< Йов 20 >

1 І відповів нааматянин Цофа́р та й сказав:
Ìgbà náà ní Sofari, ará Naama dáhùn, ó sì wí pé,
2 „Тому́ то думки́ мої відповідати мене наверта́ють, і тому́ то в мені цей мій по́спіх!
“Nítorí náà ní ìrò inú mi dá mi lóhùn, àti nítorí èyí náà ní mo sì yára si gidigidi.
3 Соромли́ву нага́ну собі я почув, та дух з мого розуму відповідає мені.
Mo ti gbọ́ ẹ̀san ẹ̀gàn mi, ẹ̀mí òye mi sì dá mi lóhùn.
4 Чи знаєш ти те, що від вічности, відколи́ люди́на на землі була поста́влена, —
“Ìwọ kò mọ̀ èyí rí ní ìgbà àtijọ́, láti ìgbà tí a sọ ènìyàn lọ́jọ̀ sílé ayé,
5 то спів несправедливих короткий, а радість безбожного — тільки на хвилю?
pé, orin ayọ̀ ènìyàn búburú, ìgbà kúkúrú ni, àti pé, ní ìṣẹ́jú kan ní ayọ̀ àgàbàgebè?
6 Якщо піднесе́ться вели́чність його аж до неба, а його голова аж до хмари дося́гне,
Bí ọláńlá rẹ̀ tilẹ̀ gòkè dé ọ̀run, ti orí rẹ̀ sì kan àwọsánmọ̀;
7 проте́ він загине навіки, немов його гній, хто бачив його, запитає: де він?
ṣùgbọ́n yóò ṣègbé láéláé bí ìgbẹ́ ara rẹ̀; àwọn tí ó ti rí i rí yóò wí pé, ‘Òun ha dà?’
8 Немов сон улетить — і не зна́йдуть його, мов виді́ння нічне́, він споло́шений буде:
Yóò fò lọ bí àlá, a kì yóò sì rí i, àní a ó lé e lọ bi ìran òru.
9 його бачило око, та бачити більше не бу́де, і вже не побачить його його місце...
Ojú tí ó ti rí i rí kì yóò sì rí i mọ́, bẹ́ẹ̀ ni ibùjókòó rẹ̀ kì yóò sì ri i mọ́.
10 Сини його запобіга́тимуть ла́ски в нужде́нних, а ру́ки його позверта́ють маєток його.
Àwọn ọmọ rẹ̀ yóò máa wá àti rí ojúrere lọ́dọ̀ tálákà, ọwọ́ rẹ̀ yóò sì kó ọrọ̀ wọn padà.
11 Повні кості його молоде́чости, — та до по́роху з ним вона ляже!
Egungun rẹ̀ kún fún agbára ìgbà èwe rẹ̀, tí yóò bá a dùbúlẹ̀ nínú erùpẹ̀.
12 Якщо в у́стах його зло солодке, — його він таї́ть під своїм язиком,
“Bí ìwà búburú tilẹ̀ dún ní ẹnu rẹ̀, bí ó tilẹ̀ pa á mọ́ nísàlẹ̀ ahọ́n rẹ̀,
13 над ним милосе́рдиться та не пускає його, і тримає його в своїх устах, —
bí ó tilẹ̀ dá a sì, tí kò si kọ̀ ọ́ sílẹ̀, tí ó pa á mọ́ síbẹ̀ ní ẹnu rẹ̀,
14 то цей хліб в його ну́трощах змі́ниться, — стане він жо́вчю змії́ною в нутрі його́!
ṣùgbọ́n oúnjẹ rẹ̀ nínú ikùn rẹ̀ ti yípadà, ó jásí òróró paramọ́lẹ̀ nínú rẹ̀;
15 Він маєток чужо́го ковтав, але́ його ви́блює: Бог виганяє його із утро́би його.
Ó ti gbé ọrọ̀ mì, yóò sì tún bí i jáde; Ọlọ́run yóò pọ̀ ọ́ yọ jáde láti inú rẹ̀ wá.
16 Отру́ту зміїну він сса́тиме, гадю́чий язик його вб'є!
Ó ti fà oró paramọ́lẹ̀ mú; ahọ́n ejò olóró ní yóò pa á.
17 Він річко́вих джере́л не побачить, струмків меду та молока.
Kì yóò rí odò wọ̀n-ọn-nì, ìṣàn omi, odò tí ń ṣàn fún oyin àti ti òrí-àmọ́.
18 Позверта́є він працю чужу, і її не ковтне́, як і маєток, набутий з виміни своєї, жувати не буде.
Ohun tí ó ṣiṣẹ́ fún ni yóò mú un padà, kí yóò sì gbé e mì; gẹ́gẹ́ bí ọrọ̀ tí ó ní, kì yóò sì ìgbádùn nínú rẹ̀.
19 Бо він переслідував, кидав убогих, він дім грабував, хоч не ставив його!
Nítorí tí ó fi owó rẹ̀ ni tálákà lára, ó sì ti pẹ̀yìndà si wọ́n; nítorí ti ó fi agbára gbé ilé tí òun kò kọ́.
20 Бо споко́ю не знав він у нутрі своїм, і свого наймилішого не збереже.
“Nítorí òun kò mọ̀ ìwà pẹ̀lẹ́ nínú ara rẹ̀, kì yóò sì gbà nínú èyí tí ọkàn rẹ̀ fẹ́ sílẹ̀.
21 Немає останку з обжи́рства його, тому нетрива́ле добро його все:
Ohun kan kò kù fún jíjẹ́ rẹ̀; nítorí náà ọ̀rọ̀ rẹ̀ kì yóò dúró pẹ́.
22 за по́вні достатку його буде тісно йому́, рука кожного скри́вдженого при́йде на нього!
Nínú ànító rẹ̀, ìdààmú yóò dé bá a; àwọn ènìyàn búburú yóò dáwọ́jọ lé e lórí.
23 Хай напо́внена буде утро́ба його, та пошле Він на нього жар гніву Свого, і бу́де дощи́ти на нього неду́гами його.
Yóò sì ṣe, nígbà tí ó bá fẹ́ jẹun, Ọlọ́run yóò fà ríru ìbínú rẹ̀ sí í lórí, nígbà tó bá ń jẹun lọ́wọ́, yóò sì rọ òjò ìbínú rẹ̀ lé e lórí.
24 Він бу́де втікати від зброї залізної, — та прони́же його мідний лук.
Bi o tilẹ̀ sá kúrò lọ́wọ́ ohun ìjà ìrìn; ọrun akọ irin ní yóò ta a po yọ.
25 Він стане меча́ витягати, і вийде він із тіла, та держа́к його вийде із жо́вчі його, і пере́страх на нього впаде́!
O fà á yọ, ó sì jáde kúrò lára; idà dídán ní ń jáde láti inú òróòro wá. Ẹ̀rù ńlá ń bẹ ní ara rẹ̀;
26 При ска́рбах його всі нещастя захо́вані, його буде же́рти огонь не роздму́хуваний, позостале в наметі його буде знищене.
òkùnkùn biribiri ní a ti pamọ́ fún ìṣúra rẹ̀. Iná ti a kò fẹ́ ní yóò jó o run yóò sì jẹ èyí tí ó kù nínú àgọ́ rẹ̀ run.
27 Небо відкриє його беззаконня, а земля проти нього повстане, —
Ọ̀run yóò fi ẹ̀ṣẹ̀ rẹ hàn, ayé yóò sì dìde dúró sí i.
28 урожай його дому втече, розпливеться в день гніву Його.
Ìbísí ilé rẹ̀ yóò kọjá lọ, àti ohun ìní rẹ̀ yóò sàn dànù lọ ni ọjọ́ ìbínú Ọlọ́run.
29 Оце доля від Бога люди́ні безбожній, і спа́дщина, обі́цяна Богом для неї!“
Èyí ni ìpín ènìyàn búburú láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá, àti ogún tí a yàn sílẹ̀ fún un láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run.”

< Йов 20 >