< Hiob 5 >

1 “Wopɛ a frɛ, na hwan na ɔbɛgye wo soɔ? Akronkronfoɔ no mu hwan nkyɛn na wobɛkorɔ?
“Ó jẹ́ pé nísinsin yìí bí ẹnìkan bá wà tí yóò dá wa lóhùn? Tàbí ta ni nínú àwọn ènìyàn mímọ́ tí ìwọ ó yípadà sí?
2 Ahisɛm kum ɔkwasea, na anibereɛ kum atetekwaa.
Nítorí pé ìbínú pa aláìmòye, ìrunú a sì pa òpè ènìyàn.
3 Mʼankasa mahunu ɔkwasea a ɔrefefɛ, nanso, mpofirim, wɔdomee ne fie.
Èmi ti rí aláìmòye ti ó ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n lulẹ̀, ṣùgbọ́n lójúkan náà mo fi ibùjókòó rẹ̀ bú.
4 Ne mma ne banbɔ ntam ɛkwan ware, wɔdwerɛ wɔn wɔ asɛnniiɛ a wɔnnya ɔkamafoɔ.
Àwọn ọmọ rẹ̀ kò jìnnà sí ewu, a sì tẹ̀ wọ́n mọ́lẹ̀ lójú ibodè, bẹ́ẹ̀ ni kò sí aláàbò kan.
5 Deɛ ɛkɔm de noɔ no di ne nnɔbaeɛ, na ɔfa firi nkasɛɛ mu mpo, na deɛ osukɔm de noɔ no pere di nʼahodeɛ akyi.
Ìkórè oko ẹni tí àwọn tí ebi ń pa sọ̀ di jíjẹ, tí wọ́n sì wọ inú ẹ̀gún lọ kó, àwọn ìgárá ọlọ́ṣà sì gbé ohun ìní wọn mì.
6 Ahokyere mmpue mfiri dɔteɛ mu na ɔhaw nso mmpue mfiri fam.
Bí ìpọ́njú kò bá ti inú erùpẹ̀ jáde wá ni, tí ìyọnu kò ti ilẹ̀ jáde wá.
7 Nanso wɔwo nnipa to ɔhaw mu mpɛn dodoɔ a ogyaframa turi kɔ ɔsoro.
Ṣùgbọ́n a bí ènìyàn sínú wàhálà, gẹ́gẹ́ bí ìpẹ́pẹ́ iná ti máa ń ta sókè.
8 “Nanso sɛ ɛyɛ me a, anka mɛdwane atoa Onyankopɔn; na mede mʼasɛm ato nʼanim.
“Ṣùgbọ́n bí ó ṣe tèmi, ọ̀dọ̀ Ọlọ́run ní èmi yóò ti ṣìpẹ̀, ní ọwọ́ Ọlọ́run ní èmi yóò máa fi ọ̀rọ̀ mi lé.
9 Ɔyɛ anwanwadeɛ a wɔntumi nhwehwɛ mu, ne nsɛnkyerɛnneɛ a wɔntumi nkan ne dodoɔ.
Ẹni tí ó ṣe ohun tí ó tóbi tí a kò lè ṣe àwárí, ohun ìyanu láìní iye.
10 Ɔtɔ nsuo gu asase so; na ɔde kɔ wira mu.
Tí ń rọ̀jò sí orí ilẹ̀ ayé tí ó sì ń rán omi sínú ilẹ̀kílẹ̀.
11 Ɔde ahobrɛasefoɔ si deɛ ɛkorɔn, na ɔma wɔn a wɔdi awerɛhoɔ nya asomdwoeɛ.
Láti gbé àwọn orílẹ̀-èdè lékè kí á lè gbé àwọn ẹni ìbànújẹ́ ga sí ibi aláìléwu.
12 Ɔsɛe anifirefoɔ nhyehyɛeɛ, ma wɔn nsa si fam.
Ó yí ìmọ̀ àwọn alárékérekè po, bẹ́ẹ̀ ní ọwọ́ wọn kò lè mú ìdáwọ́lé wọn ṣẹ.
13 Ɔkyere anyansafoɔ wɔ wɔn anifire mu, na ɔbɔ anitefoɔ nhyehyɛeɛ gu.
Ó mú àwọn ọlọ́gbọ́n nínú àrékérekè ara wọn, àti ìmọ̀ àwọn òǹrorò ní ó tì ṣubú ní ògèdèǹgbé.
14 Esum duru wɔn awia ketee; na wɔkeka owigyinaeɛ te sɛ anadwo.
Wọ́n sáré wọ inú òkùnkùn ní ọ̀sán; wọ́n sì fọwọ́ tálẹ̀ ní ọ̀sán gangan bí ẹni pé ní òru ni.
15 Ɔgye ahiafoɔ firi afena a ɛhyɛ wɔn anomu; ɔgye wɔn firi ahoɔdenfoɔ nkyehoma mu.
Ṣùgbọ́n ó gba tálákà là ní ọwọ́ idà, lọ́wọ́ ẹnu wọn àti lọ́wọ́ àwọn alágbára.
16 Enti, ahiafoɔ wɔ anidasoɔ, na ntɛnkyea ka nʼano to mu.
Bẹ́ẹ̀ ni ìrètí wà fún tálákà, àìṣòótọ́ sì pa ẹnu rẹ̀ mọ́.
17 “Nhyira ne onipa a Onyankopɔn tene no, enti mmu Otumfoɔ ntenetene no animtiaa.
“Kíyèsi i, ìbùkún ni fún ẹni tí Ọlọ́run bá wí, nítorí náà, má ṣe gan ìbáwí Olódùmarè.
18 Ɛfiri sɛ, ɔno na ɔpira na ɔno ara akyekyere; ɔpira nanso ne nsa sa yadeɛ.
Nítorí pé òun a máa pa ni lára, síbẹ̀ òun a sì tún dì í ní ìdì ìtura, ó sá lọ́gbẹ́, a sì fi ọwọ́ rẹ̀ di ojú ọgbẹ̀ náà jiná.
19 Ɔbɛgye wo afiri ɔhaw ahodoɔ nsia mu; nson so, a bɔne biara renka wo.
Yóò gbà ọ́ nínú ìpọ́njú mẹ́fà, àní nínú méje, ibi kan kì yóò bá ọ.
20 Ɛkɔm ba a, ɔbɛgye wo afiri owuo mu, na ɔko mu nso, ɔbɛgye wo afiri afena ano.
Nínú ìyanu yóò gbà ọ́ lọ́wọ́ ikú àti nínú ogun, yóò gbà ọ́ lọ́wọ́ idà.
21 Wɔbɛbɔ wo ho ban afiri kasatwie ho na sɛ ɔsɛeɛ ba a, ɛnsɛ sɛ wosuro.
A ó pa ọ́ mọ́ kúrò lọ́wọ́ iná ahọ́n, bẹ́ẹ̀ ní ìwọ kì yóò bẹ̀rù ìparun tí ó bá dé.
22 Wobɛsere ɔsɛeɛ ne ɔkɔm; na ɛnsɛ sɛ wosuro asase so mmoa.
Ìwọ yóò rẹ́rìn-ín nínú ìparun àti ìyàn, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kì yóò bẹ̀rù ẹranko ilẹ̀ ayé.
23 Wo ne afuo so aboɔ bɛyɛ apam, na emu nkekaboa nso ne wo bɛtena asomdwoeɛ mu.
Nítorí pé ìwọ ti bá òkúta igbó mulẹ̀, àwọn ẹranko igbó yóò wà pẹ̀lú rẹ ní àlàáfíà.
24 Wobɛhunu sɛ wo ntomadan wɔ banbɔ; na sɛ wosese wʼahodeɛ a, wobɛhunu sɛ hwee nyeraeɛ.
Ìwọ ó sì mọ̀ pé àlàáfíà ni ibùjókòó rẹ wà, ìwọ yóò sì máa ṣe ìbẹ̀wò ibùjókòó rẹ, ìwọ kì yóò ṣìnà.
25 Wobɛhunu sɛ wo mma bɛyɛ bebree; na wʼasefoɔ bɛdɔre sɛ ɛserɛ.
Ìwọ ó sì mọ̀ pẹ̀lú pé irú-ọmọ rẹ ó sì pọ̀ àti àwọn ọmọ ọmọ rẹ yóò rí bí koríko igbó.
26 Wode ahoɔden bɛkɔ damena mu, te sɛ afiafi a wɔaboa ano wɔ otwa berɛ mu.
Ìwọ yóò wọ isà òkú rẹ ní ògbólógbòó ọjọ́, bí síírí ọkà tí ó gbó tí á sì kó ní ìgbà ìkórè rẹ̀.
27 “Yɛahwehwɛ yei mu, na ɛyɛ nokorɛ ɛno enti tie na fa toto wʼabrabɔ ho.”
“Kíyèsi i, àwa ti wádìí rẹ̀ bẹ́ẹ̀ ní ó rí! Gbà á gbọ́, kí o sì mọ̀ pé fún ìre ara rẹ ni.”

< Hiob 5 >