< Малахії 3 >
1 Ось Я посилаю Свого ангола, і він перед обличчям Моїм приготу́є доро́гу. І на́гло прибу́де до храму Свого Госпо́дь, Якого шукаєте ви, і Ангол запові́ту, Якого жада́єте. Ось іде Він, говорить Господь Саваот!
“Wò ó, Èmi yóò ran ìránṣẹ́ mi, yóò tún ọ̀nà ṣe ṣáájú mi. Nígbà náà ni Olúwa, tí ẹ̀yin ń wa, yóò dé ni òjijì sí tẹmpili rẹ̀; àní oníṣẹ́ májẹ̀mú náà, tí inú yín dùn sí, yóò dé,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
2 І хто ви́терпить день Його прибуття́, і хто всто́їть, коли Він з'я́виться? Бо Він, як огонь той у золотаря́, і як у пра́льників луг.
Ṣùgbọ́n ta ni o lè fi ara da ọjọ́ dídé rẹ̀? Ta ni yóò sì dúró nígbà tí ó bá fi ara hàn? Nítorí òun yóò dàbí iná ẹni tí ń da fàdákà àti bi ọṣẹ alágbàfọ̀.
3 І Він сяде топи́ти та чи́стити срі́бло, і очи́стить синів Леві́я, і їх перечи́стить, як золото й срі́бло, і будуть для Господа жертву прино́сити в правді.
Òun yóò sì jókòó bí ẹni tí n yọ́, tí ó sì ń da fàdákà; yóò wẹ àwọn ọmọ Lefi mọ́, yóò sì tún wọn dàbí wúrà àti fàdákà, kí wọn bá a lè mú ọrẹ òdodo wá fún Olúwa,
4 Тоді бу́де дар Юди та Єрусалиму приє́мний для Господа, як за днів вікові́чних і за років старода́вніх.
nígbà náà ni ọrẹ Juda àti ti Jerusalẹmu yóò jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà fún Olúwa, gẹ́gẹ́ bí ti ọjọ́ àtijọ́, àti gẹ́gẹ́ bí ọdún ìgbàanì.
5 І прибу́ду до вас Я на суд, і буду сві́дком швидки́м проти чарівників, і на перелю́бників, і проти тих, хто прися́гу складає на лжу, і проти тих, хто запла́тою на́ймита тисне, вдову́ й сироту́, хто відхилює право чужи́нця, Мене ж не боїться, говорить Госпо́дь Савао́т.
“Èmi ó sì súnmọ́ yin fún ìdájọ́. Èmi yóò sì yára ṣe ẹlẹ́rìí sí àwọn oṣó, sí àwọn panṣágà, sí àwọn abúra èké, àti àwọn tí ó fi ọ̀yà alágbàṣe pọn wọn lójú, àti àwọn tí ó ni àwọn opó àti àwọn aláìní baba lára, àti sí ẹni tí kò jẹ́ kí àjèjì rí ìdájọ́ òdodo gbà, tí wọn kò sì bẹ̀rù mi,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
6 Бо Я, Господь, не змі́нююся, тому ви, сини Яковові, не будете зни́щені.
“Èmi Olúwa kò yípadà. Nítorí náà ni a kò ṣe run ẹ̀yin ọmọ Jakọbu.
7 Від уста́в Моїх ви відступили́ з днів ваших батькі́в, і їх не стерегли́. Верніться ж до Мене, і верну́сь Я до вас! промовляє Господь Савао́т. Та говорите ви: „У чо́му пове́рнемось?“
Láti ọjọ́ àwọn baba ńlá yín wá ni ẹ̀yin tilẹ̀ ti kọ ẹ̀yìn sí ìlànà mi, tí ẹ kò sì pa wọ́n mọ́. Ẹ padà wá sí ọ̀dọ̀ mi, Èmi yóò sì padà sí ọ̀dọ̀ yín,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí. “Ṣùgbọ́n ẹ̀yin béèrè pé, ‘Báwo ni àwa yóò ṣe padà?’
8 Чи Бога люди́на обманить? Мене ж ви обма́нюєте, ще й говорите: „Чи́м ми Тебе обмани́ли?“— Десяти́ною та прино́сами!
“Ènìyàn yóò ha ja Ọlọ́run ni olè bí? Síbẹ̀ ẹ̀yin ti jà mí ní olè. “Ṣùgbọ́n ẹ̀yin béèrè pé, ‘Báwo ni àwa ṣe jà ọ́ ní olè?’ “Nípa ìdámẹ́wàá àti ọrẹ.
9 Прокля́ттям ви про́кляті, а Мене обмани́ли, о люду ти ввесь!
Ríré ni a ó fi yín ré: gbogbo orílẹ̀-èdè yìí, nítorí ẹ̀yin ti jà mi lólè.
10 Принесіть же ви всю десяти́ну до дому скарбни́ці, щоб стра́ва була́ в Моїм храмі, і тим Мене ви́пробуйте, — промовляє Господь Саваот: чи небесних отво́рів вам не відчиню́, та не ви́ллю вам благослове́ння аж на́дмір?
Ẹ mú gbogbo ìdámẹ́wàá wá sí ilé ìṣúra, kí oúnjẹ bá à lè wà ní ilé mi, ẹ fi èyí dán mi wò,” ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “kí ẹ sì wò bí èmi kò bá ní sí àwọn fèrèsé ọ̀run fún yin, kí èmi sì tú ìbùkún àkúnwọ́sílẹ̀ jáde fún yín, tó bẹ́ẹ̀ tí kì yóò sì ààyè láti gbà á.
11 І ради вас насварю́ Я все те, що жере́, і воно не пони́щить вам зе́много пло́ду, і не заб'є винограду вам на по́лі, говорить Господь Саваот.
Èmi yóò sì bá kòkòrò ajẹnirun wí nítorí yín, òun kò sì ni run èso ilẹ̀ yín, bẹ́ẹ̀ ni àjàrà inú oko yín kò ní rẹ̀ dànù,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
12 І будуть всі люди вважати вас блаже́нними, бо бу́дете ви любим кра́єм, говорить Господь Саваот.
“Nígbà náà ni gbogbo orílẹ̀-èdè yóò sì pè yín ni alábùkún fún, nítorí tiyín yóò jẹ́ ilẹ̀ tí ó wu ni,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
13 Жорстокі ваші слова́ проти Мене, — говорить Госпо́дь, — а ви кажете: „Що́ ми на Тебе сказали?“
“Ẹ̀yin ti sọ ọ̀rọ̀ líle sí mi,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí. “Síbẹ̀ ẹ̀yin béèrè pé, ‘Ọ̀rọ̀ kín ni àwa sọ sí ọ?’
14 Ви кажете: „Ма́рність служити для Бога! І що за ко́ристь, що ми стереже́мо Його службу, та ходимо в жало́бі перед лицем Господа Саваота?
“Ẹ̀yin ti wí pé, ‘Asán ni láti sin Ọlọ́run. Kí ni àwa jẹ ní èrè, nígbà tí àwa ti pa ìlànà rẹ mọ́, tí àwa sì ń rìn kiri bí ẹni tí ń ṣọ̀fọ̀ ní iwájú Olúwa àwọn ọmọ-ogun?
15 А тепер ми вважаємо пи́шних щасли́вими, і ті, хто вчиня́є безбожне, буду́ються та випробо́вують Бога, і втікають“.
Ṣùgbọ́n ní ìsinsin yìí àwa pé agbéraga ni alábùkún fún. Ní òtítọ́ ni àwọn ti ń ṣe búburú ń gbèrú sí i, kódà àwọn ti ó dán Ọlọ́run wò ni a dá sí.’”
16 Змовлялись тоді один з о́дним і ті, хто стра́х перед Го́сподом має, — і прислу́хавсь Господь, і почув, і перед обличчям Його була пи́сана па́м'ятна книга про тих, хто стра́х перед Го́сподом має, і хто поважає Йме́ння Його.
Nígbà náà ni àwọn tí ó bẹ̀rù Olúwa ń ba ara wọn sọ̀rọ̀, Olúwa sì tẹ́tí sí i, ó sì gbọ́. A sì kọ ìwé ìrántí kan níwájú rẹ̀, fún àwọn tí o bẹ̀rù Olúwa, tiwọn sì bọ̀wọ̀ fún orúkọ rẹ̀.
17 І бу́дуть Мені вони вла́сністю, — каже Господь Савао́т, — на той день, що вчиню́, і змилосе́рджусь над ними, як змилосе́рджується чоловік над синами своїми, що служать йому.
“Wọn yóò sì jẹ́ tèmi,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “ni ọjọ́ náà, tí èmi ó dá; èmi yóò sì da wọ́n sí gẹ́gẹ́ bí ènìyàn tí máa ń dá ọmọ rẹ̀ tí yóò sìn ín sí.
18 І ви зно́ву побачите різницю́ між пра́ведним та нечести́вим, між тим, хто Бо́гові служить, та тим, хто не служить Йому́.
Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò rí ìyàtọ̀, ìyàtọ̀ láàrín olódodo àti ẹni búburú, láàrín ẹni tí ń sìn Ọlọ́run, àti ẹni tí kò sìn ín.