< Hiob 5 >

1 “Wobɛfrɛ a frɛ, na hena na obegye wo so? Akronkronfo no mu hena nkyɛn na wobɛkɔ?
“Ó jẹ́ pé nísinsin yìí bí ẹnìkan bá wà tí yóò dá wa lóhùn? Tàbí ta ni nínú àwọn ènìyàn mímọ́ tí ìwọ ó yípadà sí?
2 Ahisɛm kum ɔkwasea, na anibere kum atetekwaa.
Nítorí pé ìbínú pa aláìmòye, ìrunú a sì pa òpè ènìyàn.
3 Mʼankasa mahu ɔkwasea a ɔrefefɛw, nanso mpofirim, wɔdomee ne fi.
Èmi ti rí aláìmòye ti ó ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n lulẹ̀, ṣùgbọ́n lójúkan náà mo fi ibùjókòó rẹ̀ bú.
4 Ne mma ne bammɔ ntam kwan ware, wɔdwerɛw wɔn wɔ asennii a wonni ɔkamafo.
Àwọn ọmọ rẹ̀ kò jìnnà sí ewu, a sì tẹ̀ wọ́n mọ́lẹ̀ lójú ibodè, bẹ́ẹ̀ ni kò sí aláàbò kan.
5 Nea ɔkɔm de no no di ne nnɔbae, na ɔfa fi nsɔe mu mpo, na nea osukɔm de no no pere di nʼahode akyi.
Ìkórè oko ẹni tí àwọn tí ebi ń pa sọ̀ di jíjẹ, tí wọ́n sì wọ inú ẹ̀gún lọ kó, àwọn ìgárá ọlọ́ṣà sì gbé ohun ìní wọn mì.
6 Ahokyere mpue mmfi dɔte mu na ɔhaw nso mfifi mmfi fam.
Bí ìpọ́njú kò bá ti inú erùpẹ̀ jáde wá ni, tí ìyọnu kò ti ilẹ̀ jáde wá.
7 Nanso wɔwo nnipa to ɔhaw mu mpɛn dodow a gyaframa turuw kɔ soro no.
Ṣùgbọ́n a bí ènìyàn sínú wàhálà, gẹ́gẹ́ bí ìpẹ́pẹ́ iná ti máa ń ta sókè.
8 “Nanso sɛ ɛyɛ me a, anka meguan atoa Onyankopɔn; na mede mʼasɛm ato nʼanim.
“Ṣùgbọ́n bí ó ṣe tèmi, ọ̀dọ̀ Ọlọ́run ní èmi yóò ti ṣìpẹ̀, ní ọwọ́ Ọlọ́run ní èmi yóò máa fi ọ̀rọ̀ mi lé.
9 Ɔyɛ anwonwade a wontumi nhwehwɛ mu, ne nsɛnkyerɛnne a wontumi nkan ne dodow.
Ẹni tí ó ṣe ohun tí ó tóbi tí a kò lè ṣe àwárí, ohun ìyanu láìní iye.
10 Ɔtɔ osu gu asase so; na ɔde kɔ wuram.
Tí ń rọ̀jò sí orí ilẹ̀ ayé tí ó sì ń rán omi sínú ilẹ̀kílẹ̀.
11 Ɔde ahobrɛasefo si nea ɛkorɔn, na ɔma wɔn a wodi awerɛhow nya asomdwoe.
Láti gbé àwọn orílẹ̀-èdè lékè kí á lè gbé àwọn ẹni ìbànújẹ́ ga sí ibi aláìléwu.
12 Ɔsɛe aniferefo nhyehyɛe, ma wɔn nsa si fam.
Ó yí ìmọ̀ àwọn alárékérekè po, bẹ́ẹ̀ ní ọwọ́ wọn kò lè mú ìdáwọ́lé wọn ṣẹ.
13 Ɔkyere anyansafo wɔ wɔn anifere mu, na ɔbɔ anitewfo nhyehyɛe gu.
Ó mú àwọn ọlọ́gbọ́n nínú àrékérekè ara wọn, àti ìmọ̀ àwọn òǹrorò ní ó tì ṣubú ní ògèdèǹgbé.
14 Sum duru wɔn awia ketee; na wɔkeka wɔ owigyinae mu te sɛ anadwo.
Wọ́n sáré wọ inú òkùnkùn ní ọ̀sán; wọ́n sì fọwọ́ tálẹ̀ ní ọ̀sán gangan bí ẹni pé ní òru ni.
15 Ogye ahiafo fi afoa a ɛhyɛ wɔn anom; ogye wɔn fi ahoɔdenfo nkyehama mu.
Ṣùgbọ́n ó gba tálákà là ní ọwọ́ idà, lọ́wọ́ ẹnu wọn àti lọ́wọ́ àwọn alágbára.
16 Enti ahiafo wɔ anidaso, na ntɛnkyew ka nʼano to mu.
Bẹ́ẹ̀ ni ìrètí wà fún tálákà, àìṣòótọ́ sì pa ẹnu rẹ̀ mọ́.
17 “Nhyira ne onipa a Onyankopɔn teɛ no, enti mmu Otumfo nteɛteɛ no animtiaa.
“Kíyèsi i, ìbùkún ni fún ẹni tí Ọlọ́run bá wí, nítorí náà, má ṣe gan ìbáwí Olódùmarè.
18 Efisɛ ɔno na opira na ɔno ara akyekyere; opira nanso ne nsa sa yare.
Nítorí pé òun a máa pa ni lára, síbẹ̀ òun a sì tún dì í ní ìdì ìtura, ó sá lọ́gbẹ́, a sì fi ọwọ́ rẹ̀ di ojú ọgbẹ̀ náà jiná.
19 Obegye wo afi ɔhaw ahorow asia mu; ason so no, bɔne biara renka wo.
Yóò gbà ọ́ nínú ìpọ́njú mẹ́fà, àní nínú méje, ibi kan kì yóò bá ọ.
20 Ɔkɔm ba a, obegye wo afi owu mu, na ɔko mu nso, obegye wo afi afoa ano.
Nínú ìyanu yóò gbà ọ́ lọ́wọ́ ikú àti nínú ogun, yóò gbà ọ́ lọ́wọ́ idà.
21 Wɔbɛbɔ wo ho ban afi ntwirii ho na sɛ ɔsɛe ba a ɛnsɛ sɛ wusuro.
A ó pa ọ́ mọ́ kúrò lọ́wọ́ iná ahọ́n, bẹ́ẹ̀ ní ìwọ kì yóò bẹ̀rù ìparun tí ó bá dé.
22 Wobɛserew ɔsɛe ne ɔkɔm; na ɛnsɛ sɛ wusuro asase so mmoa.
Ìwọ yóò rẹ́rìn-ín nínú ìparun àti ìyàn, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kì yóò bẹ̀rù ẹranko ilẹ̀ ayé.
23 Wo ne afuw so abo bɛyɛ apam, na emu nkekaboa nso ne wo bɛtena asomdwoe mu.
Nítorí pé ìwọ ti bá òkúta igbó mulẹ̀, àwọn ẹranko igbó yóò wà pẹ̀lú rẹ ní àlàáfíà.
24 Wubehu sɛ wo ntamadan wɔ bammɔ; na sɛ wosese wʼahode a wubehu sɛ hwee nyeraa ɛ.
Ìwọ ó sì mọ̀ pé àlàáfíà ni ibùjókòó rẹ wà, ìwọ yóò sì máa ṣe ìbẹ̀wò ibùjókòó rẹ, ìwọ kì yóò ṣìnà.
25 Wubehu sɛ wo mma bɛyɛ bebree; na wʼase bɛfɛe sɛ asase so sare.
Ìwọ ó sì mọ̀ pẹ̀lú pé irú-ọmọ rẹ ó sì pọ̀ àti àwọn ọmọ ọmọ rẹ yóò rí bí koríko igbó.
26 Wode ahoɔden bɛkɔ ɔda mu, te sɛ afiafi a wɔaboa ano wɔ otwabere mu.
Ìwọ yóò wọ isà òkú rẹ ní ògbólógbòó ọjọ́, bí síírí ọkà tí ó gbó tí á sì kó ní ìgbà ìkórè rẹ̀.
27 “Yɛahwehwɛ eyi mu, na ɛyɛ nokware ɛno nti tie na fa toto wʼabrabɔ ho.”
“Kíyèsi i, àwa ti wádìí rẹ̀ bẹ́ẹ̀ ní ó rí! Gbà á gbọ́, kí o sì mọ̀ pé fún ìre ara rẹ ni.”

< Hiob 5 >