< Zekeriya 13 >

1 “O gün Davut soyunu ve Yeruşalim'de yaşayanları günahtan ve ruhsal kirlilikten arındırmak için bir pınar açılacak.
“Ní ọjọ́ náà ìsun kan yóò ṣí sílẹ̀ fún ilé Dafidi àti fún àwọn ará Jerusalẹmu, láti wẹ̀ wọ́n mọ́ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ àti àìmọ́ wọn.
2 O gün ülkeden putların adlarını kaldıracağım, bir daha anılmayacaklar” diyor Her Şeye Egemen RAB, “Sahte peygamberleri de, kirli ruhu da ülkeden uzaklaştıracağım.
“Yóò sì ṣe ní ọjọ́ náà ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ni èmi ó gé orúkọ àwọn òrìṣà kúrò ni ilẹ̀ náà, a kì yóò sì rántí wọn mọ́, àti pẹ̀lú èmi ó mú àwọn wòlíì èké àti àwọn ẹ̀mí àìmọ́ kúrò ni ilẹ̀ náà.
3 Biri yine peygamberlik edecek olursa, öz annesiyle babası, ‘Öleceksin, çünkü RAB'bin adıyla yalan söylüyorsun’ diyecekler. Peygamberlik ettiğinde de öz annesi babası onun bedenini deşecekler.
Yóò sì ṣe, nígbà tí ẹnìkan yóò sọtẹ́lẹ̀ síbẹ̀, ni baba rẹ̀ àti ìyá rẹ̀ tí ó bí í yóò wí fún un pé, ‘Ìwọ ki yóò yè, nítorí ìwọ ń sọ ọ̀rọ̀ èké ni orúkọ Olúwa.’ Àti baba rẹ̀ àti ìyá rẹ̀ tí o bí í yóò gun un ni àgúnpa nígbà tí ó bá sọtẹ́lẹ̀.
4 “O gün her peygamber peygamberlik ederken gördüğü görümden utanacak; insanları aldatmak için çuldan giysi giymeyecek.
“Yóò sì ṣe ní ọjọ́ náà, ojú yóò tí àwọn wòlíì èké olúkúlùkù nítorí ìran rẹ̀, nígbà tí òun ba tí sọtẹ́lẹ̀; bẹ́ẹ̀ ni wọn kì yóò sì wọ aṣọ wòlíì onírun rẹ̀ tí o fi ń tan ní jẹ.
5 ‘Ben peygamber değilim, çiftçiyim. Gençliğimden beri hep tarlada çalıştım’ diyecek.
Ṣùgbọ́n òun o wí pé, ‘Èmi kí í ṣe wòlíì, àgbẹ̀ ni èmi; nítorí tí a ti fi mí ṣe ìránṣẹ́ láti ìgbà èwe mi wá.’
6 Biri, ‘Bağrındaki bu yaralar ne?’ diye sorduğunda da, ‘Bunlar dostlarımın evinde aldığım yaralar’ diye yanıtlayacak.”
Ẹnìkan ó sì wí fún un pé, ‘Ọgbẹ́ kín ní wọ̀nyí ni ẹ̀yìn rẹ?’ Òun o sì dáhùn pé, ‘Wọ̀nyí ni ibi tí a ti sá mi ní ilé àwọn ọ̀rẹ́ mi.’
7 “Uyan, ey kılıç! Çobanıma, yakınıma karşı harekete geç” Diyor Her Şeye Egemen RAB. “Çobanı vur da Koyunlar darmadağın olsun. Ben de elimi küçüklere karşı kaldıracağım.
“Dìde, ìwọ idà, sí Olùṣọ́-àgùntàn mi, àti sí ẹni tí í ṣe ẹnìkejì mi,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Kọlu Olùṣọ́-àgùntàn, àwọn àgùntàn a sì túká: èmi o sì yí ọwọ́ mi sí àwọn kéékèèké.
8 Bütün ülkede” diyor RAB, “Halkın üçte ikisi vurulup ölecek, Üçte biri sağ kalacak.
Yóò sì ṣe, ni gbogbo ilẹ̀,” ni Olúwa wí, “a ó gé apá méjì nínú rẹ̀ kúrò yóò sì kú; ṣùgbọ́n apá kẹta yóò kù nínú rẹ̀.
9 Kalan üçte birini ateşten geçireceğim, Onları gümüş gibi arıtacağım, Altın gibi sınayacağım. Beni adımla çağıracaklar, Ben de onlara karşılık vereceğim, ‘Bunlar benim halkım’ diyeceğim. Onlar da, ‘Tanrımız RAB'dir’ diyecekler.”
Èmi ó sì mú apá kẹta náà la àárín iná, èmi yóò sì yọ́ wọn bí a ti yọ́ fàdákà, èmi yóò sì dán wọn wò, bi a tí ń dán wúrà wò: wọn yóò sì pé orúkọ mi, èmi yóò sì dá wọn lóhùn: èmi yóò wí pé, ‘Àwọn ènìyàn mi ni,’ àwọn yóò sì wí pé, ‘Olúwa ni Ọlọ́run wa.’”

< Zekeriya 13 >