< Nnwom 105 >

1 Ɛda Awurade ase na da ne kɛseyɛ adi. Ma ewiase nyinaa nhunu deɛ wayɛ.
Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, ké pe orúkọ rẹ̀, jẹ́ kí a mọ ohun tí ó ṣe láàrín àwọn orílẹ̀-èdè.
2 Monto dwom mma no, monto ayɛyie dwom mma no; monka nʼanwanwadeɛ no nyinaa.
Kọrin sí i, kọrin ìyìn sí i; sọ ti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ gbogbo.
3 Monhoahoa mo ho wɔ ne din kronkron mu; momma wɔn a wɔhwehwɛ Awurade no nnya akoma mu anigyeɛ.
Ṣògo nínú orúkọ mímọ́ rẹ̀, jẹ́ kí ọkàn àwọn tí ń wá Olúwa kí ó yọ̀.
4 Momma mo ani nna Awurade ne nʼahoɔden so; na monhwehwɛ nʼanim ɛberɛ biara.
Wá Olúwa àti ipá rẹ̀; wa ojú rẹ̀ nígbà gbogbo.
5 Monkae anwanwadeɛ a wayɛ ne nsɛnkyerɛnneɛ, ne atemmuo a ɔbuiɛ,
Rántí àwọn ìyanu tí ó ti ṣe, ìyanu rẹ̀, àti ìdájọ́ tí ó sọ,
6 Ao Abraham mma, Onyankopɔn ɔsomfoɔ, Ao Yakob mma a wapa wɔn.
ẹ̀yin ìran Abrahamu ìránṣẹ́ rẹ̀, ẹ̀yin ọmọkùnrin Jakọbu, àyànfẹ́ rẹ̀.
7 Ɔyɛ Awurade, yɛn Onyankopɔn. Nʼahennie da adi wɔ asase so nyinaa.
Òun ni Olúwa Ọlọ́run wa: ìdájọ́ rẹ̀ wà ní gbogbo ayé.
8 Ɔkae nʼapam daa nyinaa, asɛm a ɔhyɛ maa awoɔ ntoantoasoɔ apem no,
Ó rántí májẹ̀mú rẹ̀ láéláé, ọ̀rọ̀ tí ó pàṣẹ, fún ẹgbẹẹgbẹ̀rún ìran,
9 apam a ɔne Abraham yɛeɛ no ntam a ɔka kyerɛɛ Isak no.
májẹ̀mú tí ó dá pẹ̀lú Abrahamu, ìbúra tí ó ṣe pẹ̀lú fún Isaaki.
10 Ɔhyɛɛ mu den maa Yakob sɛ mmara, de maa Israel sɛ apam a ɛbɛtena hɔ afebɔɔ.
Ó ṣe ìdánilójú u rẹ̀ fún Jakọbu gẹ́gẹ́ bí àṣẹ, sí Israẹli, gẹ́gẹ́ bi májẹ̀mú ayérayé:
11 Ɔkaa sɛ, “Mede Kanaan asase no bɛma wo sɛ kyɛfa a ɛbɛyɛ wʼagyapadeɛ.”
“Fún ìwọ ni èmi ó fún ní ilẹ̀ Kenaani gẹ́gẹ́ bí ìpín tí ìwọ ó jogún.”
12 Ɔkaa yei ɛberɛ a na wɔnnɔɔso, ahɔhokuo ketewa bi a wɔwɔ Kanaan.
Nígbà tí wọn kéré níye, wọ́n kéré jọjọ, àti àwọn àjèjì níbẹ̀
13 Wɔfirii aman so kɔɔ aman so; firii ahemman mu kɔɔ ahemman mu.
wọ́n rìn kiri láti orílẹ̀-èdè sí orílẹ̀-èdè, láti ìjọba kan sí èkejì.
14 Wamma obi anhyɛ wɔn so; wɔn enti, ɔkaa ahene anim sɛ:
Kò gba ẹnikẹ́ni láààyè láti pọ́n wọn lójú; ó fi ọba bú nítorí tiwọn:
15 “Mommfa mo nsa nka wɔn a masra wɔn ngo; na monnyɛ mʼadiyifoɔ bɔne bi.”
“Má ṣe fọwọ́ kan ẹni àmì òróró mi; má sì ṣe wòlíì mi níbi.”
16 Ɔmaa ɛkɔm baa asase no so na ɔsɛee akwan a wɔfa so nya wɔn aduane nyinaa;
Ó pe ìyàn sórí ilẹ̀ náà ó sì pa gbogbo ìpèsè oúnjẹ wọn run;
17 na ɔsomaa ɔbarima bi dii wɔn anim, Yosef a wɔtɔn no sɛ akoa no.
Ó sì rán ọkùnrin kan síwájú wọn Josẹfu tí a tà gẹ́gẹ́ bí ẹrú.
18 Wɔde mpokyerɛ guu ne nan, na wɔde dadeɛ nkɔnsɔnkɔnsɔn hyɛɛ ne kɔn,
Wọn fi ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀ bọ ẹsẹ̀ rẹ̀ a gbé ọrùn rẹ̀ sínú irin,
19 kɔsii sɛ deɛ ɔhyɛɛ ho nkɔm no baa mu, kɔsii sɛ Awurade asɛm no daa no adi sɛ ɔyɛ nokwafoɔ.
títí ọ̀rọ̀ tí ó sọtẹ́lẹ̀ fi ṣẹ títí ọ̀rọ̀ Olúwa fi dá a láre.
20 Afei, ɔhene no soma ma wɔkɔgyaa no; aman no sodifoɔ gyaa no.
Ọba ránṣẹ́ lọ tú u sílẹ̀ àwọn aláṣẹ ènìyàn tú u sílẹ̀
21 Ɔyɛɛ no ne fiefoɔ so wura, deɛ ɔwɔ nyinaa sodifoɔ,
Ó fi jẹ olúwa lórí ilẹ̀ rẹ̀, aláṣẹ lórí ohun gbogbo tí ó ní,
22 sɛ ɔnkyerɛ ne mmapɔmma deɛ ɔpɛ na ɔnkyerɛ ne mpanimfoɔ nyansa.
gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ̀, kí ó máa ṣe àkóso àwọn ọmọ-aládé kí ó sì kọ́ àwọn àgbàgbà rẹ̀ ní ọgbọ́n.
23 Afei, Israel kɔɔ Misraim; Yakob kɔtenaa Ham asase so sɛ ɔnanani.
Israẹli wá sí Ejibiti; Jakọbu sì ṣe àtìpó ní ilé Hamu.
24 Awurade maa ne nkurɔfoɔ ase dɔreeɛ; ɔyɛɛ wɔn bebree dodo maa wɔn atamfoɔ,
Olúwa, sì mú àwọn ọmọ rẹ̀ bí sí i ó sì mú wọn lágbára jù àwọn ọ̀tá wọn lọ
25 wɔn a ɔdanee wɔn akoma sɛ wɔntane ne nkurɔfoɔ na wɔmpam nʼasomfoɔ tiri so.
Ó yí wọn lọ́kàn padà láti kórìíra àwọn ènìyàn láti ṣe àrékérekè sí àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀.
26 Ɔsomaa ne ɔsomfoɔ Mose, ne Aaron a na wayi noɔ no.
Ó rán Mose ìránṣẹ́ rẹ̀, àti Aaroni tí ó ti yàn.
27 Wɔyɛɛ ne nsɛnkyerɛnneɛ nwanwasoɔ wɔ wɔn mu, nʼanwanwadeɛ wɔ Ham asase so.
Wọ́n ń ṣe iṣẹ́ ìyanu láàrín wọn ó ṣe iṣẹ́ ìyanu ní Hamu.
28 Ɔsomaa esum, na ɔmaa asase duruu sum ɛfiri sɛ na wɔate nʼasɛm no so atua.
Ó rán òkùnkùn, o sì mú ilẹ̀ ṣú wọn kò sì sọ̀rọ̀-òdì sí ọ̀rọ̀ rẹ̀.
29 Ɔmaa wɔn nsuo nyinaa danee mogya, nam so kumm emu mpataa.
Ó sọ omi wọn di ẹ̀jẹ̀, ó pa ẹja wọn.
30 Mpɔtorɔ bɛhyɛɛ asase no so ma, na wɔhyɛnee ɔman no sodifoɔ mpia mu.
Ilẹ̀ mú ọ̀pọ̀lọ́ jáde wá, èyí tí ó lọ sí ìyẹ̀wù àwọn ọba wọn.
31 Ɔkasaeɛ, na nwansena bebree ne ntontom baa ɔman no mu baabiara.
Ó sọ̀rọ̀, onírúurú eṣinṣin sì dìde, ó sì hu kantíkantí ní ilẹ̀ wọn
32 Ɔmaa wɔn osutɔ danee ampariboɔ a anyinam nenam mu wɔ ɔman no nyinaa mu;
Ó sọ òjò di yìnyín, àti ọ̀wọ́-iná ní ilẹ̀ wọn;
33 Ɔsɛee wɔn bobe ne borɔdɔma nnua na ɔbubuu ɔman no so nnua pasaa.
Ó lu àjàrà wọn àti igi ọ̀pọ̀tọ́ wọn ó sì dá igi orílẹ̀-èdè wọn.
34 Ɔkasaeɛ, na ntutummɛ baeɛ mmɛbɛ a wɔntumi nkan wɔn;
Ó sọ̀rọ̀, eṣú sì dé, àti kòkòrò ní àìníye,
35 wɔwee nhahammono biara a ɛwɔ wɔn asase no so, na wɔdii wɔn mfuo so nnuane.
wọn sì jẹ gbogbo ewé ilẹ̀ wọn, wọ́n sì jẹ èso ilẹ̀ wọn run.
36 Afei ɔkunkumm wɔn asase so mmakan nyinaa, wɔn mmarimayɛ mu aba a ɛdi ɛkan nyinaa.
Nígbà náà, ó kọlu gbogbo àwọn ilẹ̀ wọn, ààyò gbogbo ipá wọn.
37 Ɔyii Israelfoɔ, a wɔso dwetɛ ne sikakɔkɔɔ, firii wɔn mmusuakuo mu a obiara ho antɔ kyima.
Ó mú Israẹli jáde ti òun ti fàdákà àti wúrà, nínú ẹ̀yà rẹ̀ kò sí aláìlera kan.
38 Misraim ani gyeeɛ ɛberɛ a wɔkɔeɛ, ɛfiri sɛ na Israelfoɔ ho hu atɔ wɔn so.
Inú Ejibiti dùn nígbà tí wọn ń lọ, nítorí ẹ̀rù àwọn Israẹli ń bá wọ́n.
39 Ɔtrɛɛ omununkum mu kataa wɔn so, na ɔde ogya maa wɔn, sɛ ɛnyɛ hann anadwo.
Ó ta àwọsánmọ̀ fún ìbòrí, àti iná láti fún wọn ní ìmọ́lẹ̀ lálẹ́.
40 Wɔbisaeɛ, na ɔbrɛɛ wɔn mmoko. Ɔmaa ɔsoro aduane mee wɔn.
Wọn béèrè, ó sì mú ẹyẹ àparò wá, ó sì fi oúnjẹ ọ̀run tẹ́ wọn lọ́rùn.
41 Ɔbuee ɔbotan mu maa nsuo firii mu baeɛ; na ɛtenee wɔ ɛserɛ no so sɛ asubɔnten.
Ó sì la àpáta, ó sì mú omi jáde; gẹ́gẹ́ bí odò tí ń sàn níbi gbígbẹ.
42 Ɔkaee ne bɔhyɛ kronkron bi a ɔhyɛɛ ne ɔsomfoɔ Abraham no.
Nítorí ó rántí ìlérí mímọ́ rẹ̀ àti Abrahamu ìránṣẹ́ rẹ̀.
43 Ɔyii ne nkurɔfoɔ maa wɔn ani gyeeɛ. Wɔn a wapa wɔn no dii ahurisie;
Ó sì fi ayọ̀ mú àwọn ènìyàn rẹ̀ jáde pẹ̀lú ayọ̀ ní ó yan àyànfẹ́ rẹ̀
44 ɔde amanaman no nsase maa wɔn, na deɛ ebinom abrɛ anya no bɛyɛɛ wɔn agyapadeɛ
Ó fún wọn ní ilẹ̀ ìní náà, wọ́n sì jogún iṣẹ́ àwọn ènìyàn náà,
45 na wɔahwɛ nʼahyɛdeɛ adi ne mmara so. Monyi Awurade ayɛ.
kí wọn kí ó lè máa pa àṣẹ rẹ̀ mọ́ kí wọn kí ó lè kíyèsi òfin rẹ̀. Ẹ fi ìyìn fún Olúwa.

< Nnwom 105 >