< Повторення Закону 24 >
1 Як хто ві́зьме жінку, і стане їй чоловіком, і коли вона не зна́йде ласки в оча́х його, бо знайшо́в у ній яку ганебну річ, то напише їй листа розводо́вого, і дасть в її руку, та й відпустить її з свого дому.
Bí ọkùnrin kan bá fẹ́ obìnrin kan, tí ó sì gbe ní ìyàwó, yóò sì ṣe, bí obìnrin náà kò bá rí ojúrere ní ojú ọkùnrin náà, nítorí ó rí ohun àìtọ́ kan lára rẹ̀, ǹjẹ́ kí ó kọ ìwé ìkọ̀sílẹ̀ fún obìnrin náà, kí ó sì fi lé e lọ́wọ́, kí ó sì ran jáde kúrò nínú ilé rẹ̀,
2 І ви́йде вона з його дому, і пі́де, і вийде за іншого чоловіка,
tí ó bá di ìyàwó ọkùnrin mìíràn lẹ́yìn ìgbà tí ó kúrò nílé rẹ,
3 і коли знена́видить її той останній чоловік, то напише їй листа розводо́вого, і дасть в її руку, та й відпустить її з свого дому. Або коли помре той останній чоловік, що взяв був її собі за жінку,
àti tí ọkọ rẹ̀ kejì kò bá fẹ́ràn rẹ̀ tí ó sì kọ ìwé-ẹ̀rí ìkọ̀sílẹ̀ sí i, kí ó fi fún un kí ó sì lé e kúrò nílé e rẹ̀, tàbí tí ọkọ rẹ̀ kejì bá kú,
4 не може перший її муж, що відпустив її, вернути й узяти її, щоб стала йому за жінку по тому, як була занечи́щена, бо це огида перед Господнім лицем, і ти не зробиш грішною тієї землі, яку Господь, Бог твій, дає тобі на спа́док.
nígbà náà ni ọkọ, tí ó ti kọ̀ ọ́ sílẹ̀, kò gbọdọ̀ fẹ́ ẹ mọ́ lẹ́yìn tí ó ti di àìmọ́. Nítorí èyí ni ìríra níwájú Olúwa. Má ṣe mú ẹ̀ṣẹ̀ wá sórí ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò fi fún ọ bí ogún.
5 Коли хто недавно одружився, не пі́де він до війська, і ніяка справа не покладеться на нього, — вільний він буде один рік для свого дому, і пора́дує свою жінку, що взяв.
Bí ọkùnrin kan bá ṣẹ̀ṣẹ̀ gbéyàwó, o kò gbọdọ̀ ran lọ sí ogun tàbí kí ó ní iṣẹ́ kan láti ṣe. Ó ní láti ní òmìnira fún ọdún kan kí ó dúró sílé kí ó sì mú inú dídùn bá ìyàwó rẹ̀ tí ó fẹ́.
6 Ніхто не ві́зьме в заста́ву долі́шнього каменя жо́рен або горі́шнього каменя жорен, бо він душу взяв би в заста́ву.
Ẹnikẹ́ni kò gbọdọ̀ gba ìyá ọlọ tàbí ọmọ ọlọ gẹ́gẹ́ bí ohun ìdúró fún gbèsè, nítorí pé ẹ̀mí ènìyàn ni ó gbà ní pàṣípàrọ̀ n nì.
7 Коли буде хто зна́йдений, що вкрав кого з братів своїх, з Ізраїлевих синів, і буде пово́дитися з ним як із невільником, або й продасть його, то нехай помре той злодій, і ти вигубиш зло з-посеред себе.
Bí a bá mú ọkùnrin kan tí ó jí ọ̀kan nínú arákùnrin rẹ̀ ní Israẹli gbé àti tí ó jí ọ̀kan nínú ẹrú tàbí kí ó tà á, ẹni tí ó jí ènìyàn gbé ní láti kú. Ẹ ní láti wẹ búburú kúrò láàrín yín.
8 Стережися в хворобі прока́зи, щоб дуже пильнувати, і робити все те, як навчать вас священики-Левити; як наказав я їм, будете додержувати, щоб виконати те,
Ní ti ààrùn ẹ̀tẹ̀ kíyèsára láti máa ṣe gẹ́gẹ́ bí àwọn àlùfáà tí wọ́n jẹ́ ọmọ Lefi ti pàṣẹ fún ọ. O ní láti máa fi ìṣọ́ra tẹ̀lé ohun tí mo ti pàṣẹ fún wọn.
9 Пам'ятайте те, що зробив був Господь, Бог твій, Марія́мі в дорозі, коли ви вихо́дили з Єгипту.
Rántí ohun tí Olúwa Ọlọ́run rẹ ṣe sí Miriamu lójú ọ̀nà lẹ́yìn ìgbà tí o jáde kúrò ní Ejibiti.
10 Коли ти позичиш своєму ближньому по́зичку з чогось, не вві́йдеш до дому його, щоб узяти заста́ву його, —
Nígbà tí o bá wín arákùnrin rẹ ní ohunkóhun, má ṣe lọ sí ilé rẹ̀ láti gba ohun tí ó bá mú wá bí ẹ̀rí.
11 назовні будеш стояти, а той чоловік, що ти позичив йому, винесе до тебе заста́ву назо́вні.
Dúró síta gbangba kí o sì jẹ́ kí ọkùnrin tí o wín mú ògo rẹ jáde wá fún ọ.
12 А якщо він чоловік убогий, не ляжеш спати, маючи заста́ву його, —
Bí ọkùnrin náà bá jẹ́ tálákà má ṣe lọ sùn ti ìwọ ti ògo rẹ.
13 конче ве́рнеш йому ту заста́ву при за́ході сонця, і буде він спати на одежі своїй, і буде благословляти тебе, а тобі буде це за праведність перед лицем Господа, Бога твого.
Dá aṣọ ìlekè rẹ padà ní àṣálẹ́ kí ó bá à le sùn lórí i rẹ̀. Nígbà náà ni yóò dúpẹ́ lọ́wọ́ rẹ, ó sì máa jásí ìwà òdodo níwájú Olúwa Ọlọ́run rẹ.
14 Не бу́деш утискати на́ймита, убогого й незаможного з братів своїх та з прихо́дька свого, що в кра́ї твоїм у брамах твоїх.
Má ṣe ni alágbàṣe kan lára tí ó jẹ́ tálákà àti aláìní, bóyá ó jẹ́ arákùnrin Israẹli tàbí àlejò tí ó ń gbé ní ọ̀kan nínú àwọn ìlú rẹ.
15 Того ж дня даси йому заплату, і не за́йде над нею незапла́ченою сонце, бо вбогий він, і до неї лине душа його. І не буде він кликати на тебе до Господа, і не буде гріха́ на тобі.
San owó iṣẹ́ rẹ̀ ní ọjọ́ kan náà kí ó tó di àṣálẹ́, nítorí ó jẹ́ tálákà, ó sì gbẹ́kẹ̀lé e bí kò ṣe bẹ́ẹ̀ ó lè ké pe Olúwa sí ọ, o sì máa gba ìdálẹ́bi ẹ̀ṣẹ̀.
16 Не будуть забиті батьки за синів, а сини не будуть забиті за батьків, — кожен за гріх свій смертю пока́раний буде.
Baba kò gbọdọ̀ kú fún àwọn ọmọ wọn tàbí kí àwọn ọmọ kú fún baba wọ́n; olúkúlùkù ní láti kú fún ẹ̀ṣẹ̀ òun tìkára rẹ̀.
17 Не скривиш суду на прихо́дька, на сироту, і не будеш брати в заста́ву вдови́ної одежі.
Má ṣe yí ìdájọ́ po fún àlejò tàbí aláìní baba, tàbí gba aṣọ ìlekè opó bí ẹ̀rí.
18 І будеш пам'ятати, що рабом був ти сам у Єгипті, і викупив тебе Господь, Бог твій, звідти, тому я наказую тобі робити цю річ.
Rántí pé o jẹ́ ẹrú ní Ejibiti tí Olúwa Ọlọ́run rẹ sì gbà ọ́ níbẹ̀. Ìdí nìyí tí mo fi pa á láṣẹ fún ọ láti ṣe èyí.
19 Коли будеш жати жни́во своє на своїм полі, і забудеш на полі снопа, не ве́рнешся взяти його, — він буде прихо́дькові, сироті та вдові, щоб поблагословив тебе Господь, Бог твій, у всім чині твоїх рук.
Nígbà tí o bá ń kórè oko rẹ tí o sì fojú fo ìtí kan, má ṣe padà lọ mú u. Fi í kalẹ̀ fún àwọn àlejò, aláìní baba àti opó, kí Olúwa Ọlọ́run rẹ lè bùkún fún gbogbo iṣẹ́ ọwọ́ ọ̀ rẹ.
20 Коли будеш оббивати оливку свою, не будеш переоббивати в галу́зках за собою: воно буде прихо́дькові, сироті та вдові.
Nígbà tí o bá ń gun igi olifi lára àwọn igi i rẹ, má ṣe padà lọ sí ẹ̀ka náà ní ìgbà kejì. Fi èyí tí ó kù fún àlejò, aláìní baba àti opó.
21 Коли будеш збирати виноград свого виноградника, не будеш збирати поли́шеного за собою, — воно буде прихо́дькові, сироті та вдові.
Nígbà tí ìwọ bá kórè èso àjàrà nínú ọgbà àjàrà rẹ, má ṣe lọ sí ọgbà náà mọ́. Fi èyí tí ó kù fún àlejò, aláìní baba àti opó.
22 І будеш пам'ятати, що рабом був ти в єгипетськім кра́ї, тому́ я наказую тобі робити цю річ.
Rántí pé ìwọ ti jẹ́ àlejò ní Ejibiti. Ìdí nìyí tí mo fi pa á láṣẹ fún ọ láti ṣe èyí.