< Yeremia 5 >
1 “Munni akɔneaba wɔ Yerusalem mmɔnten so, monhwɛ mo ho nhyia nhwɛ, monhwehwɛ guabɔbea nyinaa. Sɛ muhu onipa baako mpo a ɔyɛ pɛ na odi nokware a, mede kuropɔn yi ho bɛkyɛ no.
“Lọ sókè àti sódò àwọn òpópó Jerusalẹmu, wò yíká, kí o sì mọ̀, kí o sì wá kiri. Bí o bá le è rí ẹnìkan, tí ó jẹ́ olóòtítọ́ àti olódodo, n ó dáríjì ìlú yìí.
2 Ɛwɔ mu wɔka se, ‘Sɛ Awurade te ase yi,’ nanso wɔda so ka ntam hunu.”
Bí wọ́n tilẹ̀ wí pé, ‘Bí Olúwa ti ń bẹ,’ síbẹ̀ wọ́n búra èké.”
3 Awurade, wʼani mpɛ nokware ahu ana? Wobɔɔ wɔn hwee fam, nanso wɔante yaw biara; wodwerɛw wɔn, nanso wɔpoo nteɛso. Wɔyɛɛ wɔn anim dennen sen ɔbo na wɔansakra wɔn adwene.
Olúwa, ojú rẹ kò ha wà lára òtítọ́? Ìwọ lù wọ́n, kò dùn wọ́n; ìwọ bá wọn wí, wọ́n kọ̀ láti yípadà. Wọ́n mú ojú wọn le ju òkúta lọ, wọ́n sì kọ̀ láti yípadà.
4 Misusuw se, “Eyinom nko ara ne ahiafo no; wɔyɛ nkwaseafo nso, efisɛ wonnim Awurade akwan, nea wɔn Nyankopɔn hwehwɛ.
Èmi sì rò pé, “Tálákà ni àwọn yìí; wọn jẹ́ aṣiwèrè, nítorí pé wọn kò mọ ọ̀nà Olúwa, àti ohun tí Ọlọ́run wọn ń fẹ́.
5 Enti mɛkɔ ntuanofo no nkyɛn akɔkasa akyerɛ wɔn; ampa ara wonim Awurade akwan nea wɔn Onyankopɔn hwehwɛ.” Nanso wɔn nso de adwene koro abubu konnua no atetew nkyehama no mu.
Nítorí náà, èmi yóò tọ àwọn adarí lọ, n ó sì bá wọn sọ̀rọ̀; ó dájú wí pé wọ́n mọ ọ̀nà Olúwa àti ohun tí Ọlọ́run wọn ń fẹ́.” Ṣùgbọ́n pẹ̀lú ìfìmọ̀ṣọ̀kan, wọ́n ti ba àjàgà jẹ́, wọ́n sì ti já ìdè.
6 Ɛno nti gyata bi a ofi kwae mu bɛtow ahyɛ wɔn so, pataku bi a ofi nweatam so bɛtetew wɔn mu. Ɔsebɔ bi bɛtɛw abɛn wɔn nkurow, na obiara a obeyi ne ti no ɔbɛtetew ne mu nketenkete, efisɛ wɔn atuatew no ano yɛ den na wɔn akyirisan aboro so.
Nítorí náà, kìnnìún láti inú igbó yóò kọlù wọ́n, ìkookò aginjù yóò sì pa wọ́n run, ẹkùn yóò máa ṣe ibùba sí ẹ̀bá ìlú yín ẹnikẹ́ni tí ó bá jáde ni yóò fàya pẹ́rẹpẹ̀rẹ, nítorí àìgbọ́ràn yín pọ, ìpadàsẹ́yìn wọn sì pọ̀.
7 “Adɛn nti na ɛsɛ sɛ mede mo ho kyɛ mo? Mo mma apo me, wɔde anyame a wɔnyɛ anyame aka ntam. Memaa wɔn nea wohia nyinaa, nanso wɔbɔɔ aguaman na wɔbɔɔ yuu kɔɔ nguamanfo afi mu.
“Kí ni ṣe tí èmi ó ṣe dáríjì ọ́? Àwọn ọmọ rẹ ti kọ̀ mí sílẹ̀ àti pé wọ́n ti fi ọlọ́run tí kì í ṣe Ọlọ́run búra. Mo pèsè fún gbogbo àìní wọn, síbẹ̀ wọ́n tún ń ṣe panṣágà wọ́n sì kórajọ sí ilé àwọn alágbèrè.
8 Mpɔnkɔnini aniberefo a wɔhwɛ wɔn yiye, wɔn mu biara su di ne yɔnko yere akyi.
Wọ́n jẹ́ akọ ẹṣin tí a bọ́ yó, tí ó lágbára, wọ́n sì ń sọkún sí aya arákùnrin wọn.
9 Ɛnsɛ sɛ metwe wɔn aso wɔ eyi ho?” Sɛɛ na Awurade se. “Ɛnsɛ sɛ, mʼankasa metɔ ɔman a ɛte sɛɛ so were ana?
Èmi kì yóò ha ṣe ìbẹ̀wò nítorí nǹkan wọ̀nyí?” ni Olúwa wí. “Èmi kì yóò wá gba ẹ̀san fúnra mi lára irú orílẹ̀-èdè bí èyí bí?
10 “Momfa ne bobe nturo no mu na monsɛe no, nanso monnsɛe no koraa. Mompempan ne mman no, efisɛ saa nnipa yi nyɛ Awurade dea.
“Lọ sí ọgbà àjàrà rẹ̀, kí ẹ sì pa wọ́n run, ẹ má ṣe pa wọ́n run pátápátá. Ya ẹ̀ka rẹ̀ kúrò, nítorí àwọn ènìyàn wọ̀nyí kì í ṣe ti Olúwa.
11 Israelfi ne Yudafi anni me nokware koraa,” Awurade na ose.
Ilé Israẹli àti ilé Juda ti jẹ́ aláìṣòdodo sí mi,” ni Olúwa wí.
12 Wɔadi atoro afa Awurade ho, wɔkae se, “Ɔrenyɛ hwee! Ɔhaw biara remma yɛn so; yɛrenhu afoa anaa ɔkɔm da.
Wọ́n ti pa irọ́ mọ́ Olúwa; wọ́n wí pé, “Òun kì yóò ṣe ohun kan! Ibi kan kì yóò sì tọ̀ wá wá; àwa kì yóò sì rí idà tàbí ìyàn.
13 Adiyifo no yɛ mframa bi kɛkɛ na asɛm no nte wɔn mu; enti momma nea wɔka no mmra wɔn so.”
Àwọn wòlíì wá dàbí afẹ́fẹ́, ọ̀rọ̀ kò sí nínú wọn. Nítorí náà, jẹ́ kí ohun tí wọ́n bá sọ ṣẹlẹ̀ sí wọn.”
14 Enti eyi ne nea Asafo Awurade, Nyankopɔn se: “Esiane sɛ, nnipa no aka saa nsɛm yi nti, mɛyɛ me nsɛm a ɛwɔ wʼanom no ogya na saa nnipa yi ayɛ nnyina a ogya no bɛhyew.
Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Alágbára wí: “Nítorí tí àwọn ènìyàn ti sọ àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí; Èmi yóò sọ ọ̀rọ̀ mi lẹ́nu wọn di iná, àti àwọn ènìyàn wọ̀nyí di igi tí yóò jórun.
15 Israelfi,” Awurade na ose, “Mede ɔman bi a ɛwɔ akyirikyiri rebetia wo, tete man a ɛyɛ ɔmantease, nnipa a munnim wɔn kasa, na monnte wɔn kasa ase.
Háà, ẹ̀yin ilé Israẹli,” ni Olúwa wí, “Èmi yóò mú kí orílẹ̀-èdè láti ọ̀nà jíjìn dìde sí i yín Orílẹ̀-èdè àtijọ́ àti alágbára nì àwọn ènìyàn tí ìwọ kò mọ èdè rẹ̀, tí ọ̀rọ̀ rẹ̀ kò sì yé ọ.
16 Wɔn agyan mmɔtɔwa te sɛ ɔda a ano da hɔ; wɔn nyinaa yɛ dɔmmarima.
Apó-ọfà rẹ sì dàbí isà òkú tí a ṣí gbogbo wọn sì jẹ́ akọni ènìyàn.
17 Wɔbɛsɛe mo nnɔbae ne mo nnuan, asɛe mo mmabarima ne mo mmabea; wɔbɛsɛe mo nguankuw ne mo anantwikuw, asɛe mo bobe ne mo mmrɔdɔma. Wɔde afoa bɛsɛe nkuropɔn a ɛwɔ bammɔ a mode mo werɛ ahyɛ mu no.
Wọn yóò jẹ ìkórè rẹ àti oúnjẹ rẹ, àwọn ọmọ rẹ ọkùnrin àti obìnrin, wọn yóò sì jẹ agbo àti ẹran rẹ, wọn yóò jẹ àjàrà àti igi ọ̀pọ̀tọ́ rẹ. Pẹ̀lú idà ni wọn ó run ìlú tí ìwọ gbẹ́kẹ̀lé.
18 “Afei saa nna no mu mpo,” sɛɛ na Awurade se, “Merensɛe mo korakora.
“Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì,” ni Olúwa wí, “Èmi kì yóò pa yín run pátápátá.
19 Na sɛ nnipa no bisa se, ‘Adɛn nti na Awurade, yɛn Nyankopɔn, ayɛ yɛn sɛɛ’ a, mobɛka akyerɛ wɔn se, ‘Sɛnea moagyaw me hɔ akɔsom ananafo anyame wɔ mo ankasa mo asase so no, saa ara na mprempren mobɛsom ananafo wɔ asase a ɛnyɛ mo dea no so.’
Àti pé, nígbà tí àwọn ènìyàn bá sì béèrè wí pé, ‘Kí ni ìdí rẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run wa fi ṣe gbogbo èyí sí wa?’ Ìwọ yóò sì sọ fún wọn wí pé, ‘Ẹ̀yin ti kọ̀ mí sílẹ̀, ẹ sì ń sin ọlọ́run àjèjì ní ilẹ̀ yín. Nísinsin yìí, ẹ̀yin yóò máa sin àjèjì ní ilẹ̀ tí kì í ṣe tiyín.’
20 “Monka eyi nkyerɛ Yakobfi na mo mpae mu nka wɔ Yuda se:
“Kéde èyí fún ilé Jakọbu, kí ẹ sì polongo rẹ̀ ní Juda.
21 Muntie, mo nkwaseafo ne nnipa a munni adwene, mowɔ ani nso munhu ade, na mowɔ aso nso monte asɛm:
Gbọ́ èyí, ẹ̀yin aṣiwèrè àti aláìlọ́gbọ́n ènìyàn, tí ó lójú ti kò fi ríran tí ó létí ti kò fi gbọ́rọ̀.
22 Ɛnsɛ sɛ musuro me ana?” Sɛɛ na Awurade se. “Ɛnsɛ sɛ mo ho popo wɔ mʼanim ana? Mede nwea ato ɔhye ama po, ɔhye a ɛwɔ hɔ daa a ɛrentumi ntra. Asorɔkye bɛbɔ nanso ɛrentumi mmu mfa so; ebehuru so nanso ɛrentumi ntra.
Kò ha yẹ kí ẹ bẹ̀rù mi?” ni Olúwa wí. “Kò ha yẹ kí ẹ̀yin ó wárìrì níwájú mi bí? Mo fi yanrìn pààlà òkun, èyí tí kò le è rékọjá rẹ̀ láéláé. Ìjì lè jà, kò le è borí rẹ̀; wọ́n le è bú, wọn kò le è rékọjá rẹ̀.
23 Nanso saa nnipa yi wɔ asoɔden ne atuatew koma; wɔatwe wɔn ho afi me ho kɔ.
Ṣùgbọ́n, àwọn ènìyàn wọ̀nyí ní ọkàn líle àti ọkàn ọ̀tẹ̀, wọ́n ti yípadà, wọ́n sì ti lọ.
24 Wɔnnka nkyerɛ wɔn ho wɔn ho se, ‘Momma yensuro Awurade yɛn Nyankopɔn, a ɔma osu tɔ wɔ ne mmere mu, nea ɔma yɛn awerehyɛmu wɔ otwabere nnapɛn a wahyɛ no ho.’
Wọn kò sọ fún ara wọn pé, ‘Ẹ jẹ́ ká a bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run wa, ẹni tí ó fún wa ní òjò àkọ́rọ̀ àti àrọ̀kúrò òjò ní ìgbà rẹ̀, tí ó fi wá lọ́kàn balẹ̀ nípa ìkórè ọ̀sẹ̀ déédé.’
25 Mo amumɔyɛ abɔ eyinom agu; mo bɔne ama ade pa abɔ mo.
Àìṣedéédéé yín mú gbogbo nǹkan wọ̀nyí kúrò, ẹ̀ṣẹ̀ yín sì mú kí a fi nǹkan rere dù yín.
26 “Amumɔyɛfo bi wɔ me nkurɔfo yi mu a wɔtɛw sɛ nnipa a wosum nnomaa afiri, na wɔte sɛ wɔn a wosum mfiri yi nnipa.
“Láàrín ènìyàn mi ni ìkà ènìyàn wà tí ó wà ní ibùba bí ẹni tí ó ń dẹ ẹyẹ, àti bí àwọn tí ó ń dẹ pàkúté láti mú ènìyàn.
27 Sɛnea nnomaa ahyɛ kɛntɛn ma no saa ara na asisi ahyɛ wɔn afi amaama; wɔayeyɛ adefo anyinya tumi,
Bí àgò tí ó kún fún ẹyẹ, ilé wọn sì kún fún ẹ̀tàn; wọ́n ti di ọlọ́lá àti alágbára,
28 na wɔadodɔ srade ama wɔn ho ayɛ hanahana. Wɔn amumɔyɛsɛm no nni awiei; wɔnnka ayisaa asɛm mma wonni bem, na wɔmmɔ ahiafo tumi ho ban.
wọ́n sanra wọ́n sì ń dán. Ìwà búburú wọn kò sì lópin; wọn kò bẹ̀bẹ̀ fún ẹjọ́ àwọn aláìní baba láti borí rẹ̀. Wọn kò jà fún ẹ̀tọ́ àwọn tálákà.
29 Ɛnsɛ sɛ metwe wɔn aso wɔ eyinom ho ana?” Sɛɛ na Awurade se. “Ɛnsɛ sɛ, mʼankasa metɔ ɔman a ɛte sɛɛ so were ana?
Èmi kì yóò ha fi ìyà jẹ wọ́n fún èyí bí?” ni Olúwa wí. “Èmi kì yóò wá gbẹ̀san ara mi lára orílẹ̀-èdè bí èyí bí?
30 “Ade a ɛyɛ hu ne ahodwiriw asi wɔ asase no so:
“Nǹkan ìbànújẹ́ àti ohun ìtara ti ṣẹlẹ̀ ní ilẹ̀ náà.
31 Adiyifo no hyɛ akɔntoro, asɔfo no de wɔn dibea di tumi, na me nkurɔfo no pɛ no saa ara. Nanso awiei no dɛn na wobɛyɛ?”
Àwọn wòlíì ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ èké, àwọn àlùfáà sì ń ṣe àkóso pẹ̀lú àṣẹ ara wọn, àwọn ènìyàn mi sì ní ìfẹ́ sí èyí, kí ni ẹ̀yin yóò ṣe ní òpin?