< Yesaia 14 >

1 Awurade behu Yakob mmɔbɔ; ɔbɛsan afa Israel na ɔbɛbɔ wɔn atenase wɔ wɔn ankasa asase so. Ananafo bɛba abɛka wɔn ho na wɔne Yakobfi aka abɔ mu.
Olúwa yóò fi àánú hàn fún Jakọbu, yóò tún Israẹli yàn lẹ́ẹ̀kan sí i yóò sì fi ìdí wọn kalẹ̀ ní ilẹ̀ àwọn tìkára wọn. Àwọn àjèjì yóò darapọ̀ mọ́ wọn, wọn yóò sì fọwọ́sowọ́pọ̀ pẹ̀lú ilé e Jakọbu.
2 Amanaman bɛfa wɔn de wɔn aba wɔn ankasa atenae. Na Israelfi bɛfa amanaman no ayɛ wɔn de sɛ nkoa ne mfenaa wɔ Awurade asase so. Wɔbɛyɛ wɔn a wɔyɛɛ wɔn nnommumfo no nnommum na wobedi wɔn sohwɛfo so.
Àwọn orílẹ̀-èdè yóò gbà wọ́n wọn yóò sì mú wọn wá sí ààyè e wọn. Ilé Israẹli yóò gba àwọn orílẹ̀-èdè gẹ́gẹ́ bí àwọn ẹrúkùnrin àti ẹrúbìnrin ní ilẹ̀ Olúwa. Wọn yóò kó àwọn akónilẹ́rú wọn ní ìgbèkùn wọn yóò sì jẹ ọba lórí àwọn amúnisìn wọn.
3 Na da a Awurade bɛma mo ɔhome afi amanehunu, ahoyeraw ne nkoasom dennen mu no,
Ní ọjọ́ tí Olúwa yóò fi ìtura fún un yín kúrò nínú ìpọ́njú àti ìyà àti ìdè ìkà,
4 mubedi Babiloniahene ho fɛw se: hwɛ sɛnea sohyɛfo no aba nʼawie! ne sɛnea nʼabufuw nso to atwa!
ẹ ó sì fi ọ̀rọ̀ àbùkù yìí kan ọba Babeli pé, báwo ni amúnisìn ṣe wá sí òpin! Báwo ni ìbínú rẹ̀ ṣe parí!
5 Awurade abubu otirimɔdenfo no abaa mu, sodifo ahempema no,
Olúwa ti dá ọ̀pá ìkà náà, ọ̀pá àwọn aláṣẹ,
6 nea abufuw mu no ɔde bobɔɔ wɔn toatoaa so hwehwee fam, na abufuwhyew mu otintim wɔn so a ahomegye nni mu de brɛɛ amanaman no ase no.
èyí tí ó ti lu àwọn ènìyàn bolẹ̀ pẹ̀lú ti kò dáwọ́ dúró, nínú ìrunú ni ó ṣẹ́gun àwọn orílẹ̀-èdè pẹ̀lú ìgbónára tí kò lópin.
7 Nsase no nyinaa rehome wɔ asomdwoe mu; na wɔto dwom.
Gbogbo ilẹ̀ ni ó wà ní ìsinmi àti àlàáfíà, wọ́n bú sí orin.
8 Mpo, ɔpepaw nnua ne Lebanon sida nya ho anigye na wɔka se, “Afei a wɔabrɛ wo ase yi, duatwafo biara remmetwa yɛn.”
Pẹ̀lúpẹ̀lú àwọn igi junifa àti àwọn igi kedari ti Lebanoni ń yọ̀ lórí rẹ wí pé, “Níwọ́n bí a ti rẹ̀ ọ́ sílẹ̀ báyìí, kò sí agégi tí yóò wá láti gé wa lulẹ̀.”
9 Awufo nna a ɛwɔ ase no rekeka ne ho abehyia wo kwan; ɛkanyan wɔn a wɔafi mu no honhom sɛ wɔmmɛma wo akwaaba, wɔn a na wɔyɛ akannifo wɔ wiase ɛma wɔsɔre fi wɔn nhengua so, wɔn a na wɔyɛ ahemfo wɔ amanaman so. (Sheol h7585)
Ibojì tí ó wà ní ìsàlẹ̀ ni a ru sókè láti pàdé rẹ ní ìpadàbọ̀ rẹ̀ ó ru ẹ̀mí àwọn tí ó ti lọ sókè láti wá kí ọ gbogbo àwọn tí ó jẹ́ olórí ní ayé ó mú kí wọn dìde lórí ìtẹ́ wọn gbogbo àwọn tí ó jẹ ọba lórí àwọn orílẹ̀-èdè. (Sheol h7585)
10 Wɔn nyinaa begye so, wɔbɛka akyerɛ wo se, “Wo nso woayɛ mmerɛw sɛ yɛn; woayɛ sɛ yɛn ara.”
Gbogbo wọn yóò dáhùn, wọn yóò wí fún ọ wí pé, “Ìwọ pẹ̀lú ti di aláìlera, gẹ́gẹ́ bí àwa pẹ̀lú ìwọ náà ti dàbí wa.”
11 Wo kɛseyɛ nyinaa wɔde aba ɔda mu, ne huuyɛ a efi wo asanku no; wɔde nsaammoa asɛw kɛtɛ ama wo na asunson akata wo so. (Sheol h7585)
Gbogbo rẹ̀ ni ó di ìrẹ̀sílẹ̀ lọ sí ibojì, pẹ̀lú ariwo àwọn dùùrù rẹ, àwọn ìdin ni wọ́n fọ́nkálẹ̀ lábẹ́ rẹ àwọn ekòló sì ti bò ọ́ mọ́lẹ̀. (Sheol h7585)
12 Sɛnea wufi ɔsoro abɛhwe fam, anɔpa nsoromma, adekyee babarima! Wɔato wo abɛhwe asase so, wo a na kan no wobrɛ amanaman ase!
Báwo ni ìwọ ṣe ṣubú lulẹ̀ láti ọ̀run wá, ìwọ ìràwọ̀ òwúrọ̀, ọmọ òwúrọ̀ náà! A ti sọ ọ́ sílẹ̀ sínú ayé, ìwọ tí o ti tẹ orí àwọn orílẹ̀-èdè ba rí!
13 Wokaa no wo koma mu se, “Mɛforo akɔ ɔsoro; mɛma mʼahengua so asi Onyankopɔn nsoromma atifi; mɛtena ase adi hene wɔ ahyiae bepɔw so, nea ɛkorɔn pa ara wɔ bepɔw kronkron no so.
Ìwọ sọ nínú ọkàn rẹ pé, “Èmi yóò gòkè lọ sí ọ̀run; èmi yóò gbé ìtẹ́ mi sókè ga ju àwọn ìràwọ̀ Ọlọ́run, Èmi yóò gúnwà ní orí òkè àpéjọ ní ṣóńṣó orí òkè mímọ́.
14 Mɛforo atra omununkum atifi; mɛyɛ me ho sɛ Ɔsorosoroni no.”
Èmi yóò gòkè lọ rékọjá àwọn àwọsánmọ̀; èmi yóò ṣe ara mi gẹ́gẹ́ bí Ọ̀gá-ògo.”
15 Nanso wɔde wo abɛto ɔda mu, amoa donkudonku ase tɔnn. (Sheol h7585)
Ṣùgbọ́n a ti rẹ̀ ọ́ sílẹ̀ wọ inú ibojì lọ lọ sí ìsàlẹ̀ ọ̀gbun. (Sheol h7585)
16 Wɔn a wuhu wo no hwɛ wo haw, wodwen nea ato wo no ho bisa se, “Ɛnyɛ ɔbarima a ɔwosow asase na ɔmaa ahenni ho popoe,
Àwọn tí ó rí ọ yóò tẹjúmọ́ ọ, wọ́n ronú nípa àtubọ̀tán rẹ: “Ǹjẹ́ èyí ni ẹni tí ó mi ayé tìtì tí ó sì jẹ́ kí àwọn ilẹ̀ ọba wárìrì.
17 ɔbarima a ɔmaa wiase dan nweatam, nea ɔdan ne nkuropɔn butuwii na wamma ne nneduafo ankɔ wɔn nkyi no ni?”
Ẹni tí ó sọ ayé di aginjù, tí ó sì pa ìlú ńlá ńlá rẹ̀ run tí kò dá àwọn òǹdè rẹ̀ sílẹ̀ láti padà sílé?”
18 Amanaman ahemfo no nyinaa wɔadeda wɔn obiara wɔ ne da mu.
Gbogbo àwọn ọba orílẹ̀-èdè ni a tẹ́ sílẹ̀ ọ̀kọ̀ọ̀kan nínú ibojì tirẹ̀.
19 Nanso wɔapam wo afi wo da mu te sɛ dubaa a wɔapo; wɔde wɔn a wɔatotɔ akata wo so, wɔn a wɔtɔɔ wɔ afoa ano, wɔn a wosian kɔ abo amoa mu, te sɛ funu a wɔatiatia so,
Ṣùgbọ́n a jù ọ́ síta kúrò nínú ibojì gẹ́gẹ́ bí ẹ̀ka igi tí a kọ̀sílẹ̀, àwọn tí a pa ni ó bò ọ́ mọ́lẹ̀, àwọn tí idà ti gún, àwọn tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ sínú òkúta inú ọ̀gbun. Gẹ́gẹ́ bí òkú ó di ìtẹ̀mọ́lẹ̀ ní abẹ́ àtẹ́lẹsẹ̀,
20 Wɔrensie wo nka wɔn ho, efisɛ woasɛe wʼasase na wakunkum wo nkurɔfo. Otirimɔdenfo asefo no wɔrenkae wɔn bio. Wo babarima renni wʼade sɛ ɔhene.
a kò ní sin ọ́ pẹ̀lú wọn, nítorí pé o ti ba ilẹ̀ rẹ jẹ́ o sì ti pa àwọn ènìyàn rẹ. Ìran àwọn ìkà ni a kì yóò dárúkọ wọn mọ́.
21 Siesie faako a wobekunkum ne mmabarima wɔ wɔn agyanom bɔne nti; ɛnsɛ sɛ wɔsɔre di asase no so na wɔde wɔn nkuropɔn pete so.
Tọ́jú ibìkan tí a ó ti pa àwọn ọmọkùnrin rẹ nítorí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba ńlá wọn, wọn kò gbọdọ̀ dìde láti jogún ilẹ̀ kí wọ́n sì bo orí ilẹ̀ pẹ̀lú àwọn ìlú u wọn.
22 “Mɛsɔre atia wɔn,” Sɛnea Asafo Awurade se ni. “Metwa ne din ne ne nkae, ne mma ne ne nenanom afi Babilonia ho,” sɛnea Asafo Awurade se ni.
“Èmi yóò dìde sókè sí wọn,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí. “Èmi yóò ké orúkọ rẹ̀ kúrò ní Babeli àti àwọn tí ó sálà, àwọn ọmọ àti ìran rẹ̀,” ni Olúwa wí.
23 “Mɛdan no ayɛ faako a mpatu wɔ ne ɔwora; mede ɔsɛeprae bɛpra no,” sɛnea Asafo Awurade se ni.
Èmi yóò yí i padà sí ibùgbé àwọn òwìwí àti sí irà; Èmi yóò fi ọwọ́ ìparun gbá a, ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
24 Asafo Awurade aka ntam se, “Nokware, sɛnea mahyehyɛ no, saa ara na ɛbɛyɛ, na sɛnea masusuw no, ɛrensesa.
Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti búra, “Gẹ́gẹ́ bí mo ti ṣètò, bẹ́ẹ̀ ni yóò rí, àti bí mo ti pinnu, bẹ́ẹ̀ ni yóò sì dúró.
25 Mɛsɛe Asiria pasaa wɔ mʼasase so; metiatia no so me mmepɔw so. Obeyi ne konnua afi me nkurɔfo so, na nʼadesoa nso afi wɔn so.”
Èmi yóò run Asiria ní ilẹ̀ mi, ní àwọn orí òkè mi ni èmi yóò ti rún un mọ́lẹ̀. Àjàgà rẹ̀ ni a ó mú kúrò lọ́rùn àwọn ènìyàn mi, ẹrù u rẹ̀ ni ó mú kúrò ní èjìká wọn.”
26 Eyi ne nhyehyɛe a wɔayɛ ama wiase nyinaa; eyi ne nsa a wɔateɛ wɔ aman nyinaa so.
Èyí ni ètò tí a pinnu rẹ̀ fún gbogbo ayé, èyí ni ọwọ́ tí a nà jáde káàkiri gbogbo orílẹ̀-èdè.
27 Na sɛ Asafo Awurade ayɛ nʼadwene a hena na obesiw no kwan? Na sɛ wateɛ ne nsa, hena na obesianka no?
Nítorí Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti pète, ta ni yóò sì ká a lọ́wọ́ kò? Ọwọ́ọ rẹ ti nà jáde, ta ni ó sì le è fà á padà?
28 Saa adehu yi baa afe a ɔhene Ahas wui no:
Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ yí wá ní ọdún tí ọba Ahasi kú.
29 Munnni ahurusi, mo Filistifo, sɛ abaa a ɛbɔɔ mo no mu abubu; saa ɔwɔ no ase na ahurutoa befi aba, na nʼaba bɛyɛ ɔwɔ a ne ho yɛ hare na nʼano wɔ bɔre.
Má ṣe yọ̀, gbogbo ẹ̀yin Filistia, pé ọ̀pá tí ó lù ọ́ ti dá; láti ibi gbòǹgbò ejò náà ni paramọ́lẹ̀ yóò ti hù jáde, èso rẹ̀ yóò sì jẹ́ oró ejò tí í jóni.
30 Ahiafo mu hiani benya didibea, na mmɔborɔni bɛda asomdwoe mu. Nanso wʼasefo de, mede ɔkɔm bɛtɔre wɔn ase; ebekunkum wo nkae no.
Ẹni tí ó kúṣẹ̀ẹ́ jù yóò ní pápá oko, àwọn aláìní yóò sì dùbúlẹ̀ láìléwu. Ṣùgbọ́n gbòǹgbò o rẹ̀ ni èmi ó fi ìyàn parun, yóò sì ké àwọn ẹni rẹ tí ó sálà kúrò.
31 Twa adwo, kurow pon! Su teɛ mu kuropɔn! munguan, mo Filistifo! Wusiw kumɔnn bi fi atifi fam reba, na obiara ntwentwɛn ne nan ase wɔ wɔn mu.
Hu, ìwọ ẹnu-ọ̀nà! Kígbe, ìwọ ìlú! Yọ́ kúrò, gbogbo ẹ̀yin Filistia! Èéfín kurukuru kan ti àríwá wá, kò sì ṣí amóríbọ́ kan nínú ẹgbẹ́ wọn.
32 Mmuae bɛn na wɔde bɛma saa ɔman no ananmusifo? “Awurade de Sion atim hɔ, ne mu na nʼamanehunufo benya guankɔbea.”
Kí ni ìdáhùn tí a ó fún agbẹnusọ orílẹ̀-èdè náà? “Olúwa ti fi ìdí Sioni kalẹ̀, àti nínú rẹ̀ ni àwọn ènìyàn rẹ̀ tí a ti pọ́n ọn lójú yóò ti rí ààbò o wọn.”

< Yesaia 14 >