< Nnwom 135 >
1 Monkamfo Awurade. Monkamfo Awurade din; monkamfo no, mo Awurade asomfo,
Ẹ yin Olúwa. Ẹ yin orúkọ Olúwa; ẹ yìn ín, ẹ̀yin ìránṣẹ́ Olúwa.
2 mo a mosom wɔ Awurade fi, wɔ adiwo a ɛwɔ yɛn Nyankopɔn fi.
Ẹ̀yin tí ń dúró ní ilé Olúwa, nínú àgbàlá ilé Ọlọ́run wa.
3 Monkamfo Awurade efisɛ oye; monto ayeyi nnwom mma ne din, na ɛno na ɛyɛ anisɔ.
Ẹ yin Olúwa: nítorí tí Olúwa ṣeun; ẹ kọrin ìyìn sí orúkọ rẹ̀; nítorí tí ó dùn.
4 Awurade ayi Yakob sɛ ɔnyɛ ne de, wayi Israel sɛ nʼade a ɛsom bo.
Nítorí tí Olúwa ti yan Jakọbu fún ara rẹ̀; àní Israẹli fún ìṣúra ààyò rẹ̀.
5 Minim sɛ Awurade so; Ɔso sen anyame nyinaa.
Nítorí tí èmi mọ̀ pé Olúwa tóbi, àti pé Olúwa jù gbogbo òrìṣà lọ.
6 Awurade yɛ nea ɔpɛ biara wɔ ɔsoro ne asase so, po ne mu bun nyinaa.
Olúwa ṣe ohunkóhun tí ó wù ú, ní ọ̀run àti ní ayé, ní Òkun àti ní ọ̀gbun gbogbo.
7 Ɔma omununkum ma ne ho so fi asase ano ba; ɔsoma anyinam ka osu ho na ɔma ahum tu fi ne koradan mu.
Ó mú ìkùùkuu gòkè láti òpin ilẹ̀ wá: ó dá mọ̀nàmọ́ná fún òjò: ó ń mú afẹ́fẹ́ ti inú ilẹ̀ ìṣúra rẹ̀ wá.
8 Okum Misraim mmakan, nnipa ne mmoa mmakan.
Ẹni tí ó kọlu àwọn àkọ́bí Ejibiti, àti ti ènìyàn àti ti ẹranko.
9 Ɔsomaa ne nsɛnkyerɛnne ne nʼanwonwade baa mo mfimfini, Misraim, de tiaa Farao ne nʼasomfo nyinaa.
Ẹni tí ó rán iṣẹ́ àmì àti iṣẹ́ ìyanu sí àárín rẹ̀, ìwọ Ejibiti, sí ara Farao àti sí ara àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ gbogbo.
10 Ɔsɛee amanaman pii, na okunkum ahemfo akɛse,
Ẹni tí ó kọlu àwọn orílẹ̀-èdè púpọ̀, tí ó sì pa àwọn alágbára ọba.
11 Amorifo hene, Sihon Basan hene, Og ne Kanaan ahemfo nyinaa,
Sihoni, ọba àwọn ará Amori, àti Ogu, ọba Baṣani, àti gbogbo ìjọba Kenaani:
12 na ɔde wɔn nsase maa sɛ agyapade ɔde maa ne nkurɔfo Israelfo.
Ó sì fi ilẹ̀ wọn fún ni ní ìní, ìní fún Israẹli, ènìyàn rẹ̀.
13 Awurade, wo din wɔ hɔ daa. Awurade wo din ahyeta awo ntoatoaso nyinaa mu.
Olúwa orúkọ rẹ dúró láéláé; ìrántí rẹ Olúwa, láti ìrandíran.
14 Awurade bedi ama ne nkurɔfo na obehu nʼasomfo mmɔbɔ.
Nítorí tí Olúwa yóò ṣe ìdájọ́ àwọn ènìyàn rẹ̀, yóò sì ṣe ìyọ́nú sí àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀.
15 Amanaman no ahoni yɛ dwetɛ ne sikakɔkɔɔ a wɔde onipa nsa na ayɛ.
Fàdákà òun wúrà ni èrè àwọn aláìkọlà, iṣẹ́ ọwọ́ ènìyàn ni.
16 Wɔwɔ ano, nanso wontumi nkasa, wɔwɔ ani, nanso wonhu ade;
Wọ́n ní ẹnu, ṣùgbọ́n wọn kò le sọ̀rọ̀; wọ́n ní ojú, ṣùgbọ́n wọn kò fi ríran.
17 wɔwɔ aso, nanso wɔnte asɛm, na ɔhome nso nni wɔn anom.
Wọ́n ní etí, ṣùgbọ́n wọn kò fi gbọ́rọ̀; bẹ́ẹ̀ ni kò si èémí kan ní ẹnu wọn.
18 Wɔn a wɔyɛɛ ahoni no bɛyɛ sɛ wɔn ara, saa ara na wɔn a wɔde wɔn ho to wɔn so no bɛyɛ.
Àwọn tí ń ṣe wọ́n dàbí wọn: gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni olúkúlùkù ẹni tí ó gbẹ́kẹ̀ rẹ̀ lé wọn.
19 Monkamfo Awurade, mo Israelfo nyinaa; monkamfo Awurade, Aaron fi;
Ẹ̀yin ara ilé Israẹli, ẹ fi ìbùkún fún Olúwa, ẹ̀yin ará ilé Aaroni, fi ìbùkún fún Olúwa.
20 monkamfo Awurade, Lewi fi; monkamfo Awurade, mo a musuro no.
Ẹ̀yin ará ilé Lefi, fi ìbùkún fún Olúwa; ẹ̀yin tí ó bẹ̀rù Olúwa, fi ìbùkún fún Olúwa.
21 Mumfi Sion nkamfo Awurade, monkamfo nea ɔte Yerusalem no. Monkamfo Awurade.
Olùbùkún ni Olúwa, láti Sioni wá, tí ń gbé Jerusalẹmu. Ẹ fi ìyìn fún Olúwa.