< Михей 1 >

1 Слово Господнє, що було до морешетського Михе́я за днів Йотама, Ахаза та Єзекії, Юдиних царів, яке він бачив на Самарію та Єрусалим.
Ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó tọ Mika ará Moreṣeti wá ní àkókò ìjọba Jotamu, Ahasi, àti Hesekiah, àwọn ọba Juda nìwọ̀nyí, ìran tí ó rí nípa Samaria àti Jerusalẹmu.
2 „Почуйте оце, всі наро́ди, послухай, ти земле та все, що на ній! і хай буде за свідка на вас Господь Бог, Господь з храму святого Свого́!
Ẹ gbọ́, gbogbo ẹ̀yin ènìyàn, fetísílẹ̀, ìwọ ayé àti gbogbo ohun tó wà níbẹ̀, kí Olúwa Olódùmarè lè ṣe ẹlẹ́rìí sí yín, Olúwa láti inú tẹmpili mímọ́ rẹ̀ wá.
3 Бо Госпо́дь ось виходить із місця Свого́, і Він сходить і ступає по висо́тах землі.
Wò ó! Olúwa ń bọ̀ wá láti ibùgbé rẹ̀; yóò sọ̀kalẹ̀, yóò sì tẹ ibi gíga ayé mọ́lẹ̀.
4 І то́пляться гори під Ним, і та́нуть доли́ни, мов віск від огню́, мов ті во́ди, що ллються з узбі́ччя.
Àwọn òkè ńlá yóò sí yọ́ lábẹ́ rẹ̀, àwọn àfonífojì yóò sì pínyà, bí idà níwájú iná, bí omi tí ó ń sàn lọ ni ibi gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́.
5 Усе це за прови́нення Якова, за гріхи́ дому Ізраїля. Хто провинення Якова, — чи ж не Самарія? А хто гріх дому Юдиного, — чи ж не Єрусали́м?
Nítorí ìré-òfin-kọjá Jakọbu ni gbogbo èyí, àti nítorí ẹ̀ṣẹ̀ ilé Israẹli. Kí ni ìré-òfin-kọjá Jakọbu? Ǹjẹ́ Samaria ha kọ? Kí ni àwọn ibi gíga Juda? Ǹjẹ́ Jerusalẹmu ha kọ?
6 І зроблю́ Самарі́ю руїною в полі, за місце сади́ти виноград, і повикида́ю в долину камі́ння її, і відкрию осно́ви її.
“Nítorí náà, èmi yóò ṣe Samaria bí òkìtì lórí pápá, bí ibi ti à ń lò fún gbígbin ọgbà àjàrà. Èmi yóò gbá àwọn òkúta rẹ̀ dànù sínú àfonífojì. Èmi yóò sí tú ìpilẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ palẹ̀.
7 І пото́вчені будуть усі її і́доли, всі ж дару́нки її за розпусту попа́лені бу́дуть в огні, і всіх бовва́нів її Я віддам на спусто́шення. Бо зібрала вона від дару́нків за блуд, і на подару́нки за блуд це пове́рнеться.
Gbogbo àwọn ère fínfín rẹ̀ ni a ó fọ́ sí wẹ́wẹ́ gbogbo àwọn ẹ̀bùn tẹmpili rẹ̀ ni a ó fi iná sun, Èmi yóò sì pa gbogbo àwọn òrìṣà rẹ̀ run. Nítorí tí ó ti kó àwọn ẹ̀bùn rẹ̀ jọ láti inú owó èrè panṣágà, gẹ́gẹ́ bí owó èrè panṣágà, wọn yóò sì tún padà sí owó iṣẹ́ panṣágà.”
8 Над оцим голоси́тиму я та рида́тиму, ходитиму бо́сий й наги́й, заво́дити буду, немов ті шака́ли, і буду тужи́ти, як стру́сі!
Nítorí èyí, èmi yóò sì sọkún, èmi yóò sì pohùnréré ẹkún: èmi yóò máa lọ ní ẹsẹ̀ lásán àti ní ìhòhò. Èmi yóò ké bí akátá, èmi yóò sì máa dárò bí àwọn ọmọ ògòǹgò.
9 Бо рани її невиго́йні, бо це аж до Юди прийшло, воно досягло́ аж до брами наро́ду Мого, аж до Єрусалиму.
Nítorí tí ọgbẹ́ rẹ̀ jẹ́ aláìlèwòtán; ó sì ti wá sí Juda. Ó sì ti dé ẹnu-bodè àwọn ènìyàn mi, àní sí Jerusalẹmu.
10 Цього не оголо́шуйте в Ґаті, і плакати — не плачте, качайтесь по по́росі в Бет-Леафрі.
Ẹ má ṣe sọ ní Gati ẹ má ṣe sọkún rárá. Ní ilẹ̀ Beti-Ofra mo yí ara mi nínú eruku.
11 Переходь собі ти, о мешка́нко Шафіру, нага́, осоро́млена, — вже бо не вийде мешка́нка Цаанану, голосі́ння Бет-Гаецелу не дасть вам спини́тися в ньому.
Ẹ kọjá lọ ni ìhòhò àti ni ìtìjú, ìwọ tí ó ń gbé ni Ṣafiri. Àwọn tí ó ń gbé ni Saanani kì yóò sì jáde wá. Beti-Eseli wà nínú ọ̀fọ̀; a ó sì gba ààbò rẹ̀ kúrò lọ́wọ́ yin.
12 Бо мешка́нка Мароту чекала добра, та до єрусалимської брами зійшло оце лихо від Господа.
Nítorí àwọn tí ó ń gbé ni Marati ń retí ìre, ṣùgbọ́n ibi sọ̀kalẹ̀ ti ọ̀dọ̀ Olúwa wá sí ẹnu-bodè Jerusalẹmu.
13 Запряжи баскі ко́ні до воза, мешка́нко Лахішу! Ти поча́ток гріха́ для сіонської до́ньки, бо знайшли́сь серед тебе провини Ізраїлеві,
Ìwọ olùgbé Lakiṣi, dì kẹ̀kẹ́ mọ́ ẹranko tí ó yára. Òun sì ni ìbẹ̀rẹ̀ ẹ̀ṣẹ̀ sí àwọn ọmọbìnrin Sioni, nítorí a rí àìṣedéédéé Israẹli nínú rẹ̀.
14 тому́ то даси розводо́ві листи на Морешет-Ґат. Доми Ахзіва — ома́на для Ізраїлевих царів.
Nítorí náà ni ìwọ ó ṣe fi ìwé ìkọ̀sílẹ̀ fún Moreṣeti Gati. Àwọn ilé Aksibu yóò jẹ́ ẹlẹ́tàn sí àwọn ọba Israẹli.
15 Спрова́джу тобі те спадкоє́мця Я, о мешка́нко Мареші, — Аж по Адуллам прийде слава Ізраїля.
Èmi yóò sì mú àrólé kan wá sórí rẹ ìwọ olùgbé Meraṣa. Ẹni tí ó jẹ́ ògo Israẹli yóò sì wá sí Adullamu.
16 Зроби собі лисину та острижися за синів своїх лю́бих, пошир свою лисину, мов ув орла́, бо пішли на вигна́ння від тебе вони!
Fá irun orí rẹ nínú ọ̀fọ̀ nítorí àwọn ọmọ rẹ aláìlágbára, sọ ra rẹ̀ di apárí bí ẹyẹ igún, nítorí wọn yóò kúrò lọ́dọ̀ rẹ lọ sí ìgbèkùn.

< Михей 1 >