< Повторення Закону 18 >
1 Священикам-Левитам, усьому Левієвому пле́мені не буде частки та спа́дку разом з Ізраїлем, — огняні́ жертви Господа та ча́стки Його будуть їм.
Àwọn àlùfáà tí wọ́n jẹ́ ọmọ Lefi, àní gbogbo ẹ̀yà Lefi, wọn kì yóò ní ìpín tàbí ogún láàrín Israẹli, wọn yóò máa jẹ nínú ọrẹ ẹbọ tí a fi iná ṣe sí Olúwa, nítorí òun ni ogún un tiwọn.
2 А спа́дку не буде йому серед братів його: Господь — Він спа́док його, як Він говорив був йому.
Wọn kì yóò ní ìní láàrín àwọn arákùnrin wọn; Olúwa ni yóò jẹ́ ìní i tiwọn, gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe ìlérí fún wọn.
3 А оце буде належати священикам від народу, від тих, хто приносить жертву: коли це віл, коли це одне з дрібної худоби, то даси священикові плече́, і що́ки, і шлу́нок.
Gbogbo èyí ni yóò jẹ́ ìpín àwọn àlùfáà láti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn tí ó fi akọ màlúù tàbí àgùntàn rú ẹbọ; wọn yóò fi èjìká àti ẹ̀rẹ̀kẹ́ méjèèjì àti gbogbo inú fún àlùfáà.
4 Початок від збіжжя свого, від виноградного соку свого, і від оливки своєї, і початок стри́ження отари своєї даси ти йому.
Àkọ́so irúgbìn ọkà rẹ, ti wáìnì àti ti òróró rẹ, àti àkọ́rẹ́ irun àgùntàn rẹ ni ìwọ yóò fi fún wọn.
5 Бо його вибрав Господь, Бог твій, зо всіх племен твоїх, щоб ставав він служити в Господнє Ім'я́, він та сини його по всі дні.
Nítorí Olúwa Ọlọ́run rẹ ti yàn wọ́n àti àwọn ọmọ wọn láti inú gbogbo ẹ̀yà láti dúró àti láti ṣe ìránṣẹ́ ní orúkọ Olúwa títí láé.
6 А коли при́йде Левит з одної з брам твоїх з усього Ізраїля, де він мешкає там, і прибуде за всім жада́нням своєї душі до місця, яке вибере Господь,
Tí ọmọ Lefi kan bá sì wá láti ibikíbi nínú àwọn ìlú u yín ní Israẹli, níbi tí ó ń gbé ṣe àtìpó, tí ó sì wá gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ̀ sí ibi tí Olúwa yóò yàn.
7 і буде він служити в Ім'я́ Господа, Бога свого, як усі його браття Левити, що стоять там перед Господнім лицем,
Nígbà náà ni ó lè máa ṣe ìránṣẹ́ ní orúkọ Olúwa Ọlọ́run rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí àwọn ọmọ Lefi arákùnrin rẹ̀ ti ń dúró ṣe iṣẹ́ ìsìn níwájú Olúwa níbẹ̀.
8 то по рівній частці будуть вони їсти, опріч маєтку, про́даного по батьках.
Wọn yóò ní ìpín kan láti jẹ, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ó ti gba owó nípa títa ogún baba rẹ̀.
9 Коли будеш вхо́дити до кра́ю, що дає тобі Господь, Бог твій, то не навчися чинити такого, як гидо́та цих народів.
Nígbà tí o bá wọ ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò fi fún ọ, ìwọ kò gbọdọ̀ kọ́ láti tẹ̀lé àwọn ọ̀nà ìríra àwọn orílẹ̀-èdè náà tí ó wà níbẹ̀.
10 Нехай не знайдеться між тобою такий, хто переводить свого сина чи дочку́ свою через огонь, хто ворожить ворожбу́, хто ворожить по хмарах, і хто ворожить по птахах, і хто чарівни́к,
Má ṣe jẹ́ kí a rí ẹnikẹ́ni láàrín yín tí ó fi ọmọ rẹ̀ ọkùnrin tàbí ọmọ rẹ̀ obìnrin la iná já (fi ọmọ rẹ rú ẹbọ) kí ẹnikẹ́ni má ṣe lọ fọ àfọ̀ṣẹ, tàbí ṣẹ́ oṣó, tàbí túmọ̀ àwọn àmì nǹkan tí ń bọ̀, tàbí àjẹ́,
11 і хто чорнокни́жник, і хто викликає духа померлого та духа віщого, і хто питає померлих.
tàbí afògèdè, tàbí jẹ́ a bá iwin gbìmọ̀ tàbí oṣó tàbí abókùúsọ̀rọ̀.
12 Бо гидо́та для Господа кожен, хто чинить таке, і через ті гидо́ти Господь, Бог твій, виганяє їх перед тобою.
Ẹnikẹ́ni tó bá ṣe nǹkan wọ̀nyí jẹ́ ìríra sí Olúwa, àti nítorí àwọn ìwà ìríra wọ̀nyí ni Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò fi lé àwọn orílẹ̀-èdè wọ̀nyí jáde kúrò níwájú rẹ.
13 Бездоганний будеш ти перед Господом, Богом своїм,
O ní láti jẹ́ aláìlẹ́gàn níwájú Olúwa Ọlọ́run rẹ.
14 бо ці народи, що ти посядеш їх, слухають тих, хто ворожить по хмарах та ворожби́тів, а ти — не таке дав тобі Господь, Бог твій.
Àwọn orílẹ̀-èdè tí ìwọ yóò gba ilẹ̀ tí wọ́n ń gbé, wọ́n fetí sí tí àwọn tí ó ń ṣe oṣó tàbí ṣe àfọ̀ṣẹ. Ṣùgbọ́n, ní ti ìwọ, Olúwa Ọlọ́run rẹ kò fi ààyè gbà ọ́ láti ṣe bẹ́ẹ̀.
15 Пророка з-посеред тебе, з братів твоїх, Такого, як я, поставить тобі Господь, Бог твій, — Його будете слухати,
Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò gbé wòlíì kan dìde gẹ́gẹ́ bí èmi láàrín àwọn arákùnrin rẹ. Tìrẹ ni kí o gbọ́.
16 згідно з усім, чого жадав ти від Господа, Бога свого, на Хори́ві в дні зборів, говорячи: „Щоб більше не чути мені голосу Господа, Бога свого, а цього великого огню вже не побачити й не померти“.
Nítorí èyí ni ohun tí ìwọ béèrè lọ́wọ́ Olúwa Ọlọ́run rẹ ní Horebu ní ọjọ́ àjọ, nígbà tí ìwọ wí pé, “Kí àwa má ṣe gbọ́ ohùn Olúwa Ọlọ́run wa tàbí rí iná ńlá yìí mọ́. Bí bẹ́ẹ̀ kọ́ àwa yóò kú.”
17 І сказав до мене Господь: „Добре сказали вони.
Olúwa sì wí fún mi pé, “Ohun tí wọ́n sọ dára.
18 Поставлю Пророка для них з-поміж їхніх братів, Такого, як ти, і дам Я слова Свої в у́ста Його, і Він їм говоритиме все, що Я накажу.
Èmi yóò gbé wòlíì kan dìde fún wọn láàrín àwọn arákùnrin wọn bí ìwọ, Èmi yóò fi ọ̀rọ̀ mi sí i ní ẹnu, yóò sì sọ fún wọn gbogbo ohun tí mo ti paláṣẹ fún un.
19 І станеться, кожен, хто не слухатиме слів Моїх, що Той Пророк говоритиме Моїм Ім'я́м, — Я покара́ю того.
Ẹnikẹ́ni tí kò bá sì tẹ́tí sí ọ̀rọ̀ mi tí wòlíì náà yóò sọ ní orúkọ mi, èmi fúnra à mi yóò sì béèrè lọ́wọ́ rẹ̀.
20 А той пророк, що зухвало відважиться промовляти Моїм Ім'я́м слова́, яких Я не наказав був йому говорити, і що буде говорити ім'я́м інших богів, хай помре той пророк“.
Ṣùgbọ́n bí wòlíì kan bá kùgbù sọ ọ̀rọ̀ kan tí èmi kò paláṣẹ fún un láti sọ ní orúkọ mi tàbí wòlíì tí ó sọ̀rọ̀ ní orúkọ ọlọ́run mìíràn, irú wòlíì bẹ́ẹ̀ ní láti kú.”
21 А коли ти скажеш у серці своєму: Як ми пізнаємо те слово, якого Господь не говорив?
Ṣùgbọ́n ìwọ lè wí ní ọkàn rẹ pé, “Báwo ni àwa yóò ṣe mọ ọ̀rọ̀ tí Olúwa kò sọ?”
22 Що́ буде говорити той пророк Ім'я́м Господа, і не станеться та річ, і не при́йде, то це те слово, якого не сказав Господь. У зухва́лості говорив його той пророк, і ти не будеш боятися його.
Nígbà tí ohun tí wòlíì bá sọ ní orúkọ Olúwa kò bá wá sí ìmúṣẹ tàbí jẹ́ òtítọ́, ìyẹn ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa kò sọ, irú wòlíì bẹ́ẹ̀ tí sọ láìwádìí. Kí ẹ má ṣe bẹ̀rù rẹ̀.