< Nnwom 16 >

1 Dawid mpaebɔ. Bɔ me ho ban, me Nyankopɔn, na wo mu na minya guankɔbea.
Miktamu ti Dafidi. Pa mí mọ́, Ọlọ́run, nítorí nínú rẹ ni ààbò mi wà.
2 Meka kyerɛɛ Awurade se, “MʼAwurade ne wo; minni ade pa biara ka wo ho.”
Mo sọ fún Olúwa, “Ìwọ ni Olúwa mi, lẹ́yìn rẹ èmi kò ní ìre kan.”
3 Ahotefo a wɔwɔ asase no so de, wɔne anuonyamfo a mʼanigye wɔ wɔn mu.
Sí àwọn ènìyàn tí ó wà ní ayé, àwọn ni ológo nínú èyí tí ayọ̀ mí wà.
4 Wɔn a wodi anyame afoforo akyi no, wɔn awerɛhow bɛdɔɔso. Merengu mogya nsa mma saa anyame no na meremfa mʼano mmɔ wɔn din.
Ìṣòro àwọn wọ̀n-ọn-nì yóò pọ̀ sí i, àní àwọn tí ń tọ ọlọ́run mìíràn lẹ́yìn. Ẹbọ ohun mímu ẹ̀jẹ̀ wọn ni èmi kì yóò ta sílẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò dá orúkọ wọn lẹ́nu mi.
5 Awurade, wode me kyɛfa ne me kuruwa ama me; woama me kyɛfa anya bammɔ.
Olúwa, ni ìpín ìní mi tí mo yàn àti ago mi, ó ti pa ohun tí í ṣe tèmi mọ́.
6 Mʼahye akɔdeda mmeae a eye ama me; ampa ara mewɔ agyapade a ho yɛ anigye.
Okùn ààlà ilẹ̀ ti bọ́ sí ọ̀dọ̀ mi ní ibi dídára; nítòótọ́ mo ti ní ogún rere.
7 Mɛkamfo Awurade a otu me fo; na anadwo mpo, me koma kyerɛkyerɛ me.
Èmi yóò yin Olúwa, ẹni tí ó gbà mí ní ìyànjú; ní òru, ọkàn mí ń bá mi sọ̀rọ̀.
8 Mihu Awurade wɔ mʼani so daa nyinaa. Esiane sɛ ɔwɔ me nsa nifa nti, merenhinhim da.
Mo ti gbé Olúwa síwájú mi ní ìgbà gbogbo. Nítorí tí ó wà ní ọwọ́ ọ̀tún mi, a kì yóò mì mí.
9 Ɛno nti, me kra ani gye, na mede me tɛkrɛma di ahurusi; me nipadua nso bɛhome asomdwoe mu,
Nítorí èyí, ọkàn mi yọ̀, ahọ́n mi pẹ̀lú ń fò fáyọ̀; ara mi pẹ̀lú yóò sinmi ní ààbò,
10 efisɛ, worennyaw me awufo mu. Na woremma wo Kronkronni no mporɔw. (Sheol h7585)
nítorí ìwọ kò ní fi ọ̀kan sílẹ̀ nínú isà òkú, tàbí kí ìwọ jẹ́ kí ẹni mímọ́ rẹ kí ó rí ìdíbàjẹ́. (Sheol h7585)
11 Woakyerɛ me nkwagye kwan, na wobɛma mʼani agye wɔ wʼanim, na anigye a ɛrensa da wɔ wo nifa so.
Ìwọ ti fi ipa ọ̀nà ìyè hàn mí; Ìwọ yóò kún mi pẹ̀lú ayọ̀ ní iwájú rẹ, pẹ̀lú ìdùnnú ayérayé ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ.

< Nnwom 16 >