< Hiob 38 >

1 Afei, Awurade firi ahum mu buaa Hiob sɛ,
Nígbà náà ní Olúwa dá Jobu lóhùn láti inú ìjì àjàyíká wá, ó sì wí pé,
2 “Hwan ne deɛ ɔde nsɛm a nimdeɛ nni mu katakata mʼafotuo so?
“Ta ni èyí tí ń fi ọ̀rọ̀ àìlóye láti fi ṣókùnkùn bo ìmọ̀ mi?
3 Hyɛ wo ho den sɛ ɔbarima; mɛbisa wo nsɛm, na wobɛyi mʼano.
Di ẹ̀gbẹ́ ara rẹ ní àmùrè bí ọkùnrin nísinsin yìí, nítorí pé èmi yóò béèrè lọ́wọ́ rẹ kí o sì dá mi lóhùn.
4 “Ɛberɛ a metoo asase fapem no, na wowɔ he? Sɛ wonim a, ka ɛ.
“Níbo ni ìwọ wà nígbà tí mo fi ìpìlẹ̀ ayé sọlẹ̀? Wí bí ìwọ bá mòye.
5 Hwan na ɔsusuu ne tenten ne ne tɛtrɛtɛ? Ampa ara wonim! Hwan na ɔtwee susuhoma faa ani?
Ta ni ó fi ìwọ̀n rẹ lélẹ̀, dájú bí ìwọ bá mọ̀ ọ́n? Tàbí ta ni ó ta okùn wíwọ̀n sórí rẹ?
6 Ɛdeɛn so na ɛgyina, anaasɛ hwan na ɔtoo ne tweatiboɔ no,
Lórí ibo ni a gbé kan ìpìlẹ̀ rẹ̀ mọ́, tàbí ta ni ó fi òkúta igun rẹ̀ lélẹ̀,
7 ɛberɛ a anɔpa nsoromma bɔɔ mu too dwom, na abɔfoɔ nyinaa de anigyeɛ teaam no?
nígbà náà àwọn ìràwọ̀ òwúrọ̀ jùmọ̀ kọrin pọ̀, tí gbogbo àwọn ọmọ Ọlọ́run hó ìhó ayọ̀?
8 “Hwan na ɔkaa ɛpo hyɛɛ apono akyi, ɛberɛ a ɛpue firii yafunu mu,
“Tàbí ta ni ó fi ìlẹ̀kùn sé omi òkun mọ́, nígbà tí ó ya padà bí ẹni pé ó ti inú jáde wá.
9 ɛberɛ a mede omununkum yɛɛ nʼaduradeɛ na mede esum kabii kyekyeree noɔ,
Nígbà tí mo fi àwọsánmọ̀ ṣe aṣọ rẹ̀, tí mo sì fi òkùnkùn biribiri ṣe ọ̀já ìgbà inú rẹ̀.
10 ɛberɛ a metoo hyeɛ maa noɔ na mesisii nʼapono ne nʼadaban,
Nígbà tí mo ti pàṣẹ ìpinnu mi fún un, tí mo sì ṣe bèbè àti ìlẹ̀kùn.
11 ɛberɛ a mekaa sɛ, ‘Ɛha ara na wobɛduru, ɛntra ha; ɛha na wʼahantan asorɔkyeɛ no mmɛso’?
Tí mo sì wí pé níhìn-ín ni ìwọ ó dé, kí o má sì rékọjá, níhìn-ín sì ni ìgbéraga rẹ yóò gbé dúró mọ?
12 “Woahyɛ mmara ama adekyeeɛ da? Anaa woakyerɛ no nʼafa,
“Ìwọ pàṣẹ fún òwúrọ̀ láti ìgbà ọjọ́ rẹ̀ wá, ìwọ sì mú ìlà-oòrùn mọ ipò rẹ̀,
13 sɛ ɛnkɔka asase ano na ɛntu amumuyɛfoɔ mfiri so?
í ó lè di òpin ilẹ̀ ayé mú, ki a lè gbọ́n àwọn ènìyàn búburú kúrò nínú rẹ̀?
14 Asase fa ne bɔberɛ sɛ dɔteɛ a ɛhyɛ nsɔano ase; na ɛso tebea da adi te sɛ atadeɛ.
Kí ó yí padà bí amọ̀ fún èdìdì amọ̀, kí gbogbo rẹ̀ kí ó sì fi ara rẹ̀ hàn bí ẹni pé nínú aṣọ ìgúnwà.
15 Wɔde amumuyɛfoɔ hann akame wɔn, na wɔn abasa a wɔapagya no mu abu.
A sì fa ìmọ́lẹ̀ wọn sẹ́yìn kúrò lọ́dọ̀ ènìyàn búburú, apá gíga ni a sì ṣẹ́.
16 “Woapɛɛpɛɛ mu ahunu nsutire a ɛpo firi mu ba anaa woanante ne bunu mu?
“Ìwọ ha wọ inú ìsun òkun lọ rí bí? Ìwọ sì rìn lórí ìsàlẹ̀ ibú ńlá?
17 Wɔde owuo apono akyerɛ wo? Woahunu owuo sunsumma apono anaa?
A ha ṣílẹ̀kùn ikú sílẹ̀ fún ọ rí bí, ìwọ sì rí ìlẹ̀kùn òjìji òkú?
18 Woate ewiase a ɛda hɔ hahanaa no ase anaa? Sɛ wonim yeinom nyinaa a, ka kyerɛ me.
Ìwọ mòye ìbú ayé bí? Sọ bí ìwọ bá mọ gbogbo èyí.
19 “Ɛhe na hann firi ba? Na ɛhe na esum nso kɔ?
“Ọ̀nà wo ni ìmọ́lẹ̀ ń gbé? Bí ó ṣe ti òkùnkùn, níbo ni ipò rẹ̀,
20 Wobɛtumi de wɔn akɔ wɔn siberɛ? Wonim akwan a ɛkɔ wɔn atenaeɛ?
tí ìwọ í fi mú un lọ sí ibi àlá rẹ̀, tí ìwọ ó sì le mọ ipa ọ̀nà lọ sínú ilé rẹ̀?
21 Ampa ara wonim, ɛfiri sɛ na woawo wo dada. Woanyini yie!
Ìwọ mọ èyí, nítorí nígbà náà ni a bí ọ? Iye ọjọ́ rẹ sì pọ̀.
22 “Woakɔ sukyerɛmma adekoradan mu da, anaa woahunu asukɔtweaa adekoradan
“Ìwọ ha wọ inú ìṣúra ìdì òjò lọ rí bí, ìwọ sì rí ilé ìṣúra yìnyín rí,
23 a makora so ama ahohiahia berɛ, ɔsa ne akodie nna?
tí mo ti fi pamọ́ de ìgbà ìyọnu, dé ọjọ́ ogun àti ìjà?
24 Ɛkwan bɛn na ɛkɔ baabi a anyinam firi ba, anaa baabi a apueeɛ mframa firi na ɛbɔ fa asase so?
Ọ̀nà wo ni ó lọ sí ibi tí ìmọ́lẹ̀ fi ń la, tí afẹ́fẹ́ ìlà-oòrùn ń tàn káàkiri lórí ilẹ̀ ayé?
25 Hwan na ɔtwaa ɛka maa osubransam, ne ɛkwan maa aprannaa mmobom,
Ta ni ó la ipadò fún ẹ̀kún omi, àti ọ̀nà fún mọ̀nàmọ́ná àrá,
26 sɛ ɛbɛtɔ agu asase a obiara nte soɔ so, anweatam a obiara nni soɔ,
láti mú u rọ̀jò sórí ayé níbi tí ènìyàn kò sí, ní aginjù níbi tí ènìyàn kò sí;
27 na ama asase bonini a ɛyɛ wesee yi afɔ na ɛserɛ afifiri so?
láti mú ilẹ̀ tútù, ijù àti aláìro láti mú àṣẹ̀ṣẹ̀yọ ewéko rú jáde?
28 Osutɔ wɔ agya anaa? Hwan na ɔyɛ agya ma obosuo?
Òjò ha ní baba bí? Tàbí ta ni o bí ìkún ìṣe ìrì?
29 Hwan yafunu mu na nsukyeneeɛ fire? Hwan na ɔwoo nsukyeneeɛ mporoporowa firi soro
Láti inú ta ni ìdì omi ti jáde wá? Ta ni ó bí ìrì dídì ọ̀run?
30 ɛberɛ a nsuo kyene dane sɛ ɛboɔ, na ebunu ani kyene?
Nígbà tí omi di líle bí òkúta, nígbà tí ojú ibú ńlá sì dìpọ̀.
31 “Wobɛtumi de ahoma akyekyere Akokɔbaatan ne ne mma? Wobɛtumi asane Nwenwenente nhoma anaa?
“Ìwọ ha le fi ọ̀já de àwọn ìràwọ̀ Pleiadesi dáradára? Tàbí ìwọ le tún di ìràwọ̀ Orioni?
32 Wobɛtumi de anɔpa nsoromma aba wɔ ne berɛ mu anaasɛ wobɛtumi ayi sisire ne ne mma afiri hɔ?
Ìwọ le mú àwọn àmì méjìlá ìràwọ̀ Masaroti jáde wá nígbà àkókò wọn? Tàbí ìwọ le ṣe amọ̀nà Beari pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ̀?
33 Wonim mmara a ɛfa ewiem ho? Wobɛtumi de Onyankopɔn ahennie aba asase so?
Ǹjẹ́ ìwọ mọ ìlànà ọ̀run? Ìwọ le fi ìjọba Ọlọ́run lélẹ̀ lórí ayé?
34 “Wobɛtumi ama wo nne aduru omununkum so na wode nsuo akata wo ho anaa?
“Ìwọ le gbé ohùn rẹ sókè dé àwọsánmọ̀ kí ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi kí ó lè bò ọ́?
35 Wobɛtumi ama anyinam atwa? Wɔbɛka akyerɛ wo sɛ, ‘Yɛnnie anaa’?
Ìwọ le rán mọ̀nàmọ́ná kí wọn kí ó le lọ, ní ọ̀nà wọn kí wọn kí ó sì wí fún wọn pé, ‘Àwa nìyí’?
36 Hwan na ɔde nyansa ma akoma anaasɛ ɔde nteaseɛ hyɛ adwene mu.
Ta ni ó fi ọgbọ́n pamọ́ sí odò ikùn tàbí tí ó fi òye sínú àyà?
37 Hwan na ɔwɔ nyansa a wɔde kan omununkum? Hwan na ɔbɛtumi akyea ɔsoro nsuo nkotokuo,
Ta ni ó fi ọgbọ́n ka iye àwọsánmọ̀? Ta ni ó sì mú ìgò ọ̀run dà jáde,
38 ɛberɛ a mfuturo ayɛ den ama dɔteɛ atɔatɔ keka bɔ mu.
nígbà tí erùpẹ̀ di líle, àti ògúlùtu dìpọ̀?
39 “Wokɔ ahayɔ ma gyatabereɛ ma agyata didi mee
“Ìwọ ha dẹ ọdẹ fún abo kìnnìún bí? Ìwọ ó sì tẹ ebi ẹgbọrọ kìnnìún lọ́rùn,
40 ɛberɛ a wɔbutubutu wɔn abɔn ano anaasɛ wɔtetɛ nnɔtɔ ase?
nígbà tí wọ́n bá mọ́lẹ̀ nínú ihò tí wọ́n sì ba ní ibùba de ohun ọdẹ?
41 Hwan na ɔma anene aduane ɛberɛ a ne mma su frɛ Onyankopɔn na wɔkyinkyini pɛ aduane?
Ta ni ó ń pèsè ohun jíjẹ fún ẹyẹ ìwò, nígbà tí àwọn ọmọ rẹ ń ké pe Ọlọ́run, tí wọ́n sì máa ń fò kiri nítorí àìní ohun jíjẹ?

< Hiob 38 >