< Вихід 24 >
1 А до Мойсея сказав Він: „Вийди до Господа ти й Ааро́н, Надав та Авігу́, та сімдеся́т із Ізраїлевих старши́х, і вклоніться здале́ка.
Ní ìgbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé, “Gòkè tọ Olúwa wá, ìwọ àti Aaroni, Nadabu àti Abihu àti àádọ́rin àwọn àgbàgbà Israẹli. Ẹ̀yin kì ó sìn ni òkèèrè réré.
2 А Мойсей нехай піді́йде до Господа сам, а вони не піді́йдуть. А наро́д з ним не вийде“.
Ṣùgbọ́n Mose nìkan ṣoṣo ni yóò súnmọ́ Olúwa; àwọn tókù kò gbọdọ̀ súnmọ́ tòsí ibẹ̀. Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ènìyàn kò gbọdọ̀ gòkè wá pẹ̀lú rẹ̀.”
3 І прибув Мойсей, та й оповів наро́дові всі Господні слова та всі зако́ни. І ввесь народ відповів одноголосно, та й сказали: „Усе, про що́ говорив Господь, зро́бимо!“
Nígbà ti Mose lọ láti sọ fún àwọn ènìyàn, gbogbo ọ̀rọ̀ àti òfin Olúwa, wọ́n wí ní ohùn kan pé, “Gbogbo ohun ti Olúwa wí ni àwa yóò ṣe.”
4 І написав Мойсей всі Господні слова. І встав він рано вранці, та й збудува́в же́ртівника під горою, та дванадцять кам'яни́х стовпів для дванадцяти́ Ізраїлевих племе́н.
Nígbà náà ni Mose kọ gbogbo ohun tí Olúwa sọ sílẹ̀. Ó dìde ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ó sì mọ pẹpẹ ni ẹsẹ̀ òkè náà. Ó ṣe ọ̀wọ́n òkúta méjìlá. Èyí ti ó dúró fún àwọn ẹ̀yà Israẹli méjìlá.
5 І послав він юнакі́в, синів Ізраїлевих, і вони зложили цілопа́лення, і прине́сли жертви, мирні жертви для Господа, бички.
Nígbà náà ni ó rán àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin Israẹli, wọ́n sì rú ẹbọ sísun, wọ́n fi ọ̀dọ́ màlúù rú ẹbọ àlàáfíà si Olúwa.
6 І взяв Мойсей половину крови, і влив до мідниць, а другу половину тієї крови вилив на же́ртівника.
Mose bu ìlàjì ẹ̀jẹ̀ ẹran sínú abọ́, ó sì fi ìlàjì tókù wọn ara pẹpẹ.
7 І взяв він книгу заповіту, та й відчитав вголос народові. А вони сказали: „Усе, що говорив Господь, зробимо й послухаємо!“
Nígbà náà ni ó sì mú ìwé májẹ̀mú, ó sì kà á sí àwọn ènìyàn. Wọ́n dáhùn pé, “Àwa yóò ṣe gbogbo ohun tí Olúwa wí. Àwa yóò sì gbọ́rọ̀.”
8 І взяв Мойсей тієї кро́ви, і покропив на народ, та й сказав: „Оце кров запові́ту, що Господь уклав із вами про всі оці речі!“
Nígbà náà ni Mose gbé ẹ̀jẹ̀, ó sì wọn sí àwọn ènìyàn náà lára pé, “Èyí ni ẹ̀jẹ̀ májẹ̀mú tí Olúwa ti ṣe pẹ̀lú yín ni ìbámu pẹ̀lú àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí.”
9 І вийшов Мойсей й Ааро́н, Надав та Авігу, та сімдеся́т Ізраїлевих старши́х,
Mose àti Aaroni, Nadabu àti Abihu àti àádọ́rin àwọn àgbàgbà Israẹli gòkè lọ.
10 і вони спогляда́ли на Ізраїлевого Бога, а під ногами Його ніби зро́блене з сапфірової плити́, і немов саме небо, щодо ясности.
Wọ́n sì rí Ọlọ́run Israẹli. Ní abẹ́ ẹsẹ̀ rẹ̀ ni ohun kan bí i pèpéle ti a fi òkúta safire ṣe wà. Èyí ti ó mọ́ nigínnigín bí àwọ̀ sánmọ̀ fúnra rẹ̀.
11 І він не простяг Своєї руки на достойних із синів Ізраїля. І вони споглядали на Бога, — і їли й пили.
Ṣùgbọ́n Ọlọ́run kò gbé ọwọ́ rẹ̀ sókè sí àwọn àgbàgbà Israẹli wọ̀nyí; wọ́n ri Ọlọ́run, wọ́n jẹ, wọ́n sì mu.
12 І промовив Господь до Мойсея: „Вийди до Мене на го́ру, і будь там. І дам тобі кам'яні табли́ці, і зако́на та за́повідь, що Я написав для навча́ння їх“.
Olúwa sì sọ fún Mose pé, “Gòkè wá sí ọ̀dọ̀ mi, kí o sì dúró níhìn-ín. Èmi yóò sì fún ọ ní wàláà òkúta pẹ̀lú òfin àti ìlànà tí mo ti kọ sílẹ̀ fún ìtọ́sọ́nà wọn.”
13 І встав Мойсей та Ісус, слуга його, і вийшов Мойсей на Божу го́ру.
Nígbà náà ni Mose jáde lọ pẹ̀lú Joṣua arákùnrin rẹ̀. Mose lọ sí orí òkè Ọlọ́run.
14 А до старши́х сказав він: „Сидіть нам на цім місці, аж поки ми ве́рнемось до вас! А ось Аарон та Хур будуть із вами. Хто матиме справу, нехай при́йде до них“.
Ó sì wí fún àwọn àgbàgbà pé, “Ẹ dúró dè wá níhìn-ín yìí, títí àwa yóò fi tún padà tọ̀ yín wá, sì kíyèsi i, Aaroni àti Huri ń bẹ pẹ̀lú yín, bí ẹnìkan bá ni ọ̀ràn kan, kí ó tọ̀ wọ́n lọ.”
15 І вийшов Мойсей на го́ру, а хма́ра закрила го́ру.
Nígbà tí Mose gun orí òkè lọ, ìkùùkuu bo orí òkè náà.
16 І слава Господня спочива́ла на горі Сіна́й, а хма́ра закривала її шість день. А сьомого дня Він кликнув до Мойсея з сере́дини хмари.
Ògo Olúwa sì wà ní orí òkè Sinai. Ìkùùkuu bo orí òkè náà fún ọjọ́ mẹ́fà, ni ọjọ́ keje ni Olúwa kọ sí Mose láti inú ìkùùkuu náà wá.
17 А вид Господньої слави — як огонь, що пожирає на верхі́в'ї гори, на оча́х Ізраїлевих синів.
Ni ojú àwọn ọmọ Israẹli ògo Olúwa náà dàbí iná ajónirun ni orí òkè.
18 І ввійшов Мойсей у сере́дину хмари, і вийшов на го́ру. І Мойсей пробува́в на горі со́рок день та со́рок ноче́й.
Nígbà náà ni Mose wọ inú ìkùùkuu náà bí ó ti ń lọ ní orí òkè. Ó sì wà ni orí òkè náà ni ogójì ọ̀sán àti ogójì òru.