< Амос 7 >

1 Господь Бог учинив, що я бачив таке: Ось Він утворив сарану́, коли почала вироста́ти ота́ва, — і ось ота́ва як по сіноко́сі царсько́му!
Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè fihàn mí: Ó pèsè ọwọ́ eṣú lẹ́yìn ìgbà tí a kórè ìpín ọba, ní ìgbà ti èso ẹ̀ẹ̀kejì ń jáde bọ̀.
2 І сталось, як вона вже поже́рла траву на землі, я сказав: Господи, Боже, прости́! Як же Яків устояти може, бо такий він мали́й?
Nígbà tí wọ́n jẹ koríko ilẹ̀ náà mọ́ féfé nígbà náà ni mo gbé ohùn mi sókè pé, “Olúwa Olódùmarè, mo bẹ̀ ọ́, dáríjì! Báwo ni Jakọbu yóò ha ṣe lè dìde? Òun kéré jọjọ!”
3 І Господь пожалів був про те. „Не станеться це “, промовив Госпо́дь.
Olúwa ronúpìwàdà nípa èyí. “Èyí kò ni ṣẹlẹ̀,” ni Olúwa wí.
4 Господь Бог учинив, що я бачив таке: Ось Господь Бог покликав судитись огнем, і поже́р той велику безо́дню, і ча́стку пожер.
Èyí ni ohun ti Olúwa Olódùmarè fihàn mí: Olúwa Olódùmarè ń pè fún ìdájọ́ pẹ̀lú iná; ó jó ọ̀gbun ńlá rún, ó sì jẹ ilẹ̀ run.
5 І сказав я: О, Господи, Боже, спини́! Як же Яків усто́яти може, бо такий він мали́й?
Nígbà náà ni mo gbé ohùn mi sókè pé, “Olúwa Olódùmarè jọ̀wọ́ má ṣe ṣe é! Báwo ni Jakọbu yóò ha ṣe lè dìde? Òun kéré jọjọ!”
6 І Господь пожалів був про те. „Не ста́неться й це!“сказав Господь Бог!
Olúwa ronúpìwàdà nípa èyí. “Èyí náà kò ní ṣẹlẹ̀,” ni Olúwa Olódùmarè wí.
7 І Він знов учинив, що я бачив таке: Ось на мурі стрімко́му стоїть Господь Бог, а в руці Його висо́к.
Èyí ni ohun tí ó fihàn mí: Olúwa dúró ní ẹ̀gbẹ́ odi ti a fi okùn ìwọ̀n mọ́, ti òun ti okùn ìwọ̀n tí ó rún ni ọwọ́ rẹ̀.
8 І про́мовив до мене Господь: „Що ти бачиш, Амо́се?“А я відказав: „Виска́“. І промовив Господь: „Ось Я цього виска́ покладу посеред народу Мого, Ізраїля, — уже більше йому не прощу́!
Olúwa sì bi mi pé, “Amosi, kí ni ìwọ rí?” Mo dáhùn pé, “Okùn ìwọ̀n.” Nígbà náà ni Olúwa wí pé, “Wò ó, Èmí ń gbé okùn ìwọ̀n kalẹ̀ láàrín àwọn Israẹli ènìyàn mi; Èmi kì yóò sì tún kọjá lọ́dọ̀ wọn mọ́.
9 І спустоші́ють жерто́вні підгі́рки Ісакові, і поруйно́вані будуть святині Ізраїлеві, і Я ста́ну з мечем на дім Єровоамів“.
“Ibi gíga Isaaki wọ̀n-ọn-nì yóò sì di ahoro àti ibi mímọ Israẹli wọ̀n-ọn-nì yóò di ahoro. Èmi yóò sì fi idà dìde sí ilé Jeroboamu.”
10 І послав Амація, священик Бет-Елу, до Єровоама, царя Ізраїлевого, кажучи: „Амо́с змо́влюється на тебе серед Ізраїлевого дому, — не може земля змістити всіх його слів!
Nígbà náà Amasiah àlùfáà Beteli ránṣẹ́ sí Jeroboamu ọba Israẹli, wí pé: “Amosi ti dìde láti dìtẹ̀ sí ọ ni àárín gbùngbùn Israẹli. Ilẹ̀ kò sì le gba gbogbo ọ̀rọ̀ rẹ̀.
11 Бо так говорить Амос: Євровоам помре від меча, а Ізраїль конче пі́де на вигна́ння з своєї землі!“
Nítorí èyí ni ohun ti Amosi ń sọ: “‘Jeroboamu yóò ti ipa idà kú, lóòtítọ́ Israẹli yóò lọ sí ìgbèkùn, jìnnà kúrò ní ilẹ̀ ìní wọn.’”
12 І сказав Амація до Амоса: „Яснови́дче, іди, утікай собі до Юдиного кра́ю, і їж там хліб, і там пророкуй.
Nígbà náà ni Amasiah sọ fún Amosi pé, “Lọ jáde, ìwọ aríran! Padà sí ilẹ̀ àwọn Juda. Kí o máa jẹun rẹ níbẹ̀, kí o sì máa sọtẹ́lẹ̀ rẹ̀ níbẹ̀.
13 А в Бет-Елі вже більше не будеш пророкува́ти, бо він святиня царя та дім царства“.
Má ṣe sọtẹ́lẹ̀ mọ ni Beteli nítorí ibi mímọ́ ọba ni àti ibi tẹmpili ìjọba rẹ̀.”
14 І відповів Амос і сказав до Амації: „Я не пророк, і не син я пророків, — я пастух та обро́блювач диких фіґо́вниць.
Amosi dá Amasiah lóhùn pé, “Èmi kì í ṣe wòlíì tàbí àwọn ọmọ wòlíì, ṣùgbọ́n mo jẹ́ olùṣọ́-àgùntàn, mo sì ń ṣe ìtọ́jú igi ọ̀pọ̀tọ́ sikamore.
15 І взяв мене Госпо́дь від отари, і промовив до мене Госпо́дь: Іди, пророкуй Моєму наро́дові Ізраїлеві!
Ṣùgbọ́n Olúwa mu mi bí mo ti ń tọ́ agbo ẹran lẹ́yìn, ó sì wí fun mi pé, ‘Lọ sọtẹ́lẹ̀ fun àwọn Israẹli ènìyàn mi.’
16 А тепер послухай Господнього слова: Ти кажеш: Не будеш пророкува́ти на Ізраїля, і не будеш пропові́дувати на Ісаків дім.
Nítorí náà nísinsin yìí, gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa. Ìwọ wí pé, “‘Má ṣe sọ àsọtẹ́lẹ̀ sí Israẹli, má sì ṣe wàásù sí ilé Isaaki.’
17 Тому так промовляє Господь: Твоя жінка в місті буде блудли́ва, і сини твої та до́чки твої попа́дають від меча, а земля твоя буде поді́лена шнуром, і ти помреш на нечистій землі, а Ізраїль конче пі́де на вигна́ння з своєї землі!“
“Nítorí náà, èyí ni ohun ti Olúwa wí: “‘Ìyàwó rẹ yóò di panṣágà ni ìlú, àwọn ọmọ ọkùnrin àti obìnrin rẹ yóò ti ipa idà ṣubú. A ó fi okùn wọn ilẹ̀ rẹ, a ó sì pín in àti ìwọ pẹ̀lú yóò kú ni ilẹ̀ àìmọ́. Israẹli yóò sì lọ sí ìgbèkùn, kúrò ní ilẹ̀ ìní wọn.’”

< Амос 7 >