan Asuriye padishahi tirik Xudani mazaq qilishqa ewetken Rab-Shakehning geplirini Perwerdigar Xudaying nezirige élip tingshisa, bularni anglighan Perwerdigar Xudaying shu gepler üchün uning dekkisini bérermikin? Shunga qép qalghan qaldilar üchün awazingni kötürüp, bir duayingni berseng»» — dédi.
Ó lè jẹ́ pé Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò gbọ́ ọ̀rọ̀ ọ̀gágun ẹni tí ọ̀gá rẹ̀ ọba Asiria ti rán láti fi Ọlọ́run alààyè ṣe ẹlẹ́yà, àti pé òun ni yóò bá a wí nítorí àwọn ọ̀rọ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ ti gbọ́. Nítorí náà gbàdúrà fún àwọn tí ó ṣẹ́kù tí wọ́n sì wà láààyè.”
5 Shu gepler bilen Hezekiyaning xizmetkarliri Yeshayaning aldigha keldi.
Nígbà tí àwọn ìjòyè ọba Hesekiah dé ọ̀dọ̀ Isaiah,
6 Yeshaya ulargha: — «Xojayininglargha: — «Perwerdigar mundaq dédi: — «Asuriye padishahining chaparmenlirining sen anglighan ashu manga kupurluq qilghuchi gepliridin qorqma;
Isaiah sọ fún wọn pé, “Ẹ sọ fún ọ̀gá yín pé, ‘Ohun tí Olúwa sọ nìyìí. Má ṣe bẹ̀rù ohun tí ẹ ti gbọ́ gbogbo ọ̀rọ̀ tí ọba Asiria tí ó wà nínú ìdè ti fi sọ̀rọ̀-òdì sí mi.
7 Mana, Men uninggha bir rohni kirgüzimen; shuning bilen u ighwani anglap, öz yurtigha qaytidu. U öz zéminida turghanda uni qilich bilen öltürgüzimen» — denglar» — dédi.
Tẹ́tí sílẹ̀! Èmi yóò fi ẹ̀mí kan sínú rẹ̀ tó bẹ́ẹ̀ tí ó fi jẹ́ pé bí o bá ti gbọ́ ìròyìn kan, òun yóò padà sí orílẹ̀-èdè rẹ̀, níbẹ̀ ni n ó sì ti jẹ́ kí wọn ké e lulẹ̀ pẹ̀lú idà.’”
8 Rab-Shakeh kelgen yoli bilen qaytip mangghanda, Asuriye padishahining Laqish shehiridin chékin’genlikini anglap, uning yénigha keldi; Asuriye padishahi Libnah shehirige qarshi jeng qiliwatqanidi.
Nígbà tí ọ̀gágun gbọ́ pé ọba Asiria ti fi Lakiṣi sílẹ̀, ó padà sẹ́yìn, ó sì bá ọba tí ń bá Libina jà.
9 Andin padishah: «Éfiopiye padishahi Tirhakah sizge qarshi jeng qilmaqchi bolup yolgha chiqti» dégen xewerni anglidi. Shu xewerni anglighanda u yene Hezekiyagha elchilerni mundaq xet bilen ewetti: —
Ní àkókò yìí Sennakeribu gbọ́ ìròyìn kan pé Tirakah ará Kuṣi ọba Ejibiti ń jáde bọ̀ wá bá òun jà. Nígbà tí ó gbọ́ èyí, ó rán oníṣẹ́ sí Hesekiah pẹ̀lú ọ̀rọ̀ wọ̀nyí,
10 «Siler Yehuda padishahi Hezekiyagha mundaq denglar: — «Sen tayinidighan Xudayingning sanga: «Yérusalém Asuriye padishahining qoligha tapshurulmaydu» déginige aldanma;
“Ẹ sọ fún Hesekiah ọba Juda pé: Má ṣe jẹ́ kí òrìṣà tí ìwọ gbẹ́kẹ̀lé tàn ọ́ jẹ nígbà tí ó sọ pé, ‘A kì yóò jọ̀wọ́ Jerusalẹmu fún ọba Asiria.’
11 Mana, sen Asuriye padishahlirining hemme el-yurtlarni néme qilghanlirini, ularni ilah-butlirigha atap halak qilghanliqini anglighansen; emdi özüng qandaqmu qutquzulisen?
Dájúdájú, ìwọ ti gbọ́ ohun tí ọba Asiria ti ṣe sí àwọn orílẹ̀-èdè, tí ó pa wọ́n run pátápátá. Ǹjẹ́ a ó ha dá ọ nídè bí?
12 Ata-bowilirim halak qilghan ellerni bolsa, ularning ilah-butliri qutquzghanmu? Gozan, Haran, Rezef shehiridikilernichu? Télassarda turghan Édenlernichu?
Ǹjẹ́ àwọn òrìṣà àwọn orílẹ̀-èdè tí àwọn baba ńlá mi parun ha gbà wọ́n sílẹ̀ bí àwọn òrìṣà Gosani, Harani, Reṣefu àti àwọn ènìyàn Edeni tí wọ́n wà ní Teli-Assari?
13 Xamat padishahi, Arpad padishahi, Sefarwaim, Xéna hem Iwwah sheherlirining padishahliri qéni?»».
Níbo ni ọba Hamati wà, ọba Arpadi, ọba ìlú Sefarfaimi tàbí Hena tàbí Iffa?”
14 Hezekiya xetni ekelgüchilerning qolidin élip oqup chiqti. Andin u Perwerdigarning öyige kirip, Perwerdigarning aldigha xetni yéyip qoydi.
Hesekiah gba ìwé náà lọ́wọ́ àwọn oníṣẹ́ ó sì kà á. Lẹ́yìn náà ni ó gòkè lọ sí tẹmpili Olúwa ó sì tẹ́ ìwé náà sílẹ̀ níwájú Olúwa.
15 Hezekiya Perwerdigargha dua qilip mundaq dédi: —
Hesekiah sì gbàdúrà sí Olúwa:
16 «I kérublar otturisida turghan, samawi qoshunlarning Serdari bolghan Perwerdigar, Israilning Xudasi: — Sen Özüngdursen, jahandiki barliq el-yurtlarning üstidiki Xuda peqet Özüngdursen; asman-zéminni Yaratquchisen.
Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli, tí ó gúnwà láàrín àwọn kérúbù, ìwọ nìkan ni Ọlọ́run lórí i gbogbo ìjọba orílẹ̀ ayé. Ìwọ ti dá ọ̀run àti ayé.
17 I Perwerdigar, quliqingni töwen qilip anglighaysen; közüngni achqaysen, i Perwerdigar, körgeysen; Sennaxéribning adem ewetip menggü hayat Xudani haqaretlep éytqan hemme geplirini anglighaysen!
Tẹ́tí sílẹ̀, ìwọ Olúwa, kí o gbọ́, ya ojú rẹ, Ìwọ Olúwa, kí o rí i; tẹ́tí sí gbogbo ọ̀rọ̀ tí Sennakeribu rán láti fi àbùkù kan Ọlọ́run alààyè.
18 I Perwerdigar, Asuriye padishahliri heqiqeten hemme yurtlarni we shulargha béqindi bolghan yurtlarnimu xarabe qilip,
“Òtítọ́ ni Olúwa pé àwọn ọba Asiria ti sọ àwọn ènìyàn àti ilẹ̀ wọn di asán.
19 Ularning ilah-butlirini otqa tashliwetken; chünki ularning ilahliri ilah emes, belki insan qoli bilen yasalghanlar, yaghach we tash, xalas; shunga Asuriyelikler ularni halak qildi.
Wọ́n ti da àwọn òrìṣà wọn sínú iná wọ́n sì ti pa wọ́n run, nítorí àwọn wọ̀nyí kì í ṣe ọlọ́run bí kò ṣe igi àti òkúta lásán, tí a ti ọwọ́ ènìyàn ṣe.
20 Emdi, i Perwerdigar Xudayimiz, jahandiki barliq el-yurtlargha Séning, peqet Séningla Perwerdigar ikenlikingni bildürüsh üchün, bizni uning qolidin qutquzghaysen!».
Nísinsin yìí, ìwọ Olúwa, Ọlọ́run wa, gbà wá lọ́wọ́ rẹ̀, tí ó fi jẹ́ pé gbogbo ìjọba ilẹ̀ ayé yóò fi mọ̀ pé Ìwọ, Ìwọ nìkan, Olúwa ni Ọlọ́run.”
21 Shuning bilen Amozning oghli Yeshaya Hezekiyagha söz ewetip mundaq dédi: — — Israilning Xudasi Perwerdigar mundaq deydu: — «Sen Manga Sennaxérib toghruluq dua qilishing bilen,
Lẹ́yìn náà Isaiah ọmọ Amosi rán iṣẹ́ kan sí Hesekiah: “Èyí ni ohun tí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli sọ pé, nítorí pé ìwọ ti gbàdúrà sí mi nípa Sennakeribu ọba Asiria,
22 Perwerdigarning uninggha qarita dégen sözi shudurki: — «Pak qiz, yeni Zionning qizi séni kemsitidu, Séni mazaq qilip külidu; Yérusalémning qizi keyningge qarap béshini chayqaydu;
èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa ti sọ nípa rẹ̀: “Wúńdíá ọmọbìnrin Sioni ti kẹ́gàn rẹ, ó sì ti fi ọ ṣe ẹlẹ́yà. Ọmọbìnrin Jerusalẹmu ti mi orí rẹ̀ bí ó ti ń sálọ.
23 Sen kimni mazaq qilip kupurluq qilding? Sen kimge qarshi awazingni kötürüp, Neziringni üstün qilding? Israildiki Muqeddes Bolghuchigha qarshi!
Ta ni ìwọ ti bú tí ìwọ sì ti sọ̀rọ̀-òdì sí? Sí ta ní ìwọ ti gbé ohùn rẹ sókè tí o sì gbé ojú rẹ sókè ní ìgbéraga? Sí Ẹni Mímọ́ Israẹli!
24 Qulliring arqiliq sen Rebni mazaq qilip: — «Men nurghunlighan jeng harwilirim bilen tagh choqqilirigha, Liwan tagh baghirlirigha yétip keldimki, Uning égiz kédir derexlirini, ésil qarighaylirini késiwétimen; Men uning eng yuqiri égizlikige yamiship chiqip, Uning eng bük-baraqsan ormanzarliqigha kirip yétimen.
Nípa àwọn ìránṣẹ́ rẹ, ìwọ ti sọ̀rọ̀ búburú sí Olúwa. Tì wọ sì wí pé, ‘Pẹ̀lú ọ̀pọ̀ kẹ̀kẹ́ mi ni èmi sì fi dé orí àwọn òkè ńlá, sí ibi gíga jùlọ Lebanoni. Èmi a sì ké igi kedari gíga rẹ̀ lulẹ̀, àti ààyò igi firi rẹ̀. Èmi ti dé ibi rẹ̀ tí ó ga jùlọ, igbó rẹ̀ tí ó dára jùlọ.
25 Özüm quduq kolap su ichtim; Putumning uchidila men Misirning barliq derya-östenglirini qurutuwettim — déding.
Èmi ti gbẹ́ kànga ní ilẹ̀ àjèjì mo sì mu omi ní ibẹ̀, pẹ̀lú àtẹ́lẹsẹ̀ mi Èmi ti gbẹ́ gbogbo omi àwọn odò Ejibiti.’
26 — Sen shuni anglap baqmighanmiding? Uzundin buyan Men shuni békitkenmenki, Qedimdin tartip shekillendürgenmenki, Hazir uni emelge ashurdumki, Mana, sen qel’e-qorghanliq sheherlerni xarabilerge aylandurdung;
“Ṣé o kò tí ì gbọ́? Tipẹ́tipẹ́ ni mo ti fìdí rẹ̀ mulẹ̀. Láti ìgbà pípẹ́ ni mo ti ṣètò rẹ̀; ní àkókò yìí ni mo mú wá sí ìmúṣẹ, pé o ti sọ àwọn ìlú olódi di àkójọpọ̀ àwọn òkúta.
27 Shuning bilen u yerde turuwatqanlar küchsizlinip, Yerge qaritip qoyuldi, shermende qilindi; Ular étizdiki ottek, Yumran kök chöplerdek, Ögzidiki ot-chöpler ösmey qurup ketkendek boldi.
Àwọn ènìyàn, tí agbára ti wọ̀ lẹ́wù, ni wọ́n banújẹ́ tí a sì dójútì. Wọ́n dàbí ohun ọ̀gbìn nínú pápá, gẹ́gẹ́ bí ọ̀jẹ̀lẹ̀ èhíhù tuntun, gẹ́gẹ́ bí i koríko tí ó ń hù lórí òrùlé, tí ó jóná kí ó tó dàgbàsókè.
28 Biraq séning olturghiningni, ornungdin turghiningni, chiqip-kirginingni we Manga qarshi ghaljirliship ketkiningni bilimen;
“Ṣùgbọ́n mo mọ ibi tí o wà àti ìgbà tí o wá tí o sì lọ àti bí inú rẹ ṣe ru sí mi.
29 Manga qarshi ghaljirliship ketkenlikingning, hakawurliship ketkenlikingning quliqimgha yetkini tüpeylidin, Men qarmiqimni burningdin ötküzimen, Yüginimni aghzinggha salimen, Özüng kelgen yol bilen séni qayturimen.
Nítorí pé inú rẹ ru sí mi àti nítorí pé orí kunkun rẹ ti dé etí ìgbọ́ mi, Èmi yóò fi ìwọ̀ mi sí ọ ní imú, àti ìjẹ mi sí ọ lẹ́nu, èmi yóò sì jẹ́ kí o padà láti ọ̀nà tí o gbà wá.
30 I [Hezekiya], shu ish sanga alamet bésharet boliduki, — Mushu yili özlükidin ösken, Ikkinchi yili shulardin chiqqanlarmu rizqinglar bolidu; Üchinchi yili bolsa tériysiler, orisiler, üzüm köchetlirini tikisiler; Ulardin chiqqan méwilerni yeysiler.
“Èyí ni yóò ṣe àmì fún ọ, ìwọ Hesekiah: “Ní ọdún yìí, ìwọ yóò jẹ ohun tí ó hù fúnra rẹ̀, àti ní ọdún kejì ohun tí ó jáde láti ara rẹ. Ṣùgbọ́n ní ọdún kẹta, ẹ gbìn kí ẹ sì kórè, ẹ gbin ọgbà àjàrà kí ẹ sì jẹ èso wọn.
31 Yehuda jemetidiki qutulghan qaldisi bolsa yene töwen’ge qarap yiltiz tartidu, Yuqirigha qarap méwe béridu;
Lẹ́ẹ̀kan sí i, àṣẹ́kù láti ilé Juda yóò ta gbòǹgbò nísàlẹ̀ yóò sì ṣo èso lókè.
32 Chünki Yérusalémdin bir qaldisi, Zion téghidin qéchip qutulghanlar chiqidu; Samawi qoshunlarning Serdari bolghan Perwerdigarning otluq muhebbiti mushuni ada qilidu.
Nítorí láti Jerusalẹmu ni àwọn àṣẹ́kù yóò ti wá, àti láti òkè Sioni ni ikọ̀ àwọn tí ó sálà. Ìtara Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni yóò mú èyí ṣẹ.
33 Shunga Perwerdigar Asuriye padishahi toghruluq mundaq deydu: — U ne mushu sheherge yétip kelmeydu, Ne uninggha bir tal oqmu atmaydu; Ne qalqanni kötürüp aldigha kelmeydu, Ne uninggha qarita qashalarnimu yasimaydu.
“Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa wí nípa ọba Asiria, “Òun kì yóò wọ ìlú yìí wá tàbí ta ẹyọ ọfà kan níhìn-ín Òun kì yóò wá síwájú rẹ pẹ̀lú asà tàbí kí ó kó dágunró sílẹ̀ fún un.
34 U qaysi yol bilen kelgen bolsa, Shu yol bilen qaytidu we mushu sheherge kelmeydu, — deydu Perwerdigar.
Nípa ọ̀nà tí ó gbà wá náà ni yóò padà lọ; òun kì yóò wọ inú ìlú yìí,” ni Olúwa wí.
35 — Chünki Özüm üchün we Méning qulum Dawut üchün bu sheherni etrapidiki sépildek qoghdap qutquzimen».
“Èmi yóò dáàbò bo ìlú yìí èmi ó sì gbà á là, nítorí mi àti nítorí Dafidi ìránṣẹ́ mi!”
36 Shuning bilen Perwerdigarning Perishtisi chiqip, Asuriyeliklerning bargahida bir yüz seksen besh ming eskerni urdi. Mana, kishiler etigende ornidin turghanda, ularning hemmisining ölgenlikini kördi!
Lẹ́yìn náà ni angẹli Olúwa jáde lọ ó sì pa ọ̀kẹ́ mẹ́sàn-án ó lé ẹgbẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n ènìyàn ní i ibùdó àwọn Asiria. Nígbà tí àwọn ènìyàn yìí jí ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì gbogbo wọn ti dòkú!
37 Shunga Asuriye padishahi Sennaxérib chékinip, yolgha chiqip, Ninewe shehirige qaytip turdi.
Nítorí náà Sennakeribu ọba Asiria fọ́ bùdó ó sì pẹsẹ̀dà. Òun sì padà sí Ninefe, ó sì dúró síbẹ̀.
38 Shundaq boldiki, u öz buti Nisroqning butxanisida uninggha choqunuwatqanda, oghulliri Adrammelek hem Sharézer uni qilichlap öltürüwetti; andin ular Ararat dégen yurtqa qéchip ketti. Uning oghli Ésarhaddon uning ornida padishah boldi.
Ní ọjọ́ kan, bí ó ti ń jọ́sìn nínú tẹmpili Nisroki òrìṣà rẹ̀, àwọn ọmọ rẹ̀ Adrameleki àti Ṣareseri gé e lulẹ̀ pẹ̀lú idà, wọ́n sì sálọ sí ilẹ̀ Ararati. Bẹ́ẹ̀ ni Esarhadoni ọmọ rẹ̀ sì gba ipò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.