< Числа 14 >

1 І зняла́ зойк уся та громада, та й заголосила. І плакав народ той тієї ночі.
Gbogbo ìjọ ènìyàn sì gbóhùn sókè, wọ́n sì sọkún ní òru ọjọ́ náà.
2 І нарікали на Мойсея та на Аарона всі Ізраїлеві сини. І сказала до них вся громада: „О, якби ми померли були́ в єгипетськім кра́ї, або щоб ми померли були в цій пустині!
Gbogbo ọmọ Israẹli sì kùn sí Mose àti Aaroni, gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli sì wí fún wọn pé, “Àwa ìbá kúkú ti kú ní ilẹ̀ Ejibiti. Tàbí kí a kúkú kú sínú aginjù yìí.
3 І нащо Господь провадить нас до того кра́ю, щоб нам попа́дати від меча? Жінки́ наші та діти наші стануть здо́биччю... Чи не краще нам верну́тися до Єгипту?“
Kí ló dé tí Olúwa fi mú wa wá sí ilẹ̀ yìí láti fi idà pa wá? Àwọn ìyàwó wa, àwọn ọmọ wa yóò sì di ìjẹ. Ǹjẹ́ kò wa, ní í dára fún wa bí a bá padà sí Ejibiti?”
4 І сказали вони один до о́дного: „Оберімо собі го́лову, та й вертаймось до Єгипту!“
Wọ́n sì sọ fún ara wọn pé, “Ẹ jẹ́ kí á yan olórí kí á sì padà sí Ejibiti.”
5 I впали Мойсей та Аарон на обличчя свої перед усім збором громади Ізраїлевих синів.
Nígbà náà ni Mose àti Aaroni dojúbolẹ̀ níwájú gbogbo ìjọ ọmọ Israẹli.
6 А Ісу́с, син Нави́нів, та Калев, син Єфуннеїв, із тих, що розвідували той Край, пороздирали одежу свою,
Joṣua ọmọ Nuni àti Kalebu ọmọ Jefunne, tí wọ́n wà lára àwọn to lọ yẹ ilẹ̀ wò sì fa aṣọ wọn ya.
7 та й сказали до всієї громади Ізраїлевих синів, говорячи: „Той край, що перейшли́ ми по ньому, щоб розвідати його, край той дуже-дуже хороший!
Wọ́n sì sọ fún gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli pé, “Ilẹ̀ tí a là kọjá láti yẹ̀ wò náà jẹ́ ilẹ̀ tí ó dára lọ́pọ̀lọ́pọ̀.
8 Якщо Господь уподо́бає Собі нас, то впровадить нас до того Кра́ю, і дасть його нам, край, який тече молоком та медом.
Bí inú Olúwa bá dùn sí wa, yóò mú wa dé ilẹ̀ náà, ilẹ̀ tó ń sàn fún wàrà àti fún oyin, yóò fún wa ní ilẹ̀ náà.
9 Тільки не бунтуйтесь проти Господа, — і не бійтеся наро́ду того кра́ю, бо вони — хліб для нас! Їхня тінь відійшла від них, а з нами Господь, — не бійтеся їх!
Ṣùgbọ́n ẹ má ṣe ṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa. Kí ẹ sì má bẹ̀rù àwọn ènìyàn ìlú náà, nítorí pé a ó gbé wọn mì, ààbò wọn ti fi wọ́n sílẹ̀, Olúwa sì wà pẹ̀lú àwa, ẹ má ṣe bẹ̀rù wọn.”
10 І сказала була вся громада, щоб камі́нням закидати їх, та слава Господня появилася в скинії заповіту всім Ізра́їлевим синам...
Ṣùgbọ́n gbogbo ìjọ ènìyàn sì ń sọ pé àwọn yóò sọ wọ́n lókùúta pa. Nígbà náà ni ògo Olúwa fi ara hàn ní àgọ́ ìpàdé níwájú àwọn ọmọ Israẹli.
11 І промовив Господь до Мойсея: „Аж доки буде цей наро́д зневажа́ти Мене, і аж доки не будуть вони ві́рувати в Мене, у всі ті озна́ки, що Я учинив був серед нього?
Olúwa sọ fún Mose pé, “Fún ìgbà wo ni àwọn ènìyàn yìí yóò ti kẹ́gàn mi tó? Báwo ni yóò ti pẹ́ tó tí wọ́n ó fi kọ̀ jálẹ̀ láti gbà mí gbọ́, pẹ̀lú gbogbo iṣẹ́ àmì tí mo ṣe láàrín wọn?
12 Ударю його поразою, і позба́влю його насліддя, а тебе зроблю́ народом більшим і сильнішим від нього“.
Èmi ó kọlù wọ́n pẹ̀lú àjàkálẹ̀-ààrùn, èmi ó gba ogún wọn lọ́wọ́ wọn, èmi ó sì pa wọ́n run ṣùgbọ́n èmi ó sọ ọ́ di orílẹ̀-èdè ńlá tó sì lágbára jù wọ́n lọ.”
13 І сказав Мойсей до Господа: „І почує Єгипет, що Ти з-посеред нього вивів Своєю силою наро́д цей,
Ṣùgbọ́n Mose sọ fún Olúwa pé, “Nígbà náà ni àwọn ará Ejibiti yóò gbọ́! Nítorí pé nípa agbára rẹ ni ìwọ fi mú àwọn ènìyàn wọ̀nyí jáde kúrò láàrín wọn.
14 та й скаже до ме́шканців цього кра́ю, які чули, що Ти Господь серед цього наро́ду, що око-в-око являєшся Ти, Господи, а хмара Твоя стоїть над ними, і що Ти ходиш перед ними в стовпі хмари вдень, а в стовпі огню вночі, —
Wọ́n ó sì sọ fún àwọn olùgbé ilẹ̀ yìí. Àwọn tó ti mọ̀ tẹ́lẹ̀ pé ìwọ Olúwa wà láàrín àwọn ènìyàn wọ̀nyí àti pé wọ́n rí ìwọ, Olúwa, ní ojúkojú, àti pé ìkùùkuu àwọsánmọ̀ rẹ dúró lórí wọn, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ sì ń lọ níwájú wọn pẹ̀lú ìkùùkuu àwọsánmọ̀ ní ọ̀sán àti pẹ̀lú ọ̀wọ́n iná ní òru.
15 якщо заб'єш Ти цей наро́д, як одну люди́ну, то скажуть ті люди, що чули слух про Тебе, говорячи:
Bí ìwọ bá pa àwọn ènìyàn wọ̀nyí lẹ́ẹ̀kan ṣoṣo, àwọn orílẹ̀-èdè tó bá gbọ́ ìròyìn yìí nípa rẹ yóò wí pé,
16 Через неспромо́жність Господа впрова́дити той народ до кра́ю, якого Він заприся́г був їм, вигубив їх у пустині.
‘Nítorí pé Olúwa kò le è mú àwọn ènìyàn wọ̀nyí dé ilẹ̀ tí ó ṣèlérí fún wọn; torí èyí ló ṣe pa wọ́n sínú aginjù yìí.’
17 А тепер нехай же звели́читься сила Господня, як Ти наказав був, говорячи:
“Báyìí, mo gbàdúrà, jẹ́ kí agbára Olúwa tóbi gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti sọ pé,
18 „Господь довготерпели́вий, і багатомилости́вий, Він прощає провину та пере́ступ, і не очистить винного, а карає провину батьків на третіх і на четвертих поколі́ннях“.
‘Olúwa lọ́ra láti bínú, ó sì pọ̀ ní ìfẹ́ tó dúró ṣinṣin, tí ń dárí ẹ̀ṣẹ̀ àti ìrékọjá jì. Bẹ́ẹ̀ ni kì í jẹ́ kí ẹlẹ́bi lọ láìjìyà; tó ń fi ìyà ẹ̀ṣẹ̀ baba jẹ ọmọ títí dé ìran kẹta àti ìran kẹrin.’
19 Прости ж провину цього народу через велику милість Свою, як проща́в Ти цьому наро́дові від Єгипту й аж сюди!“
Dárí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ènìyàn yìí jì wọ́n, mo bẹ̀ ọ́, gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ ńlá rẹ, bí o ti ṣe ń dárí ẹ̀ṣẹ̀ wọn jì wọ́n láti ìgbà tí o ti kó wọn kúrò ní Ejibiti di ìsin yìí.”
20 А Господь сказав: „Я простив за словом твоїм.
Olúwa sì dáhùn pé, “Mo ti dáríjì wọ́n gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
21 Але, як Я живий, — слава Господня напо́внить увесь оцей край.
Ṣùgbọ́n nítòótọ́ bí mo ti wà láààyè, gbogbo ayé yóò kún fún ògo Olúwa.
22 Тому́ всі ті люди, що бачили славу Мою та озна́ки Мої, що чинив Я в Єгипті та в пустині, але випробо́вували Мене оце десять раз та не слухалися голосу Мого,
Kò sí ọ̀kan nínú àwọn ènìyàn tó rí ògo mi àti àwọn iṣẹ́ àmì tí mo ṣe ní ilẹ̀ Ejibiti àti nínú aginjù ṣùgbọ́n tí wọ́n ṣe àìgbọ́ràn sí mi, tí wọn sì dán mi wò ní ìgbà mẹ́wàá yìí,
23 поправді кажу, — не побачать вони того кра́ю, що Я заприсяг був їхнім батькам. І всі, хто зневажає Мене, не побачать його́!
ọ̀kan nínú wọn kò ní rí ilẹ̀ náà tí mo ṣe ìlérí ní ìbúra láti fún baba ńlá wọn. Kò sí ọ̀kan nínú àwọn tó kẹ́gàn mi tí yóò rí ilẹ̀ náà.
24 Але раб Мій Калев за те, що з ним був дух інший, і він вико́нував накази Мої, то Я введу́ його до того краю, куди він увійшов був, і пото́мство його оволодіє ним.
Ṣùgbọ́n nítorí pé Kalebu ìránṣẹ́ mi ní ẹ̀mí ọ̀tọ̀, tí ó sì tún tẹ̀lé mi tọkàntọkàn, èmi ó mu dé ilẹ̀ náà tó lọ yẹ̀ wò, irú àwọn ọmọ rẹ̀ yóò sì jogún rẹ̀.
25 А амалики́тянин та ханаане́янин сидить у долині. Узавтра оберніться, та й руша́йте на пустиню дорогою Червоного моря!“
Níwọ́n ìgbà tí àwọn ará Amaleki àti àwọn ará Kenaani ń gbé ní àfonífojì, ẹ yípadà lọ́la kí ẹ sì dojúkọ aginjù lọ́nà Òkun Pupa.”
26 І Господь промовляв до Мойсея й до Ааро́на, говорячи:
Olúwa sọ fún Mose àti Aaroni pé,
27 „Аж доки цій злій громаді нарікати на Мене? Наріка́ння Ізраїлевих синів, що вони нарікають на Мене, Я чув.
“Báwo ni yóò ti pẹ́ tó tí àwọn ìjọ ènìyàn búburú yìí yóò fi máa kùn sí mi? Mo ti gbọ́ kíkùn tí àwọn ọmọ Israẹli ń kùn sí mi.
28 Скажи їм: Живий Я! Мова Господня: Поправді кажу, — як ви говорили до ушей Моїх, так Я зроблю́ вам.
Sọ fún wọn, bí mo ti wà láààyè nítòótọ́ ni Olúwa wí, gẹ́gẹ́ bí ohun tí ẹ wí létí mi ni èmi ó ṣe fún un yín.
29 У цій пустині попа́дають ваші трупи, та всі перелічені ваші всім вашим числом від віку двадцяти́ літ і вище, що нарікали на Мене.
Nínú aginjù yìí ni ẹ ó kú sí, gbogbo ẹ̀yin tí ẹ kùn láti ọmọ ogún ọdún ó lé àní gbogbo ẹ̀yin tí a kà.
30 Поправді кажу, — ви не ввійдете до того кра́ю, що Я підносив був на присягу руку Свою, що будете перебувати в нім, — окрім Калева, сина Єфуннеєвого, та Ісуса, сина Нави́нового.
Ọ̀kan nínú yín kò ní í dé ilẹ̀ tí mo búra nípa ìgbọ́wọ́sókè láti fi ṣe ibùgbé yín, bí kò ṣe Kalebu ọmọ Jefunne àti Joṣua ọmọ Nuni.
31 А діти ваші, що про них казали ви: станете здо́биччю ворогові, то впрова́джу Я їх, і пізнають вони цей край, яким ви обри́дили.
Ṣùgbọ́n ní ti àwọn ọmọ yín tí ẹ wí pé wọn ó di ìjẹ, àwọn ni n ó mú dé bẹ̀ láti gbádùn ilẹ̀ tí ẹ kọ̀sílẹ̀.
32 І ваші власні трупи попа́дають у цій пустині!
Ṣùgbọ́n ẹ̀yin, òkú yín yóò ṣubú ní aginjù yìí.
33 А ваші сини будуть блукати на пустині со́рок літ, і відповідатимуть за зраду вашу, аж поки ви́гинуть ваші трупи на пустині.
Àwọn ọmọ wẹ́wẹ́ yín yóò sì máa rin kiri nínú aginjù fun ogójì ọdún wọn ó máa jìyà nítorí àìnígbàgbọ́ yín, títí tí ọkàn gbogbo yín yóò fi ṣòfò tán ní aginjù.
34 Числом тих днів, що розві́дували ви той край, сорок день, будете ви нести ваші гріхи по року за день — сорок літ, і пізнаєте, що значить бути покинутими Мною!
Fún ogójì ọdún èyí jẹ́ ọdún kan fún ọjọ́ kọ̀ọ̀kan nínú ogójì ọjọ́ tí ẹ fi yẹ ilẹ̀ náà wò ẹ̀yin ó sì jìyà fún ẹ̀ṣẹ̀ yín, ẹ ó sì mọ bí ó ti rí láti lòdì sí mi.
35 Я, Господь, говорив: Поправді кажу, — оце зроблю́ всій цій злій громаді, що змовляється проти Мене: у цій пустині вигинуть, і тут повмирають“.
Èmi, Olúwa, lo sọ bẹ́ẹ̀; Èmi ó sì ṣe àwọn nǹkan wọ̀nyí sí ìjọ ènìyàn búburú yìí tí wọ́n kó ra wọn jọ lòdì sí mi. Nínú aginjù yìí ni òpin yóò dé bá wọn, ibẹ̀ ni wọn yóò kú sí.”
36 А ті люди, яких Мойсей послав був розві́дати той край, коли вернулися, то зробили, що вся громада нарікала на нього, і пустили злу вістку на той край,
Àwọn ọkùnrin tí Mose rán láti yẹ ilẹ̀ wò, tí wọ́n sì mú gbogbo ìjọ kùn sí i nípa ìròyìn búburú tí wọ́n mú wá nípa ilẹ̀ náà;
37 то ті люди, що пустили були злу вістку на той край, повмирали від пора́зи перед Господнім лицем.
Olúwa sì kọlu àwọn ọkùnrin tó mú ìròyìn búburú wá nípa ilẹ̀ náà, àjàkálẹ̀-ààrùn sì pa wọ́n níwájú Olúwa.
38 А Ісус, син Нави́нів, та Калев, син Єфуннеїв, жили́ з тих людей, що ходили розвідати той край.
Nínú gbogbo àwọn tó lọ yẹ ilẹ̀ náà wò, Joṣua ọmọ Nuni àti Kalebu ọmọ Jefunne ló yè é.
39 І говорив Мойсей ці слова́ до всіх Ізраїлевих синів, — і наро́д був у тяжкій жало́бі!
Nígbà tí Mose sọ gbogbo ọ̀rọ̀ yìí fún àwọn ọmọ Israẹli, wọ́n sì sọkún gidigidi.
40 І повставали вони рано вранці, та й повихо́дили на верхі́в'я гори, говорячи: „Ось ми, — і ми пі́демо до місця, що Господь був сказав, бо ми прогрішили“.
Wọ́n dìde ní àárọ̀ ọjọ́ kejì wọ́n sì gòkè lọ sí ìlú orí òkè, wọ́n wí pé, “Àwa ti ṣẹ̀, àwa yóò lọ sí ibi tí Olúwa ṣèlérí fún wa.”
41 А Мойсей сказав: „Чому́ ж ви переступаєте нака́з Господній? Таж це не вдасться!
Mose sì dá wọn lóhùn pé, “Kí ló dé tí ẹ fi ṣẹ̀ sí òfin Olúwa? Èyí kò le yọrí sí rere!
42 Не виходьте, бо Господь не серед вас, а то бу́дете побиті своїми ворогами.
Ẹ má ṣe gòkè lọ nítorí pé Olúwa kò sí láàrín yín. Ki á má ba à lù yín bolẹ̀ níwájú àwọn ọ̀tá yín.
43 Бо там перед вами амалики́тянин і ханаане́янин, і ви попа́даєте від меча, бо ви відвернулися від Господа, і не буде Господь із вами“.
Nítorí pé àwọn ará Amaleki àti àwọn ará Kenaani ń bẹ níwájú yín, ẹ̀yin yóò sì ti ipa idà ṣubú. Nítorí pé, ẹ ti yà kúrò ní ọ̀nà Olúwa, Olúwa kò sì ní í wà pẹ̀lú yín.”
44 Але вони осмі́лилися вийти на верхів'я гори, а ковче́г свідоцтва Господнього та Мойсей не ру́шилися з-посеред табо́ру.
Síbẹ̀síbẹ̀, pẹ̀lú àìfarabalẹ̀ wọn, wọ́n gòkè lọ sórí òkè náà, láìjẹ́ pé àpótí ẹ̀rí Olúwa tàbí Mose kúrò nínú ibùdó.
45 І зійшов амаликитянин та ханаанеянин, що сидить на тій горі, та й побили їх, і били їх аж до Хорми.
Àwọn ará Amaleki àti àwọn ará Kenaani tó ń gbé lórí òkè sọ̀kalẹ̀ tọ̀ wọ́n, wọ́n bá wọn jà, wọ́n sì lé wọn títí dé Horma.

< Числа 14 >