< Псалми 106 >

1 Алілу́я!
Yin Olúwa! Ẹ fi ìyìn fún Olúwa, nítorí tí ó ṣeun. Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa nítorí tí ó ṣeun, nítorí tí ìfẹ́ rẹ̀ dúró láéláé.
2 Хто розка́же про ве́лич Господню, розповість усю славу Його́?
Ta ni ó lè ròyìn iṣẹ́ agbára Olúwa, ta ní lè sọ nípa ìyìn rẹ̀?
3 Блаженні, хто де́ржиться права, хто чинить правду кожного ча́су!
Ìbùkún ni fún àwọn tí ń pa ìdájọ́ mọ́? Ẹni tí n ṣe ohun tí ó tọ́.
4 Згадай мене, Господи, в ласці Своїй до народу Свого́, відві́дай мене спасі́нням Своїм,
Rántí mi, Olúwa, nígbà tí o bá fi ojúrere rẹ hàn, wá sí ìhà mi nígbà tí ìwọ bá gbà wọ́n,
5 щоб побачити добре вибра́нців Твоїх, щоб я ті́шився радощами Твого наро́ду, і хвалився зо спа́дком Твоїм!
kí èmi kí ó lè jẹ ìgbádùn àlàáfíà àwọn tí ìwọ ti yàn, kí èmi kí ó sì darapọ̀ mọ́ àwọn ènìyàn, ìní rẹ láti jọ yìn ọ́ lógo.
6 Ми згрішили з батька́ми своїми, скриви́ли, неправди́ве чинили.
Àwa ti dẹ́ṣẹ̀ gẹ́gẹ́ bí àwọn baba wa ti ṣe, àwa ti ṣe ohun tí kò dá a, a sì ti hùwà búburú.
7 Не зважа́ли на чу́да Твої батьки наші в Єгипті, многоти́ Твоїх ласк не прига́дували й бунтува́лись над морем, над морем Черво́ним.
Nígbà tí àwọn baba wa wà ní Ejibiti, iṣẹ́ ìyanu rẹ kò yé wọn, wọn kò rántí ọ̀pọ̀lọpọ̀ àánú rẹ, gẹ́gẹ́ bí wọ́n ṣe ṣọ̀tẹ̀ sí ọ níbi Òkun, àní níbi Òkun Pupa.
8 Та Він ради Ймення Свого їх спас, щоб виявити Свою силу.
Ṣùgbọ́n o gbà wọ́n là nítorí orúkọ rẹ láti jẹ́ kí agbára ńlá rẹ di mí mọ̀.
9 Він кли́кнув на море Червоне — і ви́сохло, і Він їх повів через мо́рські глиби́ни, немов по пустині!
O bá Òkun Pupa wí, ó sì gbẹ; o sì mú wọn la ìbú já bí aginjù.
10 І Він спас їх з руки неприя́теля, визволив їх з руки ворога, —
O gbà wọ́n là kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wọn, láti ọwọ́ ọ̀tá ni o ti gbà wọ́n.
11 і закрила вода супроти́вників їхніх, жоден з них не зоста́вся!
Omi ya lu àwọn ọ̀tá wọn; bẹ́ẹ̀ ni kò sí èyí tí ó yè nínú wọn.
12 Тоді то в слова́ Його вві́рували, виспі́вували Йому славу.
Nígbà náà wọn gba ìpinnu rẹ gbọ́ wọ́n sì kọrin ìyìn rẹ.
13 Та скоро забули вони Його чин, не чекали пора́ди Його́,
Ṣùgbọ́n wọn kò pẹ́ gbàgbé ohun tí o ṣe wọn kò sí dúró gba ìmọ̀ràn rẹ.
14 і пала́ли в пустині жада́нням, і Бога в пустині ізнов випробо́вували,
Nínú aginjù ni wọ́n tí ṣe ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́, nínú aṣálẹ̀, wọ́n dán Ọlọ́run wò.
15 і Він їхнє жада́ння їм дав, але худість послав в їхню душу.
Nígbà náà, ó fún wọn ní ohun tí wọ́n béèrè fún ṣùgbọ́n ó rán àìsàn búburú sí wọn.
16 Та Мойсею поза́здрили в та́борі, й Ааронові, святому Господньому.
Nínú ibùdó ni wọ́n ṣe ìlara Mose pẹ̀lú Aaroni, ẹni tí ó jẹ́ mímọ́ sí Olúwa.
17 Розкрилась земля — і Дата́на погли́нула, Авіро́нові збори накрила,
Ilẹ̀ la ẹnu ó sì gbé Datani mì ó bo ẹgbẹ́ Abiramu mọ́lẹ̀.
18 і огонь запалав на їхніх збо́рах, — і по́лум'я те попали́ло безбожних.
Ọwọ́ iná yọ ní ẹgbẹ́ àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀; iná jo àwọn ènìyàn búburú.
19 Зробили тельця́ на Хори́ві, і били поклони бовва́нові ви́литому, —
Ní Horebu wọ́n ṣe ẹgbọrọ màlúù wọ́n sì sin òrìṣà tí a ṣe láti ara irin.
20 і змінили вони свою славу на образ вола́, що траву пожирає,
Wọ́n pa ògo wọn dà sí àwòrán màlúù, tí ń jẹ koríko.
21 забули про Бога, свого Спасителя, що велике в Єгипті вчинив,
Wọ́n gbàgbé Ọlọ́run, ẹni tí ó gbà wọ́n ẹni tí ó ti ṣe ohun ńlá ní Ejibiti,
22 у землі Ха́мовій чу́да, страшні ре́чі над морем Червоним.
iṣẹ́ ìyanu ní ilẹ̀ Hamu àti ohun ẹ̀rù ni ẹ̀bá Òkun Pupa.
23 І сказав Він пони́щити їх, коли б не Мойсей, вибра́нець Його, що став був у ви́ломі перед обличчям Його — відверну́ти Його гнів, щоб не шкодив!
Bẹ́ẹ̀ ni, ó sọ wí pé, òun yóò pa wọ́n run bí kò bá ṣe ti Mose, tí ó yàn, tí ó dúró níwájú ẹ̀yà náà tí ó pa ìbínú rẹ̀ mọ́ láti má pa wọ́n run mọ́.
24 Погордили землею жада́ною, не повірили сло́ву Його,
Nígbà náà, wọ́n kẹ́gàn ilẹ̀ dídára náà wọn kò gba ìlérí rẹ̀ gbọ́.
25 і ре́мствували по наме́тах своїх, неслухня́ні були́ до Господнього голосу.
Wọ́n ń kùn nínú àgọ́ wọn wọn kò sì gbọ́rọ̀ sí Olúwa.
26 І Він підійняв Свою ру́ку на них, щоб їх повали́ти в пустині,
Bẹ́ẹ̀ ni ó búra fún wọn nípa gbígbé ọwọ́ rẹ̀ sókè kí òun lè jẹ́ kí wọn ṣubú nínú aginjù,
27 і щоб повалити їхнє пото́мство посеред наро́дів, та щоб розпоро́шити їх по країнах!
láti jẹ́ kí àwọn ọmọ rẹ̀ ṣubú lára orílẹ̀-èdè láti fọ́n wọn káàkiri lórí ilẹ̀.
28 І служили Ваа́лові пео́рському, й їли вони жертви мертвих,
Wọ́n da ara wọn pọ̀ mọ́ Baali-Peori, wọ́n sì ń jẹ ẹbọ tí a rú sí àwọn òkú òrìṣà,
29 і діла́ми своїми розгні́вали Бога, — тому вдерлась зара́за між них!
wọ́n mú Ọlọ́run bínú pẹ̀lú ohun búburú tí wọn ń ṣe àjàkálẹ̀-ààrùn jáde láàrín wọn.
30 І встав тоді Пі́нхас та й розсуди́в, — і зара́за затри́малась,
Ṣùgbọ́n Finehasi dìde láti dá sí i, àjàkálẹ̀-ààrùn náà sì dáwọ́ dúró lọ́gán.
31 і йому порахо́вано в праведність це, з роду в рід аж навіки.
A sì ka èyí sí òdodo fún un àti fún àwọn ìrandíran tí ń bọ̀
32 І розгні́вали Бога вони над водою Мері́ви, і через них стало зле для Мойсея,
Níbi omi Meriba, wọ́n bí Ọlọ́run nínú, ohun búburú wá sí orí Mose nítorí wọn.
33 бо духа його засмути́ли, і він говорив нерозва́жно уста́ми своїми.
Nítorí tí wọ́n ṣọ̀tẹ̀ sí Ẹ̀mí Ọlọ́run. Ọ̀rọ̀ àìdára sì ti ẹnu Mose wá.
34 Вони не позни́щували тих наро́дів, що Господь говорив їм про них, —
Wọn kò pa àwọn ènìyàn run gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ fún wọn,
35 і поміша́лись з пога́нами, та їхніх учинків навчи́лись.
Ṣùgbọ́n wọ́n dàpọ̀ mọ́ àwọn orílẹ̀-èdè, wọ́n sì gbà láti ṣe bí àṣà wọn.
36 І бо́жищам їхнім служили, а ті па́сткою стали для них.
Wọ́n sì sin àwọn òrìṣà wọn tí ó di ìkẹ́kùn fún wọn.
37 І прино́сили в жертву синів своїх, а дочо́к своїх — де́монам,
Wọ́n fi àwọn ọmọkùnrin wọn rú ẹbọ àti àwọn ọmọbìnrin fún òrìṣà.
38 — і кров чисту лили́, кров синів своїх і дочо́к своїх, що їх у жертву прино́сили бо́жищам ханаа́нським. І через кривавий пере́ступ земля поскверни́лась,
Wọ́n ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀, ẹ̀jẹ̀ àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin wọ. Wọ́n fi wọ́n rú ẹbọ sí ère Kenaani, ilẹ̀ náà sì di àìmọ́ fún ẹ̀jẹ̀.
39 і стали нечисті вони через учи́нки свої, і пере́люб чинили діла́ми своїми.
Wọ́n sì fi ìṣe wọn sọ ara wọn di aláìmọ́, wọ́n sì ṣe àgbèrè lọ pẹ̀lú iṣẹ́ wọn.
40 І проти наро́ду Свого запалав гнів Господній, і спа́док Його Йому став оги́дним,
Nígbà náà ni Olúwa bínú sí àwọn ènìyàn rẹ̀ ó sì kórìíra àwọn ènìyàn ìní rẹ̀
41 і віддав їх у руку наро́дів, — і їхні нена́висники панували над ними,
Ó sì fà wọ́n lé àwọn orílẹ̀-èdè lọ́wọ́, àwọn ọ̀tá wọn sì jẹ ọba lórí wọn.
42 і їхні вороги їх гноби́ли, і вони впокори́лися під їхню руку.
Àwọn ọ̀tá wọn sì ń pọ́n wọn lójú wọn sì mú wọn sìn lábẹ́ àṣẹ wọn.
43 Багато разі́в Він визво́лював їх, але вони вперті були́ своїм за́думом, — і пригно́блено їх через їхню прови́ну!
Ní ọ̀pọ̀ ìgbà òun gbà wọ́n, síbẹ̀ wọ́n sì ń ṣọ̀tẹ̀ sí i wọ́n sì ṣòfò dànù nínú ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
44 Та поба́чив Він їхню тісно́ту, коли почув їхні блага́ння,
Ṣùgbọ́n ó kíyèsi wọn nítorí ìṣòro nígbà tí ó gbọ́ ẹkún wọn,
45 і Він пригадав їм Свого заповіта, і пожалував був за Своєю великою милістю,
ó rántí májẹ̀mú rẹ̀ nítorí wọn Nítorí agbára ìfẹ́ rẹ̀, ó ṣàánú wọn.
46 і збудив милосердя до них між усі́ма, що їх полони́ли!
Lójú gbogbo àwọn tí ó kó wọn ní ìgbèkùn ó mú wọn rí àánú.
47 Спаси́ нас, о Господи, Боже наш, і нас позбирай з-між наро́дів, щоб дя́кувати Йме́нню святому Твоєму, щоб Твоєю хвали́тися славою!
Gbà wá, Olúwa Ọlọ́run wa, kí o sì ṣà wá jọ kúrò láàrín àwọn kèfèrí, láti máa fi ọpẹ́ fún orúkọ mímọ́ rẹ láti máa ṣògo nínú ìyìn rẹ.
48 Благословенний Господь, Бог Ізраїлів звіку й наві́ки! І ввесь наро́д нехай скаже: Амі́нь! Алілу́я!
Olùbùkún ni Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, láti ìrandíran. Jẹ́ kí gbogbo ènìyàn kí ó wí pé, “Àmín!” Ẹ fi ìyìn fún Olúwa!

< Псалми 106 >