< Єзекіїль 22 >
1 І було мені слово Господнє таке:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
2 „А ти, сину лю́дський, чи будеш судити, чи суди́тимеш ти місто крови? І завідо́м його про всі гидо́ти його,
“Ọmọ ènìyàn ǹjẹ́ ìwọ yóò ha ṣe ìdájọ́ rẹ̀? Ǹjẹ́ ìwọ ha ṣe ìdájọ́ ìlú atàjẹ̀sílẹ̀? Tó bá rí bẹ́ẹ̀ dojúkọ wọn pẹ̀lú gbogbo ìwà ìríra wọn.
3 та й скажеш: Так говорить Господь Бог: Місто проливає кров у своїй сере́дині, щоб прийшов його час, і робить божкі́в собі, щоб занечи́щуватися!
Kí ó sì wí pé, ‘Èyí yìí ní ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Ìwọ ìlú ńlá tí ó mú ìparun wá sórí ara rẹ nípa títàjẹ̀sílẹ̀ ní àárín rẹ, tí ó sì ba ara rẹ̀ jẹ́ nípa ṣíṣe àwọn ère.
4 Кров'ю, що ти проливала, о дочко Єрусалиму, грішила ти, а божка́ми, яких ти робила, занечи́стилася, і набли́зила свої дні, і прийшла аж до своїх ро́ків. Тому дам тебе наро́дам на га́ньбу, і на посміхо́висько для всіх країв!
Ìwọ ti jẹ̀bi nítorí ẹ̀jẹ̀ tí ìwọ ti ta sílẹ̀, àti pé àwọn ère tí ó ṣe tí bà ọ́ jẹ́. Ìwọ tí mú ọjọ́ rẹ súnmọ́ tòsí, ìparí àwọn ọdún rẹ sì ti dé. Nítorí náà èmi yóò fi ọ ṣe ohun ẹ̀gàn lójú àwọn orílẹ̀-èdè àti ohun ẹ̀sín lójú gbogbo ìlú.
5 Близькі та далекі від тебе насміхаються з тебе, нечистойме́нна, багатозаколо́тна!
Àwọn tí ó wà ní tòsí àti àwọn tí ó jìnnà sí ọ, yóò fi ọ ṣe ẹlẹ́yà, ìwọ ìlú ẹlẹ́gàn, tí ó kún fún làálàá.
6 Ось Ізраїлеві князі, кожен за раме́ном своїм, були́ в тебе, щоб кров проливати.
“‘Wo bí ọ̀kọ̀ọ̀kan nínú àwọn ọmọbìnrin ọba Israẹli tí ó wà nínú yín ti ń lo agbára rẹ̀ láti tàjẹ̀ sílẹ̀.
7 Батька та матір у тебе легкова́жать, чужи́нцеві роблять у́тиск серед тебе, сироту та вдову пригнічують у тебе.
Nínú rẹ wọn ti hùwà sí baba àti ìyá pẹ̀lú ìfojú tínrín; nínú rẹ wọn ti ni àwọn àlejò lára, wọn sì hùwàkiwà sí aláìní baba àti opó.
8 Моїми свя́тощами ти погорджуєш, а суботи Мої зневажаєш.
Ìwọ tí kọ àwọn ohun mímọ́ mi sílẹ̀, ìwọ sì ti lo ọjọ́ ìsinmi mi ní ìlòkulò.
9 У тебе є накле́пники, щоб кров проливати, і на па́гірках їдять у тебе, розпусту чинять серед тебе.
Nínú rẹ ni àwọn ayannijẹ ènìyàn pinnu láti tàjẹ̀ sílẹ̀; nínú rẹ ní àwọn tí ó ń jẹun ní orí òkè ojúbọ òrìṣà, wọn sì hùwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́.
10 Наготу́ батька в тебе відкривають, жінку, у ча́сі її місячної нечистоти́, безчестять у тебе.
Nínú rẹ ní àwọn ti kò bu ọlá fún àwọn àkéte baba wọn; nínú rẹ ni àwọn tí o ń bá àwọn obìnrin lò nígbà tí wọ́n ń ṣe àkókò lọ́wọ́, ní àsìkò tí a ka wọn sì aláìmọ́.
11 І один робить гидо́ту з жінкою свого ближнього, а той занечищує розпустою невістку свою, а той безчестить у тебе сестру свою, дочку́ батька свого́.
Nínú rẹ ọkùnrin kan ti dá ẹ̀ṣẹ̀ ìríra pẹ̀lú aya aládùúgbò rẹ̀, òmíràn bá ìyàwó ọmọ rẹ̀ jẹ́, òmíràn sì bá arábìnrin rẹ̀ lòpọ̀ èyí tí í ṣe ọbàkan rẹ̀.
12 Пі́дкуп беруть у тебе, щоб кров проливати, ли́хву та відсо́тка береш ти й ошу́куєш у́тиском ближніх своїх. А Мене ти забуваєш, говорить Господь Бог.
Nínú rẹ àwọn ènìyàn gba àbẹ̀tẹ́lẹ̀ láti tàjẹ̀ sílẹ̀; ìwọ gba èlé ìlọ́po láti mú aláìṣòótọ́ jèrè láti ara aládùúgbò rẹ nípa ìrẹ́jẹ. Ìwọ sì ti gbàgbé èmi; ni Olúwa Olódùmarè wí.
13 І ось сплесну́в Я руками Своїми за твою кривду, яку ти робила, та за кровопролиття́ твої, що були в тебе.
“‘Èmi yóò kúkú pàtẹ́wọ́ lórí èrè àìmọ̀ tí ìwọ ti jẹ, àti lórí ẹ̀jẹ̀ tí ìwọ ti ta sílẹ̀ ní àárín yín.
14 Чи всто́їть твоє серце, чи будуть міцні́ твої руки на ті дні, що Я буду з тобою чинити? Я, Господь, говорив це й зробив!
Ọkàn rẹ le gbà á, tàbí ọwọ́ rẹ lè le, ní ọjọ́ tí èmi yóò bá ọ ṣé? Èmi Olúwa ti sọ̀rọ̀, Èmi yóò sì ṣe é.
15 І розпоро́шу тебе серед наро́дів, і розси́плю тебе по края́х, і викину твою нечистість із тебе.
Èmi yóò tú yin ká ní àárín àwọn orílẹ̀-èdè, èmi yóò fọ́n ọ ká sí àwọn ìlú; èmi yóò sì fi òpin sí àìmọ́ rẹ.
16 І станеш ти збезче́щеною через себе на оча́х народів, і пізнаєш, що Я — Госпо́дь!“
Nígbà tí a ó bà ọ́ jẹ́ lójú àwọn orílẹ̀-èdè, ìwọ yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.’”
17 І було мені слово Господнє таке:
Nígbà náà ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
18 „Сину лю́дський, дім Ізраїлів став мені за жу́желицю; усі вони мідь, і ци́на, і залізо, і о́ливо в сере́дині го́рна, жу́желицею срі́бла сталися.
“Ọmọ ènìyàn, ilé Israẹli ti di ìdàrọ́ sí mi; gbogbo wọn jẹ́ bàbà, idẹ, irin àti òjé ti a fi sínú iná ìléru. Wọn jẹ́ ìdàrọ́ ti fàdákà.
19 Тому так говорить Господь Бог: За те, що всі ви стали жу́желицею, тому ось Я позбираю вас до сере́дини Єрусалиму.
Nítorí náà èyí yìí ni ohun ti Olúwa Olódùmarè wí: ‘Nítorí tí ìwọ ti di ìdàrọ́, èmi yóò kó yín jọ sí Jerusalẹmu.
20 Як збирають срі́бло, і мідь, і залізо, і о́ливо, і цину до сере́дини го́рна, щоб дмухати на нього огнем, щоб розтопи́ти, — так зберу́ у Своїм гніві та в люті Своїй, і покладу́, і розтоплю́ вас!
Gẹ́gẹ́ bí ènìyàn ṣe ń kó fàdákà, bàbà, irin, òjé àti idẹ jọ sínú iná ìléru láti fi iná yọ́ ọ, bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò kó ọ jọ ní ìbínú àti ìrunú mi, èmi yóò sì fi ọ sì àárín ìlú, èmi yóò sì yọ́ ọ. Níbẹ̀ ní ìwọ yóò sì ti yọ́.
21 І позбираю вас, і дмухну́ на вас огнем Свого гніву, і ви будете розто́плені в сере́дині його.
Èmi yóò kó yín jọ, èmi o sì fín iná ìbínú mi si yin lára, ẹ o si di yíyọ́ láàrín rẹ̀.
22 Як розто́плюється срібло в сере́дині го́рна, так бу́дете розто́плені ви в сере́дині його, і пізна́єте, що Я, Господь, вилив гнів Свій на вас!“
Bí a ti ń yọ́ fàdákà nínú iná ìléru bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ní ìwọ yóò ṣe yọ́ nínú rẹ̀, ìwọ yóò sì mọ̀ wí pé, Èmi Olúwa ti tú ìbínú mi sórí rẹ.’”
23 І було мені слово Господнє таке:
Lẹ́ẹ̀kan sí i ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé,
24 „Сину лю́дський, скажи до неї: Ти земля неочи́щена, у дні гніву доще́м не поли́тая!
“Ọmọ ènìyàn, sọ fún ilẹ̀ náà, ‘Ìwọ ní ilẹ̀ tí kò gbá mọ́, ti kò sì rọ òjò tàbí ìrì ní àkókò ìbínú.’
25 Змо́ва її пророків серед нього, як реву́чий лев, що здо́бич шматує: жеру́ть душу, маєток та багатство забирають, прибі́льшують уді́в її в сере́дині її.
Ìdìtẹ̀ sì wà láàrín àwọn ọmọ-aládé inú rẹ̀, tó dàbí bíbú kìnnìún tó ń fà ẹran ya, wọ́n ń ba àwọn ènìyàn jẹ́, wọ́n ń kó ìṣúra àti àwọn ohun iyebíye wọ́n sì ń sọ púpọ̀ di opó nínú rẹ̀.
26 Священики її ламають Зако́на Мого, і зневажаю́ть Мої святощі, не розрізняють між святим та несвятим, і не оголошують різни́ці між нечистим та чистим, і від субіт Моїх закривають свої очі. І був Я знева́жений серед них.
Àwọn àlùfáà rẹ̀ ti rú òfin mi, wọn si ti sọ ohun mímọ́ mi di àìlọ́wọ̀: wọn kò fi ìyàtọ̀ sáàrín ohun mímọ́ àti àìlọ́wọ̀, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò fi ìyàtọ̀ hàn láàrín ohun àìmọ́, àti mímọ́, wọn sì ti fi ojú wọn pamọ́ kúrò ní ọjọ́ ìsinmi mi, mó sì dí ẹni àìlọ́wọ̀ láàrín wọn.
27 Князі́ її в сере́дині її, немов ті вовки́, що здо́бич шмату́ють, щоб розливати кров, щоб губити ду́ші ради ко́ристи.
Àwọn ọmọ-aládé àárín rẹ̀ dàbí ìkookò ti ń ṣọdẹ, láti tàjẹ̀ sílẹ̀, láti pa ọkàn run, láti jèrè àìṣòótọ́.
28 А пророки її все замазують болотом, бачать марно́ту, і чару́ють собі неправдою, вони кажуть: „Так говорить Господь Бог“, а Господь не говорив.
Àti àwọn wòlíì rẹ́ ti ṣẹ̀tàn sí wọn, wọn ń rì ìran asán, wọn sì ń fọ àfọ̀ṣẹ èké sí wọn, wí pé, ‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí,’ nígbà tí ó ṣépè Olúwa kò sọ̀rọ̀.
29 Наро́ди Кра́ю тиснуть у́тиском та грабують грабунком, а вбогого та бідака́ гно́блять, а чужи́нця тиснуть у безправ'ї.
Àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà, tí lo ìwà ìninilára, wọn sì já olè, wọn sì ni àwọn tálákà àti aláìní lára; nítòótọ́, wọn tí ní àlejò lára láìnídìí. Kò sì ṣí ìdájọ́ òdodo.
30 І шукав Я між ними чоловіка, що поставив би загоро́ду, і став би в ви́ломі перед Моїм обличчям за цей Край, щоб Я не знищив його, — та Я не знайшов!
“Èmi si wá ẹnìkan láàrín wọn, tí ìbá tún odi náà mọ́, tí ìbá dúró ní ibi tí ó ya náà níwájú mi fún ilẹ̀ náà, kí èmi má bá à parun: ṣùgbọ́n èmi kò rí ẹnìkan.
31 І Я вилив на них Свій гнів, огнем пересе́рдя Свого повигу́блював їх, їхню дорогу Я дав на їхню го́лову, каже Господь Бог“.
Nítorí náà ni mo ṣe da ìbínú mi sí wọn lórí, mo ti fi iná ìbínú mi run wọn, mo si ti fi ọ̀nà wọn gbẹ̀san lórí ara wọn, ní Olúwa Olódùmarè wí.”