< Çölde Sayim 30 >

1 Musa İsrail'in oymak önderlerine şöyle dedi: “RAB şöyle buyurdu:
Mose sì sọ fún olórí àwọn ẹ̀yà ọmọ Israẹli pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa pàṣẹ,
2 ‘Eğer bir adam RAB'be adak adar ya da ant içerek kendini yükümlülük altına sokarsa, verdiği sözü bozmayacak, ağzından her çıkanı yerine getirecek.
nígbà tí ọkùnrin kan bá jẹ́ ẹ̀jẹ́ sí Olúwa tàbí búra láti fi de ara rẹ̀ ní ìdè kí òun má bà ba ọ̀rọ̀ rẹ̀ jẹ́ kí ó ṣe gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe sọ.
3 “‘Genç bir kadın babasının evindeyken RAB'be adak adar ya da kendini yükümlülük altına sokarsa,
“Nígbà tí ọmọbìnrin kan bá sì wà ní ilé baba rẹ̀ tó bá jẹ́ ẹ̀jẹ́ fún Olúwa tàbí búra láti fi de ara rẹ̀
4 babası da onun RAB'be adadığı adağı ve kendini yükümlülük altına soktuğunu duyar, ona karşı çıkmazsa, kadının adadığı adaklar ve kendini altına soktuğu yükümlülük geçerli sayılacak.
tí baba rẹ̀ bá sì gbọ́ ẹ̀jẹ́ rẹ̀ tàbí ìdè rẹ̀ tí kò sì sọ nǹkan kan sí i, kí gbogbo ẹ̀jẹ́ rẹ̀ kí ó dúró àti gbogbo ìdè tí ó fi de ara rẹ̀ yóò sì dúró.
5 Ama babası bunları duyduğu gün engel olursa, kadının adadığı adaklar ve kendini altına soktuğu yükümlülük geçerli sayılmayacak; RAB onu bağışlayacak, çünkü babası ona engel olmuştur.
Ṣùgbọ́n tí baba rẹ̀ bá kọ̀ fun un ní ọjọ́ tí ó gbọ́, kò sí ọ̀kan nínú ẹ̀jẹ́ rẹ̀ tàbí nínú ìdè tí ó fi de ara rẹ̀ tí yóò dúró; Olúwa yóò sì tú u sílẹ̀ nítorí baba rẹ̀ kọ̀ fún un.
6 “‘Eğer kadın adak adadıktan ya da düşünmeden kendini yükümlülük altına soktuktan sonra evlenirse,
“Tí ó bá sì ní ọkọ lẹ́yìn ìgbà tí ó jẹ́ ẹ̀jẹ́ tàbí lẹ́yìn ìgbà tí ó sọ ọ̀rọ̀ kan láti ẹnu rẹ̀ jáde nínú èyí tí ó fi de ara rẹ̀ ní ìdè,
7 kocası da bunu duyar ve aynı gün ona karşı çıkmazsa, adadığı adaklar ve kendini altına soktuğu yükümlülük geçerli sayılacak.
tí ọkọ rẹ̀ sì gbọ́ nípa èyí ṣùgbọ́n tí kò sọ nǹkan kan, nígbà náà ni ẹ̀jẹ́ tàbí ìdè tí ó fi de ara rẹ̀ tó dúró.
8 Ama kocası bunu duyduğu gün engel olur, kadının adadığı adağı ya da düşünmeden kendini altına soktuğu yükümlülüğü geçerli saymazsa, RAB kadını bağışlayacaktır.
Ṣùgbọ́n tí ọkọ rẹ̀ bá kọ̀ nígbà tí ó gbọ́, ǹjẹ́ òun yóò mú ẹ̀jẹ́ rẹ̀ tí ó jẹ́ àti ohun tí ó ti ti ẹnu rẹ̀ jáde, èyí tí ó fi de ara rẹ̀ dasán, Olúwa yóò sì dáríjì í.
9 “‘Dul ya da boşanmış bir kadının adadığı adak, kendini yükümlülük altına soktuğu her şey geçerli sayılacak.
“Ṣùgbọ́n ẹ̀jẹ́ kí ẹ̀jẹ́ tàbí ìdè kí ìdè tí opó tàbí obìnrin tí a kọ̀sílẹ̀ bá ṣe yóò wà lórí rẹ̀.
10 “‘Eğer bir kadın evliyken bir adak adar ya da ant içerek kendini yükümlülük altına sokarsa,
“Bí obìnrin tí ó ń gbé pẹ̀lú ọkọ rẹ̀ bá jẹ́ ẹ̀jẹ́ tàbí de ara rẹ̀ ní ìdè lábẹ́ ìbúra,
11 kocası da bunu duyar, karşı çıkmaz, ona engel olmazsa, kadının adadığı bütün adaklar ya da kendini altına soktuğu her yükümlülük geçerli sayılacak.
tí ọkọ rẹ̀ bá sì gbọ́, ṣùgbọ́n tí kò sọ̀rọ̀, tí kò sì kọ̀, nígbà náà ni ẹ̀jẹ́ rẹ̀ yóò dúró.
12 Ama kocası bunları duyduğu gün engel olursa, kadının adadığı bütün adaklar ve kendini altına soktuğu yükümlülük geçerli sayılmayacak. Kocası geçersiz kılmıştır, RAB kadını bağışlayacak.
Ṣùgbọ́n tí ọkọ rẹ̀ bá sọ wọ́n dasán, nígbà tí ó gbọ́, nígbà náà kò sí ẹ̀jẹ́ tàbí ìdè tí ó ti ẹnu rẹ̀ jáde tí yóò dúró, ọkọ rẹ̀ ti sọ wọ́n dasán, Olúwa yóò tú u sílẹ̀.
13 Kocası, kadının kendi isteklerini denetlemesi için adadığı adağı ya da ant içerek kendini altına soktuğu yükümlülüğü onaylayabilir ya da geçersiz kılabilir.
Ọkọ rẹ̀ lè ṣe ìwádìí tàbí sọ ọ́ dasán ẹ̀jẹ́ tàbí ìbúra ìdè tí ó ti ṣe láti fi de ara rẹ̀.
14 Eğer kocası bir gün içinde bu konuda ona karşı çıkmazsa, bütün adaklarını ya da yükümlülüklerini onaylamış olur. Onları duyduğu gün kadına karşı çıkmamakla onaylamış sayılır.
Ṣùgbọ́n tí ọkọ rẹ̀ kò bá sọ nǹkan kan sí í nípa rẹ̀ ní ọjọ́ dé ọjọ́, nígbà náà ni ó ṣe ìwádìí nípa ẹ̀jẹ́ àti ìbúra ìdè tí ó dè é. Kí ọkùnrin náà ṣe ìwádìí lórí rẹ̀ láìsọ nípa rẹ̀ si nígbà tí ó gbọ́ nípa rẹ̀.
15 Eğer onları duyduktan bir süre sonra engel olursa, kadının suçundan kocası sorumlu olacaktır.’”
Bí ó ti wù kí ó rí, bí ọkùnrin náà bá sọ ọ́ dasán, ní àkókò kan lẹ́yìn tí ó ti gbọ́ wọn, nígbà náà ó jẹ̀bi ọ̀rọ̀ náà.”
16 Erkekle karısı, babayla evinde yaşayan genç kızı arasındaki ilişki konusunda RAB'bin Musa'ya buyurduğu kurallar bunlardır.
Èyí ni ìlànà tí Olúwa fún Mose nípa ìbátan láàrín ọkùnrin àti obìnrin àti láàrín baba àti ọ̀dọ́mọbìnrin rẹ̀ tí ó sì ń gbé ní ilé rẹ̀.

< Çölde Sayim 30 >