< Nnwom 78 >

1 Asaf dwom. Me nkurɔfo, muntie me nkyerɛkyerɛ; monyɛ aso mma mʼanom nsɛm.
Maskili ti Asafu. Ẹ̀yin ènìyàn mi, ẹ gbọ́ ẹ̀kọ́ mi; tẹ́tí rẹ sí ọ̀rọ̀ ẹnu mi.
2 Mɛkasa wɔ abebu mu, mɛka ahintasɛm, teteete nneɛma no,
Èmi ó la ẹnu mi ní òwe, èmi o sọ ohun ìkọ̀kọ̀, ohun ti ọjọ́ pípẹ́;
3 nneɛma a yɛate na yɛahu; nneɛma a yɛn agyanom aka ho asɛm akyerɛ yɛn.
ohun tí a ti gbọ́ tí a sì ti mọ̀, ohun tí àwọn baba wa ti sọ fún wa.
4 Yɛremfa nkame wɔn mma; yɛbɛka akyerɛ nkyirimma Awurade nneyɛe a ɛfata nkamfo no, ne tumi ne anwonwade a wayɛ no.
Àwa kì yóò pa wọ́n mọ́ kúrò lọ́dọ̀ àwọn ọmọ, ní fífi ìyìn Olúwa, àti ipa rẹ̀ àti iṣẹ́ ìyanu tó ti ṣe hàn fún ìran tí ń bọ̀.
5 Ɔyɛɛ ahyɛde maa Yakob na ɔyɛɛ mmara wɔ Israel, nea ɔhyɛɛ yɛn nenanom sɛ wɔnkyerɛ wɔn mma,
Ó gbé ẹ̀rí kalẹ̀ ní Jakọbu o sì fìdí àṣẹ múlẹ̀ ní Israẹli, èyí tí ó pàṣẹ fún àwọn baba ńlá wa láti kọ́ àwọn ọmọ wọn,
6 sɛnea ɛbɛyɛ a nkyirimma besua, mpo mmofra a wonnya nwoo wɔn, na wɔn nso akyerɛkyerɛ wɔn mma.
nítorí náà, àwọn ìran tí ń bọ̀ yóò mọ̀ wọ́n bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọ tí a kò tí ì bí tí yóò dìde tí wọn yóò sọ fún àwọn ọmọ wọn.
7 Afei wɔde wɔn ho bɛto Onyankopɔn so, na wɔn werɛ remfi ne nneyɛe, na wobedi nʼahyɛde so.
Nígbà náà ni wọ́n ò fi ìgbẹ́kẹ̀lé wọn sínú Ọlọ́run wọn kò sì ní gbàgbé iṣẹ́ Ọlọ́run ṣùgbọ́n wọn ó pa àṣẹ rẹ̀ mọ́.
8 Wɔrenyɛ sɛ wɔn nenanom, a na wɔyɛ asoɔdenfo ne atuatewfo, wɔn a wonni Onyankopɔn nokware wɔ wɔn koma mu na woyɛ honhom mu atorofo ma no no.
Kí wọn kí ó má ṣe dàbí àwọn baba ńlá wọn, ìran alágídí àti ọlọ́tẹ̀, ìran tí ọkàn wọn kò ṣọ òtítọ́ si olóore, àti ẹ̀mí ẹni tí kò bá Ọlọ́run dúró ṣinṣin.
9 Ɛwɔ mu sɛ na Efraim mmarima kurakura agyan, nanso ɔko da no woguanee;
Àwọn ọkùnrin Efraimu, tí ó há mọ́ ọ tí wọ́n mú ọrun, wọ́n yípadà ní ọjọ́ ogun
10 Wɔanni Onyankopɔn apam no so, wɔampɛ sɛ wodi ne mmara no so.
Wọn kò pa májẹ̀mú Ọlọ́run mọ́ wọn sì kọ̀ láti máa gbé nínú òfin rẹ̀.
11 Wɔn werɛ fii nea wayɛ, anwonwade a wayɛ akyerɛ wɔn no.
Wọ́n gbàgbé ohun tí ó ti ṣe, àwọn ìyanu tí ó ti fihàn wọ́n.
12 Ɔyɛɛ anwonwade wɔ wɔn nenanom anim, wɔ Soan mantam a ɛwɔ Misraim asase so.
Ó ṣe ìyanu níwájú àwọn baba wọn ní ilẹ̀ Ejibiti, ní agbègbè Ṣoani.
13 Ɔkyɛɛ po mu na ɔde wɔn faa mu. Ɔmaa nsu no gyinaa sɛ afasu.
Ó pín òkun ní yà, ó sì mú wọn kọjá Ó mù kí omi náà dúró bi odi gíga.
14 Ɔde omununkum dii wɔn anim awia na ɔde ogyatɛn dii wɔn anim anadwo nyinaa.
Ní ọ̀sán, ó fi ìkùùkuu àwọsánmọ̀ ṣe amọ̀nà wọn àti ní gbogbo òru pẹ̀lú ìmọ́lẹ̀ iná.
15 Ɔpaee ɔbotan mu wɔ sare so, na ɔmaa wɔn nsu a ɛdɔɔso sɛ po;
Ó sán àpáta ní aginjù ó sì fún wọn ní omi mímu lọ́pọ̀lọ́pọ̀ bí ẹni pé láti inú ibú wá.
16 Ɔmaa asuti fii abotan mu na ɔmaa nsu sen sɛ nsubɔnten.
Ó mú ìṣàn omi jáde láti inú àpáta omi ṣíṣàn sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí odò.
17 Nanso wɔkɔɔ so yɛɛ bɔne tiaa no, wɔsɔre tiaa Ɔsorosoroni no wɔ sare no so.
Wọ́n sì tún tẹ̀síwájú láti dẹ́ṣẹ̀ sí i ní ìṣọ̀tẹ̀ sí Ọ̀gá-ògo ní aginjù.
18 Wɔhyɛɛ da kaa aduan a wɔpɛ, de sɔɔ Onyankopɔn hwɛe.
Wọ́n mọ̀ ọ́n mọ̀ dán Ọlọ́run wò nípa bíbéèrè fún oúnjẹ tí wọn bẹ̀bẹ̀ fún.
19 Wɔkasa tiaa Onyankopɔn se, “Onyankopɔn betumi ato pon wɔ sare so ana?
Wọ́n sọ̀rọ̀-òdì sí Ọlọ́run, wí pé “Ọlọ́run ha lè tẹ́ tábìlì ní aginjù?
20 Ɔde ade bɔɔ ɔbotan mu no, nsu tue fii mu, na nsuwa sen buu so. Na obetumi ama yɛn aduan nso? Obetumi ama ne nkurɔfo nam ana?”
Nígbà tí ó lu àpáta, omi tú jáde, odò sì sàn lọ́pọ̀lọ́pọ̀ ṣùgbọ́n òun ha lè fún wa lóúnjẹ ó ha le pèsè ẹran fún àwọn ènìyàn rẹ̀?”
21 Bere a Awurade tee nea wɔreka no, ne bo fuw yiye; ne gya beguu Yakob so, na nʼabufuwhyew sɔre tiaa Israel,
Nígbà tí Olúwa gbọ́ wọn, ó bínú gidigidi; iná rẹ̀ sọ̀kalẹ̀ sí Jakọbu, ìbínú rẹ̀ sì rú sí Israẹli,
22 efisɛ na wonni Onyankopɔn mu gyidi anaasɛ ne nkwagye mu ahotoso.
nítorí wọn kò gba Ọlọ́run gbọ́, wọn kò sì gbẹ́kẹ̀lé ìgbàlà rẹ̀.
23 Nanso ɔkasa kyerɛɛ ɔsoro wɔ ɔhyɛ so; na obuee ɔsorosoro apon.
Síbẹ̀ ó pàṣẹ fún ìràwọ̀ ojú ọ̀run, ó sì ṣí ìlẹ̀kùn ọ̀run sílẹ̀;
24 Ɔtɔɔ mana guu fam maa nnipa no sɛ wunni, ɔmaa wɔn ɔsoro aduan.
Ó rọ manna fún àwọn ènìyàn láti jẹ, ó fún wọn ní ọkà láti ọ̀run.
25 Nnipa dii abɔfo aduan; ɔmaa wɔn aduan a wobetumi adi nyinaa.
Àwọn ènìyàn jẹ oúnjẹ àwọn angẹli; Ó fún wọn ní oúnjẹ ní àjẹyó,
26 Ogyaa apuei mframa fi ɔsoro, na ofi ne tumi mu bɔɔ atɔe mframa.
Ó mú afẹ́fẹ́ ìlà-oòrùn láti ọ̀run wá ó mú afẹ́fẹ́ gúúsù wá nípa agbára rẹ̀.
27 Ɔtɔɔ nam sɛ mfutuma guu wɔn so, nnomaa a wotu bebree sɛ mpoano nwea.
Ó rọ òjò ẹran sílẹ̀ sórí wọn bí erùpẹ̀ ilẹ̀, àti ẹyẹ abìyẹ́ gẹ́gẹ́ bí iyanrìn etí òkun
28 Ɔma wɔbaa fam kɔɔ wɔn atenae, ne wɔn ntamadan ho nyinaa.
Ó jẹ́ kí wọn jáde ní ibùdó wọn, yíká àgọ́ wọn.
29 Wodidi maa aduan no boroo wɔn so efisɛ ɔmaa wɔn nea wɔhwehwɛ.
Wọ́n jẹ, wọ́n sì yó jọjọ nítorí ó ti fún wọn ní ohun tí wọn fìtara bẹ̀bẹ̀ fún.
30 Nanso ansa na wobefi aduan a wɔhwehwɛ no ho, bere a ɛhyehyɛ wɔn anom mpo no,
Ṣùgbọ́n wọn kò kúrò nínú oúnjẹ tí wọn fìtara bẹ̀bẹ̀ fún, nígbà tí oúnjẹ wọn sì wà ní ẹnu wọn,
31 Onyankopɔn abufuw sɔree wɔn so; okum ahoɔdenfo a wɔwɔ wɔn mu twitwaa Israel mmerante gui.
ìbínú Ọlọ́run dìde sí wọn ó pa àwọn tí ó jùlọ nínú wọn, ó sì lu àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin Israẹli bolẹ̀.
32 Eyinom nyinaa akyi, wɔkɔɔ so yɛɛ bɔne; nʼanwonwade akyi no, wɔannye anni.
Nínú gbogbo ìwọ̀nyí, wọ́n ń dẹ́ṣẹ̀ síwájú; nínú gbogbo iṣẹ́ ìyanu rẹ̀, wọ́n kò gbàgbọ́.
33 Enti otwaa wɔn nna so te sɛ ahuru yɛɛ wɔn mfe awiei huhuuhu.
O fi òpin sí ayé wọn nínú asán àti ọdún wọn nínú ìpayà.
34 Bere biara a Onyankopɔn bekum wɔn no, wɔhwehwɛ no na wɔpere wɔn ho san ba ne nkyɛn.
Nígbàkígbà tí Ọlọ́run bá pa wọ́n, wọn yóò wá a kiri; wọn yóò fi ìtara yípadà sí i.
35 Wɔkaee sɛ Onyankopɔn yɛ wɔn botan, sɛ Ɔsorosoro Nyankopɔn no yɛ wɔn Gyefo.
Wọ́n rántí pé Ọlọ́run ní àpáta wọn; wí pé Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo jùlọ ni olùràpadà àpáta wọn.
36 Nanso wɔde wɔn ano bɛdaadaa no, na wɔde wɔn tɛkrɛma atwa atoro akyerɛ no;
Ṣùgbọ́n nígbà náà ni wọ́n yóò pọ́n ọn pẹ̀lú ẹnu wọ́n wọ́n fi ahọ́n wọ́n purọ́ fún un;
37 wɔn koma nni no nokware, na wonni nʼapam no so.
ọkàn wọn kò sòtítọ́ sí i, wọn kò jẹ́ olódodo sí májẹ̀mú rẹ̀.
38 Nanso na ɔyɛ ahummɔbɔ; ɔde wɔn amumɔyɛ kyɛɛ wɔn a wansɛe wɔn. Mpɛn pii, ɔtwentwɛn nʼabufuw so na wanhwie nʼabufuwhyew nyinaa.
Síbẹ̀ ó ṣàánú; ó dárí àìṣedéédéé wọn jì òun kò sì pa wọ́n run nígbà púpọ̀ ló ń yí ìbínú rẹ̀ padà kò sì ru ìbínú rẹ̀ sókè
39 Ɔkaee sɛ wɔyɛ ɔhonam ara kwa, mframa bi a ɛbɔ twa mu na ɛnsan nʼakyi.
Ó rántí pé ẹlẹ́ran ara ni wọ́n, afẹ́fẹ́ tó ń kọjá tí kò lè padà.
40 Mpɛn ahe na wɔansɔre antia no wɔ sare no so hɔ, na mpɛn ahe na wɔamma ne werɛ anhow wɔ asase wosee no so!
Nígbà gbogbo ní wọn ń ṣọ̀tẹ̀ sí i ní aginjù wọn mú un bínú nínú ilẹ̀ tí ó di ahoro!
41 Wɔsɔɔ Onyankopɔn hwɛɛ bere biara; na woyii Israel Ɔkronkronni no abufuw.
Síwájú àti síwájú wọ́n dán Ọlọ́run wò; wọ́n mú ẹni mímọ́ Israẹli bínú.
42 Wɔn werɛ fii ne tumi no, da a ogyee wɔn fii wɔn nhyɛsofo nsam no,
Wọ́n kò rántí agbára rẹ̀: ní ọjọ́ tí ó rà wọ́n padà lọ́wọ́ àwọn aninilára,
43 da a ɔyɛɛ nsɛnkyerɛnne nwonwaso wɔ Misraim no ne nʼanwonwade wɔ Soan mantam mu no.
ní ọjọ́ tí ó fi iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ hàn ní Ejibiti, àti iṣẹ́ àmì rẹ̀ ni ẹkùn Ṣoani
44 Ɔmaa wɔn nsubɔnten dan mogya; wɔantumi annom wɔn nsuten mu nsu.
Ó sọ omi wọn di ẹ̀jẹ̀; wọn kò lè mu láti odò wọn.
45 Ɔmaa nwansenadɔm baa wɔn so bɛhaw wɔn na mpɔtorɔ nso bɛsɛee wɔn asase.
Ó rán ọ̀wọ́ eṣinṣin láti pa wọ́n run, àti ọ̀pọ̀lọ́ tí ó bá wọn jẹun.
46 Ɔmaa tɛwtɛw bedii wɔn mfuw so aduan na ɔde wɔn nnɔbae nso maa mmoadabi.
Ó fi ọkà wọn fún láńtata, àwọn ìre oko wọn fún eṣú.
47 Ɔde mparuwbo sɛee wɔn bobe na ɔde sukyerɛmma sɛee wɔn ankye nnua.
Ó fi yìnyín ba àjàrà wọn jẹ́ ó bá èso sikamore wọn jẹ́.
48 Ɔde sukyerɛmma kum wɔn anantwi ɔde anyinam kum wɔn nyɛmmoa.
Ó fi ohun ọ̀sìn wọn fún yìnyín, agbo ẹran wọn fún mọ̀nàmọ́ná.
49 Ohwiee nʼabufuwhyew guu wɔn so, abufuw, anibere ne ɔtan; abɔfo asɛefo kuw no.
Ó mú kíkorò ìbínú rẹ̀ wá sí wọn lára, ìrunú àti ìkáàánú, àti ìpọ́njú, nípa rírán angẹli apanirun sí wọn.
50 Ɔbɔɔ kwan maa nʼabufuw; na wamfa wɔn nkwa ankyɛ wɔn, mmom, ɔde wɔn maa ɔyaredɔm.
Ó pèsè ipa fún ìbínú rẹ̀, òun kò gbà wọ́n lọ́wọ́ ikú, ṣùgbọ́n ó fi ẹ̀mí wọ́n fún àjàkálẹ̀-ààrùn.
51 Okunkum Misraimfo mmakan nyinaa, Ham ntamadan mu nnipa mu abakan.
Ó kọlu àwọn àkọ́bí ọmọ ọkùnrin Ejibiti, olórí agbára wọn nínú àgọ́ Hamu.
52 Nanso oyii ne nkurɔfo fii mu sɛ nguankuw; odii wɔn anim sɛ nguan wɔ sare no so.
Ṣùgbọ́n ó mú àwọn ènìyàn rẹ̀ jáde bí ọ̀wọ́ ẹran; ó ṣọ́ wọn gẹ́gẹ́ bí àgùntàn nínú aginjù.
53 Odii wɔn anim dwoodwoo, enti wɔansuro; nanso wɔn atamfo de, po asorɔkye bu faa wɔn so.
Ó dáàbò bò wọ́n dáradára, nítorí náà ni ẹ̀rù kò ṣe bà wọ́n ṣùgbọ́n òkun padé mọ́ àwọn ọ̀tá wọn.
54 Sɛɛ na ɔyɛ de wɔn baa nʼasase kronkron no ahye so, bepɔw asase a ɔde ne nsa nifa gyee no.
Bákan náà ni ó mú wọn wá sí etí ilẹ̀ mímọ́ rẹ̀ òkè tí ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ ti gbà
55 Ɔpam amanaman a wɔwɔ wɔn anim no na ɔkyekyɛɛ wɔn nsase no mu maa wɔn sɛ wɔn agyapade; ɔbɔɔ Israel mmusuakuw no atenase wɔ wɔn afi mu.
Ó lé kèfèrí jáde níwájú wọn ó sì fi títa okùn pín ilẹ̀ náà fún wọn gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀ ìní; ó mú àwọn ẹ̀yà Israẹli jókòó ní ilẹ̀ wọn.
56 Nanso wɔsɔɔ Onyankopɔn hwɛe, na wɔsɔre tiaa Ɔsorosoroni no; na wɔanni ne mmara so.
Ṣùgbọ́n wọn dán Ọlọ́run wò wọn sì ṣọ̀tẹ̀ sí Ọ̀gá-ògo; wọn kò pa àṣẹ rẹ̀ mọ́.
57 Wɔyɛɛ sɛ wɔn agyanom, wɔanni nokware na wɔannya gyidi, ahotoso nni wɔn mu na wɔte sɛ agyan a asɛe.
Ṣùgbọ́n wọ́n yípadà, wọn jẹ́ aláìṣòdodo gẹ́gẹ́ bí àwọn baba wọn wọ́n sì pẹ̀yìndà sí apákan bí ọrun ẹ̀tàn.
58 Wɔde wɔn sorɔnsorɔmmea hyɛɛ no abufuw na wɔn ahoni maa ne ninkutwe mu yɛɛ den.
Wọ́n bí i nínú pẹ̀lú ibi gíga wọn; wọn rú owú rẹ̀ sókè nípa òrìṣà wọn.
59 Onyankopɔn tee wɔn nka no, ne bo fuwii; na ɔpoo Israel korakora.
Nígbà tí Ọlọ́run gbọ́ wọn, inú bí i gidigidi; ó kọ Israẹli pátápátá.
60 Ogyaw nʼatenae a ɛwɔ Silo no, ntamadan a wasi wɔ nnipa mu no.
Ó kọ àgọ́ Ṣilo sílẹ̀, àgọ́ tí ó ti gbé kalẹ̀ láàrín àwọn ènìyàn.
61 Ɔde Apam Adaka a ɛyɛ ne tumi no kɔɔ nnommum mu, nʼanuonyam kɔɔ atamfo nsam.
Ó rán àpótí ẹ̀rí, agbára rẹ̀ lọ sí ìgbèkùn, dídán ògo rẹ̀ lọ sí ọwọ́ àwọn ọ̀tá.
62 Ɔde ne nkurɔfo maa afoa; ne bo fuw nʼagyapade yiye.
Ó fi àwọn ènìyàn rẹ̀ lé idà lọ́wọ́, ó sì bínú sí àwọn ohun ìní rẹ̀.
63 Ogya hyew wɔn mmerante kum wɔn, na wɔn mmabaa annya ayeforohyia dwom anto;
Iná run àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin wọn, àwọn ọmọbìnrin wọn kò sì ní orin ìgbéyàwó:
64 Wɔn asɔfo wuwuu afoa ano, na wɔn akunafo antumi ansu.
àfi àlùfáà wọn fún idà, àwọn opó wọn kò sì le è sọkún.
65 Afei Awurade sɔree sɛnea ofi nna mu no, sɛnea ɔbarima a wabow nsa nyan fi nnahɔɔ mu no.
Olúwa sì jí gẹ́gẹ́ bí ẹni ojú oorun, gẹ́gẹ́ bí ọkùnrin ti i jí kúrò nínú ìraníyè ọtí.
66 Ɔbobɔɔ nʼatamfo ma woguan kɔɔ wɔn akyi; ɔhyɛɛ wɔn aniwu afebɔɔ.
Ó kọlu àwọn ọ̀tá rẹ̀ padà; ó fi wọn sínú ìtìjú ayérayé.
67 Afei ɔpoo Yosef ntamadan no, na wamfa Efraim abusuakuw no nso;
Nígbà náà ni ó kọ́ àgọ́ Josẹfu, kò sì yan ẹ̀yà Efraimu,
68 Na mmom, ɔfaa Yuda abusuakuw no, Bepɔw Sion a ɔdɔ no no.
ṣùgbọ́n ó yan ẹ̀yà Juda, òkè Sioni, èyí tí ó fẹ́ràn.
69 Osii ne kronkronbea te sɛ sorɔnsorɔmmea, te sɛ asase a etim hɔ daa.
Ó kọ́ ibi mímọ́ rẹ̀, ibi gíga, gẹ́gẹ́ bí ayé tí ó fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀ títí láé.
70 Oyii ne somfo Dawid, ɔfrɛɛ no fii nguannan mu;
Ó yan Dafidi ìránṣẹ́ rẹ̀ ó mú láti inú àwọn agbo ẹran;
71 fii nguan akyi na ɔde no bae se ɔmmɛyɛ oguanhwɛfo mma ne nkurɔfo Yakob, mma Israel a wɔyɛ nʼagyapade.
Ó mú un jáde nínú ìtọ́jú àgùntàn láti jẹ́ olùṣọ́-àgùntàn àwọn ènìyàn rẹ̀ Jakọbu àti Israẹli ogún un rẹ̀.
72 Na Dawid de koma pa hwɛɛ wɔn so na ɔde ne nimdeɛ dii wɔn anim.
Dafidi sì ṣọ́ wọn pẹ̀lú òtítọ́ inú ọkàn; pẹ̀lú ọwọ́ òye ni ó fi darí wọn.

< Nnwom 78 >