< Nahum 1 >

1 Ninova ile ilgili bildiri, Elkoşlu Nahum'un görümünü anlatan kitaptır.
Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ nípa Ninefe. Ìwé ìran Nahumu ará Elkoṣi.
2 RAB kıskanç, öç alıcı bir Tanrı'dır. Öç alır ve gazapla doludur. Hasımlarından öç alır, Düşmanlarına karşı öfkesi süreklidir.
Ọlọ́run ń jẹ owú, ó sì ń gbẹ̀san, Olúwa ń gbẹ̀san, ó sì kún fún ìbínú. Olúwa ń gbẹ̀san lára àwọn ọ̀tá rẹ̀. Ìbínú rẹ̀ kò sì yí padà lórí àwọn ọ̀tá rẹ̀.
3 RAB tez öfkelenmez ve çok güçlüdür. Suçlunun suçunu asla yanına koymaz. Geçtiği yerde kasırgalar, fırtınalar kopar. O'nun ayaklarının tozudur bulutlar.
Olúwa lọ́ra láti bínú, ó sì tóbi ní agbára; Olúwa kì yóò fi àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ sílẹ̀ láìjìyà. Ọ̀nà rẹ̀ wà nínú afẹ́fẹ́ àti nínú ìjì, ìkùùkuu sánmọ̀ sì ni eruku ẹsẹ̀ rẹ̀.
4 Bir buyrukla kurutur denizi, Kurutur bütün ırmakları. Solar Başan'ın, Karmel Dağı'nın yeşillikleri Ve Lübnan'ın çiçekleri.
Ó bá òkun wí, ó sì mú kí ó gbẹ; Ó sìsọ gbogbo odò di gbígbẹ. Baṣani àti Karmeli sì rọ. Ìtànná Lebanoni sì rẹ̀ sílẹ̀.
5 Dağlar RAB'bin önünde titrer, Erir tepeler. Yer sarsılır önünde. Dünya ve üzerinde yaşayanların tümü titrer.
Àwọn òkè ńlá wárìrì níwájú rẹ̀, àwọn òkè kéékèèké sì di yíyọ́, ilẹ̀ ayé sì jóná níwájú rẹ̀, àní ayé àti gbogbo àwọn tí ń gbé inú rẹ̀.
6 O'nun gazabına kim karşı durabilir, Kim dayanabilir kızgın öfkesine? Ateş gibi dökülür öfkesi, Kayaları paramparça eder.
Ta ni ó lé dúró níwájú ìbínú rẹ̀? Ta ni ó lé faradà gbígbóná ìbínú rẹ̀? Ìbínú rẹ̀ tú jáde bí iná; àwọn àpáta sì fọ́ túútúú níwájú rẹ̀.
7 RAB iyidir, Sığınaktır sıkıntı anında. Korur kendisine sığınanları.
Rere ni Olúwa, òun ni ààbò ní ọjọ́ ìpọ́njú. Òun sì tọ́jú àwọn tí ó gbẹ́kẹ̀lé e,
8 Ama Ninova'yı azgın sellerle yok edecek, Düşmanlarını karanlığa sürecek.
ṣùgbọ́n pẹ̀lú ìkún omi ńlá ní òun yóò fi ṣe ìparun láti ibẹ̀ dé òpin; òkùnkùn yóò sì máa lépa àwọn ọ̀tá rẹ̀.
9 RAB'be karşı neler tasarlarsanız, Hepsini yok edecek. İkinci kez kimse karşı koyamayacak.
Kí ni ẹ̀yìn ń gbìmọ̀ lòdì sí Olúwa? Òun yóò fi òpin sí i, ìpọ́njú kì yóò wáyé ní ìgbà kejì.
10 Birbirine dolaşmış dikenler gibi, Kuru anız gibi, Yanıp biteceksiniz, ey ayyaşlar.
Wọn yóò sì lọ́lù papọ̀ bí ẹ̀gún òṣùṣú wọn yóò sì mu àmupara nínú ọtí wáìnì wọn a ó sì run wọn gẹ́gẹ́ bi àgékù koríko gbígbẹ.
11 Ey Ninova, RAB'be karşı kötülük tasarlayan, Şer öğütleyen kişi senden çıktı.
Láti ọ̀dọ̀ rẹ, ìwọ Ninefe, ni ẹnìkan ti jáde wá tí ó ń gbèrò ibi sí Olúwa ti ó sì ń gbìmọ̀ búburú.
12 RAB diyor ki, “Asurlular güçlü ve çok olsalar bile, yok olup gidecekler. Ey halkım, seni sıkıntıya soktuysam da, bir daha sokmayacağım.
Báyìí ni Olúwa wí: “Bí wọ́n tilẹ̀ ni ìfọwọ́sowọ́pọ̀, tí wọ́n sì pọ̀ níye, ṣùgbọ́n, báyìí ní a ó ké wọn lulẹ̀, nígbà tí òun ó bá kọjá. Bí mo tilẹ̀ ti pọ́n ọ lójú ìwọ Juda, èmi kì yóò pọ́n ọ lójúmọ́.
13 Şimdi boyunduruğunu parçalayıp üzerindeki bağları koparacağım.”
Nísinsin yìí ni èmi yóò já àjàgà wọn kúrò ní ọrùn rẹ èmi yóò já ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀ rẹ dànù.”
14 RAB, “Artık soyunu sürdürecek torunların olmasın” Diye buyurdu, ey Ninova. “Tanrılarının tapınağındaki oyma ve dökme putları yok edeceğim” diyor. “Mezarını hazırlayacağım. Çünkü sen aşağılıksın.”
Olúwa ti fi àṣẹ kan lélẹ̀ nítorí tìrẹ Ninefe: “Ìwọ kì yóò ni irú-ọmọ láti máa jẹ́ orúkọ rẹ mọ́, Èmi yóò pa ère fínfín àti ère dídà run tí ó wà nínú tẹmpili àwọn ọlọ́run rẹ. Èmi yóò wa ibojì rẹ, nítorí ẹ̀gbin ni ìwọ.”
15 İşte, müjde getirenin ayakları dağları aşıp geliyor, Size esenlik haberini getiriyor. Ey Yahudalılar, bayramlarınızı kutlayın, Adak sözünüzü yerine getirin. O kötü ulusun istilasına uğramayacaksınız bir daha. Çünkü o büsbütün yok edildi.
Wò ó, lórí àwọn òkè, àwọn ẹsẹ̀ ẹni tí ó mú ìròyìn ayọ̀ wá, ẹni tí ó ń kéde àlàáfíà. Ìwọ Juda, pa àṣẹ rẹ tí ó ní ìrònú mọ́, kí ó sì san àwọn ẹ̀jẹ́ rẹ. Àwọn ènìyàn búburú kì yóò sì gbóguntì ọ́ mọ́; wọn yóò sì parun pátápátá.

< Nahum 1 >