< Yeremia 4 >
1 “Sɛ wo, Israel, wobɛsan wʼakyi a, san bra me nkyɛn,” sɛɛ na Awurade se. “Sɛ wuyi wʼahoni a ɛyɛ akyiwade fi mʼani so na sɛ woamman bio,
“Tí ìwọ yóò bá yí padà, ìwọ Israẹli, padà tọ̀ mí wá,” ni Olúwa wí. “Tí ìwọ yóò bá sì mú ìríra rẹ kúrò níwájú mi, ìwọ kí ó sì rìn kiri.
2 na sɛ wufi nokware, pɛpɛyɛ ne trenee mu ka ntam se, ‘Sɛ Awurade te ase yi,’ a afei wobehyira aman no na ne mu na wobenya anuonyam.”
Tí ó bá jẹ́ lóòtítọ́ àti òdodo ni ìwọ búra. Nítòótọ́ bí Olúwa ti wà láààyè, nígbà náà ni orílẹ̀-èdè yóò di alábùkún fún nípasẹ̀ rẹ, àti nínú rẹ̀ ni wọn yóò ṣògo.”
3 Eyi ne asɛm a, Awurade ka kyerɛ Yuda mmarima ne Yerusalem: “Munsiesie mo asase a womfuntum da, na munnnua wɔ nsɔe mu.
Èyí ni ohun tí Olúwa wí fún àwọn ènìyàn Juda àti Jerusalẹmu: “Hú gbogbo ilẹ̀ tí ẹ kò lò rí, kí o má sì ṣe gbìn sáàrín ẹ̀gún.
4 Muntwitwa mo ho twetia mma Awurade muntwitwa mo koma twetia, mo Yuda mmarima ne Yerusalemfo, anyɛ saa a mʼabufuwhyew bɛsɔre na adɛw sɛ ogya mo bɔne a moayɛ nti, ɛbɛhyew a obiara rennum.”
Kọ ara rẹ ní ilà sí Olúwa, kọ ọkàn rẹ ní ilà, ẹ̀yin ènìyàn Juda àti gbogbo ènìyàn Jerusalẹmu, bí bẹ́ẹ̀ kọ́, ìbínú mi yóò ru jáde yóò sì jó bí iná, nítorí ibi tí o ti ṣe kì yóò sí ẹni tí yóò pa á.
5 “Bɔ nkae wɔ Yuda na pae mu ka wɔ Yerusalem se ‘Hyɛn torobɛnto no wɔ asase no nyinaa so!’ Teɛ mu dennen se: ‘Mommoaboa mo ho ano! Momma yenguan nkɔ nkuropɔn a wɔabɔ ho ban no mu!’
“Kéde ní Juda, kí o sì polongo ní Jerusalẹmu, kí o sì wí pé: ‘Fun fèrè káàkiri gbogbo ilẹ̀!’ Kí o sì kígbe: ‘Kó ara jọ pọ̀! Jẹ́ kí a sálọ sí ìlú olódi.’
6 Momma frankaa so na monkɔ Sion munguan nkɔbɔ mo ho aguaa! Efisɛ mede amanehunu fi atifi fam reba, ɔsɛe a ɛyɛ hu.”
Fi àmì láti sálọ sí Sioni hàn, sálọ fún ààbò láìsí ìdádúró. Nítorí èmi ó mú àjálù láti àríwá wá, àní ìparun tí ó burú jọjọ.”
7 Gyata bi afi ne tu mu; ɔbɔɔaman bi asi mu. Wafi ne tenabea sɛ ɔrebɛsɛe wʼasase. Wo nkurow bebubu na ada mpan.
Kìnnìún ti sá jáde láti inú ibùgbé rẹ̀, apanirun orílẹ̀-èdè sì ti jáde. Ó ti fi ààyè rẹ̀ sílẹ̀ láti ba ilẹ̀ rẹ̀ jẹ́. Ìlú rẹ yóò di ahoro láìsí olùgbé.
8 Enti fura atweaatam, di awerɛhow na twa adwo, efisɛ Awurade abufuwhyew no nnan mfii yɛn so.
Nítorí náà, gbé aṣọ ọ̀fọ̀ wọ̀ káàánú kí o sì pohùnréré ẹkún, nítorí ìbínú ńlá Olúwa kò tí ì kúrò lórí wa.
9 “Saa da no,” Awurade na ose, “ɔhene no ne adwumayɛfo no bɛbɔ hu, asɔfo no bo betu, na adiyifo no ho bedwiriw wɔn.”
“Ní ọjọ́ náà,” ni Olúwa wí pé, “Àwọn ọba àti ìjòyè yóò pàdánù ẹ̀mí wọn, àwọn àlùfáà yóò wárìrì, àwọn wòlíì yóò sì fòyà.”
10 Afei, mekae se, “Aa, Otumfo Awurade, woadaadaa nnipa yi ne Yerusalem, wokae se, ‘Mubenya asomdwoe,’ wɔ bere a afoa da yɛn mene mu.”
Nígbà náà ni mo sì wí pé, “Háà! Olúwa Olódùmarè, báwo ni ìwọ ti ṣe tan àwọn ènìyàn wọ̀nyí àti Jerusalẹmu jẹ nípa sísọ wí pé, ‘Ìwọ yóò wà ní àlàáfíà,’ nígbà tí o jẹ́ wí pé idà wà ní ọ̀fun wa.”
11 Saa bere no wɔbɛka akyerɛ nnipa yi ne Yerusalem se, “Mframa a emu yɛ hyew bɛbɔ afi nkoko wosee a ɛwɔ nweatam so aba me nkurɔfo so, ɛnyɛ nea ɛpo ho anaa ehuhuw so;
Nígbà náà ni a ó sọ fún Jerusalẹmu àti àwọn ènìyàn pé, “Ẹ̀fúùfù líle láti aṣálẹ̀ fẹ́ lu àwọn ènìyàn mi, kì í ṣe láti sọ di mímọ́.
12 mframa a ano yɛ den boro saa no fi me nkyɛn. Afei mepae mu ka mʼatemmu a etia wɔn.”
Ẹ̀fúùfù líle tí ó wá láti ọ̀dọ̀ mi. Báyìí mo kéde ìdájọ́ mi lórí wọn.”
13 Hwɛ! ɔreba sɛ omununkum, ne nteaseɛnam reba sɛ mfɛtɛ, nʼapɔnkɔ ho yɛ hare sen akɔre. Yennue! Yɛawu!
Wò ó! O ń bọ̀ bí ìkùùkuu kẹ̀kẹ́ ogun rẹ̀ sì wá bí ìjì líle ẹṣin rẹ̀ sì yára ju idì lọ. Ègbé ni fún wa àwa parun.
14 Yerusalem, yi bɔne fi wo koma mu na woanya nkwa. Wode adwemmɔne bɛhyɛ wo mu akosi da bɛn?
Ìwọ Jerusalẹmu, mú búburú kúrò lọ́kàn rẹ kí o sì yè. Yóò ti pẹ́ tó tí ìwọ yóò mú èrò búburú wà ní ọkàn rẹ?
15 Nne bi rebɔ amanneɛ fi Dan, ɛrebɔ amanehunu ho dawuru fi Efraim nkoko so.
Ohùn kan sì ń kéde ní Dani o ń kókìkí ìparun láti orí òkè Efraimu wá.
16 “Monka eyi nkyerɛ aman no, mommɔ no dawuru nkyerɛ Yerusalem se, ‘Atuafo dɔm fi akyirikyiri asase bi so reba, wɔma ɔko nteɛmu so de tia Yuda nkuropɔn.
“Sọ èyí fún àwọn orílẹ̀-èdè, kéde rẹ̀ fún Jerusalẹmu pé: ‘Ọmọ-ogun ọ̀tá ń bọ̀ láti ilẹ̀ jíjìn wá wọ́n sì ń kígbe ogun láti dojúkọ ìlú Juda.
17 Wotwa ne ho hyia sɛ mmarima a wɔrewɛn afuw, efisɛ watew me so atua,’” sɛɛ na Awurade se.
Wọ́n yí i ká bí ìgbà tí àwọn ọkùnrin bá ń ṣọ́ pápá, nítorí pé ó ti dìtẹ̀ sí mi,’” ni Olúwa wí.
18 “Wo ankasa abrabɔ ne nneyɛe, na ɛde eyi aba wo so. Eyi yɛ wʼasotwe. Ɛyɛ nwen! Ɛwowɔ koma!”
“Ìwà rẹ àti ìṣe rẹ ló fa èyí bá ọ ìjìyà rẹ sì nìyìí. Báwo ló ti ṣe korò tó! Báwo ló ti ṣe gún ọkàn rẹ sí!”
19 Ao, mʼahoyeraw, mʼahoyeraw! midi me mu yaw. Me koma mu yawdi! Me koma bɔ kitirikitiri wɔ me mu, mintumi nyɛ komm. Efisɛ, mate torobɛnto no nnyigye; mate ɔko frɛ no.
Háà! Ìrora mi, ìrora mi! Mo yí nínú ìrora. Háà, ìrora ọkàn mi! Ọkàn mi lù kìkì nínú mi, n kò le è dákẹ́. Nítorí mo ti gbọ́ ohùn ìpè, mo sì ti gbọ́ igbe ogun.
20 Amanehunu di amanehunu akyi; asase no nyinaa asɛe. Wɔasɛe me ntamadan prɛko pɛ, ne me hintabea mpofirim.
Ìparun ń gorí ìparun; gbogbo ilẹ̀ náà sì ṣubú sínú ìparun lọ́gán ni a wó àwọn àgọ́ mi, tí ó jẹ́ ohun ààbò mi níṣẹ́jú kan.
21 Ɛsɛ sɛ mehwɛ ɔko frankaa no na mitie torobɛnto no nnyigye kosi da bɛn?
Yóò ti pẹ́ tó, tí èmi yóò rí ogun tí èmi yóò sì gbọ́ ìró fèrè?
22 “Me nkurɔfo yɛ nkwaseafo; wonnim me. Wɔyɛ mma a wonni adwene; wɔnte hwee ase. Wɔwɔ bɔneyɛ ho nyansa; na wonnim sɛnea wɔyɛ papa.”
“Aṣiwèrè ni àwọn ènìyàn mi; wọn kò mọ̀ mí. Wọ́n jẹ́ aláìgbọ́n ọmọ; wọ́n sì jẹ́ aláìlóye. Wọ́n mọ ibi ni ṣíṣe; wọn kò mọ bí a ti í ṣe rere.”
23 Mehwɛɛ asase no, na enni bɔbea, na ɛda mpan; mehwɛɛ ɔsorosoro, na wɔn hann no nni hɔ.
Mo bojú wo ayé, ó sì wà ní júujùu, ó sì ṣófo àti ní ọ̀run, ìmọ́lẹ̀ wọn kò sì ṣí.
24 Mehwɛɛ mmepɔw no, na wɔrewosowosow, na nkoko no nyinaa rehinhim.
Mo wo àwọn òkè ńlá, wọ́n wárìrì; gbogbo òkè kéékèèké mì jẹ̀jẹ̀.
25 Mehwɛe, na nnipa nni hɔ; wim anomaa biara atu kɔ.
Mo wò yíká n kò rí ẹnìkan; gbogbo ẹyẹ ojú ọ̀run ló ti fò lọ.
26 Mehwɛe, na nsasebere no adan nweatam na ne nkurow nyinaa asɛe wɔ Awurade anim, wɔ nʼabufuwhyew ano.
Mo bojú wò, ilẹ̀ eléso, ó sì di aṣálẹ̀ gbogbo àwọn ìlú inú rẹ̀ sì ṣubú sínú ìparun níwájú Olúwa àti níwájú ríru ìbínú rẹ̀.
27 Sɛnea Awurade se: “Wɔbɛsɛe asase no nyinaa; mmom, merensɛe no korakora.
Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Gbogbo ìlú náà yóò sì di ahoro, síbẹ̀ èmi kì yóò pa á run pátápátá.
28 Enti asase bedi awerɛhow na ɔsorosoro beduru sum, efisɛ makasa na merentwe nsan; masi gyinae na merennan no.”
Nítorí náà, ayé yóò pohùnréré ẹkún àwọn ọ̀run lókè yóò ṣú òòkùn nítorí mo ti sọ, mo sì ti pète rẹ̀ mo ti pinnu, n kì yóò sì yí i padà.”
29 Apɔnkɔsotefo ne agyantowfo nnyigyei ma kurow biara sofo guan. Ebinom kɔhyɛ nkyɛkyerɛ mu, ebinom foro kɔ abotan mu. Nkurow no nyinaa so adeda mpan; na obiara nte so.
Nípa ariwo àwọn ẹlẹ́ṣin àti àwọn tafàtafà gbogbo ìlú yóò sálọ. Ọ̀pọ̀ sálọ sínú igbó; ọ̀pọ̀ yóò sì gun orí àpáta lọ. Gbogbo ìlú náà sì di ahoro; kò sì ṣí ẹnìkan nínú rẹ̀.
30 Dɛn na woreyɛ, wo a wɔasɛe wo? Adɛn na wufura ɔkɔben de sikakɔkɔɔ agude asiesie wo ho? Adɛn na wode nnuru keka wʼani? Wohyehyɛ wo ho kwa. Wʼadɔfo bu wo animtiaa; wɔrehwehwɛ wo akum wo.
Kí ni ò ń ṣe, ìwọ tí o ti di ìjẹ tán? Ìwọ ìbá wọ ara rẹ ní aṣọ òdodo kí o sì fi wúrà ṣe ara rẹ lọ́ṣọ̀ọ́. Àwọn olólùfẹ́ rẹ kẹ́gàn rẹ; wọ́n sì ń lépa ẹ̀mí rẹ.
31 Mete osu bi te sɛ ɔbea a ɔwɔ awoko mu, apinisi te sɛ ɔbea a ɔrewo nʼabakan, Ɔbabea Sion resu te sɛ nea osi apini, ɔtrɛw ne nsa mu na ɔreka se, “Afei de meretɔ piti; wɔde me nkwa ama awudifo.”
Mo gbọ́ ìró kan bí i igbe obìnrin tó ń rọbí, tí ó ń rọbí, ìrora bí i abiyamọ ọmọbìnrin Sioni tí ń pohùnréré ẹkún ara rẹ̀. Tí ó na ọwọ́ rẹ̀ tí ó sì wí pé, “Kíyèsi i mo gbé, nítorí a ti fi ẹ̀mí mi lé àwọn apani lọ́wọ́.”