< Yaritilish 32 >

1 Yaqup öz yoligha kétip baratti; yolda Xudaning perishtiliri uninggha uchridi.
Jakọbu sì ń bá ọ̀nà tirẹ̀ lọ, àwọn angẹli Ọlọ́run sì pàdé rẹ̀.
2 Yaqup ularni körüp: — Bu jay Xudaning bargahi iken! — dep, bu jayning namini «Mahanaim» dep qoydi.
Nígbà tí Jakọbu rí wọn, ó wí pé, “Àgọ́ Ọlọ́run ni èyí!” Ó sì pe orúkọ ibẹ̀ ni Mahanaimu.
3 Andin Yaqup Séir zéminidiki «Édom yayliqi»gha, akisi Esawning qéshigha aldin xewerchilerni ewetip,
Jakọbu sì rán àwọn oníṣẹ́ ṣáájú ara rẹ̀ sí Esau arákùnrin rẹ̀ ni ilẹ̀ Seiri ní orílẹ̀-èdè Edomu.
4 ulargha jékilep: — Siler xojamgha, yeni Esawgha: «Keminiliri Yaqup mundaq dédi: — Men Labanning qéshida musapir bolup, ta mushu waqitqiche turdum.
Ó pàṣẹ fún wọn pé, “Èyí ni ẹ̀yin yóò wí fún Esau olúwa mi, Jakọbu ìránṣẹ́ rẹ̀ wí pé, ‘Mo ti ṣe àtìpó lọ́dọ̀ Labani títí ó fi di àsìkò yìí.
5 Emdi mende kala, éshek we qoylar, qul-dédeklermu bar; men özlirining neziride iltipat taparmenmikin dep xojamgha xewer yetküzüshni layiq kördüm», denglar, — dédi.
Mo ní màlúù, kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àgùntàn àti ewúrẹ́. Mo tún ni àwọn ìránṣẹ́kùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin. Mo ń ránṣẹ́ yìí sí olúwa mi kí èmi le è rí ojúrere rẹ.’”
6 Xewerchiler Yaqupning yénigha yénip kélip: — Biz akiliri Esawning qéshigha barduq; u töt yüz kishini élip, silining aldilirigha kéliwatidu, — dédi.
Nígbà tí àwọn ìránṣẹ́ náà padà tọ Jakọbu wà, wọ́n wí pé “Esau arákùnrin rẹ ti múra láti wá pàdé rẹ pẹ̀lú irinwó ọkùnrin.”
7 Yaqup nahayiti qorqup, ghem-ghussige chüshüp ademlirini qoy, kala we tögilirige qoshup, ikki topqa ayridi.
Pẹ̀lú ìbẹ̀rù àti ìbànújẹ́ ni Jakọbu fi pín àwọn ènìyàn tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀ sí ìpín méjì, ó sì pín àwọn ẹran ọ̀sìn, agbo ẹran àti ìbákasẹ bẹ́ẹ̀ pẹ̀lú.
8 U: — «Eger Esaw kélip bir topimizgha hujum qilsa, yene bir top qéchip qutulup qalar» — dep oylidi.
Nítorí ó rò ó nínú rẹ̀ pé, “Bí Esau bá kọjú ogun sí ìpín kan, ìpín kejì yóò sá àsálà.”
9 Andin Yaqup mundaq dua qildi: — I atam Ibrahimning Xudasi we atam Ishaqning Xudasi! Manga: «Öz zémining we uruq-tughqanliringning qéshigha yénip ketkin, sanga yaxshiliq qilimen» dep wede qilghan Perwerdigar!
Nígbà náà ni Jakọbu gbàdúrà pe, “Ọlọ́run Abrahamu baba mi, àti Ọlọ́run Isaaki baba mi, Olúwa tí ó wí fún mi pé, ‘Padà sí orílẹ̀-èdè rẹ àti sọ́dọ̀ àwọn ìbátan rẹ, èmi yóò sì ṣe ọ́ ní rere,’
10 — Men Séning Öz qulunggha körsetken özgermes barliq méhribanliqing we barliq wapadarliqing aldida héchnéme emesmen; chünki men bu Iordan deryasidin ötkinimde yalghuz bir hasam bar idi. Emdi men ikki top adem bolup qaytiwatimen.
èmi kò tilẹ̀ yẹ fún àánú àti òtítọ́ tí o ń fihàn fún ìránṣẹ́ rẹ. Nítorí pé, kìkì ọ̀pá mi ni mo mu kúrò ni ilé kọjá Jordani yìí, ṣùgbọ́n nísinsin yìí, èmi ti di ẹgbẹ́ méjì.
11 Ötünüp qalay, méni akam Esawning qolidin qutquzghaysen; chünki u kélip men bilen xotun-balilirimni öltürüwétemdikin, dep qorqimen.
Jọ̀wọ́ Olúwa gbà mí lọ́wọ́ Esau arákùnrin mi, nítorí ẹ̀rù ń bà mí pé yóò wá dojú ìjà kọ mí àti àwọn ìyàwó pẹ̀lú àwọn ọmọ mi.
12 Sen: «Men jezmen sanga zor yaxshiliq qilip, séning neslingni déngizdiki qumdek heddi-hésabsiz köp qilimen», dégeniding, — dédi.
Ṣùgbọ́n ìwọ ti ṣèlérí pé, ‘Èmi yóò mú ọ gbilẹ̀, èmi yóò sì mú kí àwọn ìran rẹ dà bì í yanrìn òkun tí ẹnikẹ́ni kò le è kà.’”
13 U shu kéchisi shu yerde qonup qaldi; andin u qol ilikidiki mallardin élip, akisi Esawgha ikki yüz öchke, yigirme téke, ikki yüz saghliq, yigirme qochqar, ottuz chishi tögini taylaqliri bilen, qiriq inek, on buqa, yigirme mada éshek, on hangga éshekni sowghat qilip teyyarlap,
Ó sì lo òru ọjọ́ náà níbẹ̀. Ó mú ẹ̀bùn fún Esau arákùnrin rẹ̀ nínú ohun ìní rẹ̀.
Igba ewúrẹ́, ogún òbúkọ, igba àgùntàn, ogún àgbò,
ọgbọ̀n abo ìbákasẹ pẹ̀lú ọmọ wọn, ogójì abo màlúù àti akọ màlúù mẹ́wàá, ogún abo kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ àti akọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ mẹ́wàá.
16 Bularni ayrim-ayrim top qilip xizmetkarlirining qoligha tapshurup, ulargha jékilep: — Siler mendin burun méngip, her topning arisida ariliq qoyup heydep ménginglar, — dédi.
Ó sì fi wọ́n lé àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ lọ́wọ́ ní ọ̀wọ̀ọ̀wọ́, ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ lọ ṣáájú mi, kí ẹ sì jẹ́ kí àlàfo wà láàrín ọ̀wọ́ agbo ẹran kọ̀ọ̀kan sí èkejì.”
17 U eng aldidiki top bilen mangghan kishike emr qilip: — Akam Esaw sanga uchrighanda, eger u sendin: «Kimning adimisen? Qeyerge barisen? Aldingdiki janiwarlar kimning?» — dep sorisa,
Ó pàṣẹ fún èyí tí ó ṣáájú pé, “Nígbà tí arákùnrin mi Esau bá pàdé rẹ tí ó sì béèrè ẹni tí ìwọ í ṣe àti ibi tí ìwọ ń lọ àti ẹni tí ó ni agbo ẹran tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ,
18 Undaqta sen jawab bérip: «Bular keminiliri Yaqupning bolup, xojam Esawgha ewetken sowghattur. Mana, u özimu keynimizdin kéliwatidu» — dégin, dédi.
nígbà náà ni ìwọ yóò wí pé, ‘Ti ìránṣẹ́ rẹ Jakọbu ni wọ́n. Ẹ̀bùn ni ó sì fi wọ́n ṣe fún Esau olúwa mi, òun pàápàá ń bọ̀ lẹ́yìn wa.’”
19 Shu teriqide u ikkinchi, üchinchi we ulardin kéyinki padilarni heydep mangghuchi kishilergimu oxshash emr qilip: — Esaw sizlerge uchrighanda, silermu uninggha shundaq denglar, andin: — Mana, keminiliri Yaqup özimu arqimizdin kéliwatidu, — denglar, dédi; chünki u: — Men aldimda barghan sowghat bilen uni méni kechürüm qildurup, andin yüzini körsem, méni qobul qilarmikin, — dep oylighanidi.
Jakọbu sì pàṣẹ bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ fún ọ̀wọ́ kejì àti ẹ̀kẹta àti àwọn tókù tí ó tẹ̀lé agbo ẹran pé, “Ohun kan ṣoṣo yìí náà ni kí ẹ sọ fún Esau nígbà tí ẹ bá pàdé rẹ̀.
Kí ẹ rí i dájú wí pé, ẹ sọ fún un pé, ‘Jakọbu ìránṣẹ́ rẹ̀ ń bọ̀ lẹ́yìn wa.’” Èrò Jakọbu ni láti fi àwọn ẹ̀bùn wọ̀nyí tu Esau lójú pé bóyá inú Esau yóò dùn sí òun nígbà tí àwọn bá pàdé.
21 Shundaq qilip sowghat aldin ewetildi; u shu kéchisi bargahda qonup qaldi.
Nítorí náà ẹ̀bùn Jakọbu ṣáájú rẹ̀ lọ, Jakọbu pàápàá sì lo òru ọjọ́ náà nínú àgọ́.
22 U shu kéchide qopup, ikki ayali we ikki dédiki we on bir oghlini élip, Yabbok kéchikidin ötüp ketti.
Ó sì dìde ní òru ọjọ́ náà, ó mú àwọn aya rẹ̀ méjèèjì, àwọn ìránṣẹ́bìnrin rẹ̀ méjèèjì, àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ mọ́kọ̀ọ̀kànlá, wọ́n sì kọjá ní ìwọdò Jabbok.
23 U ularni éqindin ötküzdi, shundaqla hemme teelluqinimu u qarshi terepke ötküzdi.
Lẹ́yìn ìgbà tí ó ti rán wọn kọjá odò tán sí òkè odò, ó sì rán àwọn ohun ìní rẹ̀ kọjá pẹ̀lú.
24 Yaqup bolsa bu qatta yalghuz qaldi; bir zat kélip shu yerde uning bilen tang atquche chélishti.
Ó sì ku Jakọbu nìkan, ọkùnrin kan sì bá a ja ìjàkadì títí ó fi di àfẹ̀mọ́júmọ́.
25 Lékin bu zat uni yéngelmeydighanliqini körüp, uning yotisining yiriqigha qolini tegküzüp qoydi; shuning bilen ular chélishiwatqanda Yaqupning yotisi qazandin chiqip ketti.
Ṣùgbọ́n nígbà tí ọkùnrin náà rí i pé òun kò le borí Jakọbu, ó fọwọ́ kàn án ní ọ̀ọ́kán ibi tí eegun itan ti bẹ̀rẹ̀, egungun náà sì yẹ̀ kúrò lórí ike, bí ó ti ń ja ìjàkadì.
26 U zat: — Méni qoyup bergin, chünki tang atay dep qaldi, dédi. — Sen méni beriketlimigüche, séni qoyup bermeymen, dédi Yaqup.
Nígbà náà ni ọkùnrin náà wí fún un pé, “Jẹ́ kí ń máa lọ, nítorí ojúmọ́ ti mọ́.” Ṣùgbọ́n Jakọbu dá a lóhùn pé, “Èmi kò ní jẹ́ kí o lọ, àyàfi bí o bá súre fún mi.”
27 U uningdin: — Éting néme? dep soridi. U: étim Yaqup, — dédi.
Ọkùnrin náà béèrè orúkọ rẹ̀. Ó sì wí fún un pé, “Jakọbu ni òun ń jẹ́.”
28 U uninggha: — Séning éting buningdin kéyin Yaqup bolmay, belki Israil bolidu; chünki sen Xuda bilenmu, insan bilenmu éliship ghalib kelding, — dédi.
Nígbà náà ni ọkùnrin náà wí pé, “Orúkọ rẹ kì yóò jẹ́ Jakọbu mọ́ bí kò ṣe Israẹli, nítorí pé ìwọ ti bá Ọlọ́run àti ènìyàn jà, o sì borí.”
29 Andin Yaqup uningdin: — Namingni manga dep bergin, déwidi, u: — Némishqa méning namimni soraysen? — dédi we shu yerde uninggha bext-beriket ata qildi.
Jakọbu sì bẹ ọkùnrin náà pé, “Sọ orúkọ rẹ fún mi.” Ṣùgbọ́n ọkùnrin náà sá à dáhùn pé, “Èéṣe tí o ń béèrè orúkọ mi?” Lẹ́yìn náà ó súre fún Jakọbu níbẹ̀.
30 Shuning bilen Yaqup: — Xudani yüzmu-yüz körüp, jénim qutulup qaldi, dep u jayning namini «Peniel» dep atidi.
Jakọbu sì pe orúkọ ibẹ̀ ní Penieli pé, “Mo rí Ọlọ́run ní ojúkojú, síbẹ̀ a dá ẹ̀mí mi sí.”
31 U Penieldin ötüp mangghanda, kün uning üstibéshini yorutti; emma u yotisi tüpeylidin aqsap mangatti.
Bí ó sì ti ń kọjá Penieli, oòrùn ràn bá a, ó sì ń tiro nítorí itan rẹ̀.
32 Bu sewebtin Israillar bügün’giche yotining ügisidiki peyni yémeydu; chünki shu Zat Yaqupning yotisining yiriqigha, yeni uning péyige qolini tegküzüp qoyghanidi.
Ìdí nìyí tí àwọn ọmọ Israẹli kì í fi í jẹ iṣan tí ó wà ní ọ̀ọ́kán ibi tí eegun itan ti bẹ̀rẹ̀ títí di òní olónìí, nítorí níbi iṣan náà ni a ti fọwọ́ kan ibi tí egungun itan Jakọbu ti bẹ̀rẹ̀.

< Yaritilish 32 >