< Єзекіїль 11 >
1 І підійняв мене Дух, і привів мене до схі́дньої брами Господнього дому, що обе́рнена на схід. І ось при вході до брам двадцять і п'ять чоловіка, а серед них бачив я Яазанію, сина Аззурового, та Пелатію, сина Венаїного, князі́в народу.
Ẹ̀mí sì gbé mi sókè, ó mú mi lọ sí ẹnu-ọ̀nà ilé Olúwa èyí tó dojúkọ ìlà-oòrùn. Ní àbáwọlé ẹnu-ọ̀nà yìí ni àwọn ọkùnrin mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n wá, mo rí Jaaṣaniah ọmọ Assuri àti Pelatiah ọmọ Benaiah, tí wọ́n jẹ́ ìjòyè àwọn ènìyàn.
2 І сказав Він до мене: „Сину лю́дський, оце ті люди, що заду́мують кривду, і радять злу раду в цьому місті,
Olúwa sì sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, àwọn ọkùnrin yìí ló ń pète ibi, wọ́n sì ń gbé ìmọ̀ràn búburú kalẹ̀ nínú ìlú.
3 що говорять: „Не скоро будувати доми́. Воно — казан, а ми — м'ясо“.
Wọ́n ní, ‘Kò ha tí ì tó àsìkò láti kọ́lé? Ìlú yìí ni ìkòkò ìdáná, àwa sì ni ẹran’.
4 Тому́ пророкуй на них, пророкуй, сину лю́дський!“
Nítorí náà sọtẹ́lẹ̀ nípa wọn; ọmọ ènìyàn, sọtẹ́lẹ̀.”
5 І зійшов на мене Дух Господній, та й до мене сказав: „Скажи: Так говорить Господь: Отак кажете, доме Ізраїлів, і заміри вашого духа — Я знаю їх.
Ẹ̀mí Olúwa sì bà lé mi, ó sì wí pé, “Sọ̀rọ̀!” Báyìí ni Olúwa wí, ohun tí ẹ ń sọ nìyìí, ilé Israẹli, mo mọ ohun tó wà lọ́kàn yín.
6 Ви намно́жили своїх забитих у цьому місті, і напо́внили його вулиці тру́пами.
Ẹ̀yin ti sọ òkú yín di púpọ̀ nínú ìlú yìí, òkú sì ti kún gbogbo ìgboro rẹ̀.
7 Тому так говорить Госпо́дь Бог: Ваші забиті, що ви їх поклали серед нього, вони те м'ясо, а воно — той каза́н. Та Я ви́проваджу вас із нього!
“Torí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, àwọn òkú tí ẹ fọn sílẹ̀ sí àárín yín ni ẹran, ìlú yìí sì ni ìkòkò ìdáná ṣùgbọ́n èmi yóò le yín jáde níbẹ̀.
8 Ви боїте́ся меча — і меча наведу́ Я на вас, говорить Господь Бог.
Ẹ bẹ̀rù idà, èmi yóò sì mú idà wá sórí yín, bẹ́ẹ̀ ni Olúwa Olódùmarè wí.
9 І ви́проваджу вас із нього, і дам вас у руку чужих, і зроблю́ між вами при́суди!
Èmi yóò lé yín jáde kúrò ní ìlú yìí, èmi yóò sì fà yín lé àjèjì lọ́wọ́, èmi yóò sì mú ìdájọ́ ṣẹ lé yín lórí.
10 Від меча ви попа́даєте; на границі Ізраїля розсуджу́ вас, і ви пізнаєте, що Я — то Господь!
Nípa idà ni ẹ̀yin yóò ṣubú, èmi yóò sì ṣe ìdájọ́ yín ní àwọn ààlà ìlú Israẹli. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.
11 Воно не буде вам казано́м, і ви не станете в ньому м'ясом. При границі Ізраїля розсуджу́ вас!
Ìlú yìí kò ní i jẹ́ ìkòkò ìdáná, bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀yin náà kò sì ní jẹ́ ẹran nínú rẹ̀, Èmi yóò ṣe ìdájọ́ yín ní àwọn ààlà ìlú Israẹli.
12 І пізнаєте ви, що Я — Господь, бо за уставами Його ви не ходили, а постано́в Моїх не виконували, але виконували за постано́вами тих наро́дів, що навколо вас“.
Ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa, nítorí pé ẹ̀yin kò tẹ̀lé àṣẹ mi ẹ̀yin kò sì pa òfin mi mọ́, ṣùgbọ́n ẹ̀yin ti hùwà gẹ́gẹ́ bí àwọn aláìgbàgbọ́ orílẹ̀-èdè tó yí yín ká.”
13 І сталося, коли я пророкував, то Пелатія, син Бенаніїн, помер. І впав я на своє обличчя, і закричав сильним голосом та й сказав: „О Господи Боже, Ти робиш кінець з Ізраїлевим останком!“
Bí mo ṣe ń sọtẹ́lẹ̀ lọ́wọ́, Pelatiah ọmọ Benaiah kú. Mo sì dojúbolẹ̀, mo sì kígbe sókè pé, “Háà! Olúwa Olódùmarè! Ṣé ìwọ yóò ha pa ìyókù Israẹli run pátápátá ni?”
14 І було мені слово Господнє таке:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tún tọ̀ mí wá wí pé,
15 „Сину лю́дський, брати твої, брати твої — мужі рідні тобі, а ввесь Ізраїлів дім — увесь той, що до них говорили ме́шканці Єрусалиму: Віддалі́ться від Господа, нам даний цей край на володі́ння,
“Ọmọ ènìyàn, àwọn arákùnrin rẹ, àní àwọn ará rẹ, àwọn ọkùnrin nínú ìbátan rẹ, àti gbogbo ilé Israẹli pátápátá, ni àwọn ará Jerusalẹmu ti wí fún pé, ‘Ẹ jìnnà sí Olúwa, àwa ni a fi ilẹ̀ yìí fún yín ní ìní.’
16 тому скажи: Так говорить Господь Бог: Хоч Я віддали́в їх поміж народи, і хоч розпоро́шив їх по края́х, проте буду для них хоч малою святинею в тих края́х, куди вони ввійшли.
“Nítorí náà, sọ fún àwọn tó wà ní ìgbèkùn pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, bó tilẹ̀ jẹ́ pé mo ti fọ́n wọn káàkiri orílẹ̀-èdè, síbẹ̀ fún ìgbà díẹ̀, èmi yóò jẹ́ ibi mímọ́ fún wọn níbi tí wọ́n lọ.’
17 Тому́ скажи: Так говорить Господь Бог: І позбираю Я вас із народів, зберу́ з тих країв, серед яких ви розпоро́шені, і дам вам Ізраїлеву землю.
“Nítorí náà, wí pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, Èmi yóò kó wọn jọ kúrò láàrín àwọn orílẹ̀-èdè tí mo fọ́n wọn ká sí, Èmi yóò sì fún wọn ní ilẹ̀ Israẹli padà.’
18 І вони вві́йдуть туди, і викинуть з неї усі мерзо́ти її та всі гидо́ти її.
“Wọn yóò padà síbẹ̀, wọn yóò sì mú gbogbo àwòrán ìríra rẹ̀ àti ìbọ̀rìṣà rẹ̀ kúrò.
19 І дам їм одне серце, і ново́го духа дам у вас, і вийму з їхнього тіла серце камінне, і дам їм серце із м'яса,
Èmi yóò fún wọn ní ọ̀kankan; èmi yóò sì fi ẹ̀mí tuntun sínú wọn, Èmi yóò mú ọkàn òkúta kúrò lára wọn, èmi yóò sì fún wọn ní ọkàn tó rọ̀ bí ara ẹran.
20 щоб вони ходили за уставами Моїми, і додержували Мої постанови та виконували їх. І вони стануть Мені народом, а Я буду їм Богом!
Kí wọn le tẹ̀lé àṣẹ mi, kí wọn sì le pa òfin mi mọ́. Wọ́n yóò jẹ́ ènìyàn mi, Èmi náà yóò sì jẹ́ Ọlọ́run wọn.
21 А щодо тих, що їхнє серце ходить за гидо́тами своїми та мерзо́тами своїми, то поверну́ їхню дорогу на їхню голову, говорить Господь Бог“.
Ṣùgbọ́n fún àwọn tí wọ́n ń fi gbogbo ọkàn wọn sin àwọn àwòrán ìríra àti àwọn òrìṣà, Èmi yóò mú ẹ̀san ohun tí wọ́n ṣe wá sí orí wọn bẹ́ẹ̀ ni Olúwa Olódùmarè wí.”
22 І попідійма́ли Херувими кри́ла свої, а коле́са при них, і слава Ізраїлевого Бога зверху над ними.
Àwọn kérúbù sì gbé ìyẹ́ wọn sókè pẹ̀lú kẹ̀kẹ́ lẹ́gbẹ̀ẹ́ wọn, ògo Ọlọ́run Israẹli sì wà lókè orí wọn.
23 І підняла́ся слава Господня з-над сере́дини міста, і стала на горі, що зо сходу міста.
Ògo Olúwa sì gòkè lọ kúrò láàrín ìlú, ó sì dúró lórí òkè tó wà ní ìlà-oòrùn ìlú náà.
24 І дух підні́с мене, і ввів мене в Халдею до полоня́н у видінні, Духом Божим. І підійняло́ся від мене те виді́ння, яке я бачив.
Lẹ́yìn náà, Ẹ̀mí gbé mi sókè, ó sì mú mi wá sí Kaldea lójú ìran, nípa ti Ẹ̀mí Ọlọ́run sí ọ̀dọ̀ àwọn ti ìgbèkùn. Bẹ́ẹ̀ ni ìran tí mo rí lọ kúrò ní ọ̀dọ̀ mi,
25 І я говорив до полоня́н усі Господні слова, які Він наказав був мені.
mo sì sọ gbogbo ohun tí Olúwa fihàn mí fún àwọn tó wà ní ìgbèkùn.