< 2 царів 4 >

1 А одна з жінок пророчих синів кли́кала до Єлисей, говорячи: „Помер раб твій, мій чоловік! А ти знаєш, що раб твій боявся Господа. А позича́льник прийшов ось, щоб забрати собі двоє дітей моїх за рабів“.
Ìyàwó ọkùnrin kan láti ara ẹgbẹ́ wòlíì sọkún tọ Eliṣa wá, “Ìránṣẹ́ rẹ ọkọ mi ti kú, ó sì mọ̀ wí pé ó bu ọlá fún Olúwa. Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, onígbèsè rẹ̀ ti ń bọ̀ láti wá kó ọmọ ọkùnrin mi gẹ́gẹ́ bí ẹrú rẹ̀.”
2 І сказав до неї Єлисей: „Що́ я зроблю тобі? Розкажи мені, що́ є в тебе в домі“. А та відказала: „Нічого нема в домі твоєї невільниці, — є тільки горня́ оливи“.
Eliṣa dá a lóhùn pé, “Báwo ni èmi ṣe lè ràn ọ́ lọ́wọ́? Sọ fún mi; kí ni ìwọ ní ní ilé rẹ?” Ó wí pé, “Ìránṣẹ́ rẹ kò ní ohunkóhun níbẹ̀ rárá, àyàfi òróró kékeré.”
3 А він сказав: „Іди, позич собі настороні́ по́суд від усіх сусі́док твоїх, по́суд порожній. Не бери мало!
Eliṣa wí pé, “Lọ yíká kí o sì béèrè lọ́wọ́ gbogbo àwọn aládùúgbò fún ìkòkò òfìfo. Má ṣe béèrè fún kékeré.
4 І вві́йдеш, і замкне́ш двері за собою та за синами своїми, і поналива́єш у всі ті посу́дини, а повні повідставля́й“.
Nígbà náà, lọ sí inú ilé kí o sì pa lẹ́kun dé ní ẹ̀gbẹ́ ìwọ àti àwọn ọmọ rẹ ọkùnrin, dà òróró sínú gbogbo ìkòkò, gẹ́gẹ́ bí gbogbo rẹ̀ ti kún, kó o sí apá kan.”
5 І пішла вона від нього, і замкну́ла двері за собою та за синами своїми. Вони подава́ли їй по́суд, а вона налива́ла.
Ó sì fi sílẹ̀ lẹ́yìn náà ó ti ìlẹ̀kùn ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀ àti àwọn ọmọ rẹ̀. Wọ́n gbé ìkòkò wá fún un ó sì ń dà á.
6 І сталося, коли понапо́внювано по́суд, то сказала вона до сина свого: „Подай мені ще по́суду!“А він відказав їй: „Нема вже по́суду“. І спини́лася олива.
Nígbà tí gbogbo ìkòkò náà kún, ó sọ fún ọmọ rẹ̀ pé, “Ẹ gbé òmíràn fún mi wá.” Ṣùgbọ́n wọ́n dáhùn pé, “Kò sí ìkòkò tí ó kù mọ́.” Nígbà náà ni òróró kò dà mọ́.
7 І вона прийшла, і доне́сла Божому чоловікові. І він сказав: „Іди, продай ту оливу, та й заплати своєму позича́льникові. А ти та сини́ твої будете жити на позоста́ле“.
Ó sì lọ ó sì lọ sọ fún àwọn ènìyàn Ọlọ́run, ó sì wí pé, “Lọ, ta òróró náà kí o sì san gbèsè rẹ. Ìwọ àti ọmọ rẹ kí ẹ máa sinmi lórí èyí tí ó kù.”
8 І сталося певного дня, і прийшов Єлисе́й до Шуна́му, а там була багата жінка, — і вона сильно просила його до себе поїсти хліба. І бувало, скільки разів прихо́див він, захо́див туди їсти хліб.
Ní ọjọ́ kan Eliṣa lọ sí Ṣunemu. Obìnrin ọlọ́rọ̀ kan sì wà níbẹ̀, ẹni tí ó rọ̀ ọ́ kí ó dúró jẹun. Bẹ́ẹ̀ ni nígbàkígbà tí ó bá ń kọjá lọ, ó máa ń dúró níbẹ̀ láti jẹun.
9 І сказала вона до чоловіка свого: „Ось я познала, що Божий чоловік, який за́вжди прихо́дить до нас, він святий.
Ó sọ fún ọkọ rẹ̀, “Mo mọ̀ pé ọkùnrin tí ó máa ń sábà wá sí ọ̀dọ̀ wa jẹ́ ọkùnrin mímọ́ Ọlọ́run.
10 Зробім же малу муровану го́рницю, і поставимо йому там ліжко, і стола, і стільця́, і свічника́. І коли він прихо́дитиме до нас, то захо́дитиме туди“.
Jẹ́ kí a ṣe yàrá kékeré kan sórí ilé kí a sì gbé ibùsùn àti tábìlì oúnjẹ, àga kan àti fìtílà fún un. Nígbà náà ó lè dúró níbẹ̀ ní ìgbàkúgbà tí ó bá wá sọ́dọ̀ wa.”
11 Одно́го ра́зу прийшов він туди, і зайшов до горниці та й ліг там.
Ní ọjọ́ kan nígbà tí Eliṣa wá, ó lọ sí orí òkè ní yàrá rẹ̀ ó sì dùbúlẹ̀ síbẹ̀.
12 І сказав він до свого слуги Ґехазі: „Поклич оцю шунамі́тянку!“І той покли́кав її, і вона стала перед ним.
Ó sì wí fún ìránṣẹ́ rẹ̀ Gehasi pé, “Pe ará Ṣunemu.” Bẹ́ẹ̀ ni ó sì pè é wá, ó sì dúró níwájú rẹ̀.
13 І сказав він до нього: „Скажи їй: Ось ти старанно піклува́лася про всі наші потреби. Що́ зробити тобі за це! Чи є що, щоб сказати про тебе цареві або начальникові війська?“А вона відказала: „ Ні, — я сиджу́ серед народу свого!“
Eliṣa wí fún un pé, “Wí fún un, ‘Ìwọ ti lọ ṣe gbogbo àníyàn iṣẹ́ ìyìnrere fún wa. Nísinsin yìí kí ni a lè ṣe fún ọ?’” “Ṣé a lè jẹ́ agbẹnusọ fún ọ ní ọ̀dọ̀ ọba tàbí olórí ogun?”
14 І сказав він: „Що́ ж зробити їй?“А Ґехазі відказав: „Та вона не має сина, а чоловік її стари́й“.
“Kí ni a lè ṣe fún obìnrin yìí?” Eliṣa béèrè. Gehasi wí pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, kò ní ọmọ, ọkọ rẹ̀ náà sì tún di arúgbó.”
15 А він сказав: „Поклич її“. І він покликав її, і вона стала при вході.
Nígbà náà Eliṣa wí pé, “Pè é,” bẹ́ẹ̀ ni ó sì pè é, ó sì dúró ní àbáwọlé ẹnu-ọ̀nà.
16 І він сказав: „На цей озна́чений час, коли саме цей час ве́рнеться, ти обійма́тимеш сина!“А вона відказала: „Ні, пане, чоловіче Божий, не говори неправди своїй невільниці!“
Eliṣa sọ wí pé, “Ìwòyí ọdún tí ń bọ̀, ìwọ yóò fi ọwọ́ rẹ gbé ọmọ.” “Bẹ́ẹ̀ kọ́, olúwa mi!” n kò fi ara mọ́ ọn. “Jọ̀wọ́, ìwọ ènìyàn Ọlọ́run, ma ṣe ṣi ìránṣẹ́ rẹ lọ́nà!”
17 Та зачала́ та жінка, і породи́ла сина на той озна́чений час, того саме ча́су, про який говорив до неї Єлисей.
Ṣùgbọ́n obìnrin náà lóyún ní ọdún kejì ní àkókò náà, ó bí ọmọ ọkùnrin kan, gẹ́gẹ́ bí Eliṣa ti sọ fún un.
18 І росло те дитя. А одно́го ра́зу вийшло воно до свого́ ба́тька до женці́в.
Ọmọ náà dàgbà, ní ọjọ́ kan, ó jáde lọ sí ọ̀dọ̀ baba rẹ̀, ó wà pẹ̀lú àwọn olùkórè.
19 І сказало воно до свого батька: „Голова моя, голова моя!“А той сказав слузі: „Занеси́ його до його матері!“
“Orí mi! Orí mi!” Ó wí fún baba rẹ̀. Baba rẹ̀ sọ fún ìránṣẹ́, “Gbé e lọ sọ́dọ̀ ìyá rẹ̀.”
20 І той поніс його, і приніс його до його матері. І сиділо воно на її колінах аж до полу́дня, та й померло...
Lẹ́yìn ìgbà tí ìránṣẹ́ náà ti gbé e sókè tí ó sì gbé e tọ ìyá rẹ̀ lọ, ọmọ ọkùnrin náà jókòó sórí ẹsẹ̀ rẹ̀ títí ó fi di ọ̀sán gangan, nígbà náà ó sì kú.
21 І ввійшла вона, і поклала його на ліжко Божого чоловіка, і замкну́ла за ним двері та й вийшла.
Ó lọ sí òkè ó sì tẹ́ ọmọ náà lórí ibùsùn ènìyàn Ọlọ́run, ó sì tìlẹ̀kùn, ó jáde lọ.
22 І покликала вона свого чоловіка та й сказала: „Пришли мені одно́го із слуг та одну з ослиць, і я поїду до Божого чоловіка й вернуся“.
Ó pe ọkọ rẹ̀ ó sì wí pé, “Jọ̀wọ́ rán ọ̀kan lára àwọn ìránṣẹ́ rẹ àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ kan kí èmi kí ó lè lọ sí ọ̀dọ̀ ènìyàn Ọlọ́run kíákíá kí n sì padà.”
23 А він сказав: „Чому ти їдеш до нього? Сьогодні не новомісяччя й не субота“. А вона відказала: „Добре!“
“Kí ni ó dé tí o fi fẹ́ lọ sọ́dọ̀ rẹ̀ lónìí?” Ó béèrè. “Kì í ṣe oṣù tuntun tàbí ọjọ́ ìsinmi.” Ó wí pé, “Gbogbo rẹ̀ ti dára.”
24 І осідла́ла вона ослицю, і сказала до свого слуги: „Поганяй та йди. Не затримуй мені в їзді, аж поки не скажу́ тобі“.
Ó sì di kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ní gàárì ó sì wí fún ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Máa nìṣó; má ṣe dẹ́sẹ̀ dúró dè mí àyàfi tí mo bá sọ fún ọ.”
25 І поїхала вона, і приїхала до Божого чоловіка, до гори Карме́л. І сталося, як Божий чоловік побачив її зда́лека, то сказав до слуги свого Ґехазі: „Ось та шунамі́тянка!
Bẹ́ẹ̀ ni ó sì jáde wá, ó sì wá sọ́dọ̀ ènìyàn Ọlọ́run ní orí òkè Karmeli. Nígbà tí ó sì rí i láti òkèrè, ènìyàn Ọlọ́run sọ fún ìránṣẹ́ rẹ̀ Gehasi, “Wò ó! Ará Ṣunemu nì!
26 Побіжи ж назу́стріч їй та й скажи їй: Чи все гара́зд тобі, чи гаразд чоловікові твоєму, чи гаразд дитині?“А та відказала: „Усе гаразді“
Sáré lọ pàdé rẹ̀ kí o sì béèrè lọ́wọ́ rẹ̀, ‘Ṣé o wà dáradára? Ṣé ọkọ rẹ wà dáradára? Ṣé ọmọ rẹ wà dáradára?’” Ó wí pé, “Gbogbo nǹkan wà dáradára.”
27 І прийшла вона до Божого чоловіка на го́ру, і сильно схопи́ла за но́ги його. А Ґехазі підійшов, щоб відіпхну́ти її, та Божий чоловік сказав: „Позостав її, бо затурбо́вана душа її, а Господь затаїв це передо мною й не сказав мені“.
Nígbà tí ó dé ọ̀dọ̀ ènìyàn Ọlọ́run ní orí òkè, ó gbá a ní ẹsẹ̀ mú. Gehasi wá láti wá lé e dànù, ṣùgbọ́n ènìyàn Ọlọ́run wí pé, “Fi í sílẹ̀! Ó wà nínú ìpọ́njú kíkorò, ṣùgbọ́n Olúwa fi pamọ́ fún mi kò sì sọ ìdí rẹ̀ fún mi.”
28 А вона сказала: „Чи я жадала сина від пана? Чи я не говорила: Не впрова́джуй мене в обма́ну?“
“Ṣé mo béèrè ọmọ lọ́wọ́ rẹ, olúwa mi?” Obìnrin náà wí pé, “Ṣé mi ò sọ fún ọ pé kí o, ‘Má ṣe fa ìrètí mi sókè’?”
29 І він сказав до Ґехазі: „Опережи сте́гна свої, і візьми мою па́лицю в руку свою та й іди. Коли спітка́єш кого, не повітаєш його, а коли хто повітає тебе, не відповіси́ йому. І покладеш мою палицю на хло́пцеве обличчя“.
Eliṣa wí fún Gehasi pé, “Ká agbádá rẹ sínú ọ̀já àmùrè, mú ọ̀pá mi sí ọwọ́ rẹ kí o sì sáré. Tí o bá pàdé ẹnikẹ́ni má ṣe kí i, tí ẹnikẹ́ni bá kí ọ, má ṣe dá a lóhùn, fi ọ̀pá náà lé ojú ọmọ ọkùnrin náà.”
30 А мати того хлопця сказала: „ Як живий Господь і жива душа твоя, — я не полишу́ тебе!“І він устав і пішов за нею.
Ṣùgbọ́n ìyá ọmọ náà wí pé, “Gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti ń bẹ láààyè àti gẹ́gẹ́ bí ó ti wà láààyè, èmi kò ní í fi ọ́ sílẹ̀.” Bẹ́ẹ̀ ni ó sì dìde ó sì tẹ̀lé e.
31 А Ґехазі пішов перед ними, і поклав ту палицю на хлопцеве обличчя, та не було ані голосу, ані чуття. І вернувся він навпроти нього, і доніс йому, говорячи: „Не збуди́вся той хлопець!“
Gehasi sì ń lọ síbẹ̀ ó sì fi ọ̀pá náà lé ojú ọmọ náà, ṣùgbọ́n kò sí ohùn tàbí ìdáhùn. Bẹ́ẹ̀ ni Gehasi padà lọ láti lọ bá Eliṣa láti sọ fún un pé, “Ọmọ ọkùnrin náà kò tí ì dìde.”
32 І ввійшов Єлисей у дім, аж ось той хлопець лежить мертвий на ліжку його!
Nígbà tí Eliṣa dé inú ilé, níbẹ̀ ni òkú ọmọ ọkùnrin náà dùbúlẹ̀ lórí ibùsùn.
33 І ввійшов він, і замкнув двері за ними обома́, та й молився до Господа.
Ó sì wọ ilé, ó sì ti ìlẹ̀kùn mọ́ àwọn méjèèjì ó sì gbàdúrà sí Olúwa.
34 І ввійшов він, і ліг на того хло́пця, і поклав уста свої на уста його, а очі свої на очі його, і долоні свої на долоні його. І схилився над ним, і стало тепле тіло тієї дитини!...
Nígbà náà ó dé orí ibùsùn, ó sùn sórí ọmọ ọkùnrin náà, ẹnu sí ẹnu, ojú sí ojú, ọwọ́ sí ọwọ́. Gẹ́gẹ́ bí ó ti nà ara rẹ̀ lórí rẹ̀, ara ọmọ náà sì gbóná.
35 І він зно́ву ходив по дому раз сюди́, а раз туди́. І ввійшов він, і знову схилився над ним, — і чхнув той хлопець аж до семи раз. І розплю́щив той хлопець очі свої.
Eliṣa yípadà lọ, ó sì rìn padà ó sì jáde wá sínú ilé nígbà náà ó sì padà sí orí ibùsùn ó sì tún nà lé e ní ẹ̀ẹ̀kan sí i. Ọmọ ọkùnrin náà sì sín ní ìgbà méje ó sì ṣí ojú rẹ̀.
36 І покликав він Ґехазі та й сказав: „Поклич ту шунамі́тянку!“І той покликав її. І прийшла вона до нього, і він сказав: „Забери свого сина!“
Eliṣa sì pe Gehasi ó sì wí pé, “Pe ará Ṣunemu.” Ó sì ṣe bẹ́ẹ̀. Nígbà tí ó dé, ó wí pé, “Gba ọmọ rẹ.”
37 І ввійшла вона, і впала до його ніг, і вклони́лася до землі. І взяла́ вона сина свого та й вийшла...
Ó sì wọlé, ó sì kúnlẹ̀ síwájú ẹsẹ̀ rẹ̀ ó sì tẹ̀ orí sílẹ̀. Nígbà náà ó sì mú ọmọ rẹ̀ ó sì jáde lọ.
38 І вернувся Єлисей до Ґілґалу. А в Краю́ був голод, і пророчі сини сиділи перед ним. І сказав він до свого хлопця: „Пристав великого горшка́, і звари їжу для пророчих синів“.
Eliṣa padà sí Gilgali ìyàn sì wà ní ilẹ̀ náà. Nígbà tí àwọn ọmọ wòlíì ṣe ìpàdé pẹ̀lú rẹ̀, ó sì wí fún ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Gbé ìkòkò ńlá ka iná kí o sì se ọbẹ̀ aláta díẹ̀ fún àwọn ọkùnrin yìí.”
39 І вийшов один на поле, щоб назбирати ярини́, і знайшов там витку́ рослину, і назбирав із неї повну свою одежу диких огіркі́в. І він прийшов, і накриши́в до горшка́ ї́жі, бо вони не знали того́.
Ọ̀kan lára wọn jáde lọ sí orí pápá láti kó ewébẹ̀ jọ àti láti wá àjàrà igbó. Ó sì kó díẹ̀ nínú ẹ̀fọ́ gbọ̀rọ̀ rẹ̀ jọ, ó sì ka a kún aṣọ agbádá rẹ̀. Nígbà tí ó padà dé, ó sì gé wọn sínú ìkòkò ọbẹ̀, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé kò sí ẹni tí ó mọ ohun tí wọ́n ń jẹ.
40 І поналива́ли вони лю́дям їжі. І сталося, як вони їли ту їжу, то закричали й сказали: „Смерть у горшку, чоловіче Божий!“І не могли вони їсти...
Wọ́n da ọbẹ̀ náà jáde fun àwọn ọkùnrin náà, ṣùgbọ́n bí wọ́n ti bẹ̀rẹ̀ sí ní jẹ oúnjẹ náà, wọ́n sọkún jáde, “Ìwọ ènìyàn Ọlọ́run ikú ń bẹ nínú ìkòkò yìí!” Wọn kò sì le jẹ ẹ́.
41 А він сказав: „Дайте муки́!“І він всипав її до горшка і сказав: „Наливай наро́дові, і нехай їдять!“І вже не було́ нічого злого в горшку́.
Eliṣa sì wí pé, “Mú ìyẹ̀fun díẹ̀ wá,” Ó sì fi sínú ìkòkò ó sì wí pé, “Kí ó sì fi fún àwọn ènìyàn láti jẹ.” Kò sì sí ohun tí ó léwu nínú ìkòkò náà.
42 І прийшов один чоловік із Баал-Шалішу, і приніс Божому чоловікові хліб первопло́ду, — двадцять ячмінних хлібці́в та зе́рна в колоска́х у своїй торбі. І сказав Єлисе́й: „Дай наро́дові, і нехай вони їдять!“
Ọkùnrin kan wá láti Baali-Ṣaliṣa, ó sì mú àkàrà àkọ́so èso, ogún ìṣù àkàrà barle, tí wọ́n dín láti ara àkọ́so èso àgbàdo, àti pẹ̀lú síírí ọkà tuntun nínú àpò rẹ̀ wá fún ènìyàn Ọlọ́run náà. Òun sì wí pé, “Fún àwọn ènìyàn láti jẹ.”
43 А слуга його сказав: „Що оце покладу я перед сотнею чоловіка?“Та він відказав: „Дай наро́дові, і нехай їдять, бо так сказав Господь: їжте й позоставте!“
“Báwo ni èmi yóò ṣe gbé èyí ka iwájú àwọn ọgọ́rùn-ún ènìyàn?” ìránṣẹ́ rẹ̀ béèrè. Ṣùgbọ́n Eliṣa dá a lóhùn pé, “Gbé e fún àwọn ènìyàn láti jẹ, nítorí èyí ni ohun tí Olúwa sọ: ‘Wọn yóò jẹ yóò sì tún ṣẹ́kù.’”
44 І він поклав перед ними, і вони їли й позоставили, за словом Господнім.
Nígbà náà ó gbé e ka iwájú wọn, wọ́n sì jẹ ẹ́, wọ́n sì ní èyí tó ṣẹ́kù, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa.

< 2 царів 4 >