< Книга Суддів 13 >
1 А Ізраїлеві сини й далі робили зло в Господніх оча́х. І Господь віддав їх у руку филисти́млян на сорок літ.
Àwọn ọmọ Israẹli sì túnṣe ohun tí ó burú ní ojú Olúwa, Olúwa sì fi wọ́n lé àwọn ará Filistini lọ́wọ́ fún ogójì ọdún.
2 І був один чоловік з Цар'ї, да́нівець з роду, а ім'я́ йому — Мано́ах. А жінка його була неплідна, і не родила.
Ọkùnrin ará Sora kan wà, orúkọ rẹ̀ a máa jẹ́ Manoa láti ẹ̀yà Dani. Aya rẹ̀ yàgàn kò sì bímọ.
3 І явився Ангол Господній до тієї жінки, та й промовив до неї: „Ось ти неплі́дна, і не роджала, але ти зачнеш і породиш сина.
Angẹli Olúwa fi ara han obìnrin náà, ó sì wí fún un pé, “Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ìwọ yàgàn, ìwọ kò sì tí ì bímọ, ìwọ yóò lóyún, ìwọ yóò sì bí ọmọkùnrin kan.
4 А тепер стережись, і не пий вина та п'янко́го напо́ю, і не їж нічого нечистого,
Báyìí rí i dájúdájú pé ìwọ kò mu wáìnì tàbí ọtí líle kankan àti pé ìwọ kò jẹ ohun aláìmọ́ kankan,
5 бо ось ти зачнеш, і сина породиш, і бри́тва не торкнеться його голови, бо дитя те буде Божим назоре́єм від утро́би, — і він зачне спаса́ти Ізраїля з руки филисти́млян“.
nítorí ìwọ yóò lóyún, ìwọ yóò sì bí ọmọkùnrin kan. Má ṣe fi abẹ kan orí rẹ̀, nítorí pé Nasiri, ẹni ìyàsọ́tọ̀ fún Ọlọ́run ni ọmọ náà yóò jẹ́ láti ọjọ́ ìbí rẹ̀. Òun ni yóò bẹ̀rẹ̀ ìdáǹdè àwọn ọmọ Israẹli kúrò ní ọwọ́ àwọn ará Filistini.”
6 І прийшла та жінка, та й сказала до чоловіка свого, говорячи: „Божий чоловік прихо́див до мене, а вигляд його — як вигляд Божого Ангола, дуже грізни́й. І я не питала його, звідки він, а йме́ння свого він мені не сказав.
Nígbà náà ni obìnrin náà tọ ọkọ rẹ̀ lọ, o sì sọ fún un wí pé, “Ènìyàn Ọlọ́run kan tọ̀ mí wá. Ó jọ angẹli Ọlọ́run, ó ba ènìyàn lẹ́rù gidigidi. Èmi kò béèrè ibi tí ó ti wá, òun náà kò sì sọ orúkọ rẹ̀ fún mi.
7 І сказав він мені: Ось ти зачне́ш, і поро́диш сина, а тепер не пий вина та п'янко́го напо́ю, і не їж жодної нечистости, бо дитя те буде Божим назоре́єм від утро́би аж до дня смерти своєї“.
Ṣùgbọ́n ó sọ fún mi wí pé, ‘Ìwọ yóò lóyún, ìwọ yóò sì bí ọmọkùnrin kan, fún ìdí èyí, má ṣe mu wáìnì tàbí àwọn ọtí líle mìíràn bẹ́ẹ̀ ni kí ìwọ má ṣe jẹ ohunkóhun tí í ṣe aláìmọ́, nítorí pé Nasiri Ọlọ́run ni ọmọ náà yóò jẹ́ láti ọjọ́ ìbí rẹ̀ títí di ọjọ́ ikú rẹ̀.’”
8 І благав Мано́ах Господа, та й сказав: „О Господи, — Божий чоловік, що його́ посилав Ти, нехай при́йде ще до нас, і нехай нас навчи́ть, що́ ми зробимо для дитини, що народиться“.
Nígbà náà ni Manoa gbàdúrà sí Olúwa wí pé, “Háà Olúwa, èmi bẹ̀ ọ́, jẹ́ kí ènìyàn Ọlọ́run tí ìwọ rán sí wa padà tọ̀ wá wá láti kọ́ wa bí àwa yóò ti ṣe tọ́ ọmọ tí àwa yóò bí náà.”
9 І вислухав Бог цей Маноахів голос, і прийшов Божий Ангол ще до тієї жінки. А вона сиділа на полі, і Мано́аха, чоловіка її, не було́ з нею.
Ọlọ́run fetí sí ohùn Manoa, angẹli Ọlọ́run náà tún padà tọ obìnrin náà wá nígbà tí ó wà ní oko ṣùgbọ́n ọkọ rẹ̀ Manoa kò sí ní ọ̀dọ̀ rẹ̀.
10 І поспішила та жінка, і побігла та й оповіла́ чоловікові своєму, і сказала до нього: „Ось з'явився мені той чоловік, що прихо́див був того дня до ме́не“.
Nítorí náà ni obìnrin náà ṣe yára lọ sọ fún ọkọ rẹ̀ pé, “Ọkùnrin tí ó fi ara hàn mí ní ọjọ́sí ti tún padà wá.”
11 І встав, і пішов Маноах за своєю жінкою, і прийшов до того чоловіка, та й сказав йому: „Чи ти той чоловік, що говорив до цієї жінки?“А той сказав: „Я“.
Manoa yára dìde, ó sì tẹ̀lé aya rẹ̀, nígbà tí ó dé ọ̀dọ̀ ọkùnrin náà ó ní, “Ǹjẹ́ ìwọ ni o bá obìnrin yìí sọ̀rọ̀?” Ọkùnrin náà dáhùn pé, “Èmi ni.”
12 І сказав Маноах: „Тепер нехай спо́вниться слово твоє. Та як нам вихо́вувати ту дитину, і що чинити з нею?
Manoa bi ọkùnrin náà pé, “Nígbà tí ọ̀rọ̀ rẹ bá ṣẹ kí ni yóò jẹ́ ìlànà fún ìgbé ayé àti iṣẹ́ ọmọ náà?”
13 І сказав Ангол Господній до Маноаха: „Усього, що́ сказав я жінці, нехай вона стереже́ться.
Angẹli Olúwa náà dáhùn wí pé, “Aya rẹ gbọdọ̀ ṣe gbogbo ohun tí mo ti sọ fún un
14 Усього, що́ виходить із виноградного куща́, не буде вона їсти, а вина та напо́ю п'янко́го нехай не п'є, і нічого нечистого нехай не їсть. Нехай додержує всього, що я наказав“.
kò gbọdọ̀ jẹ ohunkóhun tí ó bá ti inú èso àjàrà jáde wá, bẹ́ẹ̀ ni kò gbọdọ̀ mu wáìnì tàbí àwọn ọtí líle mìíràn tàbí jẹ ohunkóhun tí ó bá jẹ́ aláìmọ́. Ó ní láti ṣe ohun gbogbo tí mo ti pàṣẹ fún un.”
15 І сказав Маноах до Ангола Господнього: „Нехай ми заде́ржимо тебе, і пригото́вимо для тебе козля́“.
Manoa sọ fún angẹli Olúwa náà pé, “Jọ̀wọ́ dára dúró títí àwa yóò fi pèsè ọ̀dọ́ ewúrẹ́ kan fún ọ.”
16 І сказав Ангол Господній до Маноаха: „Якщо ти заде́ржиш мене, я не бу́ду їсти твого хліба. А якщо приготу́єш цілопа́лення — для Господа принесеш його“. Бо Маноах не знав, що це Ангол Господній.
Angẹli Olúwa náà dá Manoa lóhùn pé, “Bí ẹ̀yin tilẹ̀ dá mi dúró, èmi kì yóò jẹ ọ̀kankan nínú oúnjẹ tí ẹ̀yin yóò pèsè. Ṣùgbọ́n tí ẹ̀yin bá fẹ́ ẹ pèsè ọrẹ ẹbọ sísun, kí ẹ sì fi rú ẹbọ sí Olúwa.” (Manoa kò mọ̀ pé angẹli Olúwa ní i ṣe.)
17 І сказав Маноах до Господнього Ангола: „Яке ім'я́ твоє? Коли спо́вниться твоє слово, то ми вшануємо тебе“.
Manoa sì béèrè lọ́wọ́ angẹli Olúwa náà pé, “Kí ni orúkọ rẹ, kí àwa bá à lè fi ọlá fún ọ nígbà tí ọ̀rọ̀ rẹ bá ṣẹ?”
18 І сказав йому Ангол Господній: „Чому ти питаєшся про моє ім'я́? Воно дивне“.
Ṣùgbọ́n angẹli Olúwa náà dáhùn pé, “Èéṣe tí ìwọ ń béèrè orúkọ mi? Ìyanu ni, ó kọjá ìmọ̀.”
19 І взяв Маноах козля́ та жертву хлі́бну, і на скелі приніс Господе́ві. І Він учинив чудо, а Маноах та його жінка бачили те.
Lẹ́yìn náà ni Manoa mú ọ̀dọ́ ewúrẹ́, pẹ̀lú ẹbọ ọkà, ó sì fi rú ẹbọ lórí àpáta kan sí Olúwa. Nígbà tí Manoa àti ìyàwó dúró tí wọn ń wò Olúwa ṣe ohun ìyanu kan.
20 І сталося, коли по́лум'я підіймалося з-над жертівника до неба, то Ангол Господній вознісся в по́лум'ї жертівника. А Маноах та жінка його бачили це, та й попа́дали обличчям своїм на землю.
Bí ẹ̀là ahọ́n iná ti là jáde láti ibi pẹpẹ ìrúbọ náà sí ọ̀run, angẹli Olúwa gòkè re ọ̀run láàrín ahọ́n iná náà. Nígbà tí wọ́n rí ìṣẹ̀lẹ̀ yìí, Manoa àti aya rẹ̀ wólẹ̀ wọ́n sì dojúbolẹ̀.
21 І Ангол Господній більш уже не появлявся до Маноаха та до жінки його. Тоді Маноах пізнав, що це Ангол Господній.
Nígbà tí angẹli Olúwa náà kò tún fi ara rẹ̀ han Manoa àti aya rẹ̀ mọ́, Manoa wá mọ̀ pé angẹli Olúwa ni.
22 І сказав Маноах до своєї жінки: „Ми справді помремо́, бо ми бачили Бога“.
Manoa sọ fún aya rẹ̀ pé, “Dájúdájú àwa yóò kú nítorí àwa ti fi ojú rí Ọlọ́run.”
23 І сказала йому жінка його: „Коли б Господь хотів був повбивати нас, не взяв би з нашої руки цілопа́лення та хлібної жертви, і не дав би нам побачити всього цьо́го, і не об'явив би нам цього ча́су речі, як це“.
Ṣùgbọ́n ìyàwó rẹ̀ dáhùn pé, “Bí Olúwa bá ní èrò àti pa wá kò bá tí gba ẹbọ sísun àti ọrẹ ọkà wa, tàbí fi gbogbo nǹkan wọ̀nyí hàn wá tó sọ nǹkan ìyanu yìí fún wa.”
24 І породила та жінка сина, і назвала ім'я́ йому: Самсо́н. І виро́став той хло́пець, і Господь благословля́в його́.
Obìnrin náà sì bí ọmọkùnrin kan, ó sì sọ orúkọ rẹ̀ ní Samsoni. Ọmọ náà dàgbà Olúwa sì bùkún un.
25 А Дух Господній почав дія́ти в ньо́му в Дановім табо́рі між Цор'а та між Ештаолом.
Ẹ̀mí Olúwa sì bẹ̀rẹ̀ sí ru sókè nígbà tí ó wà ní Mahane-Dani ní agbede-méjì Sora àti Eṣtaoli.