< Від Луки 10 >

1 Після того призна́чив Господь і інших Сімдеся́т, і послав їх по двох перед Себе до кожного міста та місця, куди Сам мав іти.
Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí, Olúwa sì yan méjìléláàádọ́rin ọmọ-ẹ̀yìn mìíràn pẹ̀lú, ó sì rán wọn ní méjì méjì lọ ṣáájú rẹ̀, sí gbogbo ìlú àti ibi tí òun tìkára rẹ̀ yóò sì dé.
2 І промовив до них: „Хоч жни́во велике, та робі́тників мало; тож благайте Господаря жни́ва, щоб робі́тників вислав на жни́во Своє.
Ó sì wí fún wọn pé, “Ìkórè pọ̀, ṣùgbọ́n àwọn alágbàṣe kò tó nǹkan, nítorí náà ẹ bẹ Olúwa ìkórè, kí ó lè rán àwọn alágbàṣe sínú ìkórè rẹ̀.
3 Ідіть! Оце посилаю Я вас, як ягнят між вовки́.
Ẹ mú ọ̀nà yín pọ̀n: sá wò ó, èmi rán yín lọ bí ọ̀dọ́-àgùntàn sáàrín ìkookò.
4 Не носіть ні кали́тки, ні торби, ні санда́ль, і не вітайте в дорозі ніко́го.
Ẹ má ṣe mú àpò, ẹ má ṣe mú àpamọ́wọ́, tàbí bàtà: ẹ má sì ṣe kí ẹnikẹ́ni lọ́nà.
5 Як до дому ж якого ви вві́йдете, то найперше кажіть: „Мир дому цьому́!“
“Ní ilékílé tí ẹ̀yin bá wọ̀, kí ẹ kọ́ wí pé, ‘Àlàáfíà fún ilé yìí!’
6 І коли син миру там буде, то спочи́не на ньому ваш мир, коли ж ні — до вас ве́рнеться.
Bí ọmọ àlàáfíà bá sì wà níbẹ̀, àlàáfíà yín yóò bà lé e: ṣùgbọ́n bí kò bá sí, yóò tún padà sọ́dọ̀ yín.
7 Зоставайтеся ж у домі тім самім, споживайте та пийте, що є в них, — бо вартий робі́тник своєї заплати. Не ходіть з дому в дім.
Ẹ dúró sínú ilé náà, kí ẹ máa jẹ, kí ẹ sì máa mu ohunkóhun tí wọ́n bá fi fún yín, nítorí ọ̀yà alágbàṣe tọ́ sí i. Ẹ má ṣe lọ láti ilé dé ilé.
8 А як при́йдете в місто яке, і вас при́ймуть, — споживайте, що вам подадуть.
“Ìlúkílùú tí ẹ̀yin bá wọ̀, tí wọ́n bá sì gbà yín, ẹ jẹ ohunkóhun tí a bá gbé ka iwájú yín.
9 Уздоро́влюйте хворих, що в нім, промовляйте до них: „Набли́зилося Царство Боже до вас!“
Ẹ sì mú àwọn aláìsàn tí ń bẹ nínú rẹ̀ láradá, kí ẹ sì wí fún wọn pé, ‘Ìjọba Ọlọ́run kù sí dẹ̀dẹ̀ sí yín!’
10 А як при́йдете в місто яке, і вас не приймуть, то вийдіть на вулиці його та й кажіть:
Ṣùgbọ́n ní ìlúkílùú tí ẹ̀yin bá sì wọ̀, tí wọn kò bá sì gbà yín, nígbà tí ẹ̀yin bá sì jáde ní ìgboro ìlú náà, kí ẹ̀yin sì wí pé,
11 „Ми обтру́шуємо вам навіть порох, що прилип до нас із вашого міста. Та знайте оце, що набли́зилося Ца́рство Боже!“
‘Eruku ìlú yín tí ó kù sí wa lẹ́sẹ̀, a gbọ̀n ọ́n sílẹ̀ fún yín! Ṣùgbọ́n ẹ mọ èyí pé, ìjọba Ọlọ́run kù sí dẹ̀dẹ̀.’
12 Кажу вам: того дня легше буде содо́млянам, аніж місту тому́!“
Ṣùgbọ́n mo wí fún yín, yóò sàn fún Sodomu ní ọjọ́ náà, ju fún ìlú náà lọ.
13 „Горе тобі, Хоразі́не, горе тобі, Віфсаїдо! Бо коли б то у Тирі й Сидоні були відбули́ся ті чу́да, що сталися в вас, то давно б вони покаялися в волосяни́ці та в попелі!
“Ègbé ni fún ìwọ, Korasini! Ègbé ni fún ìwọ Betisaida! Nítorí ìbá ṣe pé a ti ṣe iṣẹ́ agbára tí a ṣe nínú yín, ní Tire àti Sidoni, wọn ìbá ti ronúpìwàdà lọ́jọ́ pípẹ́ sẹ́yìn, wọn ìbá sì jókòó nínú aṣọ ọ̀fọ̀ àti nínú eérú.
14 Але на суді відрадніш буде Тиру й Сидону, як вам.
Ṣùgbọ́n yóò sàn fún Tire àti Sidoni nígbà ìdájọ́ jù fún yín lọ.
15 А ти, Капернау́ме, що „до неба піднісся, — аж до аду ти зійдеш!“ (Hadēs g86)
Àti ìwọ, Kapernaumu, a ó ha gbé ọ ga dé òkè ọ̀run? A ó rẹ̀ ọ́ sílẹ̀ dé isà òkú. (Hadēs g86)
16 Хто слухає вас — Мене слухає, хто ж погорджує вами — погорджує Мною, хто ж погорджує Мною — погорджує Тим, Хто послав Мене“.
“Ẹni tí ó bá gbọ́ tiyín, ó gbọ́ tèmi. Ẹni tí ó bá sì kọ̀ yín, ó kọ̀ mi. Ẹni tí ó bá sì kọ̀ mi, ó kọ ẹni tí ó rán mi.”
17 А ті Сімдеся́т повернулися з радістю, кажучи: „Господи, — навіть де́мони ко́ряться нам у Ім'я́ Твоє!“
Àwọn àádọ́rin náà sì fi ayọ̀ padà, wí pé, “Olúwa, àwọn ẹ̀mí èṣù tilẹ̀ foríbalẹ̀ fún wa ní orúkọ rẹ.”
18 Він же промовив до них: „Я бачив того сатану, що з неба спадав, немов блискавка.
Ó sì wí fún wọn pé, “Èmí rí Satani ṣubú bí mọ̀nàmọ́ná láti ọ̀run wá.
19 Ось Я вла́ду вам дав наступати на змій та скорпіо́нів, і на всю силу ворожу, — і ніщо вам не зашко́дить.
Kíyèsi i, èmí fún yín ní àṣẹ láti tẹ ejò àti àkéekèe mọ́lẹ̀, àti lórí gbogbo agbára ọ̀tá, kò sì ṣí ohun kan bí ó ti wù tí ó ṣe, tí yóò pa yín lára.
20 Та не тіштеся тим, що вам ко́ряться духи, але тіштесь, що ваші ймення записані в небі!“
Ṣùgbọ́n kí ẹ má ṣe yọ̀ nítorí èyí pé, àwọn ẹ̀mí ń foríbalẹ̀ fún yín; ṣùgbọ́n ẹ kúkú yọ̀, pé; a kọ̀wé orúkọ yín ní ọ̀run!”
21 Того ча́су Ісус звеселився був Духом Святим і промовив: „Прославляю Тебе, Отче, Господи неба й землі, що втаїв Ти оце від премудрих і розумних, та його немовлятам відкрив. Так, Отче, бо Тобі так було до вподоби!
Ní wákàtí kan náà Jesu yọ̀ nínú Ẹ̀mí mímọ́ ó sì wí pé, “Mo dúpẹ́ lọ́wọ́ rẹ, Baba, Olúwa ọ̀run àti ayé, pé, ìwọ pa nǹkan wọ̀nyí mọ́ kúrò lọ́dọ̀ àwọn ọlọ́gbọ́n àti amòye, ìwọ sì fi wọ́n hàn fún àwọn ọmọ ọwọ́. Bẹ́ẹ̀ ni, Baba, bẹ́ẹ̀ ni ó sá à yẹ ní ojú rẹ.
22 Передав Мені все Мій Отець. І не знає ніхто, хто є Син, — тільки Отець, і хто Отець — тільки Син, та кому Син захоче відкрити“.
“Ohun gbogbo ni a ti fi fún mi láti ọ̀dọ̀ Baba mi; kò sì ṣí ẹni tí ó mọ ẹni tí ọmọ jẹ́, bí kò ṣe Baba, àti ẹnikẹ́ni tí ó bá sì wu ọmọ láti fi í hàn fún.”
23 І, звернувшись до учнів, наодинці їм сказав: „Блаженні ті очі, що бачать, що́ бачите ви!
Ó sì yípadà sí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ ní apá kan. Ó ní, “Ìbùkún ni fún ojú tí ń rí ohun tí ẹ̀yin ń rí.
24 Кажу ж вам, що багато пророків і царів бажали побачити, що бачите ви — та й не бачили, і почути, що́ чуєте ви — і не чули!“
Nítorí mo wí fún yín, ọ̀pọ̀ àwọn wòlíì àti àwọn ọba ni ó ń fẹ́ láti rí ohun tí ẹ̀yin ń rí, wọn kò sì rí wọn, àti láti gbọ́ ohun tí ẹ̀yin ń gbọ́, wọn kò sì gbọ́ wọn.”
25 І підвівсь ось зако́нник один, і сказав, Його випробо́вуючи: „Учителю, що́ робити мені, щоб вічне життя осягну́ти?“ (aiōnios g166)
Sì kíyèsi i amòfin kan dìde, ó ń dán an wò, ó ní, “Olùkọ́, kín ni èmi ó ṣe kí èmi lè jogún ìyè àìnípẹ̀kun?” (aiōnios g166)
26 Він же йому відказав: „Що́ в Зако́ні написано, як ти читаєш?“
Ó sì bi í pé, “Kí ni a kọ sínú ìwé òfin? Báwo ni ìwọ sì ti kà á?”
27 А той відповів і сказав: „Люби Господа Бога свого́ всім серцем своїм, і всією душею своєю, і всією силою своєю, і всім своїм розумом“, і свого ближнього, як само́го себе“.
Ó sì dáhùn wí pé, “‘Kí ìwọ fi gbogbo àyà rẹ, àti gbogbo ọkàn rẹ, àti gbogbo agbára rẹ, àti gbogbo inú rẹ fẹ́ Olúwa Ọlọ́run rẹ’; àti, ‘Ẹnìkejì rẹ bí ara rẹ.’”
28 Він же йому́ відказав: „Правильно ти відповів. Роби це, — і будеш жити“.
Ó sì wí fún un pé, “Ìwọ́ dáhùn rere. Ṣe èyí, ìwọ ó sì yè.”
29 А той бажав сам себе ви́правдати, та й сказав до Ісуса: „А хто то мій ближній?“
Ṣùgbọ́n ó ń fẹ́ láti da ara rẹ̀ láre, ó wí fún Jesu wí pé, “Ta ha sì ni ẹnìkejì mi?”
30 А Ісус відповів і промовив: „Один чоловік ішов з Єрусалиму до Єрихо́ну, і попався розбійникам, що обдерли його, і завдали́ йому рани, та й утекли́, покинувши ле́две живого його́.
Jesu sì dáhùn ó wí pé, “Ọkùnrin kan ń ti Jerusalẹmu sọ̀kalẹ̀ lọ sí Jeriko, ó sì bọ́ sí ọwọ́ àwọn ọlọ́ṣà; wọ́n gbà á ní aṣọ, wọ́n sá a lọ́gbẹ́, wọ́n sì fi sílẹ̀ lọ ní àìpatán.
31 Прохо́див випа́дком тією дорогою священик один, побачив його, — і проминув.
Ní kòńgẹ́ àkókò yìí ni àlùfáà kan sì ń sọ̀kalẹ̀ lọ lọ́nà náà. Nígbà tí ó sì rí i ó kọjá lọ níhà kejì.
32 Так само й Левит надійшов на те місце, поглянув, — і теж проминув.
Bẹ́ẹ̀ náà sì ni ọmọ Lefi kan pẹ̀lú, nígbà tí ó dé ibẹ̀, tí ó sì rí i, ó kọjá lọ níhà kejì.
33 Прохо́див же там якийсь самаряни́н, та й натра́пив на нього, і, побачивши, змилосе́рдився.
Ṣùgbọ́n ará Samaria kan, bí ó ti ń re àjò, ó dé ibi tí ó gbé wà; nígbà tí ó sì rí i, àánú ṣe é.
34 І він підійшов, і обв'язав йому рани, наливши оливи й вина. Потому його посадив на худо́бину власну, і приставив його до гостиниці, та й клопота́вся про нього.
Ó sì tọ̀ ọ́ lọ, ó sì di ọgbẹ́ rẹ̀, ó da òróró àti ọtí wáìnì sí i, ó sì gbé e lé orí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ti òun tìkára rẹ̀, ó sì mú un wá sí ilé èrò, a sì ń ṣe ìtọ́jú rẹ̀.
35 А другого дня, від'їжджавши, вийняв він два динарії, та й дав їх госпо́дареві й проказав: „Заопікуйся ним, а як більше що витратиш, — заплачу́ тобі, як верну́ся“.
Nígbà tí ó sì lọ ní ọjọ́ kejì, ó fi owó idẹ méjì fún olórí ilé èrò ó sì wí fún un pé, ‘Máa tọ́jú rẹ̀; ohunkóhun tí ìwọ bá sì ná kún un, nígbà tí mo bá padà dé, èmi ó san án fún ọ.’
36 Котри́й же з цих трьох — на думку твою — був ближній тому, хто попався розбійникам?“
“Nínú àwọn mẹ́tẹ̀ẹ̀ta wọ̀nyí, ta ni ìwọ rò pé ó jẹ́ ẹnìkejì ẹni tí ó bọ́ sí ọwọ́ àwọn ọlọ́ṣà?”
37 А він відказав: „Той, хто вчинив йому ми́лість“. Ісус же сказав йому: „Іди, — і роби так і ти!“
Ó sì dáhùn wí pé, “Ẹni tí ó ṣàánú fún un ni.” Jesu sì wí fún un pé, “Lọ, kí o ṣe bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́!”
38 І сталось, коли вони йшли, Він прийшов до одно́го села. Одна ж жінка, Марта їй на ім'я́, прийняла Його в дім свій.
Ó sì ṣe, bí wọ́n ti ń lọ, o wọ ìletò kan, obìnrin kan tí a ń pè ní Marta sì gbà á sí ilé rẹ̀.
39 Була ж в неї сестра, що звалась Марія; вона сіла в ногах у Ісуса, та й слухала сло́ва Його.
Ó sì ní arábìnrin kan tí a ń pè ní Maria tí ó sì jókòó lẹ́bàá ẹsẹ̀ Olúwa, tí ó ń gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀.
40 А Марта великою по́слугою клопота́лась, а спинившись, сказала: „Господи, чи байду́же Тобі, що на мене саму́ полишила служити сестра моя? Скажи ж їй, щоб мені помогла“.
Ṣùgbọ́n Marta ń ṣe ìyọnu ohun púpọ̀, ó sì tọ̀ ọ́ wá, ó wí pé, “Olúwa, ìwọ kò sì bìkítà sí ti arábìnrin mi pé ó fi mí sílẹ̀ láti máa nìkan ṣe ìránṣẹ́? Wí fún un kí ó ràn mí lọ́wọ́.”
41 Госпо́дь же промовив у відповідь їй: „Марто, Марто, — турбуєшся й жу́ришся ти про багато чого́,
Ṣùgbọ́n Olúwa sì dáhùn, ó sì wí fún un pé, “Marta, Marta, ìwọ ń ṣe àníyàn àti làálàá nítorí ohun púpọ̀.
42 а потрібне одне. Марія ж обрала найкращу ча́стку, яка не відбереться від неї“.
Ṣùgbọ́n ohun kan ni a kò lè ṣe aláìní, Maria sì ti yan ipa rere náà tí a kò lè gbà lọ́wọ́ rẹ̀.”

< Від Луки 10 >