< Hoshiya 12 >

1 Efraimning yégini shamaldur, U sherq shamilini qoghlap yüridu; U künlep yalghanchiliq, zulum-zorluqni köpeytmekte; Ular Asuriye bilen ehde tüzidu, Shuningdek Misirgha may «soghiliri» kötürüp apirilidu.
Efraimu ń jẹ afẹ́fẹ́; o ń lépa afẹ́fẹ́ ìwọ̀-oòrùn ní gbogbo ọjọ́. O sì ń gbèrú nínú irọ́ o dá májẹ̀mú pẹ̀lú Asiria o sì fi òróró olifi ránṣẹ́ sí Ejibiti.
2 Perwerdigarning Yehuda bilenmu bir dewasi bar; U Yaqupni yolliri boyiche jazalaydu; Uning qilmishlirini öz üstige qayturidu.
Olúwa ní ẹjọ́ kan tí yóò bá Juda rò, yóò fì ìyà jẹ Jakọbu gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà rẹ̀ yóò sì sán fún un gẹ́gẹ́ bí i ìṣe rẹ̀.
3 U baliyatquda turup akisini tapinidin tutuwalghan, Öz küchi bilen Xuda bilen élishqan;
Láti inú oyún ni ó ti di arákùnrin rẹ̀ mú ni gìgísẹ̀, àti nípa ipá rẹ̀ ó ni agbára pẹ̀lú Ọlọ́run
4 U berheq Perishte bilen éliship, ghelibe qildi; U yighlidi, Uninggha dua-tilawet qildi; [Xuda] uni Beyt-Elde tépiwaldi, We shu yerde bizge söz qildi;
Ó bá angẹli ja ìjàkadì, ó sì borí rẹ̀, o sọkún, ó sì bẹ̀bẹ̀ fún ojúrere rẹ̀. Ó bá Olúwa ní Beteli, Ó sì bá a sọ̀rọ̀ níbẹ̀,
5 — Yeni Perwerdigar, samawi qoshunlarning Serdari bolghan Xuda, — «Perwerdigar» bolsa Uning xatire namidur!
àní Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun; Olúwa ni orúkọ ìrántí rẹ̀.
6 Shunga sen, Xudaying arqiliq, Uning yénigha qayt; Méhribanliq we adaletni qolungdin berme, Xudayinggha ümid baghlap, Uni izchil kütkin.
Ṣùgbọ́n ìwọ gbọdọ̀ padà sọ́dọ̀ Ọlọ́run rẹ̀; di ìfẹ́ àti ìdájọ́ òdodo mú kí ẹ sì dúró de Ọlọ́run yín nígbà gbogbo.
7 Mana bu sodiger! Uning qolida aldamchiliq tarazisi bar; U bozek qilishqa amraqtur.
Oníṣòwò ń lo òsùwọ̀n èké o fẹ́ràn láti rẹ́ ni jẹ.
8 Efraim: «Men derweqe béyidim, Özümge köp bayliqlarni toplidim; Biraq ular barliq ejirlirimde mendin héch gunahiy qebihlikni tapalmaydu!» — deydu.
Efraimu gbéraga, “Èmi ní ìní fún ara mi, mo sì ti di ọlọ́rọ̀, pẹ̀lú gbogbo ọrọ̀ mi yìí, wọn kò le ká àìṣedéédéé tàbí ẹ̀ṣẹ̀ kankan mọ́ mi lọ́wọ́.”
9 Biraq Misir zéminidin tartip Men Perwerdigar séning Xudaying bolghanmen, Men séni yene «[kepiler] héyti»dikidek chédirlarda turghuzimen!
“Èmi ni Olúwa Ọlọ́run rẹ; ẹni tí ó mu ọ jáde wá láti ilẹ̀ Ejibiti; èmi yóò tún mú yín gbé nínú àgọ́ bí i ọjọ́ àjọ̀dún tí a yàn wọ̀n-ọn-nì.
10 «Men peyghemberlerge söz qilghanmen, Alamet körünüshlerni köpeytkenmen, Shundaqla peyghemberler arqiliq temsillerni körsetkenmen.
Mo sọ fún àwọn wòlíì, mo fi ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìran hàn wọ́n mo sì pa òwe láti ẹnu wòlíì wọn.”
11 Giléad qebihmu? Ular berheq peqet yarimaslardur! Ular Gilgalda torpaqlarni qurbanliq qilidu; Ularning qurban’gahliri derweqe étiz qirliridiki tash döwiliridek köptur!
Gileadi ha burú bí? Àwọn ènìyàn rẹ̀ jẹ́ asán. Ǹjẹ́ wọ́n ń fi akọ màlúù rú ẹbọ ní Gilgali? Gbogbo pẹpẹ wọ́n sì dàbí ebè nínú aporo oko.
12 (Yaqup Suriyege qéchip ketti, Shu yerde Israil xotun élish üchün ishligen; Berheq, xotun élish üchün u qoylarni baqqanidi).
Jakọbu sálọ si orílẹ̀-èdè Aramu; Israẹli sìn kí o tó fẹ́ ìyàwó ó ṣe ìtọ́jú ẹran láti fi san owó ìyàwó.
13 Perwerdigar yene peyghember arqiliq Israilni Misirdin chiqirip qutquzghan, Peyghember arqiliq uningdin xewermu alghan.
Olúwa lo wòlíì kan láti mú Israẹli jáde wá láti Ejibiti, nípasẹ̀ wòlíì kan ó ṣe ìtọ́jú rẹ̀.
14 Efraim [Xudaning] qehrini intayin qattiq qozghighan; Uning Rebbi u tökken qan qerzni uning gedinige artidu, Shermendilik-ahanetini öz béshigha qayturidu.
Ṣùgbọ́n Efraimu ti mú un bínú gidigidi; Olúwa rẹ̀ yóò sì fi ẹ̀bi ìtàjẹ̀ sílẹ̀ sí orí rẹ̀ òun yóò sì san án padà fún un nítorí ìwà ẹ̀gàn an rẹ̀.

< Hoshiya 12 >