< Mika 1 >

1 Yahuda kralları Yotam, Ahaz ve Hizkiya zamanında RAB Moreşetli Mika'ya, Samiriye ve Yeruşalim'le ilgili olarak bir görümde şunu bildirdi:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó tọ Mika ará Moreṣeti wá ní àkókò ìjọba Jotamu, Ahasi, àti Hesekiah, àwọn ọba Juda nìwọ̀nyí, ìran tí ó rí nípa Samaria àti Jerusalẹmu.
2 Ey halklar, hepiniz duyun; Ey dünya ve bütün içindekiler, dinleyin. Egemen RAB kendi kutsal tapınağından size karşı tanıklık edecek.
Ẹ gbọ́, gbogbo ẹ̀yin ènìyàn, fetísílẹ̀, ìwọ ayé àti gbogbo ohun tó wà níbẹ̀, kí Olúwa Olódùmarè lè ṣe ẹlẹ́rìí sí yín, Olúwa láti inú tẹmpili mímọ́ rẹ̀ wá.
3 İşte, RAB yerinden çıkıp gelecek, Yeryüzüne inip dağ doruklarında yürüyecek.
Wò ó! Olúwa ń bọ̀ wá láti ibùgbé rẹ̀; yóò sọ̀kalẹ̀, yóò sì tẹ ibi gíga ayé mọ́lẹ̀.
4 Dağlar O'nun önünde ateş karşısında eriyen balmumu gibi eriyecek, Vadiler, bayır aşağı akan sular gibi yarılacak.
Àwọn òkè ńlá yóò sí yọ́ lábẹ́ rẹ̀, àwọn àfonífojì yóò sì pínyà, bí idà níwájú iná, bí omi tí ó ń sàn lọ ni ibi gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́.
5 Bütün bunlar Yakupoğulları'nın isyanı Ve İsrail halkının günahları yüzünden olacak. Yakupoğulları'nın isyanından kim sorumlu? Samiriye değil mi? Yahuda'daki putperestlikten kim sorumlu? Yeruşalim değil mi?
Nítorí ìré-òfin-kọjá Jakọbu ni gbogbo èyí, àti nítorí ẹ̀ṣẹ̀ ilé Israẹli. Kí ni ìré-òfin-kọjá Jakọbu? Ǹjẹ́ Samaria ha kọ? Kí ni àwọn ibi gíga Juda? Ǹjẹ́ Jerusalẹmu ha kọ?
6 Bu yüzden RAB, “Samiriye'yi kırdaki taş yığınına, Bağ dikilecek yere çevireceğim” diyor, “Taşlarını vadiye döküp temellerini açacağım.
“Nítorí náà, èmi yóò ṣe Samaria bí òkìtì lórí pápá, bí ibi ti à ń lò fún gbígbin ọgbà àjàrà. Èmi yóò gbá àwọn òkúta rẹ̀ dànù sínú àfonífojì. Èmi yóò sí tú ìpilẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ palẹ̀.
7 Bütün putları paramparça edilecek, Tapınaklarındaki fahişelere verilen armağanlar yakılacak. Samiriye'nin bütün putlarını yok edeceğim. Fahişelerin ücretiyle topladığı armağanlar Yine fahişelere ücret olacak.”
Gbogbo àwọn ère fínfín rẹ̀ ni a ó fọ́ sí wẹ́wẹ́ gbogbo àwọn ẹ̀bùn tẹmpili rẹ̀ ni a ó fi iná sun, Èmi yóò sì pa gbogbo àwọn òrìṣà rẹ̀ run. Nítorí tí ó ti kó àwọn ẹ̀bùn rẹ̀ jọ láti inú owó èrè panṣágà, gẹ́gẹ́ bí owó èrè panṣágà, wọn yóò sì tún padà sí owó iṣẹ́ panṣágà.”
8 Ben Mika, bundan ötürü ağlayıp ağıt yakacağım, Çırçıplak, yalınayak dolaşacağım. Çakal gibi uluyup baykuş gibi öteceğim.
Nítorí èyí, èmi yóò sì sọkún, èmi yóò sì pohùnréré ẹkún: èmi yóò máa lọ ní ẹsẹ̀ lásán àti ní ìhòhò. Èmi yóò ké bí akátá, èmi yóò sì máa dárò bí àwọn ọmọ ògòǹgò.
9 Çünkü Samiriye'nin yaraları onmaz. Yahuda da aynı sona uğramak üzere. Halkımın yaşadığı Yeruşalim'in kapılarına dayandı yıkım.
Nítorí tí ọgbẹ́ rẹ̀ jẹ́ aláìlèwòtán; ó sì ti wá sí Juda. Ó sì ti dé ẹnu-bodè àwọn ènìyàn mi, àní sí Jerusalẹmu.
10 Bunu Gat'a duyurmayın, Ağlamayın sakın! Beytofra'da toz toprak içinde yuvarlanın.
Ẹ má ṣe sọ ní Gati ẹ má ṣe sọkún rárá. Ní ilẹ̀ Beti-Ofra mo yí ara mi nínú eruku.
11 Ey Şafir halkı, Çıplak ve utanç içinde geçip git. Saanan'da yaşayanlar kentlerinden çıkamayacaklar, Beytesel halkı yas tutacak. Kesecek sizden yardımını.
Ẹ kọjá lọ ni ìhòhò àti ni ìtìjú, ìwọ tí ó ń gbé ni Ṣafiri. Àwọn tí ó ń gbé ni Saanani kì yóò sì jáde wá. Beti-Eseli wà nínú ọ̀fọ̀; a ó sì gba ààbò rẹ̀ kúrò lọ́wọ́ yin.
12 Marot'ta yaşayanlar kurtulmayı sabırsızlıkla bekliyor. Çünkü RAB'bin gönderdiği felaket Yeruşalim'in kapılarına dayandı.
Nítorí àwọn tí ó ń gbé ni Marati ń retí ìre, ṣùgbọ́n ibi sọ̀kalẹ̀ ti ọ̀dọ̀ Olúwa wá sí ẹnu-bodè Jerusalẹmu.
13 Ey Lakiş'te oturanlar, atları koşun arabalara. Siyon Kenti'ni günaha ilk düşüren siz oldunuz. Çünkü İsrail'in isyanını örnek aldınız.
Ìwọ olùgbé Lakiṣi, dì kẹ̀kẹ́ mọ́ ẹranko tí ó yára. Òun sì ni ìbẹ̀rẹ̀ ẹ̀ṣẹ̀ sí àwọn ọmọbìnrin Sioni, nítorí a rí àìṣedéédéé Israẹli nínú rẹ̀.
14 Bundan ötürü Moreşet-Gat'a veda armağanları vereceksiniz. İsrail kralları Akziv Kenti'nden boşuna yardım bekleyecek.
Nítorí náà ni ìwọ ó ṣe fi ìwé ìkọ̀sílẹ̀ fún Moreṣeti Gati. Àwọn ilé Aksibu yóò jẹ́ ẹlẹ́tàn sí àwọn ọba Israẹli.
15 Ey Mareşa'da yaşayanlar, RAB kentinizi ele geçirecek olanı üzerinize gönderecek. İsrail'in yüce önderleri Adullam'daki mağaraya sığınacak.
Èmi yóò sì mú àrólé kan wá sórí rẹ ìwọ olùgbé Meraṣa. Ẹni tí ó jẹ́ ògo Israẹli yóò sì wá sí Adullamu.
16 Sevgili çocuklarınız için saçlarınızı yolup kazıyın. Akbabalar gibi kafalarınızın keli görünsün. Çünkü çocuklarınız sizden alınıp sürgüne götürülecek.
Fá irun orí rẹ nínú ọ̀fọ̀ nítorí àwọn ọmọ rẹ aláìlágbára, sọ ra rẹ̀ di apárí bí ẹyẹ igún, nítorí wọn yóò kúrò lọ́dọ̀ rẹ lọ sí ìgbèkùn.

< Mika 1 >