< Ezakiyal 5 >
1 «We sen, i insan oghli, özüng ötkür bir qilichni al; uni ustira süpitide ishlitip, chéching we saqilinggha sürtüp qoy; andin tarazini élip alghan chachlarni teng bölgin.
“Báyìí, ọmọ ènìyàn, mú ìdá tí ó mú kí o sì fi ṣe abẹ ìfárí onígbàjámọ̀, kí o fi fá irun orí àti irùngbọ̀n rẹ. Fi irun yìí sórí ìwọ̀n kí o sì pín in.
2 Muhasire künliri tügigende, üchtin birini sheher ichide köydürgin; yene üchtin birini élip sheher etrapigha chépiwetkin; yene üchtin birini shamalgha soriwetkin; Men bir qilichni sughurup ularni qoghlaymen.
Nígbà tí ọjọ́ ìgbóguntì bá parí, sun ìdákan nínú ìdámẹ́ta irun yìí níná láàrín ìlú. Mú ìdákan nínú mẹ́ta kí o fi idà bù ú káàkiri ìlú. Kí o sì tú ìdákan yòókù ká sínú afẹ́fẹ́. Nítorí pé pẹ̀lú idà ni èmi yóò máa lé wọn ká.
3 Sen yene ulardin birnechche talni élip tonungning péshige tiqip qoyghin;
Ṣùgbọ́n mú díẹ̀ nínú irun yìí kí o sì ta á mọ́ etí aṣọ rẹ.
4 bulardin yene nechche talni élip ot ichige tashlap köydüriwetkin; bulardin pütün Israil jemetige ot tutiship kétidu».
Tún ju díẹ̀ nínú irun yìí sínú iná, kí o sun ún níná. Torí pé láti ibẹ̀ ni iná yóò ti jáde lọ sí gbogbo ilé Israẹli.
5 Reb Perwerdigar mundaq deydu: — Mana, bu Yérusalém; Men uni ellerning del otturisigha orunlashturdum; bashqa memliketler uning öpchöriside turidu;
“Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Èyí ní Jerusalẹmu, tí mo gbé kalẹ̀ sí àárín àwọn Orílẹ̀-èdè, pẹ̀lú àwọn ìlú gbogbo tí o yí i ká.
6 Biraq u Méning hökümlirimge qarshiliship rezillikte ellerdinmu ashuruwetti, belgilimilirimge qarshilishishta öpchörisidiki memliketlerdinmu ashuruwetti; chünki Méning hökümlirimni ular ret qildi, Méning belgilimilirim bolsa, ularda aqmaydu.
Síbẹ̀ nínú ìwà búburú rẹ ó ti ṣọ̀tẹ̀ si òfin àti ìlànà mi ju àwọn orílẹ̀-èdè àti àwọn ilẹ̀ tó yí i ká lọ. Ó ti kọ òfin mi sílẹ̀, o kò sì pa ìlànà mi mọ́.
7 Shunga Reb Perwerdigar mundaq deydu: — Chünki siler öpchörenglerdiki ellerdinmu bekrek bashbashtaqliq qilghanliqinglardin, Méning belgilimilirimde mangmasliqinglardin we hökümlirimni tutmasliqinglardin, hetta öpchörenglerdiki ellerning hökümliridimu mangmasliqinglar tüpeylidin,
“Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Nítorí pé ẹ̀yin ti ṣe àìgbọ́ràn ju àwọn orílẹ̀-èdè tó yí yín ká lọ, tí ẹ kò sì tẹ̀lé ìlànà mi tàbí kí o pa òfin mi mọ́. O kò tilẹ̀ túnṣe dáradára tó àwọn orílẹ̀-èdè tó yí ọ ká.
8 Emdi Reb Perwerdigar mundaq deydu: — «Mana, Men Özümki sanga qarshimen, [i Yérusalém]; séning aranggha ellerning köz alidila jazalarni yürgüzimen;
“Nítorí náà báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Èmi gan an lòdì sí ọ, Jerusalẹmu, èmi yóò sì jẹ ọ́ ní yà lójú àwọn orílẹ̀-èdè tó yí ọ ká.
9 We séning barliq yirginchlikliring tüpeylidin arangda Özüm qilip baqmighan hemde kelgüsi ikkinchi qilmaydighan ishni qilimen.
Nítorí gbogbo ohun ìríra rẹ, èmi yóò ṣe ohun tí n kò tí ì ṣe rí láàrín rẹ àti èyí tí n kò ní í ṣe irú rẹ̀ mọ́.
10 Shuning bilen atilar öz balilirini yeydighan bolidu, balilar öz atilirini yeydighan bolidu; we Men sanga jazalarni yürgüzimen, we séning barliq qalghanliringning hemmisini her tereptin chiqqan shamalgha soriwétimen.
Nítorí náà láàrín rẹ àwọn baba yóò máa jẹ ọmọ wọn, àwọn ọmọ náà yóò máa jẹ baba wọn. Èmi yóò jẹ ọ́ ní yà, èmi yóò sì tú àwọn tó bá ṣẹ́kù ká sínú ẹ̀fúùfù.
11 Shunga, Men hayatim bilen qesem qilimenki, — deydu Reb Perwerdigar — chünki sen Méning muqeddes jayimni özüngning barliq lenetlik nersiliring hem barliq yirginchlikliring bilen bulghighining tüpeylidin, berheq, Men silerni qirghin qilimen; közüm sanga rehim qilmaydu, ichimnimu sanga aghritmaymen.
Nítorí náà, Olúwa Olódùmarè wí pé, bí mo ṣe wà láààyè, nítorí pé ìwọ ti sọ ibi mímọ́ mi di àìmọ́ pẹ̀lú àwọn àwòrán ẹ̀gbin àti àwọn ohun ìríra rẹ, èmi yóò mú ojúrere mi kúrò lára rẹ, èmi kò ní í da ọ sí, bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò wò ọ́ pẹ̀lú àánú mọ́.
12 Sheherdikilerdin üchtin bir qismi waba késili bilen ölidu hemde aranglarda bolidighan acharchiliqtin béshini yeydu; üchtin bir qismi öpchörenglerde qilichlinidu; we Men üchtin bir qismini her tereptin chiqqan shamalgha soriwétimen, andin bir qilichni ghilaptin sughurup ularni qoghlaymen.
Ìdámẹ́ta nínú àwọn ènìyàn rẹ yóò kú nípa àjàkálẹ̀-ààrùn tàbí kí ìyàn run wọ́n: ìdámẹ́ta yóò ṣubú nípa idà lẹ́yìn odi rẹ, èmi yóò sì tú ìdámẹ́ta yòókù ká sínú ẹ̀fúùfù, èmi yóò sì máa fi idà lé wọn.
13 Shuning bilen Méning ghezipim bésiqidu, Méning qehrimni ularning üstige chüshürüp qon’ghuzup, pighandin chiqimen; Men Öz qehrimni ular üstige töküp tügetkendin kéyin, ular Men Perwerdigarning rezillikke chidimaydighan otumdin söz qilghanliqimni tonup yétidu.
“Ìbínú mi yóò sì dúró, bẹ́ẹ̀ ni ìbínú gbígbóná mi yóò sì rọlẹ̀, èmi yóò sì ti gba ẹ̀san mi. Nígbà tí mo bá sì parí ìbínú mi lórí wọn, wọn ó mọ̀ pé, Èmi Olúwa ti sọ̀rọ̀ nínú ìtara mi.
14 We Men séning öpchörengdiki eller arisida hemde ötüp kétiwatqanlarning köz aldida séni weyrane qilimen we mesxire obyékti qilimen;
“Èmi yóò fi ọ́ ṣòfò, èmi yóò sì sọ ọ́ di ẹ̀gàn fún àwọn orílẹ̀-èdè tó yí ọ ká, àti lójú àwọn tó ń kọjá.
15 séning üstüngge ghezep hem qehr we qehrlik eyibler bilen jazalarni yürgüzginimde sen öpchörengdiki ellerge xorluq we tapa-tenining obyékti, bir ibret hem alaqzadilik chiqarghuchi bolisen; chünki Men Perwerdigar shundaq söz qildim!
O ó wá di ẹ̀gàn, ẹ̀sín àti ẹ̀kọ̀ àti ohun ẹ̀rù àti ìyanu fún àwọn orílẹ̀-èdè tó yí ọ ká, nígbà tí mo bá fìyà jẹ ọ́ nínú ìbínú àti nínú ìbínú gbígbóná mi. Èmi Olúwa ni ó sọ bẹ́ẹ̀.
16 Men ulargha halaket élip kelgüchi, acharchiliq zeherlik oqlirini yaghdurghinimda, silerning üstünglardiki acharchiliqni kücheytimen, we yölenchük bolghan néningni qurutiwétimen.
Nígbà tí èmi ó rán ọfà búburú ìyàn sí wọn, èyí tí yóò jẹ́ fún ìparun wọn. Èmí tí èmi yóò rán run yín. Èmí yóò sì sọ ìyàn di púpọ̀ fún yín. Èmí yóò sì ṣẹ́ ọ̀pá oúnjẹ yín.
17 We üstünglargha öz baliliringlarni özünglardin juda qilidighan acharchiliq hem yirtquch haywanlarni ewetimen; waba késilliri we qan tökküchiler aranglargha yamrap kétidu; üstünglargha qilich chüshürimen; Menki Perwerdigar söz qildim!».
Èmi yóò rán ìyàn àti ẹranko búburú sí i yín, wọn yóò fi yín sílẹ̀ ni àìlọ́mọ. Àjàkálẹ̀-ààrùn àti ìtàjẹ̀ sílẹ̀ yóò kọjá láàrín yín. Èmi yóò si mú idà wá sórí rẹ. Èmi Olúwa ló sọ bẹ́ẹ̀.”