< Захарія 7 >

1 І сталося, у четвертому році царя Да́рія було Господнє слово до Заха́рія четвертого дня дев'ятого місяця, кіслева.
Ó sì ṣe ní ọdún kẹrin Dariusi ọba, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ́ Sekariah wá ni ọjọ́ kẹrin oṣù Kisleu tí ń ṣe oṣù kẹsànán.
2 І послав Бет-Ел Сар'ецера й Реґем-Ме́леха та людей його, щоб Господа вблага́ти,
Nígbà tí wọ́n ènìyàn Beteli rán Ṣareseri àti Regemmeleki, àti àwọn ènìyàn wọn sí ilé Ọlọ́run láti wá ojúrere Olúwa.
3 щоб сказати священикам, які в домі Господа Саваота, та пророкам, говорячи: „Чи я маю плакати п'ятого місяця та по́стити, як я робив це багато ро́ків?“
Àti láti bá àwọn àlùfáà tí ó wà ní ilé Olúwa àwọn ọmọ-ogun, àti àwọn wòlíì sọ̀rọ̀ wí pé, “Ṣé kí èmi ó sọkún ní oṣù karùn-ún kí èmi ya ara mi sọ́tọ̀, bí mo ti ń ṣe láti ọdún mélòó wọ̀nyí wá bí?”
4 І було́ слово Господа Саваота таке:
Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa àwọn ọmọ-ogun tọ̀ mí wá pé,
5 „Говори до всього наро́ду землі й до священиків, кажучи: Якщо ви по́стили та лементува́ли п'ятого й сьомого місяця, і то сімдеся́т років чи то ви по́стили для Мене?
“Sọ fún gbogbo àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà, àti fún àwọn àlùfáà pé, ‘Nígbà tí ẹ̀yin gbààwẹ̀, tí ẹ sì ṣọ̀fọ̀ ní oṣù karùn-ún àti keje, àní fun àádọ́rin ọdún wọ̀nyí, ǹjẹ́ èmi ni ẹ̀yin ha ń gbààwẹ̀ yín fún?
6 А коли ви їсте та коли ви п'єте́, чи ж то не собі ви їсте й не собі ви п'єте́?
Nígbà tí ẹ sì jẹ, àti nígbà tí ẹ mu, fún ara yín kọ́ ni ẹ̀yin jẹ, àti fún ara yín kọ́ ni ẹ̀yin mú bí?
7 Чи ж це не ті слова́, які Господь виголо́шував через да́вніх пророків, коли Єрусалим був насе́лений та спокійний, і його міста́ навколо нього, і пі́вдень, і рівни́на були насе́лені?“
Wọ̀nyí kọ́ ni ọ̀rọ̀ ti Olúwa ti kígbe láti ọ̀dọ̀ àwọn wòlíì ìṣáájú wá, nígbà tí a ń gbé Jerusalẹmu, tí ó sì wà ní àlàáfíà, pẹ̀lú àwọn ìlú rẹ̀ tí ó yí i káàkiri, nígbà tí a ń gbé gúúsù àti pẹ̀tẹ́lẹ̀.’”
8 І було до Заха́рія слово Господнє таке:
Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Sekariah wá, wí pé,
9 „Так говорить Господь Саваот, промовляючи: „Судіть суд по правді, і чиніть один о́дному милосердя та милість.
“Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé, ‘Ṣe ìdájọ́ òtítọ́, kí ẹ sì ṣe àánú àti ìyọ́nú olúkúlùkù sí arákùnrin rẹ̀.
10 А вдови́ й сироти́, чужи́нця та вбогого не гнобі́ть, і не ду́майте зла один о́дному в серці своєму!“
Má sì ṣe ni opó lára tàbí aláìní baba, àlejò, tàbí tálákà; kí ẹnikẹ́ni nínú yín má ṣe gbèrò ibi ní ọkàn sí arákùnrin rẹ̀.’
11 Та вони не хотіли слу́хати, і відверну́ли своє раме́но від Мене, а ву́ха свої вчинили тяжки́ми, щоб не слу́хати,
“Ṣùgbọ́n wọ́n kọ̀ láti gbọ́, wọ́n sì gún èjìká, wọ́n sì pa ẹ̀yìn dà, wọ́n di etí wọn, kí wọn má ba à gbọ́.
12 і серце своє зробили кре́менем, щоб не слу́хати Зако́ну, та тих слів, що послав Господь Саваот Своїм Духом через давніх пророків. І був великий гнів від Господа Саваота.
Wọ́n sé ọkàn wọn bí òkúta líle, kí wọn má ba à gbọ́ òfin, àti ọ̀rọ̀ tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti fi ẹ̀mí rẹ̀ rán nípa ọwọ́ àwọn wòlíì ìṣáájú wá. Ìbínú ńlá sì dé láti ọ̀dọ̀ Olúwa àwọn ọmọ-ogun.
13 „І сталося, як Я кликав, то вони не слу́халися, так вони будуть кликати, та не буду Я слухати, каже Господь Савао́т.
“‘Ó sì ṣe, gẹ́gẹ́ bí ó ti kígbe, tí wọn kò sì fẹ́ gbọ́, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n kígbe, tí èmi kò sì fẹ́ gbọ́,’ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
14 І розвіяв Я їх по всіх наро́дах, які не знали їх, а край був спусто́шений по них, так що не було́ такого, хто б перехо́див чи верта́вся, і вони зробили улю́блений край спусто́шенням“.
‘Mo sì fi ìjì tú wọn ká sí gbogbo orílẹ̀-èdè tí wọn kò mọ̀. Ilẹ̀ náà sì dahoro lẹ́yìn wọn, tí ẹnikẹ́ni kò là á kọjá tàbí kí ó padà bọ̀, wọ́n sì sọ ilẹ̀ ààyò náà dahoro.’”

< Захарія 7 >