< Yoɛl 2 >
1 Hyɛn torobɛnto no wɔ Sion; hyɛn abɛn no wɔ me bepɔw kronkron no so. Ma wɔn a wɔte asase no so nyinaa ho mpopo, efisɛ Awurade da no reba, na abɛn koraa.
Ẹ fun ìpè ní Sioni, ẹ sì fún ìpè ìdágìrì ní òkè mímọ́ mi. Jẹ́ kí àwọn ará ilẹ̀ náà wárìrì, nítorí tí ọjọ́ Olúwa ń bọ̀ wá, nítorí ó kù sí dẹ̀dẹ̀.
2 Sum ne kusukuukuu da. Omununkum ne sum kabii da. Sɛnea adekyee hann trɛtrɛw wɔ mmepɔw so no, saa ara na asraafo a wɔdɔɔso na wɔyɛ den ba no te. Wonhuu wɔn sɛso bi da, na wɔrenhu ne sɛso nso da.
Ọjọ́ òkùnkùn àti ìrọ́kẹ̀kẹ̀, ọjọ́ ìkùùkuu àti òkùnkùn biribiri. Bí ọyẹ́ òwúrọ̀ ti í la bo orí àwọn òkè ńlá: àwọn ènìyàn ńlá àti alágbára; ya dé, ti kó ti ì sí irú rẹ̀ rí, bẹ́ẹ̀ ni irú rẹ̀ kì yóò sí mọ́ lẹ́yìn rẹ̀, títí dé ọdún ìran dé ìran.
3 Ogya rehyew wɔ wɔn anim, ogyatannaa dɛw wɔ wɔn akyi, asase a ɛda wɔn anim no te sɛ Eden turo, nea ɛda wɔn akyi no te sɛ nweatam, hwee nguan wɔn.
Iná ń jó níwájú wọ́n; ọwọ́ iná sì ń jó lẹ́yìn wọn. Ilẹ̀ náà dàbí ọgbà Edeni níwájú wọn, àti lẹ́yìn wọn bí ahoro ijù; nítòótọ́, kò sì sí ohun tí yóò bọ́ lọ́wọ́ wọn.
4 Wɔte sɛ apɔnkɔ. Wohuruhuruw te sɛ apɔnkɔsotefo asraafo.
Ìrí wọn dàbí ìrí àwọn ẹṣin; wọ́n ń sáré lọ bí àwọn ẹlẹ́ṣin ogun.
5 Wɔyɛ gyegyeegye te sɛ nteaseɛnam na wotu fa mmepɔw atifi, wɔte sɛ ogyatannaa a ɛhyew nwuraguanee wɔte sɛ asraafo akantinka a wɔrekɔ ɔsa.
Bí ariwo kẹ̀kẹ́ ogun ni wọn ń fo ní orí òkè bí ariwo ọ̀wọ́-iná tí ń jó koríko gbígbẹ, bí akọni ènìyàn tí a kójọ fún ogun.
6 Aman ani bɔ wɔn so a, ehu bɔ wɔn; na wɔn anim hoa.
Ní ojú wọn, àwọn ènìyàn yóò jẹ ìrora púpọ̀: gbogbo ojú ní yóò ṣú dudu.
7 Wɔko kɔ wɔn anim te sɛ akofo; wɔforo afasu te sɛ asraafo na wɔn nyinaa kɔ wɔn anim tee, na wɔmman benkum anaa nifa.
Wọn yóò sáré bi àwọn alágbára; wọn yóò gùn odi bí ọkùnrin ológun; olúkúlùkù wọn yóò sì rìn lọ ní ọ̀nà rẹ̀, wọn kì yóò sì yà kúrò ni ọ̀nà wọn.
8 Wontwintwan wɔn ho wɔn ho anan mu; obiara nantew kɔ nʼanim tee. Wobu fa abandennen so, na wɔpem kɔ wɔn anim ara.
Bẹ́ẹ̀ ni ẹnìkan kì yóò kọlu ẹnìkejì rẹ̀; olúkúlùkù wọn yóò rìn ní ọ̀nà rẹ̀, nígbà tí wọn bá sì ṣubú lù idà wọn kì yóò gbọgbẹ́.
9 Wɔtow hyɛ kuropɔn no so wotu mmirika fa afasu no so wɔforo kɔ afi mu, wɔfa mfɛnsere mu te sɛ akorɔmfo.
Wọn yóò sáré síwá sẹ́yìn ní ìlú; wọn yóò súré lórí odi, wọn yóò gùn orí ilé; wọn yóò gbà ojú fèrèsé wọ̀ inú ilé bí olè.
10 Asase wosow wɔ wɔn anim, na ɔsoro hinhim. Owia ne ɔsram duru sum, na nsoromma nhyerɛn bio.
Ayé yóò mì níwájú wọn; àwọn ọ̀run yóò wárìrì; oòrùn àti òṣùpá yóò ṣókùnkùn, àwọn ìràwọ̀ yóò sì fà ìmọ́lẹ̀ wọn sẹ́yìn.
11 Awurade bobɔ mu de di nʼasraafo no anim. Nʼakofo no dɔɔso bebree, ahoɔdenfo ne wɔn a wodi nʼahyɛde so. Awurade da no yɛ kɛse na ɛyɛ hu; hena na obetumi agyina ano?
Olúwa yóò sì bú ramúramù jáde níwájú ogun rẹ̀: nítorí ibùdó rẹ̀ tóbi gidigidi; nítorí alágbára ní òun, tí n mú ọ̀rọ̀ rẹ̀ ṣẹ; nítorí ọjọ́ Olúwa tóbi ó sì ní ẹ̀rù gidigidi; ara ta ni ó lè gbà á?
12 “Na afei,” sɛnea Awurade se ni, “San fa wo koma nyinaa bra me nkyɛn, wɔ akɔnkyen, osu ne awerɛhow mu.”
“Ǹjẹ́ nítorí náà nísinsin yìí,” ni Olúwa wí, “Ẹ fi gbogbo ọkàn yín yípadà sí mi, àti pẹ̀lú àwẹ̀, àti pẹ̀lú ẹkún, àti pẹ̀lú ọ̀fọ̀.”
13 Sunsuan wo koma na ɛnyɛ wo ntade mu. San bra Awurade wo Nyankopɔn nkyɛn, efisɛ, ɔyɛ ɔdomfo, ne yam ye. Ne bo kyɛ fuw na ne dɔ boro so, na ɛnyɛ no anigye sɛ ɔtwe yɛn aso.
Ẹ sì fa ọkàn yín ya, kì í sì í ṣe aṣọ yín, ẹ sì yípadà sí Olúwa Ọlọ́run yín, nítorí tí o pọ̀ ní oore-ọ̀fẹ́, ó sì kún fun àánú, ó lọ́ra láti bínú, ó sì ṣeun púpọ̀, ó sì ronúpìwàdà láti ṣe búburú.
14 Hena na onim? Ebia ɔbɛsesa nʼadwene na wahu mmɔbɔ na wagyaw nhyira, a ɛyɛ aduan ne ahwiesa afɔrebɔde a mode ma Awurade mo Nyankopɔn no.
Ta ni ó mọ̀ bí òun yóò yípadà, kí o sì ronúpìwàdà, kí ó sì fi ìbùkún sílẹ̀ lẹ́yìn rẹ̀— àní ọrẹ-jíjẹ àti ọrẹ mímu fún Olúwa Ọlọ́run yín?
15 Hyɛn torobɛnto wɔ Sion! Mommɔ akɔnkyen kronkron ho dawuru, momfrɛ nhyiamu kronkron.
Ẹ fún ìpè ní Sioni, ẹ ya àwẹ̀ kan sí mímọ́, ẹ pe àjọ tí ó ni ìrònú.
16 Mommoaboa nnipa no ano montew nhyiamu no ho na ɛnyɛ kronkron; mommoaboa mpanyimfo, mmofra ne mmea a wɔrema nufu ano. Ma ayeforo ne ayeforokunu mfi wɔn pia mu mmra.
Ẹ kó àwọn ènìyàn jọ, ẹ ya ìjọ sí mímọ́; ẹ pe àwọn àgbàgbà jọ, ẹ kó àwọn ọmọdé jọ, àti àwọn tí ń mú ọmú, jẹ kí ọkọ ìyàwó kúrò nínú ìyẹ̀wù rẹ̀. Kí ìyàwó sì kúrò nínú iyàrá rẹ̀.
17 Asɔfo a wɔsom wɔ Awurade anim no, nsu wɔ afɔremuka no ne abrannaa no ntam; na wɔnka se, “Awurade fa wo nkurɔfo ho kyɛ wɔn. Mma wʼagyapade nyɛ ahohorade anaa fɛwdi wɔ aman no mu. Adɛn nti na ɛsɛ sɛ wubisa wɔ nnipa no mu se, ‘Wɔn Nyame no wɔ he?’”
Jẹ́ kí àwọn àlùfáà, àwọn ìránṣẹ́ Olúwa, sọkún láàrín ìloro àti pẹpẹ. Sí jẹ́ kí wọn wí pé, “Dá àwọn ènìyàn rẹ sí, Olúwa. Má sì ṣe fi ìní rẹ fun ẹ̀gàn, tí yóò sì di òwe ní àárín àwọn kèfèrí. Èéṣe tí wọn yóò fi wí láàrín àwọn ènìyàn pé, ‘Ọlọ́run wọn ha da?’”
18 Na Awurade bɛtwe ninkunu wɔ nʼasase ho na ne nkurɔfo ayɛ no mmɔbɔ.
Nígbà náà ní Olúwa yóò jowú fún ilẹ̀ rẹ̀, yóò sì káàánú fún ènìyàn rẹ̀.
19 Awurade bebua se, “Merebrɛ mo aduan, nsa foforo ne ngo, a ɛbɛso mo ama moamee pintinn. Merenyɛ mo ahohorade mma aman no bio.
Nítòótọ́, Olúwa yóò dá wọn lóhùn, yóò sì wí fun àwọn ènìyàn rẹ̀ pé: “Wò ó èmi yóò rán ọkà, àti ọtí wáìnì tuntun, àti òróró sí i yín, a ó sì fi wọn tẹ́ yín lọ́rùn; Èmi kì yóò sì fi yín ṣe ẹ̀gàn mọ́ láàrín àwọn aláìkọlà.
20 “Mɛpam atifi fam asraafo no afi wo nkyɛn akɔ akyirikyiri, mepia wɔn akɔ asase a awo na ɛyɛ kesee so. Nifa dɔm no bɛmem wɔ Nkyene Po no mu, na kyidɔm no bɛmem wɔ Ntam Po no mu. Na afunu no bɛbɔn na ne nka betu.” Nokware wayɛ nneɛma akɛse!
“Ṣùgbọ́n èmi yóò lé ogun àríwá jìnnà réré kúrò lọ́dọ̀ yín, èmi yóò sì lé e lọ sí ilẹ̀ tí ó ṣá, tí ó sì di ahoro, pẹ̀lú ojú rẹ̀ sí Òkun ìlà-oòrùn, àti ẹ̀yìn rẹ̀ sí ìwọ̀-oòrùn Òkun. Òórùn rẹ̀ yóò sì gòkè, òórùn búburú rẹ̀ yóò sì gòkè.” Nítòótọ́ ó ti ṣe ohun ńlá.
21 Munnsuro, me nkurɔfo! Momma mo ani nnye, na monsɛpɛw mo ho. Nokware Awurade ayɛ nneɛma akɛse.
Má bẹ̀rù, ìwọ ilẹ̀; jẹ́ kí inú rẹ̀ dùn kí o sì yọ̀, nítorí Olúwa ti ṣe ohun ńlá.
22 Munnsuro, mo wuram mmoa! Efisɛ sare so adidibea reyɛ frɔmfrɔm. Nnua no resow wɔn aba; borɔdɔma ne bobe nso resow wɔn aba.
Ẹ má bẹ̀rù, ẹranko igbó, nítorí pápá oko aginjù ń rú. Nítorí igi ń so èso rẹ̀, igi ọ̀pọ̀tọ́ àti àjàrà ń so èso ọ̀rọ̀ wọn.
23 Momma mo ani nnye, mo Sion mma, Munni ahurusi wɔ Awurade mo Nyankopɔn mu, efisɛ watɔ asusowsu ama mo, ne nokwaredi nti. Watɔ osu bebree ama mo wɔ ne bere mu te sɛ kan no.
Ẹ jẹ́ kí inú yín dùn, ẹ̀yin ọmọ Sioni, ẹ sì yọ̀ nínú Olúwa Ọlọ́run yín, nítorí ó ti fi àkọ́rọ̀ òjò fún yín bí ó ti tọ́, Òun ti mú kí òjò rọ̀ sílẹ̀ fún un yín, àkọ́rọ̀ àti àrọ̀kúrò òjò ní oṣù kìn-ín-ní.
24 Aduan bɛyɛ awiporowbea hɔ ma, nsa foforo ne ngo bebu so wɔ kyi amoa mu.
Àwọn ilẹ̀ ìpakà yóò kún fún ọkà; àti ọpọ́n wọn nì yóò sàn jáde pẹ̀lú ọtí wáìnì tuntun àti òróró.
25 “Mɛhyɛ mo anan mu, nea mohweree mfe dodow a mmoadabi bɛsɛee mo nneɛma, mmoadabi akɛse ne nkumaa, ne wɔn a aka no nyinaa, me dɔm a mesomaa wɔn baa mo so no.
“Èmi yóò sì mú ọdún wọ̀nyí ti eṣú jẹ run padà fún un yín. Èyí tí eṣú agénijẹ àti eṣú jewéjewé ọwọ́ eṣú agénijẹ àti kòkòrò ajẹnirun mìíràn ti fi jẹ àwọn ogun ńlá mi tí mo rán sí àárín yín.
26 Mubedidi amee, na mubeyi Awurade mo Nyankopɔn din ayɛ. Ɔno na wayɛ anwonwade ama mo; me nkurɔfo ani renwu bio.
Ẹ̀yin yóò ni ọ̀pọ̀lọpọ̀ láti jẹ, títí ẹ̀yin yóò fi yó ẹ ó sì yín orúkọ Olúwa Ọlọ́run yín, ẹni tí ó fi ìyanu bá yín lò; ojú kì yóò sì ti àwọn ènìyàn mi láéláé.
27 Afei, mubehu sɛ, mewɔ Israel, mubehu sɛ mene Awurade, mo Nyankopɔn, na obiara nni hɔ sɛ me; Me nkurɔfo ani renwu bio da.”
Ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, èmi wà láàrín Israẹli, àti pé; Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín, àti pé kò sí ẹlòmíràn, ojú kì yóò sì ti àwọn ènìyàn mí láéláé.
28 “Na akyiri no, mehwie me honhom agu nnipa nyinaa so, mo mmabarima ne mo mmabea bɛhyɛ nkɔm, mo nkwakoraa bɛsoso adae, mo mmerante benya anisoadehu.
“Yóò sì ṣe níkẹyìn ọjọ́, èmi yóò tú nínú Ẹ̀mí mí sí ara ènìyàn gbogbo; àwọn ọmọ yín ọkùnrin àti àwọn ọmọ yín obìnrin yóò máa sọtẹ́lẹ̀, àwọn arúgbó yín yóò máa lá àlá, àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin yín yóò máa ríran.
29 Saa mmere no mu no, mehwie me Honhom agu mʼasomfo so, mmarima ne mmea.
Àti pẹ̀lú sí ara àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ ọkùnrin, àti sí ara àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ obìnrin, ní èmi yóò tú ẹ̀mí mí jáde ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì.
30 Mɛyɛ anwonwade wɔ ɔsoro ne asase so, mede mogya, ogya ne wusiw kumɔnn.
Èmi yóò sì fi iṣẹ́ ìyanu hàn ní ọrun àti ní ayé, ẹ̀jẹ̀ àti iná, àti ọ̀wọ́n èéfín.
31 Ansa na Awurade da kɛse no bɛba no, owia beduru sum na ɔsram nso ayɛ sɛ mogya.
A á sọ oòrùn di òkùnkùn, àti òṣùpá di ẹ̀jẹ̀, kí ọjọ́ ńlá àti ọjọ́ ẹ̀rù Olúwa tó dé.
32 Na obiara a ɔbɔ Awurade din no, wobegye no nkwa. Efisɛ nkwagye bɛba ama wɔn a wɔanya wɔn ti adidi mu a Awurade afrɛ wɔn wɔ Sion bepɔw so ne Yerusalem nyinaa,” sɛnea Awurade aka no.
Yóò sí ṣe, ẹnikẹ́ni tí ó ba ké pè orúkọ Olúwa ní a ó gbàlà, nítorí ní òkè Sioni àti ní Jerusalẹmu ní ìgbàlà yóò gbé wà, bí Olúwa ti wí, àti nínú àwọn ìyókù tí Olúwa yóò pè.