< Від Луки 20 >
1 І сталось одного з тих днів, як навчав Він народ у церкві та благовіствував, поприходили архиєреї та письменники з старшими,
Ní ọjọ́ kan, bí ó ti ń kọ́ àwọn ènìyàn ní tẹmpili tí ó sì ń wàásù ìyìnrere, àwọn olórí àlùfáà, àti àwọn akọ̀wé, pẹ̀lú àwọn àgbàgbà dìde sí i.
2 і промовили до Него, кажучи: Скажи нам, якою властю се робиш? або хто дав Тобі власть сю?
Wọ́n sì wí fún un pé, “Sọ fún wa, àṣẹ wo ni ìwọ fi ń ṣe nǹkan wọ̀nyí? Tàbí ta ni ó fún ọ ní àṣẹ yìí?”
3 Відказуючи ж рече до них: Спитаю вас і я про одну річ, і скажіть мені:
Ó sì dáhùn ó sì wí fún wọn pé, “Èmi pẹ̀lú yóò sì bi yín léèrè ọ̀rọ̀ kan; ẹ sì fi ìdáhùn fún mi.
4 Хрещеннє Йоанове з неба було чи від людей?
Ìtẹ̀bọmi Johanu, láti ọ̀run wá ni tàbí láti ọ̀dọ̀ ènìyàn?”
5 Вони ж міркували в собі говорячи: Коли скажемо: З неба, казати ме: Чом же не поняли ви віри йому?
Wọ́n sì bá ara wọn gbèrò pé, “Bí àwa bá wí pé, ‘Láti ọ̀run wá ni,’ òun yóò wí pé, ‘Èéṣe tí ẹ̀yin kò fi gbà á gbọ́?’
6 Коли ж скажемо: Від людей, то ввесь народ покаменує нас; певен бо він, що Йоан пророк.
Ṣùgbọ́n bí àwa bá sì wí pé, ‘Láti ọ̀dọ̀ ènìyàn,’ gbogbo ènìyàn ni yóò sọ wá ní òkúta, nítorí wọ́n gbàgbọ́ pé, wòlíì ni Johanu.”
7 І відказали, що не знають, звідкіля.
Wọ́n sì dáhùn wí pé, “Àwa kò mọ̀ ibi tí ó ti wá.”
8 А Ісус Їм рече: То й я не скажу вам, якою властю я се роблю.
Jesu sì wí fún wọn pé, “Ǹjẹ́ èmi kì yóò wí fún yín àṣẹ tí èmi fi ń ṣe nǹkan wọ̀nyí.”
9 Почав же до народу глаголати приповість сю: Один чоловік насадив виноградник, та й дав його виноградарям, та й від'їхав на довгий час.
Nígbà náà ni ó bẹ̀rẹ̀ sí í pa òwe yìí fún àwọn ènìyàn pé, “Ọkùnrin kan gbin ọgbà àjàrà kan, ó sì fi ṣe àgbàtọ́jú fún àwọn olùṣọ́gbà, ó sì lọ sí àjò fún ìgbà pípẹ́.
10 І післав у пору до виноградарів слугу, щоб з овощу винограднього дали йому; виноградарі ж, побивши його, відослали впорожні.
Nígbà tí ó sì tó àkókò, ó rán ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ kan sí àwọn olùṣọ́gbà náà, kí wọn lè fún un nínú èso ọgbà àjàrà náà, ṣùgbọ́n àwọn alágbàtọ́jú lù ú, wọ́n sì rán an padà lọ́wọ́ òfo.
11 І післав ще другого слугу; вони ж і того, побивши та обезчестивши, відослали впорожні,
Ó sì tún rán ọmọ ọ̀dọ̀ mìíràn, wọ́n sì lù ú pẹ̀lú, wọ́n sì jẹ ẹ́ ní yà, wọ́n sì rán an padà lọ́wọ́ òfo.
12 І післав ще третього; вони ж і сього, поранивши, прогнали.
Ó sì tún rán ẹ̀kẹta: wọ́n sì sá a lọ́gbẹ́ pẹ̀lú, wọ́n sì tì í jáde.
13 Рече ж пан виноградинка: Що робити? пішлю сина мого любого: може, того побачивши, посоромлять ся.
“Nígbà náà ni Olúwa ọgbà àjàrà wí pé, ‘Èwo ni èmi ó ṣe? Èmi ó rán ọmọ mi àyànfẹ́ lọ: bóyá nígbà tí wọ́n bá rí i, wọn yóò bu ọlá fún un.’
14 Побачивши ж його виноградарі, казали між собою, говорячи: Се наслїдник; ходімо вбємо його, щоб наше було наслїддє.
“Ṣùgbọ́n nígbà tí àwọn alágbàtọ́jú náà rí i, wọ́n bá ara wọn gbèrò pé, ‘Èyí ni àrólé; ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a pa á, kí ogún rẹ̀ lè jẹ́ ti wa.’
15 І, викинувши його за виноградник, убили. Що ж робити ме пан виноградника?
Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì tì í jáde sẹ́yìn ọgbà àjàrà, wọ́n sì pa á. “Ǹjẹ́ kín ni olúwa ọgbà àjàrà náà yóò ṣe sí wọn?
16 Прийде та й вигубить виноградарів сих, і дасть виноградник иншим. Почувши ж, сказали: Борони Боже!
Yóò wá, yóò sì pa àwọn alágbàtọ́jú náà run, yóò sì fi ọgbà àjàrà náà fún àwọn ẹlòmíràn.” Nígbà tí wọ́n sì gbọ́, wọ́n ní, “Kí a má ri i!”
17 Він же, поглянувши на них, рече: Що ж се написано? Камінь, що відкинули будівничі; сей став ся головою угла?
Nígbà tí ó sì wò wọ́n, ó ní, “Èwo ha ni èyí tí a ti kọ̀wé rẹ̀ pé: “‘Òkúta tí àwọn ọ̀mọ̀lé kọ̀sílẹ̀, òun náà ni ó di pàtàkì igun ilé’?
18 Всякий, хто впаде на той камінь, розібєть ся, на кого ж він упаде, розітре його.
Ẹnikẹ́ni tí ó ṣubú lu òkúta náà yóò fọ́; ṣùgbọ́n ẹnikẹ́ni tí òun bá ṣubú lù, yóò lọ̀ ọ́ lúúlúú.”
19 І шукали архиєреї та письменники наложити на Него руки тієї години, та боялись народу; зрозуміли бо що до них приповість сю сказав.
Àwọn olórí àlùfáà àti àwọn akọ̀wé ń wá ọ̀nà láti mú un ní wákàtí náà; ṣùgbọ́n wọ́n bẹ̀rù àwọn ènìyàn, nítorí tí wọ́n mọ̀ pé, ó pa òwe yìí mọ́ wọn.
20 І, назираючи Його, післали підглядників, що видавали себе за праведних, щоб схопити Його на слові та віддати старшині та власті игемоновій.
Wọ́n sì ń ṣọ́ ọ, wọ́n sì rán àwọn ayọ́lẹ̀wò tí wọ́n ṣe ara wọn bí ẹni pé olóòtítọ́ ènìyàn, kí wọn ba à lè gbá ọ̀rọ̀ rẹ̀ mú, kí wọn ba à lè fi í lé agbára àti àṣẹ Baálẹ̀ lọ́wọ́.
21 І питали вони Його, кажучи: Учителю, знаємо, що право говориш, і навчаєш, і не дивиш ся на лице, а по правді на путь Божий наставляєш.
Wọ́n sì bí i, pé, “Olùkọ́ àwa mọ̀ pé, ìwọ a máa sọ̀rọ̀ fún ni, ìwọ a sì máa kọ́ni bí ó ti tọ́, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kì í ṣe ojúsàájú ẹnìkan ṣùgbọ́n ìwọ ń kọ́ni ní ọ̀nà Ọlọ́run lóòtítọ́.
22 Годить ся нам кесареві данину давати, чи нї?
Ǹjẹ́ ó tọ́ fún wa láti máa san owó òde fún Kesari, tàbí kò tọ́?”
23 Постерігши ж їх підступ, рече до них: Що мене спокутуєте?
Ṣùgbọ́n ó kíyèsi àrékérekè wọn, ó sì wí fún wọn pé,
24 Покажіть менї денария. Чиє мав обличчє і надпись? Озвавшися ж сказали: Кесареве.
“Ẹ fi owó idẹ kan hàn mí. Àwòrán àti àkọlé ti ta ni ó wà níbẹ̀?” Wọ́n sì dá a lóhùn pé, “Ti Kesari ni.”
25 Він же рече їм: Оддайте ж оце кесареве кесареві, а Боже Богові.
Ó sì wí fún wọn pé, “Ǹjẹ́ ẹ fi ohun tí i ṣe ti Kesari fún Kesari, àti ohun tí í ṣe ti Ọlọ́run fún Ọlọ́run.”
26 І не могли вони схопити Його на слові перед народом; і, дивуючись одповіддю Його, мовчали.
Wọn kò sì lè gbá ọ̀rọ̀ rẹ̀ mú níwájú àwọn ènìyàn: ẹnu sì yà wọ́n sí ìdáhùn rẹ̀, wọ́n sì pa ẹnu wọn mọ́.
27 Приступивши ж тоді деякі з Садукеїв, котрі перечять, шо є воекресеннє, питали Його,
Àwọn Sadusi kan sì tọ̀ ọ́ wá, àwọn tí wọ́n ń wí pé àjíǹde òkú kò sí wọ́n sì bi í,
28 говорячи: Учителю, Мойсей написав нам: Коли чий брат умре, мавши жінку, й сей бездітний умре, щоб узяв брат його жінку й воскресив насїннє братові своєму.
wí pé, “Olùkọ́, Mose kọ̀wé fún wa pé, Bí arákùnrin ẹnìkan bá kú, ní àìlọ́mọ, tí ó sì ní aya, kí arákùnrin rẹ̀ ṣú aya rẹ̀ lópó, kí ó lè gbé irú-ọmọ dìde fún arákùnrin rẹ̀.
29 Сім оце братів було; й первий, взявши жінку, умер бездітний.
Ǹjẹ́ àwọn arákùnrin méje kan ti wà; èkínní gbé ìyàwó, ó sì kú ní àìlọ́mọ.
30 І взяв другий жінку, та й сей умер бездітний.
Èkejì sì ṣú u lópó: òun sì kú ní àìlọ́mọ.
31 І третій узяв її, та й не зоставили дітей, і повмирали.
Ẹ̀kẹta sì ṣú u lópó: gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ sì ni àwọn méjèèje pẹ̀lú: wọn kò sì fi ọmọ sílẹ̀, wọ́n sì kú.
32 Опісля ж усїх умерла й жінка.
Nígbẹ̀yìn pátápátá obìnrin náà kú pẹ̀lú.
33 Оце ж у воскресенню кому з них буде жінкою? сім бо мали її за жінку.
Ǹjẹ́ ní àjíǹde òkú, aya ti ta ni yóò ha ṣe nínú wọn? Nítorí àwọn méjèèje ni ó sá à ni í ní aya.”
34 І відказуючи рече їм Ісус: Сини сьвіту сього женять ся й видають заміж: (aiōn )
Jesu sì dáhùn ó wí fún wọn pé, “Àwọn ọmọ ayé yìí a máa gbéyàwó, wọn a sì máa fa ìyàwó fún ni. (aiōn )
35 которі ж удостоють ся дождати віку того й воскресення з мертвих, ті нї женять ся анї віддають заміж: (aiōn )
Ṣùgbọ́n àwọn tí a kà yẹ láti jogún ìyè ayérayé náà, àti àjíǹde kúrò nínú òkú, wọn kì í gbéyàwó, wọn kì í sì í fa ìyàwó fún ni. (aiōn )
36 бо ані вмерти не можуть, рівні бо ангелам і сини вони Божі, воскресення синами бувши.
Nítorí wọn kò lè kú mọ́; nítorí tí wọn bá àwọn angẹli dọ́gba; àwọn ọmọ Ọlọ́run sì ni wọ́n, nítorí wọ́n di àwọn ọmọ àjíǹde.
37 А що встають мертві, то й Мойсей показав коло купини, як зве Господа Богом Авраама, й Богом Ісаака, й Богом Якова.
Ní ti pé a ń jí àwọn òkú dìde, Mose tìkára rẹ̀ sì ti fihàn nínú igbó, nígbà tí ó pe ‘Olúwa ni Ọlọ́run Abrahamu, àti Ọlọ́run Isaaki, àti Ọlọ́run Jakọbu.’
38 Бог же не мертвих а живих, всї бо Йому живуть.
Bẹ́ẹ̀ ni òun kì í ṣe Ọlọ́run àwọn òkú, bí kò ṣe ti àwọn alààyè, nítorí gbogbo wọn wà láààyè fún un.”
39 Озвавши ся ж деякі з письменників, казали: Учителю, добре глаголав єси.
Nígbà náà ni àwọn kan nínú àwọn akọ̀wé dá a lóhùn, pé, “Olùkọ́ ìwọ wí rere!”
40 І більш не сьміли питати Його нї про що.
Wọn kò sì jẹ́ bi í léèrè ọ̀rọ̀ kan mọ́.
41 Рече ж до них: Як се кажуть, що Христос син Давидів?
Ó sì wí fún wọn pé, “Èéṣe tí wọ́n fi ń wí pé, ọmọ Dafidi ni Kristi?
42 А сам Давид говорить у книзї псальм: Рече Господь Господеві моєму: Сиди по правиці в мене,
Dafidi tìkára rẹ̀ sì wí nínú ìwé Saamu pé: “‘Olúwa sọ fún Olúwa mi pé: “Ìwọ jókòó ní ọwọ́ ọ̀tún mi
43 доки положу ворогів Твоїх підніжком ніг твоїх.
títí èmi ó fi sọ àwọn ọ̀tá rẹ di àpótí ìtìsẹ̀ rẹ.”’
44 Давид оце Господом Його зве: як же Він син Його?
Ǹjẹ́ bí Dafidi bá pè é ní ‘Olúwa.’ Òun ha sì ti ṣe jẹ́ ọmọ rẹ̀?”
45 Як же слухав увесь народ, рече ученикам своїм:
Ó sì wí fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ ní etí gbogbo ènìyàn pé,
46 Остерегайтесь письменників, що бажають ходити в шатах, та люблять витання на торгах, та перві сїдалища по школах, та перві місця на бенкетах;
“Ẹ máa kíyèsára lọ́dọ̀ àwọn akọ̀wé, tí wọ́n fẹ́ láti máa rìn nínú aṣọ gígùn, tí wọ́n sì fẹ́ ìkíni ní ọjà, àti ibùjókòó ọlá nínú Sinagọgu, àti ipò ọlá ní ibi àsè;
47 що жеруть доми вдовиць, і для виду довго молять ся. Сї приймуть ще тяжчий осуд.
Àwọn tí ó jẹ ilé àwọn opó run, tí wọ́n sì ń gbàdúrà gígùn fún àṣehàn, àwọn wọ̀nyí náà ni yóò jẹ̀bi pọ̀jù.”